< 1 Kings 21 >

1 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Naboti ará Jesreeli sì ní ọgbà àjàrà kan ní Jesreeli, ní ẹ̀gbẹ́ ààfin Ahabu ọba Samaria.
Forsothe after these wordis, in that tyme, the vyner of Naboth of Jezrael, `that was in Jezrael, was bisidis the paleis of Achab, kyng of Samarye.
2 Ahabu sì wí fún Naboti pé, “Fún mi ní ọgbà àjàrà rẹ, kí èmi kí ó fi ṣe ọgbà-ewébẹ̀, nítorí tí ó súnmọ́ tòsí ilé mi, èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà tí ó sàn jù ú lọ dípò rẹ̀; tàbí bí ó bá sì dára ní ojú rẹ, èmi yóò fi iye owó rẹ̀ fún ọ.”
Therfor Achab spak to Naboth, and seide, Yyue thou to me the vyner, that Y make to me a gardyn of wortis, for it is nyy, and nyy myn hows; and Y schal yyue to thee a betere vyner for it; ethir if thou gessist it more profitable to thee, Y schall yyue the prijs of siluer, as myche as it is worth.
3 Ṣùgbọ́n Naboti wí fún Ahabu pé, “Olúwa má jẹ́ kí èmi fi ogún àwọn baba mi fún ọ.”
To whom Naboth answeride, The Lord be merciful to me, that Y yyue not to thee the eritage of my fadris.
4 Ahabu sì wá sí ilé rẹ̀, ó wugbọ́, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí ọ̀rọ̀ tí Naboti ará Jesreeli sọ fún un; nítorí tí ó wí pé, “Èmi kì yóò fún ọ ní ogún àwọn baba mi.” Ó sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀, ó sì yí ojú rẹ̀ padà, kò sì fẹ́ jẹun.
Therfor Acab cam in to his hows, hauynge indignacioun, and gnastyng on the word which Naboth of Jezrael hadde spoke to him, and seide, Y schal not yyue to thee the eritage of my fadirs. And Achab castide doun him silf in to his bed, and turnede awei his face to the wal, and ete not breed.
5 Jesebeli aya rẹ̀ sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí inú rẹ fi bàjẹ́, èéṣe tí ìwọ kò sì jẹun?”
Forsothe Jezabel, his wijf, entride to hym, and seide to hym, What is this thing, wherof thi soule is maad sory? and whi etist thou not breed?
6 Ó sì dá a lóhùn pé, “Nítorí tí mo wí fún Naboti ará Jesreeli pé, ‘Ta ọgbà àjàrà rẹ fún mi, tàbí bí ó bá wù ọ́, èmi yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mìíràn ní ipò rẹ̀.’ Ṣùgbọ́n ó wí pé, ‘Èmi kì yóò fún ọ ní ọgbà àjàrà mi.’”
Which answeride to hir, Y spak to Naboth of Jezrael, and Y seide to hym, Yyue thi vyner to me for money takun, ethir if it plesith thee, Y schal yyue to thee a betere vyner for it. And he seide, Y schal not yyue to thee my vyner.
7 Jesebeli aya rẹ̀ sì wí pé, “Ṣé báyìí ni ìwọ yóò ṣe ṣe bí ọba lórí Israẹli? Dìde, jẹun! Kí o sì jẹ́ kí inú rẹ̀ dùn. Èmi yóò sì fún ọ ní ọgbà àjàrà Naboti ará Jesreeli.”
Therfor Jezabel, his wijf, seide to hym, Thou art of greet auctorite, and thou gouernest wel Israel; rise thou, and ete breed, and be thou `pacient, ethir coumfortid; Y schal yyue to thee the vyner of Naboth of Jezrael.
8 Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Ahabu, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Naboti pẹ̀lú rẹ̀.
Therfor sche wroot lettris in the name of Achab, and seelide tho with the ryng of hym; and sche sente to the grettere men in birthe, and to the beste men, that weren in the citee of hym, and dwelliden with Naboth.
9 Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé, “Ẹ kéde àwẹ̀, kí ẹ sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Sotheli this was the sentence of the lettre; Preche ye fastyng, and make ye Naboth to sitte among the firste men of the puple;
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú síwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí sí i wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”
and sende ye priueli twei men, the sones of Belial, ayens hym, and sey thei fals witnessyng, Naboth blesside God and the kyng; and lede ye out hym, and stoon ye him, and die he so.
11 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Naboti sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwé tí Jesebeli kọ ránṣẹ́ sí wọn.
Therfor hise citeseyns, the grettere men in birthe, and the beste men that dwelliden with hym in the citee, diden as Jezabel hadde comaundid, and as it was writun in the lettris, whiche sche hadde sent to hem.
12 Wọ́n sì kéde àwẹ̀, wọ́n sì fi Naboti sí ipò ọlá láàrín àwọn ènìyàn.
Thei prechiden fastyng, and maden Naboth to sitte among the firste men of the puple;
13 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin méjì sì dé, àwọn ẹni búburú, wọ́n sì jókòó síwájú rẹ̀, wọ́n sì jẹ́rìí lòdì sí Naboti níwájú àwọn ènìyàn wí pé, “Naboti ti bú Ọlọ́run àti ọba.” Nígbà náà ni wọ́n mú jáde kúrò ní ìlú, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa.
and whanne twey men, sones of the deuel, weren brouyt, thei maden hem to sitte ayens hym, and thei, that is, as men of the deuel, seiden witnessyng ayens him bifor al the multitude, Naboth blesside God and the kyng; for which thing thei ledden hym with out the citee, and killiden him with stoonys.
