< 1 Kings 20 >
1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
Wtedy Ben-Hadad, król Syrii, zebrał całe swoje wojsko, a było z nim trzydzieści dwóch królów, konie i rydwany. Wyruszył, obległ Samarię i walczył przeciwko niej.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
I wyprawił posłańców do Achaba, króla Izraela, do miasta, i powiedział mu: Tak mówi Ben-Hadad:
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
Twoje srebro i złoto są moje; także twoje żony i twoi najpiękniejsi synowie są moi.
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
Król Izraela odpowiedział: Według twego słowa, królu, mój panie – twój jestem ja i wszystko, co mam.
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
Potem posłańcy wrócili [do niego] i powiedzieli: Tak powiedział Ben-Hadad: Wprawdzie posłałem do ciebie [ludzi], aby ci powiedzieli: Oddasz swoje srebro i złoto, swoje żony i swoich synów oddasz mi.
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
Jednak jutro o tej porze poślę swoje sługi do ciebie. Oni przeszukują twój dom i domy twoich sług, a wszystko, co jest cenne w twoich oczach, wezmą w ręce i zabiorą.
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
Król Izraela zwołał więc wszystkich starszych ziemi i powiedział [im]: Rozważcie, proszę, i zobaczcie, że ten [człowiek] szuka nieszczęścia. Posłał bowiem do mnie po moje żony i moich synów, po moje srebro i złoto, a nie odmówiłem mu.
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
Wszyscy starsi i cały lud odpowiedzieli: Nie słuchaj [go] i nie gódź się.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
Odpowiedział więc posłom Ben-Hadada: Powiedzcie królowi, memu panu: Wszystko, czego na początku żądałeś od swego sługi, uczynię. Lecz tej rzeczy nie mogę uczynić. Posłańcy odeszli i zanieśli mu odpowiedź.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
Ben-Hadad znowu posłał do niego [sługi] i powiedział: Niech mi to uczynią bogowie i tamto dorzucą, jeśli starczy prochu Samarii po pełnej garści dla każdego spośród całego ludu, który idzie za mną.
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
Król Izraela odpowiedział: Powiedzcie [mu]: Niech się nie chlubi ten, kto zapina [pas], jak ten, kto go odpina.
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
A gdy [Ben]-[Hadad] usłyszał to słowo – a właśnie pił z królami w namiotach – powiedział do swoich sług: Ruszajcie. I ruszyli na miasto.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
A oto pewien prorok przyszedł do Achaba, króla Izraela, i powiedział: Tak mówi PAN: Czy widzisz cały ten wielki tłum? Oto wydam go dziś w twoje ręce, abyś wiedział, że ja jestem PANEM.
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
Wtedy Achab zapytał: Przez kogo? Odpowiedział: Tak mówi PAN: Przez sługi książąt prowincji. Zapytał dalej: Kto rozpocznie bitwę? Odpowiedział mu: Ty.
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Dokonał więc przeglądu sług książąt prowincji i [było] ich dwustu trzydziestu dwóch. A po nich policzył cały lud, wszystkich synów Izraela, i było ich siedem tysięcy.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
I wyruszyli w południe. A Ben-Hadad oddawał się pijaństwu w namiotach, a z nim trzydziestu dwóch królów, którzy go wspierali.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
Wyszli więc jako pierwsi słudzy książąt prowincji. Gdy Ben-Hadad posłał [sługę], powiedziano mu: Ludzie wyszli z Samarii.
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
Polecił: Jeśli wyszli [prosić] o pokój, pojmijcie ich żywych, również jeśli wyszli walczyć, pojmijcie ich żywych.
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
Wyszli więc z miasta słudzy książąt prowincji oraz wojsko razem z nimi.
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
A każdy pokonał swego przeciwnika, tak że Syryjczycy uciekli, a Izrael ich ścigał. Ben-Hadad, król Syrii, również uciekł na koniu i z jeźdźcami.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Potem król Izraela wyruszył i pobił konie i rydwany, a zadał Syryjczykom wielką klęskę.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Prorok znowu przyszedł do króla Izraela i powiedział mu: Idź, wzmocnij się, rozważ i zastanów się, co masz czynić. Po roku bowiem król Syrii nadciągnie przeciwko tobie.
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Wtedy słudzy króla Syrii powiedzieli do niego: Ich bogowie są bogami gór, dlatego nas pokonali. Walczmy jednak z nimi na równinie i na pewno ich pokonamy.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
Tak więc uczyń: Usuń każdego z królów z jego stanowiska, a na ich miejsce ustanów dowódców.
