< 1 Kings 22 >

1 Fún ọdún mẹ́ta kò sì sí ogun láàrín Aramu àti Israẹli.
Aram laklo neh Israel laklo ah kum thum caemtloek om kolla kho a sak uh.
2 Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, Jehoṣafati ọba Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti rí ọba Israẹli.
A kum thum dongla a pha vaengah tah Judah manghai Jehoshaphat te Israel manghai taengla suntla.
3 Ọba Israẹli sì ti wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin mọ̀ pé ti wa ni Ramoti Gileadi, àwa sì dákẹ́ síbẹ̀, a kò sì gbà á padà lọ́wọ́ ọba Aramu?”
Te vaengah Israel manghai loh a sal rhoek te, “Ramothgilead te mamih kah la na ming nama? Tedae Aram manghai kut lamloh te te n'lat parhi mamih m'mong uh coeng,” a ti nah.
4 Ó sì béèrè lọ́wọ́ Jehoṣafati pé, “Ṣé ìwọ yóò bá mi lọ láti lọ bá Ramoti Gileadi jà?” Jehoṣafati sì dá ọba Israẹli lóhùn pé, “Èmi bí ìwọ, ènìyàn mi bí ènìyàn rẹ, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
Te phoeiah Jehoshaphat te Ramothgilead ah caemtloek ham kai neh cet sih ne? a ti nah. Jehoshaphat loh Israel manghai taengah, “Kai khaw nang banghui ni, ka pilnam khaw na pilnam banghui, ka marhang khaw na marhang banghui,” a ti nah.
5 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì tún wí fún ọba Israẹli pé, “Kọ́kọ́ béèrè lọ́wọ́ Olúwa.”
Tedae Jehoshaphat loh Israel manghai taengah, “Tihnin kah bangla BOEIPA ol te dawtlet mai,” a ti nah.
6 Nígbà náà ni ọba Israẹli kó àwọn wòlíì jọ, bí irinwó ọkùnrin. Ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ṣé kí n lọ sí Ramoti Gileadi lọ jagun, tàbí kí èmi kí ó jọ̀wọ́ rẹ̀?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Lọ, nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Te dongah Israel manghai loh tonghma hlang ya li tluk te a coi. Te phoeiah amih te, “Ramothgilead ah caemtloek la ka cet aya? Ka paa aya?” a ti nah vaengah, “Cet, ka Boeipa loh manghai kut ah m'paek bitni,” a ti uh.
7 Ṣùgbọ́n Jehoṣafati béèrè pé, “Ǹjẹ́ wòlíì Olúwa kan kò sí níhìn-ín, tí àwa ìbá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?”
Jehoshaphat loh, “Amah n'dawtlet uh thil ham khaw heah he BOEIPA kah tonghma om pawt nim?” a ti nah.
8 Ọba Israẹli dá Jehoṣafati lóhùn pé, “Ọkùnrin kan ṣì wà, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa lè béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ṣùgbọ́n mo kórìíra rẹ̀ nítorí kì í sọ àsọtẹ́lẹ̀ rere kan nípa mi, bí kò ṣe ibi. Mikaiah ọmọ Imla ni.” Jehoṣafati sì wí pé, “Kí ọba má ṣe sọ bẹ́ẹ̀.”
Israel manghai loh Jehoshaphat te, “BOEIPA dawtlet ham hlang pakhat om pueng sitoe cakhaw, Imlah capa Mikhaiah long he kai ham tah hnothen neh a tonghma pawt dongah anih te ka hmuhuet. Tedae Imlah capa Mikhaiah tah a boethae bueng ni,” a ti nah. Jehoshaphat loh, “Manghai he te tla a cal moenih,” a ti nah.
9 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli sì pe ìránṣẹ́ kan, ó sì wí pé, “Lọ yára mú Mikaiah, ọmọ Imla wá.”
Te dongah Israel manghai loh imkhoem pakhat te a khue tih, “Imlah capa Mikhaiah te a loe la lo,” a ti nah.
10 Ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda jókòó lórí ìtẹ́ wọn, wọ́n wọ aṣọ ìgúnwà wọn ní ìta ẹnu ibodè Samaria, gbogbo àwọn wòlíì náà sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú wọn.
Te vaengah hlang he Israel manghai khaw, Judah manghai Jehoshaphat khaw a himbai bai neh a ngolkhoel neh Samaria vongka thohka kah cangtilhmuen ah ngol uh. Te vaengah tonghma tom khaw amih mikhmuh ah tonghma uh van.