14 Nígbà náà ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jesebeli wí pé, “A ti sọ Naboti ní òkúta, ó sì kú.”
And thei senten to Jezabel, and seiden, Naboth is stoonyd, and is deed.
15 Bí Jesebeli sì ti gbọ́ pé, a ti sọ Naboti ní Òkúta pa, ó sì wí fún Ahabu pé, “Dìde! Kí o sì jogún ọgbà àjàrà Naboti, ará Jesreeli, tí ó kọ̀ láti tà fún ọ kò sí láààyè mọ́, ó ti kú.”
Forsothe it was doon, whanne Jezabel hadde herd Naboth stonyd and deed, sche spak to Achab, Rise thou, take thou in possessioun the vyner of Naboth of Jezrael, which nolde assente to thee, and yyue it for money takun; for Naboth lyueth not, but is deed.
16 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ pé Naboti ti kú, ó sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún ọgbà àjàrà Naboti.
And whanne Achab hadde herd this, that is, Naboth deed, he roos, and yede doun in to the vyner of Naboth of Jezrael, to haue it in possessioun.
17 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
Therfor the word of the Lord was maad to Elie of Thesbi,
18 “Sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ pàdé Ahabu ọba Israẹli, tí ó wà ní Samaria. Ó wà ní ọgbà àjàrà Naboti báyìí, níbi tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ láti jogún rẹ̀.
and seide, Rise thou, go doun in to the comyng of Achab, kyng of Israel, which is in Samarie; lo! he goith doun to the vyner of Naboth, that he haue it in possessioun.
19 Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Naboti, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’”
And thou schalt speke to hym, and `thou schalt seie, The Lord God seith these thingis, Thou hast slayn, ferthermore and thou hast take in possessioun; and aftir these thingis thou schalt adde, In this place, wherynne doggis lickiden the blood of Naboth, thei schulen licke also thi blood.
20 Ahabu sì wí fún Elijah pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀tá mi!” Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.
And Achab seyde to Elie, Whether thou hast founde me thin enemy? Which Elie seide, Y haue founde, for thou art seeld that thou schuldist do yuel in the siyt of the Lord.
21 ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Ahabu gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Israẹli.
Therfor the Lord seith these thingis, Lo! Y schal brynge yn on thee yuel, and Y schal kitte awey thin hyndrere thingis, and Y schal sle of Achab a pissere to the wal, and prisoned, and the laste in Israel;
22 Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jeroboamu, ọmọ Nebati, àti bí ilé Baaṣa, ọmọ Ahijah, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Israẹli ṣẹ̀.’
and Y schal yyue thin hows as the hows of Jeroboam, sone of Naboth, and as the hows of Baasa, sone of Ahia; for thou didist to excite me to wrathfulnesse, and madist Israel to do synne.
23 “Àti ní ti Jesebeli pẹ̀lú Olúwa wí pé, ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jesebeli nínú yàrá Jesreeli.’
But also the Lord spak of Jezabel, and seide, Doggis schulen ete Jezabel in the feeld of Jesrael;
24 “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Ahabu tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní igbó.”
if Achab schal die in the citee, doggis schulen ete hym; sotheli if he schal die in the feeld, briddis of the eyr schulen ete hym.
25 (Kò sí ẹnìkan bí Ahabu tí ó ta ara rẹ̀ láti ṣe búburú níwájú Olúwa, ẹni tí Jesebeli aya rẹ̀ ń tì.
Therfor noon other was sich as Achab, that was seeld to do yuel in the siyt of the Lord; for Jezabel his wijf excitide hym;
26 Ó sì ṣe ohun ìríra gidigidi ní tí tọ òrìṣà lẹ́yìn, gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí àwọn ará Amori ti ṣe, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.)
and he was maad abhomynable, in so myche that he suede the ydols that Ammorreis maden, which Ammorreis the Lord wastide fro the face of the sones of Israel.
27 Nígbà tí Ahabu sì gbọ́ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ sí ara rẹ̀, ó sì gbààwẹ̀. Ó sì dùbúlẹ̀ nínú aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì ń lọ jẹ́ẹ́.
Therfor whanne Achab hadde herd these wordis, he to-rente his cloth, and hilide his fleisch with an hayre, and he fastide, and slepte in a sak, and yede with the heed cast doun.
28 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah ará Tiṣibi wá wí pé,
The word of the Lord was maad to Elie of Thesbi, and seide,
29 “Ǹjẹ́ ìwọ ti rí bí Ahabu ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀ níwájú mi? Nítorí tí ó ti rẹ̀ ara rẹ̀ sílẹ̀, èmi kì yóò mú ibi náà wá ní ọjọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò mú u wá sí ilé rẹ̀ ní ọjọ́ ọmọ rẹ̀.”
Whethir thou hast not seyn Achab maad low bifor me? Therfor for he is maad low for the cause of me, Y schal not brynge yn yuel in hise daies, but in the daies of his sone Y schal bryng yn yuel to his hows.

< 1 Kings 21 >