< 1 Kings 21 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
Дупэ ачесте лукрурь, ятэ че с-а ынтымплат. Набот, дин Изреел, авя о вие ла Изреел, лынгэ каса луй Ахаб, ымпэратул Самарией.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
Ши Ахаб а ворбит астфел луй Набот: „Дэ-мь мие вия та сэ фак дин еа о грэдинэ де вердецурь, кэч есте фоарте апроапе де каса мя. Ын локул ей ыць вой да о вие май бунэ сау, дакэ-ць вине май бине, ыць вой плэти прецул ей ын арӂинт.”
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
Дар Набот а рэспунс луй Ахаб: „Сэ мэ феряскэ Домнул сэ-ць дау моштениря пэринцилор мей!”
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Ахаб а интрат ын касэ трист ши мыният дин причина кувинтелор пе каре и ле спусесе Набот дин Изреел: „Ну-ць вой да моштениря пэринцилор мей!” Ши с-а кулкат пе пат, шь-а ынторс фаца ши н-а мынкат нимик.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Невастэ-са, Изабела, а венит ла ел ши й-а зис: „Пентру че ыць есте тристэ инима ши ну мэнынчь?”
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
Ел й-а рэспунс: „Ам ворбит ку Набот дин Изреел ши й-ам зис: ‘Дэ-мь вия та пе прец де арӂинт сау, дакэ врей, ыць вой да о алтэ вие ын локул ей.’ Дар ел а зис: ‘Ну пот сэ-ць дау вия мя!’”
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
Атунч, Изабела, неваста луй, й-а зис: „Оаре ну домнешть ту акум песте Исраел? Скоалэ-те, я ши мэнынкэ ши фий ку инима веселэ, кэч еу ыць вой да вия луй Набот дин Изреел!”
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
Ши еа а скрис ниште скрисорь ын нумеле луй Ахаб, ле-а печетлуит ку печетя луй Ахаб ши ле-а тримис бэтрынилор ши дрегэторилор каре локуяу ку Набот ын четатя луй.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Ятэ че а скрис ын ачесте скрисорь: „Вестиць ун пост, пунець пе Набот ын фрунтя попорулуй
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
ши пунеци-й ын фацэ дой оамень де нимик, каре сэ мэртурисяскэ астфел ымпотрива луй: ‘Ту ай блестемат пе Думнезеу ши пе ымпэратул!’ Апой скоатеци-л афарэ, ымпрошкаци-л ку петре ши сэ моарэ.”
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
Оамений дин четатя луй Набот, бэтрыний ши дрегэторий каре локуяу ын четате ау фэкут кум ле спусесе Изабела, дупэ кум ера скрис ын скрисориле пе каре ли ле тримисесе еа.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Ау вестит ун пост ши ау пус пе Набот ын фрунтя попорулуй.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
Чей дой оамень де нимик ау венит ши с-ау ашезат ын фаца луй ши ачешть оамень рэй ау мэртурисит аша ынаинтя попорулуй, ымпотрива луй Набот: „Набот а блестемат пе Думнезеу ши пе ымпэратул!” Апой л-ау скос афарэ дин четате, л-ау ымпрошкат ку петре ши а мурит.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
Ши ау тримис сэ спунэ Изабелей: „Набот а фост ымпрошкат ку петре ши а мурит.”
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
Кынд а аузит Изабела кэ Набот фусесе ымпрошкат ку петре ши кэ мурисе, а зис луй Ахаб: „Скоалэ-те ши я ын стэпынире вия луй Набот дин Изреел, каре н-а врут сэ ць-о дя пе прец де арӂинт, кэч Набот ну май трэеште, а мурит.”
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
Ахаб, аузинд кэ а мурит Набот, с-а скулат сэ се кобоаре ла вия луй Набот дин Изреел ка с-о я ын стэпынире.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Атунч, кувынтул Домнулуй а ворбит луй Илие, Тишбитул, астфел:
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
„Скоалэ-те ши кобоарэ-те ынаинтя луй Ахаб, ымпэратул луй Исраел, ла Самария; ятэ-л, есте ын вия луй Набот, унде с-а коборыт с-о я ын стэпынире.
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
Сэ-й спуй: ‘Аша ворбеште Домнул: «Ну ешть ту ун учигаш ши ун хоц?»’ Ши сэ-й май спуй: ‘Аша ворбеште Домнул: «Кяр ын локул унде ау линс кыний сынӂеле луй Набот вор линӂе кыний ши сынӂеле тэу.»’”
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
Ахаб а зис луй Илие: „М-ай гэсит, врэжмашуле?” Ши ел а рэспунс: „Те-ам гэсит, пентру кэ те-ай вындут ка сэ фачь че есте рэу ынаинтя Домнулуй.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
Ятэ че зиче Домнул: ‘Вой адуче ненорочиря песте тине; те вой мэтура, вой нимичи пе орьчине есте ал луй Ахаб, фие роб, фие слобод ын Исраел,
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
ши вой фаче касей тале кум ам фэкут касей луй Иеробоам, фиул луй Небат, ши касей луй Баеша, фиул луй Ахия, пентру кэ М-ай мыният ши ай фэкут пе Исраел сэ пэкэтуяскэ.’”
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
Домнул а ворбит ши деспре Изабела ши а зис: „Кыний вор мынка пе Изабела лынгэ ынтэритура Изреелулуй.
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
Чине ва мури ын четате дин каса луй Ахаб ва фи мынкат де кынь, яр чине ва мури пе кымп ва фи мынкат де пэсэриле черулуй.”
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
Н-а фост нимень каре сэ се фи вындут пентру ка сэ факэ че есте рэу ынаинтя Домнулуй ка Ахаб, пе каре невастэ-са Изабела ыл ацыца ла ачаста.
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
Ел а лукрат ын кипул чел май урычос, мергынд дупэ идоль, кум фэчяу амориций, пе каре-й изгонисе Домнул динаинтя копиилор луй Исраел.
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
Дупэ че а аузит кувинтеле луй Илие, Ахаб шь-а рупт хайнеле, шь-а пус ун сак пе труп ши а постит: се кулка ку сакул ачеста ши мерӂя ынчет.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Ши кувынтул Домнулуй а ворбит луй Илие, Тишбитул, астфел:
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
„Ай вэзут кум с-а смерит Ахаб ынаинтя Мя? Пентру кэ с-а смерит ынаинтя Мя, ну вой адуче ненорочиря ын тимпул веций луй, чи ын тимпул веций фиулуй сэу вой адуче ненорочиря касей луй!”

< 1 Kings 21 >