< 1 Kings 20 >

1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
Tedy Benadad, król Syryjski, zebrał wszystko wojsko swoje, mając z sobą trzydzieści i dwóch królów, przytem jezdne i wozy; a przyciągnąwszy obległ Samaryję i dobywał jej.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
I wyprawił posły do Achaba, króla Izraelskiego, do onego miasta;
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
I rzekł mu: Tak mówi Benadad: Srebro twoje i złoto twoje mojeć jest; także żony twoje i synowie twoi najcudniejsi moi są.
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
I odpowiedział król Izraelski a rzekł: Według słowa twego królu, panie mój, twojem ja, i wszystko, co mam.
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
A wróciwszy się posłowie do niego, rzekli: Tak powiedział Benadad, mówiąc: Posłałem do ciebie, abyć rzeczono: Srebro twoje, i złoto twoje, i żony twoje, i syny twoje dasz mi.
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
Ale wiedz, że jutro o tym czasie poślę sługi moje do ciebie, którzy wyszperają dom twój, i domy sług twoich, i wszystko, w czem się kochasz, w ręce swe wezmą, i rozbiorą.
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
A tak wezwał król Izraelski wszystkich starszych ziemi onej, i rzekł im: Uważcież proszę, a obaczcie, żeć ten złego szuka; albowiem posłał do mnie po żony moje, i po syny moje, i po srebro moje, i po złoto moje, a nie odmówiłem mu.
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
I rzekli do niego oni wszyscy starsi, i wszystek lud: Nie słuchaj ani przyzwalaj.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
Przetoż odpowiedział posłom Benadadowym: Powiedzcie królowi, panu memu: wszystko, o coś posłał do sługi twego przedtem, uczynię: ale tej rzeczy uczynić nie mogę. A tak posłowie odeszli, i odnieśli mu odpowiedź.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
Znowu posłał do niego Benadad i rzekł: Niech mi to uczynią bogowie, i to niech przyczynią, jeźli się dostanie prochu Samaryi po garści wszystkiemu ludowi, który za mną idzie.
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
I odpowiedział król Izraelski, a rzekł: Powiedzcie mu: Niech się nie chlubi zbrojny, jako ten, który złożył zbroję.
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
A gdy Benadad usłyszał to słowo, (a on w tenczas z królmi pił w namiotach, ) rzekł do sług swych: Ruszcie się. I ruszyli się ku miastu.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
A oto, niektóry prorok przyszedł do Achaba, króla Izraelskiego, i rzekł: Tak powiada Pan: Izażeś nie wiedział tego wszystkiego wielkiego mnóstwa? Oto Ja je dam w rękę twoję dzisiaj, abyś wiedział, żem Ja Pan.
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
Tedy rzekł Achab: Przez kogoż? A on odpowiedział: Tak mówi Pan: przez sługi książąt powiatowych. I rzekł: Którz pocznie bitwę? Tedy mu on odpowiedział: Ty.
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Obliczył tedy sługi książąt powiatowych, których było dwieście trzydzieści i dwa; a po nich policzył wszystek lud, wszystkich synów Izraelskich siedm tysięcy.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
I wyszli o południu. A Benadad pił, i upił się w namiotach, sam i trzydzieści i dwóch królów, pomocników jego.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
A tak wyszli słudzy książąt powiatowych naprzód. Tedy posłał Benadad, (gdy mu powiedziano, mówiąc: Mężowie wyszli z Samaryi, )
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
I rzekł: Chociażby o pokój szli prosić, pojmajcie je żywo; chociażby też ku bitwie wyszli, żywo je pojmajcie.
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
A gdy oni słudzy książąt powiatowych wyszli z miasta, i inne wojsko za nimi,
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
Poraził każdy męża swego, tak, że uciekli Syryjczycy, i gonił je Izrael; uciekł też Benadad, król Syryjski, na koniu i z jezdnymi.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Potem wyciągnął król Izraelski, i pobił konie i wozy, a poraził Syryjczyka porażką wielką.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Znowu przyszedł prorok do króla Izraelskiego, i rzekł mu: Idź, zmacniaj się, a wiedz i bacz, co masz czynić; albowiem po roku król Syryjski wyciągnie przeciwko tobie.
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Tedy słudzy króla Syryjskiego rzekli do niego: Bogowie ich są bogowie górni, przetoż nas przemogli; a wszakże zwiedźmy z nimi bitwę w polu a ujrzysz, jeźli ich nie przemożemy.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
Przetoż tak uczyń: Odpraw królów, każdego z miejsca swego, a postanów hetmanów miasto nich.
