< 1 Kings 21 >
1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
A poslije ovijeh stvari dogodi se: Navutej Jezraeljanin imaše vinograd u Jezraelu do dvora Ahava cara Samarijskoga.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
I reèe Ahav Navuteju govoreæi: daj mi svoj vinograd da naèinim od njega vrt za zelje, jer je blizu do dvora mojega; a ja æu ti dati za nj bolji vinograd, ili ako voliš, daæu ti u novcu šta vrijedi.
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
A Navutej reèe Ahavu: saèuvaj Bože da bih ti dao našljedstvo otaca svojih.
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Tada Ahav doðe kuæi zlovoljan i ljutit radi rijeèi koju mu reèe Navutej Jezraeljanin govoreæi: ne dam ti našljedstva otaca svojih. I leže na postelju svoju, i okrenu lice svoje na stranu, i ne jede hljeba.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Tada doðe k njemu Jezavelja žena njegova i reèe mu: zašto je duša tvoja zlovoljna te ne jedeš hljeba?
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
A on joj reèe: jer govorih s Navutejem Jezraeljaninom i rekoh mu: daj mi vinograd svoj za novce, ili ako voliš, daæu ti drugi vinograd za taj. A on reèe: ne dam ti svoga vinograda.
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
Tada mu reèe Jezavelja žena njegova: ti li si car nad Izrailjem? Ustani, jedi hljeba i budi veseo. Ja æu ti dati vinograd Navuteja Jezraeljanina.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
I napisa knjigu na ime Ahavovo, i zapeèati je peèatom njegovijem i posla knjigu starješinama i glavarima koji bijahu u gradu njegovu, koji nastavahu s Navutejem.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
A u knjizi napisa ovo: oglasite post, i posadite Navuteja meðu glavare narodne.
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
I postavite dva nevaljala èovjeka prema njemu, pa neka zasvjedoèe na nj govoreæi: hulio si na Boga i na cara. Tada ga izvedite i zaspite kamenjem, da pogine.
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
I uèiniše ljudi onoga grada, starješine i glavari, koji življahu u gradu njegovu, kako im zapovjedi Jezavelja, kako bijaše napisano u knjizi koju im posla.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
I oglasiše post, i posadiše Navuteja meðu glavare narodne.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
I doðoše dva nevaljala èovjeka, i sjedoše prema njemu; i svjedoèiše na Navuteja ti nevaljali ljudi pred narodom govoreæi: Navutej je hulio na Boga i na cara. I izvedoše ga iza grada, i zasuše ga kamenjem, te pogibe.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
Potom poslaše k Jezavelji i poruèiše joj: zasut je kamenjem Navutej, i poginuo je.
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
A kad Jezavelja èu da je Navutej zasut kamenjem i poginuo, reèe Ahavu Jezavelja: ustani, uzmi vinograd Navuteja Jezraeljanina, kojega ti ne htje dati za novce, jer Navutej nije živ nego je umro.
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
A kad èu Ahav da je umro Navutej, usta i poðe u vinograd Navuteja Jezraeljanina da ga uzme.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Ali doðe rijeè Gospodnja k Iliji Tesviæaninu govoreæi:
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
Ustani, izidi na susret Ahavu caru Izrailjevu, koji sjedi u Samariji; eno ga u vinogradu Navutejevu, kuda je otišao da ga uzme.
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
I reci mu i kaži: ovako veli Gospod: nijesi li ubio i nijesi li prisvojio? Pa mu kaži i reci: ovako veli Gospod: kako psi lizaše krv Navutejevu, tako æe lizati psi i tvoju krv.
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
A Ahav reèe Iliji: naðe li me, neprijatelju moj? A on reèe: naðoh, jer si se prodao da èiniš što je zlo pred Gospodom.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
Evo, pustiæu zlo na te, i uzeæu natražje tvoje, i istrijebiæu Ahavu i ono što uza zid mokri, i uhvaæenoga i ostavljenoga u Izrailju.
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
I uèiniæu s domom tvojim kao s domom Jerovoama sina Navatova i kao s domom Vase sina Ahijina, što si me gnjevio i što si naveo na grijeh Izrailja.
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
Takoðe i za Jezavelju reèe Gospod govoreæi: psi æe izjesti Jezavelju ispod zidova Jezraelskih.
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
Ko Ahavov pogine u gradu izješæe ga psi, a ko pogine u polju izješæe ga ptice nebeske.
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
I ne bi takoga kao Ahav, koji se prodade da èini što je zlo pred Gospodom, jer ga podgovaraše žena njegova Jezavelja.
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
I poèini vrlo grdna djela iduæi za gadnim bogovima sasvijem kao što èiniše Amoreji, koje izagna Gospod ispred sinova Izrailjevijeh.
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
A kad Ahav èu te rijeèi, razdrije haljine svoje, i priveza kostrijet oko tijela svojega, i pošæaše, i spavaše u kostrijeti, i hoðaše polagano.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
I doðe rijeè Gospodnja Iliji Tesviæaninu govoreæi:
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
Jesi li vidio kako se Ahav ponizio preda mnom? Zato što se tako ponizio preda mnom, neæu pustiti onoga zla za njegova života; nego za sina njegova pustiæu ono zlo na dom njegov.