< 1 Kings 21 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
Kwathi ngemva kwesikhathi esithile kwaba lesenzo esithile ngesivini sikaNabhothi umJezerili. Isivini leso sasiseJezerili, phansi kwesigodlo sika-Ahabi inkosi yaseSamariya.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
U-Ahabi wathi kuNabhothi, “Kahle mina ngilime imibhida yami esivinini sakho, njengoba siphansi kwesigodlo sami. Mina ngizakunika isivini esingcono, loba nxa uthanda, ngizakunika intengo ofisa ukusithengisa ngayo.”
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
Kodwa uNabhothi wathi, “UThixo kangavumi ukuba ngikunike ilifa labobaba.”
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Ngalokho u-Ahabi wabuyela ekhaya enyukubele njalo ethukuthele ngoba uNabhothi umJezerili wayethe, “Angizukukunika ilifa labobaba.” U-Ahabi walala embhedeni enyukubele wala lokudla.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Umkakhe uJezebheli wangena endlini wambuza wathi, “Kungani usineme kangaka? Kungani usala ukudla?”
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
Yena wamphendula wathi, “Kungenxa yokuthi ngithe kuNabhothi umJezerili, ‘Ngithengisela isivini sakho; loba nxa ufuna, ngikunike esinye isivini esikhundleni salesi.’ Kodwa ungiphendule wathi ‘Angizukukunika isivini sami.’”
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
UJezebheli umka-Ahabi wathi, “Lokhu yikho okwenzayo njengenkosi yako-Israyeli na? Vuka udle! Uchelese. Mina ngizakuzuzela isivini sikaNabhothi umJezerili.”
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
UJezebheli wasebhala izincwadi ngebizo lika-Ahabi, wazidinda ngophawu luka-Ahabi, wazithumela ebadaleni lakuzo izikhulu ezazihlala loNabhothi emzini wakibo.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Ezincwadini lezo waloba ukuthi: “Memezelani usuku lokuzila libe selibeka uNabhothi esihlalweni esiqakathekileyo phakathi kwabantu.
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
Libe selihlalisa izigangi ezimbili maqondana laye lithi kazifakaze ngokuthi uthuke uNkulunkulu kanye lenkosi. Libe selimkhuphela phandle liyemkhanda ngamatshe limbulale.”
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
Ngakho abadala lezikhulu ababehlala emzini kaNabhothi benza lokho ababekuthunywe nguJezebheli ngezincwadi ayebalobele zona.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Bamemezela isikhathi sokuzila bahlalisa uNabhothi esihlalweni esiphakemeyo phambi kwabantu.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
Kwasuka izigangi ezimbili zahlala phambi kwakhe zakhangelana laye zaqalisa ukwethesa uNabhothi amacala, zisithi, “UNabhothi uthuke uNkulunkulu kanye lenkosi.” Ngakho bamkhuphela ngaphandle komuzi bamkhanda ngamatshe bambulala.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
Basebethumela ilizwi kuJezebheli besithi, “UNabhothi ukhandwe ngamatshe njalo usefile.”
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
Masinyazana uJezebheli esezwe ukuthi uNabhothi ukhandwe ngamatshe wabulawa, wathi ku-Ahabi, “Vuka uyethatha isivini sikaNabhothi umJezerili sona lesiyana alileyo ukukuthengisela sona. Uvele kasekho, usefile.”
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
U-Ahabi uthe esizwa ukuthi uNabhothi kasekho, wavuka wayathatha lesosivini sikaNabhothi waseJezerili.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Ilizwi likaThixo leza ku-Elija umThishibi lisithi:
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
“Yehla uyehlangabeza u-Ahabi inkosi yako-Israyeli obusa eSamariya. Usesivinini sikaNabhothi, uye khona ukuze azithathele lesosivini.
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
Ufike uthi kuye, ‘Nanku okutshiwo nguThixo: Awubulalanga umuntu wathumba impahla yakhe na?’ Ubususithi kuyo, ‘Nanku okutshiwo nguThixo; Khonapho lapho izinja ezikhothele khona igazi likaNabhothi, kukhonapho kanye lapho izinja ezizakhothela khona elakho, yebo, elakho kanye!’”
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
U-Ahabi wathi ku-Elija, “Wo usungitholile, wena sitha sami!” U-Elija wamphendula wathi, “Yebo sengikutholile ngoba uzinikele ukwenza isono emehlweni kaThixo.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
‘Ngizokwehlisela ukubhujiswa. Ngizabhubhisa izizukulwane zakho ngisuse sonke isilisa sokucina ku-Ahabi ko-Israyeli loba yisigqili loba ngokhululekileyo.
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
Indlu yakho ngizayenza lokhu engakwenza ekaJerobhowamu indodana kaNebhathi lekaBhasha indodana ka-Ahija, ngoba ungithukuthelisile wabangela ukuthi u-Israyeli enze isono.’
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
Ngalokho uThixo uthi ngoJezebheli: ‘Izinja zizamdabudabula uJezebheli zimdlele emidulini yaseJezerili.’
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
Izinja zizakudla bonke abangabaka-Ahabi abafela edolobheni, izinyoni zezulu zizakudla labo abazafela emaphandleni.”
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
(Akuzange kube lendoda eyayifanana lo-Ahabi yena owazinikela ukuthi adale isono phambi kukaThixo, ekhuthazwa ngumkakhe uJezebheli.
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
Waziphatha butshapha kakhulu elandela izithombe, njengama-Amori wona ayesuswe nguThixo phambi kuka-Israyeli.)
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
U-Ahabi wathi esizwa lawomazwi, wadabula izigqoko zakhe, wembatha amasaka wazila. Walala embethe amasaka wahamba edanile.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Ngemva kwalokho ilizwi likaThixo lathi ku-Elija umThishibi:
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
“Ukubonile na ukuthi u-Ahabi usezithobe kanganani phambi kwami? Ngenxa yokuzithoba kwakhe, angiyikumehlisela lobobubi esaphila, kodwa ngizakwehlisela endlini yakhe ensukwini zendodana yakhe.”

< 1 Kings 21 >