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
A ty nalicz sobie wojska z swoich, jako było wojsko onych, którzy polegli, a koni jako one konie, a wozów, jako one wozy, i stoczymy bitwę z nimi w polu, a ujrzysz, jeźli ich nie przemożemy. I usłuchał głosu ich, a uczynił tak.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
A gdy wyszedł rok, obliczył Benadad Syryjczyki, a ciągnął ku Afeku na wojnę przeciw Izraelitom.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
Synowie Izraelscy także są obliczeni, a nabrawszy z sobą żywności, ciągnęli przeciwko nim. I położyli się obozem synowie Izraelscy przeciwko nim, jakoby dwa małe stadka kóz; a Syryjczycy napełnili ziemię.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Tedy przyszedł mąż Boży, i mówił do króla Izraelskiego, a rzekł: Tak mówi Pan: Przeto iż mówili Syryjczycy: Bogiem gór jest Pan, a nie jest Bogiem równim, podam to wszystko mnóstwo wielkie w ręce twoje, abyście wiedzeli, żem Ja Pan.
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
A tak oni leżeli obozem przeciwko nim przez siedm dni. I stało się dnia siódmego, że stoczyli bitwę, i porazili synowie Izraelscy Syryjczyków sto tysięcy pieszych jednegoż dnia.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
A ostatek uciekli do Afeku miasta, i upadł mur na dwadzieścia i siedm tysięcy mężów, co byli pozostali. A Benadad uciekłszy przyszedł do miasta, i skrył się do najskrytszej komory.
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
Ale mu rzekli słudzy jego: Słychaliśmy za pewne, że królowie domu Izraelskiego są królowie miłosierni. Niech włożymy proszę wory na biodra nasze, i powrozy na głowy nasze, a wynijdziemy do króla Izraelskiego, snać żywo zostwi duszę twoję.
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Tedy opasali wormi biodra swe, a włożyli powrozy na głowy swoje i przyszli do króla Izraelskiego, i rzekli: Benadad, sługa twój, mówi: Niech żyje proszę dusza moja! A on rzekł: a żywże jeszcze? Brat to mój.
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
A oni mężowie wziąwszy to za dobry znak, i prędko uchwyciwszy to słowo od niego, rzekli: Bratci twój Benadad. I rzekł: Idźcież, przywiedźcie go. Przetoż wyszedł do niego Benadad, i kazał mu wsiąść na wóz.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
I rzekł do niego Benadad: miasta, które wziął ojciec mój ojcu twemu, powrócę, a ty ulice sobie poczynisz w Damaszku, jako poczynił ojciec mój w Samaryi. I odpowiedzał: Ja według przymierza puszczę cię wolno. A tak z nim uczynił przmierze i puścił go wolno.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
Tedy niektóry mąż z synów prorockich rzekł do bliźniego swego z rozkazania Pańskiego: Uderz mię proszę; ale go nie chciał on mąż uderzyć.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
I rzekł mu: Przeto iżeś nie usłuchał głosu Pańskiego, oto skoro odejdziesz odemnie, zabije cię lew. A gdy odszedł od niego, znalazł go lew, i zabił go.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
Potem znalazł drugiego męża, i rzekł mu: Uderz mię proszę; który mąż tak go uderzył, że go ranił.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Szedł tedy on prorok, a zabieżał królowi na drodze, i odmienił się, zasłoniwszy oczy swoje.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
A gdy król mijał, zawołał na króla, i rzekł; sługa twój wyszedł w pośrodek bitwy, a oto mąż przyszedłszy przywiódł do mnie męża, i rzekł: Strzeż tego męża; bo jeźlibyś go opuścił, dusza twoja będzie za duszę jego, albo talent srebra odważysz.
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
Wtem gdy się sługa twój zabawił tem i owem, oto on zniknął. Tedy rzekł do niego król Izraelski: Taki jest sąd twój, sameś się osądził.
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
A on zaraz odjął zasłonę od oczu swych, i poznał go król Izraelski, że był prorokiem.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
Zatem rzekł do niego: Tak mówi Pan: Ponieważeś wypuścił z ręki swej męża godnego śmierci, dusza twoja będzie za duszę jego, i lud twój za lud jego.
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Przetoż odszedł król Izraelski do domu swego smutny i zagniewany, i przyszedł do Samaryi.

< 1 Kings 20 >