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Następnie odlicz sobie wojska takiego jak [to] wojsko, które ci poległo, koni jak tamte konie i rydwanów jak tamte rydwany. Wtedy stoczymy z nimi bitwę na równinie i na pewno ich pokonamy. I posłuchał ich głosu, i tak uczynił.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
A gdy upłynął rok, Ben-Hadad dokonał przeglądu Syryjczyków i nadciągnął do Afek, aby walczyć z Izraelem.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
Również u synów Izraela dokonano przeglądu, a gdy się zebrali, wyruszyli przeciwko nim. I synowie Izraela rozbili obóz przed nimi jak dwa małe stadka kóz. Syryjczycy zaś napełnili ziemię.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Wtedy przyszedł mąż Boży i mówił do króla Izraela: Tak mówi PAN: Ponieważ Syryjczycy powiedzieli: PAN jest Bogiem gór, a nie jest Bogiem równin, wydam cały ten wielki tłum w twoje ręce, abyście wiedzieli, że ja jestem PANEM.
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
Obozowali jedni naprzeciw drugich przez siedem dni. A siódmego dnia stoczyli bitwę i synowie Izraela pobili w jednym dniu sto tysięcy pieszych spośród Syryjczyków.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
Pozostali zaś uciekli do Afek, do miasta, i runął mur na dwadzieścia siedem tysięcy pozostałych mężczyzn. Ben-Hadad uciekł i wszedł do miasta, gdzie [ukrył się] w wewnętrznej komnacie.
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
Wtedy jego słudzy powiedzieli mu: Oto słyszeliśmy, że królowie domu Izraela są królami miłosiernymi. Pozwól, proszę, że włożymy wory na nasze biodra, powrozy na nasze głowy i wyjdziemy do króla Izraela, może zostawi nas przy życiu.
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Opasali więc worami swoje biodra, [włożyli] powrozy na swoje głowy, przyszli do króla Izraela i powiedzieli: Ben-Hadad, twój sługa, mówi: Proszę, zachowaj moją duszę przy życiu. Zapytał: Czy jeszcze żyje? To jest mój brat.
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
Ci ludzie wzięli to za dobry znak i szybko podchwycili [to słowo] od niego, i powiedzieli: Twój brat Ben-Hadad. On zaś powiedział: Idźcie i przyprowadźcie go. Ben-Hadad wyszedł więc do niego i kazał mu wsiąść na rydwan.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
[Ben]-[Hadad] powiedział do niego: Miasta, które mój ojciec zabrał twemu ojcu, zwrócę, a ty uczynisz sobie ulice w Damaszku, jak uczynił mój ojciec w Samarii. [I odpowiedział]: Puszczę cię wolno na podstawie tego przymierza. Tak więc zawarł z nim przymierze i puścił go wolno.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
Wtedy pewien mąż spośród synów proroków powiedział do swego bliźniego na słowo PANA: Uderz mnie, proszę. Ale ten człowiek nie chciał go uderzyć.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
I powiedział mu: Ponieważ nie posłuchałeś głosu PANA, oto gdy tylko odejdziesz ode mnie, zabije cię lew. A gdy odszedł od niego, spotkał go lew i zabił go.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
Potem spotkał drugiego mężczyznę i powiedział mu: Uderz mnie, proszę. Człowiek ten tak go uderzył, że go zranił.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Prorok poszedł więc i czekał na króla na drodze, i zmienił swój wygląd dzięki zasłonie na twarzy.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
A gdy król przejeżdżał, zawołał do króla: Twój sługa wszedł w sam środek bitwy, a oto podszedł pewien mężczyzna i przyprowadził do mnie człowieka, i powiedział: Pilnuj tego człowieka. Jeśli ci się wymknie, zapłacisz swoim życiem za jego życie albo zapłacisz talent srebra.
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
A gdy twój sługa zajął się tym i owym, on zniknął. Król Izraela powiedział do niego: Taki [jest] twój wyrok, ty sam rozstrzygnąłeś [tę sprawę].
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
Wtedy on szybko zdjął zasłonę z twarzy i król Izraela rozpoznał, że jest on jednym z proroków.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
I powiedział do niego: Tak mówi PAN: Ponieważ wypuściłeś ze swojej ręki człowieka przeznaczonego na śmierć, swoim życiem zapłacisz za jego życie i swoim ludem za jego lud.
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Król Izraela odszedł więc do swego domu smutny i rozgniewany i przybył do Samarii.