11 Sedekiah ọmọ Kenaana sì ṣe ìwo irin fún ara rẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Wọ̀nyí ni ìwọ yóò fi kan àwọn ará Aramu títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’”
Kenaanah capa Zedekiah long tah amah ham thi kii a saii tih, “BOEIPA loh he ni a thui. Amih Aram te a thok hil he nen he na thoeh ni,” a ti nah.
12 Gbogbo àwọn wòlíì tókù sì ń sọtẹ́lẹ̀ ohun kan náà wí pé, “Kọlu Ramoti Gileadi, kí o sì ṣẹ́gun.” Wọ́n sì wí pé, “Nítorí tí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Tonghma boeih khaw tonghma uh tangloeng tih, “Ramothgilead te paan lamtah thaihtak laeh, BOEIPA loh manghai kut ah a tloeng bitni,” a ti uh.
13 Ìránṣẹ́ tí ó lọ pe Mikaiah wí fún un pé, “Wò ó, ẹnu kan náà ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì fi jẹ́ rere fún ọba. Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ rẹ bá ti àwọn tókù mu, kí o sì sọ rere.”
Mikhaiah khue ham aka cet puencawn loh anih te a voek tih, “Tonghma rhoek kah ol he a ka pakhat la a caeh dongah manghai ham khaw then coeng ke. Ol he tah nang ol khaw amih neh ol pakhat la om saeh lamtah a then mah thui laeh,” a ti nah.
14 Ṣùgbọ́n Mikaiah wí pé, “Bí Olúwa ti wà, ohun tí Olúwa bá sọ fún mi ni èmi yóò sọ fún un.”
Tedae Mikhaiah loh, “BOEIPA kah hingnah bangla BOEIPA loh kai taengah a thui bueng te ni ka thui,” a ti nah.
15 Nígbà tí ó sì dé, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Mikaiah, ṣé kí a lọ bá Ramoti Gileadi jagun, tàbí kí a jọ̀wọ́ rẹ̀?” Ó sì dáhùn wí pé, “Lọ, kí o sì ṣẹ́gun, nítorí Olúwa yóò fi lé ọba lọ́wọ́.”
Manghai taeng a pha vaengah manghai loh anih te, “Mikhaiah, caemtloek ham Ramothgilead la ka paan aya? ka paa aya?” a ti nah. Te dongah manghai te, “Paan lamtah thaihtak laeh, BOEIPA loh manghai kut ah a paek bitni,” a ti nah.
16 Ọba sì wí fún un pé, “Ìgbà mélòó ni èmi yóò fi ọ bú pé kí o má ṣe sọ ohun kan fún mi bí kò ṣe òtítọ́ ní orúkọ Olúwa?”
Tedae manghai loh anih te, “Kai taengah tah BOEIPA ming neh oltak dawk na thui pawt ham Kai loh nang te voei me yet hil lae kan caeng aih,” a ti nah.
17 Mikaiah sì dáhùn pé, “Mo rí gbogbo Israẹli túká kiri lórí àwọn òkè bí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́, Olúwa sì wí pé, ‘Àwọn wọ̀nyí kò ní olúwa. Jẹ́ kí olúkúlùkù padà sí ilé rẹ̀ ní àlàáfíà.’”
Te vaengah, “Israel pum he tlang ah a taekyak boiva bangla ka hmuh. Amih aka dawn ham he om pawh. Te dongah BOEIPA loh, ‘He rhoek he a boei a om moenih. Hlang loh amah im te ngaimong la paan uh saeh,’ a ti,” a ti nah.
18 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún ọ pé kò sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìre kan sí mi rí bí kò ṣe ibi?”
Israel manghai loh Jehoshaphat taengah, “Nang taengah ka thui moenih a? Kai ham tah a thae bueng tih a then la a tonghma tlaih moenih,” a ti nah.
19 Mikaiah sì tún wí pé, “Nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Mo rí Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo ogun ọ̀run dúró ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì rẹ̀.
Te phoeiah, “Te dongah BOEIPA ol he hnatun. BOEIPA he amah ngolkhoel dongah ngol tih a banvoei a bantang kah amah taengah vaan caempuei boeih a pai te ka hmuh.
20 Olúwa sì wí pé, ‘Ta ni yóò tan Ahabu láti kọlu Ramoti Gileadi? Kí ó sì tọ ikú rẹ̀ lọ níbẹ̀?’ “Ẹnìkan wí báyìí, ẹlòmíràn sì sọ òmíràn.
