< 1 Kings 21 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
Ket napasamak nga iti saan a nagbayag, ni Nabot a taga-Jezreel ket adda kaubasanna idiay Jezreel, nga asideg ti palasio ni Ahab, nga ari ti Samaria.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
Kinasao ni Ahab ni Nabot a kunana, “Itedmo kaniak ti kaubasam, tapno aramidek a pagmulaan kadagiti natnateng, gapu ta asideg daytoy iti balayko. Kas kasukatna, ikkanka iti nasaysayaat a kaubasan, wenno, no kayatmo, itedko lattan ti bayadna.”
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
Simmungbat ni Nabot kenni Ahab, “Saan koma nga ipalubos ni Yahweh nga itedko kenka ti tawid dagiti kapuonak.”
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Nagawid ngarud ni Ahab iti palasiona a nasakit ti nakemna ken makapungtot gapu iti insungbat kenkuana ni Nabot a taga-Jezreel idi kinunana, “Saanko nga ited kenka ti tawid dagiti kapuonak.” Nagidda isuna iti katrena, simmango iti diding, ket saanna a kayat ti mangan iti aniaman a taraon.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Napan kenkuana ni Jezebel nga asawana ket kinunana kenkuana, “Apay nga agliday unay ti pusom, ket saanka a mangmangan?”
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
Simmungbat isuna kenkuana, “Kinasaok ni Nabot a taga-Jezreel ket kinunak kenkuana, 'Ilakom kaniak ti kaubasam, wenno no kayatmo, 'Ikkanka iti sabali a kaubasan!' Ket simmungbat kaniak, 'Saanko nga ited kenka ti kaubasak.”'
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
Simmungbat ngarud kenkuana ni Jezebel nga asawana, “Saan kadi a sika pay laeng ti mangiturturturay iti pagarian ti Israel? Bumangonka ket manganka; agragsak koma ti pusom. Alaek ti kaubasan ni Nabot a taga-Jezreel para kenka.”
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
Nagsurat ngarud ni Jezebel babaen iti nagan ni Ahab, sinelioanna dagitoy babaen iti pagselio ti ari, ket impatulodna dagitoy kadagiti panglakayen ken kadagiti nababaknang a makipagtugtugaw kenkuana kadagiti panaguummong, a kaarruba ni Nabot.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Inlanadna kadagiti surat a kunana, “Mangipakdaarkayo iti panagayunar ket pagtugawenyo ni Nabot iti sangoanan dagiti tattao.
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
Mangikabilkayo met ti dua nga ulbod a tao a kaduana ket pagsaksienyo ida maibusor kenkuana, a kunada, 'Inlunodmo ti Dios ken ti ari.”' Kalpasanna iruaryo isuna ket batoenyo isuna agingga a matay.
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
Isu a dagiti tattao iti siudadna, dagiti panglakayen ken nababaknang nga agnanaed iti siudadna, inaramidda ti imbilin ni Jezebel kadakuada, a kas nailanad iti surat nga impatulodna kadakuada.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Nangipakdaarda iti panagayunar ket pinagtugawda ni Nabot iti sangoanan dagiti tattao.
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
Immay dagiti dua nga ulbod a tattao ket nagtugawda iti sangoanan ni Nabot; nagsaksida maibusor kenni Nabot iti sangoanan dagiti tattao, a kunada, “Inlunod ni Nabot ti Dios ken ti ari.” Kalpasanna, inruarda isuna iti siudad ket binato-batoda isuna agingga a natay.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
Kalpasanna, nangipatulod dagiti panglakayen iti sao kenni Jezebel, a kunada, “Binatodan ni Nabot ket natayen.”
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
Ket idi nadamag ni Jezebel a nabato ken natayen ni Nabot, kinunana kenni Ahab, “Tumakderka ket mapanmo alaem ti sanikua ni Nabot a taga-Jezreel, a saanna a kayat nga ilako kenka, gapu ta saanen a sibibibiag ni Nabot ngem ketdi natayen.”
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
Idi nangngeg ni Ahab a natayen ni Nabot, nagrubbuat isuna tapno mapan iti kaubasan ni Nabot a taga-Jezreel ket tagikuaenna daytoy.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Ket immay ti sao ni Yahweh kenni Elias a taga-Tisbi, a kunana,
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
“Tumakderka ket mapanmo saraken ni Ahab nga ari ti Israel, nga agnanaed idiay Samaria. Adda isuna iti kaubasan ni Nabot, tapno tagikuaenna daytoy.
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
Nasken a kasaom isuna ket ibagam a kuna ni Yahweh, ‘Pimmatayka kadi ken nangtagikuaka?' Ket ibagam kenkuana a kuna ni Yahweh, 'Iti lugar a nangdilpatan dagiti aso iti dara ni Nabot, dilpatanto met dagiti aso ti daram, wen, ti daram,’ “
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
Kinuna ni Ahab kenni Elias, “Nasarakannak kadi, kabusorko?” Simmungbat ni Elias, “Nasarakanka, gapu ta inlakom ti bagim iti panagaramid iti dakes iti imatang ni Yahweh.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
Ibagbaga ni Yaweh daytoy kenka: 'Kitaem, mangiyegakto iti didigra kenka ket ikisapkonto amin ken pukawek kenka ti tunggal ubing a lalaki, adipen ken siwawaya a tao iti Israel.
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
Pagbalinekto ti pamiliam a kas iti pamilia ni Jeroboam nga anak ni Nabat, ken kas iti pamilia ni Baasa nga anak ni Ahijah, gapu ta pinagpungtotnak ken insungsongmo ti Israel nga agbasol.'
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
Nagsao met ni Yahweh maipapan kenni Jezebel, a kunana, 'Kanento dagiti aso ni Jezebel iti asideg ti pader ti Jezreel.'
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
Siasinoman a maibilang kenni Ahab a matay iti siudad-kanento dagiti aso dayta a tao. Ket siasinoman a matay iti away-kanento dagiti billit iti tangatang dayta a tao.”
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
Awan ti kas kenni Ahab, a nangilako iti bagina iti panagaramid iti dakes iti imatang ni Yahweh, a sinugsugan ni Jezebel nga asawana nga agbasol.
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
Nagaramid ni Ahab kadagiti makarimon nga aramid para kadagiti didiosen a dinayawna, a kas iti amin nga inaramid dagiti Amorreo, nga innikkat ni Yahweh iti sangoanan dagiti tattao ti Israel.
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
Idi nangngeg ni Ahab dagitoy a sasao, rinay-abna dagiti kawesna ket nagkawes iti nakersang a lupot ken nagayunar ket nagidda a sikakawes iti nakersang a lupot ket kasta unay ti panaglidayna.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Ket immay ti sao ni Yawheh kenni Elias a taga-Tisbi, a kunana,
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
“Nakitam kadi no kasano a nagpakumbaba ni Ahab iti sangoanak? Gapu ta impakumbabana ti bagina iti sangoanak, saankon nga iyeg ti umay a didigra bayat iti panagbiagna; kadagiti al-aldaw a panagbiag dagiti annakna nga iyegkonto daytoy a didigra iti pamiliana.”

< 1 Kings 21 >