< 1 Kings 21 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
Mago'a kna evutegeno Jezrieli kumate ne' Naboti'a Jezrieli kumatera, Sameria kini ne' Ahapu nomofo tavaonte waini hoza'a me'negeno kegava hu'ne.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
Hagi mago zupa kini ne' Ahapu'a amanage huno Nabotina antahige'ne, Waini hozakamo'a kumani'a tava'onte me'negu, namige'na nani'za hoza nentena, ana nona'a ete mago hoza knarema hu'neania kamige, mizanku'ma hananke'na mizasege haneno.
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
Hianagi Naboti'a amanage hu'ne, Ra Anumzamo'a negafampinti'ma erisantima hare'nenana zana, vahera omio huno hu'neanki'na onkamigahue.
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Higeno'a Ahapuna avugosamo'a evuneramigeno tusi rimpa neheno noma'arega vu'ne. Na'ankure Naboti'a huno, nenfampinti'ma erisantima hare'noa zana onkamigosue, huno hu'neazanku anara hu'ne. Anama higeno'a Ahapu'a kavera oneno avugosa rukrehe huno tafe'are mase'ne.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Hianagi nenaro Jesebeli'a eazamo amanage huno eme antahige'ne, na'anku kavugosamo'a evuneramigenka kavera nonane?
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
Higeno amanage huno kenona hu'ne, Na'ankure Jezrieli kumateti ne' Naboti'na amanage hu'na antahige'noe, waini hozaka'a namige'na hoza nentena, ana nona'a ete mago hoza kamige, mizanku'ma hananke'na mizasege haneno hu'na huana, i'o onkamigosue huno hu'ne.
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
Higeno nenaro, Jesebeli'a amanage huno asami'ne, kagra Israeli kinia mani'nenka Israeli vahera kegava huzmantenananki, otinka ne'zana nenenka atregeno karimpamo'a kna osino. Jezrieli kumateti ne' Naboti waini hoza omeri kamigahue.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
Anage nehuno Naboti'ma nemania kumate ranra vahetamintegane kva vahe'teganena mago avo kreno Ahapu azanko avo rukamare nenteno atregeno vu'ne.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Hagi ana avompina amanage huno krente'ne. Ne'zana atreta nunamu hu kne huta maka vahetamina kehu atru hinke'za atruma hanageta, Nabotina agesga huta ese trate hinkeno, vahetmimofo zamavuga manino.
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
Ana nehuta mago kaziga kefo netre huznantenkeno, umanineke Nabotinkura, Anumzamofone kini ne'enena huhaviza hu'ne huke hunte'o. Hagi anagema hanageta, Nabotina avre atiramita have knonu ahe friho.
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
Hagi anankema nentahi'za ana kumapi ranra vahe'ene, kva vahe'mo'za Jesebeli'ma avoma krezamino'ma hiho huno'ma hiaza hu'naze.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Hagi ne'za atreno nunamu hu kna erintazageno, vahe'ma atruma haza vahetmimofo zamavuga Nabotina ese trate avrente'naze.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
Hagi tare kefo netremokea Naboti'ma mania tra'mofo kantikaziga emanike amanage huka Nabotina havigea hunte'na'e. Naboti'a Anumzamofone, kini ne'enena huhaviza huzanante'ne. Hagi anagema hakeno'a, Nabotina rankumapintira avre'atirami'za havenknonu ahe fri'naze.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
Hagi ana'ma nehu'za ana kumapi kva vahe'mo'za Jesebelintega amanage hu'za kea atre'naze, Nabotina hago havenknonu ahe frunkeno fri'ne, hu'za kea atrente'naze.
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
Hagi Jesebeli'ma ana kema nentahino'a, amanage huno Ahapuna asami'ne, Jezrieliti ne' Naboti'ma zagore'ma kami zanku'ma i'o huno'ma hu'nea ne'mofo waini hoza otinka omerio. Na'ankure agra omani'neanki, hago fri'ne.
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
Hagi Naboti'ma frie nanekema Ahapu'ma nentahino'a, ana waini hoza omeri nafa'a hunaku urami'ne.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Hianagi Ra Anumzamo'a amanage huno Tisbe kumateti kasnampa ne' Elaijana asami'ne,
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
Otinka vunka Israeli kini ne' Ahapu'a Sameriama nemania ne'mo, Naboti waini hoza erinaku ana hozafi umani'neanki uraminka ome negenka,
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
amanage hunka ome asamio, Ra Anumzamo'a amanage huno hie, kagrama Nabotima ahenka hoza'ama enerinka korama'a eriraginanku, kramo'zama Naboti korama hu'zama naza kumate, anahukna hu'za kramo'za kagri korana hu'za negahaze hunka ome asamio.
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
Higeno vigeno Ahapu'a amanage huno Elaijankura hu'ne, Ha' vahenimoka nagrira eme nagenka erifore hane. Anage higeno Elaija'a amanage huno kenona hu'ne, Izo kagriku hake'na e'noe. Na'ankure kagra Ra Anumzamofo avurera kefo kavukava hu'nane.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
E'ina hu'negu Ra Anumzamo'a amanage huno hie, Kagrira rama'a hazenke kamigahue. Hagi Ahapuga kagripinti'ma fore'ma hanaza vahera amne vahe'ene, kazokzo vahe'enena maka zamahe vagaregahue.
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
Hagi Nebati nemofo Jeroboamu naga'ene, Ahiza nemofo Ba-asa naga'enema hu'noaza hu'na kagri nagara zamahe hana hugahue. Na'ankure kagra tusiza hunka nazeri narimpa nehenka, Israeli vahera zamazeri kumipina zamante'nane.
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
Hagi Jesebelinkura amanage huno Ra Anumzamo'a hu'ne, Jesebeli avufga kramo'za Jesrieli kuma keginamofo agu'afi negahaze.
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
Hagi Ahapu nagapinti'ma rankuma agu'afima frisaza vahera kramo'za nesageno, megi'ama frisnaza vahera namamo'za negahaze.
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
Hagi Ahapu nenaro Jesebeli'ma havi antahintahi amino azeri savari'ma Ahapu'ma higeno, Ra Anumzamofo avure'ma havi avu'ava'ma hu'neankna avu'avara mago vahe'mo'e huno kora osu'neaza hu'ne.
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
Hagi ko'ma Israeli vahe'ma ome'nazageno ana mopafima Amori vahe'ma mani'nezama haviza huno kasrino agote avu'ava'ma nehazageno, Ra Anumzamo'ma zamahe natitre'neankna huno kaza osu havi anumzantaminte Ahapu'a monora ome hunte'ne.
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
Hianagi Ahapu'ma ana nanekema nentahino'a, kukena'a tagato huno zamasunku'ma nehu'za atafa kukenama nehaza kukena eri nehuno, kavera a'o huno mani'ne. Hagi kenage'enena ana kukena antanino mase'neno, tusi asunku hu'ne.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Hagi ana'ma nehigeno'a, Ra Anumzamo'a amanage huno Tisbe kumateti ne' Elaijana asami'ne,
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
Nagri navugama Ahapu'ma agu'ama erinteramino asunku'ma hiazana hago kano. Na'ankure agra agu'ama erinteramino navuga asunku hianki'na agri knafina ana hazenke zana eriforera osugahuanki, mofavre'amofo knafi ana hazenke zana eri fore hugahue.

< 1 Kings 21 >