BOEIPA loh, ‘Ramothgilead a paan vaengah cungku sak ham Ahab te ulong a cuek eh?’ a ti. Te dongah he tlam he a thui pah tih ke tlam khaw a thui pah.
21 Ẹ̀mí kan sì jáde wá, ó sì dúró níwájú Olúwa, ó sì wí pé, ‘Èmi yóò tàn án.’
Mueihla ha pawk tih BOEIPA mikhmuh ah a pai phoeiah tah, ‘Anih te kamah loh ka cuek eh,’ a ti. Te vaengah BOEIPA loh anih te, ‘Me nen nim?’ a ti nah.
22 “Olúwa sì béèrè pé, ‘Báwo?’ “Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò jáde lọ, èmi yóò sì di ẹ̀mí èké ní ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ̀.’ “Olúwa sì wí pé, ‘Ìwọ yóò tàn án, ìwọ yóò sì borí, jáde lọ, kí o sì ṣe bẹ́ẹ̀.’
Te vaengah, ‘Ka paan vetih a tonghma boeih kah a ka dongah laithae mueihla la ka om pah ni,’ a ti nah. Te dongah, ‘Na cuek vetih na coeng pataeng bitni, cet lamtah saii tangloeng,’ a ti nah.
23 “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ti fi ẹ̀mí èké sí ẹnu gbogbo àwọn wòlíì rẹ wọ̀nyí. Olúwa sì ti sọ ibi sí ọ.”
Te dongah BOEIPA loh laithae mueihla te na tonghma boeih kah ka dongah a khueh coeng he. BOEIPA loh nang ham yoethae kawng ni a thui,” a ti nah.
24 Nígbà náà ni Sedekiah ọmọ Kenaana sì dìde, ó sì gbá Mikaiah lójú, ó sì wí pé, “Ọ̀nà wo ni ẹ̀mí Olúwa gbà lọ kúrò lọ́dọ̀ mi láti bá ọ sọ̀rọ̀?”
Te vaengah Kenaanah capa Zedekiah te thoeih tih Mikhaiah te a kam ah a thoek. Te phoeiah, “Nang aka voek ham BOEIPA mueihla he kai taeng lamloh melam a kat,” a ti nah.
25 Mikaiah sì dáhùn pé, “Ìwọ yóò ṣe ìwádìí ní ọjọ́ tí ìwọ yóò sá pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.”
Te dongah Mikhaiah loh, “Imkhui kah imkhui ah thuh hamla na mop khohnin daengah nang loh hmu ne,” a ti nah.
26 Ọba Israẹli sì pàṣẹ pé, “Ẹ mú Mikaiah, kí ẹ sì mú un padà sọ́dọ̀ Amoni, olórí ìlú, àti sọ́dọ̀ Joaṣi ọmọ ọba
Te vaengah Israel manghai loh, “Mikhaiah te khuen uh lamtah khopuei mangpa Amon taeng neh manghai capa Joash taengla thak uh.
27 kí ẹ sì wí pé, ‘Báyìí ni ọba wí: Ẹ fi eléyìí sínú túbú, kí ẹ sì fi oúnjẹ ìpọ́njú àti omi ìpọ́njú bọ́ ọ, títí èmi yóò fi padà bọ̀ ní àlàáfíà.’”
Te phoeiah, ‘Manghai loh he ni a thui. Anih he thongim ah khueh uh. Kai sading la ka pawk hil anih he hnaemtaeknah tui neh hnaemtaeknah buh mah cah uh,’ ti nah,” a ti nah.
28 Mikaiah sì wí pé, “Bí ìwọ bá padà bọ̀ ní àlàáfíà, Olúwa kò ti ipa mi sọ̀rọ̀.” Ó sì tún wí pé, “Ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ mi, ẹ̀yin ènìyàn gbogbo!”
Tedae Mikhaiah loh, “Sading neh na mael la na mael atah kai dongah BOEIPA cal pawt mako,” a ti nah. Te phoeiah amih pilnam pum te khaw, “Hnatun uh he,” a ti nah.
29 Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati ọba Juda gòkè lọ sí Ramoti Gileadi.
Te phoeiah Israel manghai neh Judah manghai Jehoshaphat loh Ramothgilead te a paan.
30 Ọba Israẹli sì wí fún Jehoṣafati pé, “Èmi yóò pa aṣọ dà, èmi yóò sì lọ sí ojú ìjà, ṣùgbọ́n ìwọ yóò wọ aṣọ ìgúnwà rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli pa aṣọ dà, ó sì lọ sí ojú ìjà.
Israel manghai loh Jehoshaphat te, “Ka sa uh vetih caemtloek la ka cet ni, nang te namah kah himbai bai ngawn,” a ti nah. Te dongah Israel manghai te sa uh tih caemtloek la cet.
31 Ọba Aramu ti pàṣẹ fún àwọn olórí kẹ̀kẹ́ rẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n wí pé, “Ẹ má ṣe bá ẹnìkankan jà, ẹni kékeré tàbí ẹni ńlá, bí kò ṣe ọba Israẹli nìkan.”
Aram manghai loh leng mangpa rhoek sawmthum panit te a uen tih, “Israel manghai amah bueng phoeiah tah, a tanoe a kangham khaw tloek uh boeh,” a ti nah.
32 Nígbà tí àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí Jehoṣafati, wọ́n sì wí pé, “Dájúdájú ọba Israẹli ni èyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yípadà láti bá a jà, ṣùgbọ́n nígbà tí Jehoṣafati sì kígbe sókè,
Leng mangpa rhoek loh Jehoshaphat te a hmuh vaengah amih loh Israel manghai rhep a ti uh. Te dongah anih te tloek ham dong uh dae Jehoshaphat lo a pang thil.
33 àwọn olórí kẹ̀kẹ́ sì rí i pé kì í ṣe ọba Israẹli, wọ́n sì padà kúrò lẹ́yìn rẹ̀.
Tedae anih te Israel manghai moenih tila leng mangpa rhoek loh a hmuh van neh anih hnuk lamloh mael uh.
34 Ṣùgbọ́n ẹnìkan sì fa ọrun rẹ̀ láìròtẹ́lẹ̀, ó sì ta ọba Israẹli láàrín ìpàdé ẹ̀wù irin. Ọba Israẹli sì wí fún olùtọ́jú kẹ̀kẹ́ rẹ̀ pé, “Yí ọwọ́ rẹ dà, kí o sì mú mi jáde kúrò nínú ogun. Èmi ti gbọgbẹ́.”
Tedae hlang pakhat loh amah thincaknah neh lii a phuk hatah Israel manghai te rhuhcong laklo neh caempho laklo ah a kah. Te dongah amah kah lengboei te, “Na kut hooi lamtah caem lamloh kai n'khuen laeh, ka nue coeng,” a ti nah.
35 Ogun náà sì le ní ọjọ́ náà, a sì dá ọba dúró nínú kẹ̀kẹ́ kọjú sí àwọn ará Aramu. Ẹ̀jẹ̀ sì sàn jáde láti inú ọgbẹ́ rẹ̀ sí àárín kẹ̀kẹ́ náà, ó sì kú ní àṣálẹ́.
Hnin at puet caemtloek khaw a caeh vaengah tah manghai te Aram dan kah leng dongah pai sut. Hlaem vaengah tah duek tih a hmasoe thii te leng kah tungngol dongla long.
36 A sì kéde la ibùdó já ní àkókò ìwọ̀-oòrùn wí pé, “Olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀ àti olúkúlùkù sí ilẹ̀ rẹ̀!”
Khomik a tlak vaengah tah caem khuiah tamlung cet tih, “Hlang te amah khopuei la, amah khohmuen la rhip mael saeh,” a ti.
37 Bẹ́ẹ̀ ni ọba kú, a sì gbé e wá sí Samaria, wọ́n sì sin ín ní Samaria.
Manghai te a duek daengah Samaria la pawk tih Samaria ah manghai te a up uh.
38 Wọ́n sì wẹ kẹ̀kẹ́ náà ní adágún Samaria, àwọn ajá sì lá ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, àwọn àgbèrè sì wẹ ara wọn nínú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti sọ.
Leng te Samaria tuibuem ah a lae tih BOEIPA ol loh a thui bangla pumyoi tuihluk ah a thii te ui loh a laeh.
39 Ní ti ìyókù ìṣe Ahabu, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ilé eyín erin tí ó kọ́, àti gbogbo ìlú tí ó tẹ̀dó, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Ahab kah ol noi neh a saii boeih, vueino im a sak te khaw, khopuei tom a sak te khaw, Israel manghai rhoek kah khokhuen olka cabu dongah a daek uh moenih a?
40 Ahabu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Ahasiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A napa rhoek taengla Ahab a khoem uh phoeiah tah a capa Ahaziah he anih yueng la manghai.
41 Jehoṣafati ọmọ Asa, sì bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba lórí Juda ní ọdún kẹrin Ahabu ọba Israẹli.
Israel manghai Ahab kah a kum li dongah Asa capa Jehoshaphat te Judah ah manghai.
42 Jehoṣafati sì jẹ́ ẹni ọdún márùndínlógójì nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba ní ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ ni Asuba ọmọbìnrin Silihi.
Jehoshaphat he sawmthum kum nga a lo ca vaengah manghai tih Jerusalem ah kum kul kum nga manghai. A manu ming tah Shilhi canu Azubah ni.
43 Ó sì rìn nínú gbogbo ọ̀nà Asa baba rẹ̀, kò sì yípadà kúrò nínú rẹ̀; ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú Olúwa. Kìkì àwọn ibi gíga ni a kò mú kúrò, àwọn ènìyàn sì ń rú ẹbọ, wọ́n sì ń sun tùràrí níbẹ̀.
BOEIPA mikhmuh ah a thuem saii ham he a napa Asa kah longpuei cungkuem dongah pongpa tih anih lamkah te phaelh pawh.
44 Jehoṣafati sì wà ní àlàáfíà pẹ̀lú ọba Israẹli.
Tedae hmuensang a khoe uh kolla pilnam a nawn pueng tih hmuensang ah a phum uh.
45 Ní ti ìyókù ìṣe Jehoṣafati àti ìṣe agbára rẹ̀ tí ó ṣe, àti bí ó ti jagun sí, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
Jehoshaphat loh Israel manghai te a thuung. Jehoshaphat kah ol noi neh a thayung thamal a saii khaw, a vathoh te khaw Judah manghai rhoek kah khokhuen olka cabu dongah a daek uh moenih a?
46 Ó pa ìyókù àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà ní ọjọ́ Asa baba rẹ̀ run kúrò ní ilẹ̀ náà.
Hlanghalh kah a coih, a napa Asa tue lamloh aka om te khohmuen lamloh a khoe.
47 Nígbà náà kò sí ọba ní Edomu; adelé kan ni ọba.
Edom ah manghai tal tih manghai a khueh pah.
48 Jehoṣafati kan ọkọ̀ Tarṣiṣi láti lọ sí Ofiri fún wúrà, ṣùgbọ́n wọn kò lọ, nítorí àwọn ọkọ̀ náà fọ́ ní Esioni-Geberi.
Ophir sui te paan hamla Jehoshaphat loh Tarshish sangpho te a saii tah a saii dae Eziongeber ah sangpho te a rhek la a rhek pah tih hlaikan pawh.
49 Ní ìgbà náà Ahasiah ọmọ Ahabu wí fún Jehoṣafati pé, “Jẹ́ kí àwọn ìránṣẹ́ mi bá àwọn ìránṣẹ́ rẹ lọ nínú ọkọ̀,” ṣùgbọ́n Jehoṣafati kọ̀.
Ahab capa Ahaziah loh Jehoshaphat taengah, “Ka sal rhoek he na sal rhoek taengah sangpho neh pongpa uh mai saeh,” a ti nah dae Jehoshaphat loh ngaih pawh.
50 Nígbà náà ni Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi, baba rẹ. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Jehoshaphat khaw a napa taengla a khoem uh vaengah a napa David khopuei kah a napa rhoek taengah a up uh tih a capa Jehoram te anih yueng la manghai.
51 Ahasiah ọmọ Ahabu bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún kẹtàdínlógún Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjì lórí Israẹli.
Judah manghai Jehoshaphat kah kum hlai rhih vaengah Ahab capa Ahaziah loh Samaria ah Israel a manghai thil tih Israel soah kum nit manghai.
52 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, nítorí tí ó rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀, àti ní ọ̀nà ìyá rẹ̀, àti ní ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó mú Israẹli dẹ́ṣẹ̀.
BOEIPA mikhmuh ah boethae a saii tih a napa longpuei ah, a manu longpuei ah, Israel aka tholh sak Nebat capa Jeroboam kah longpuei ah pongpa.
53 Ó sì sin Baali, ó sì ń bọ Baali, ó sì mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ ti ṣe.
Baal te tho a thueng thil tih a taengah a bakop dongah a napa kah a saii bangla a cungkuem dongah Israel Pathen BOEIPA te a veet.

< 1 Kings 22 >