< 1 Kings 20 >
1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
Un BenHadads, Sīrijas ķēniņš, sapulcināja visu savu spēku, un trīsdesmit un divi ķēniņi bija viņam līdz un zirgi un rati, un viņš nogāja un apmetās pret Samariju, un karoja pret to.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
Un viņš sūtīja vēstnešus pilsētā pie Ahaba, Israēla ķēniņa,
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
Un lika tam sacīt: tā saka BenHadads: tavs sudrabs un tavs zelts būs mans, arī tavas sievas un tavi labākie bērni būs mani.
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
Un Israēla ķēniņš atbildēja un sacīja: pēc tava vārda, mans kungs un ķēniņ, es esmu tavs, un viss, kas man ir.
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
Un tie vēstneši nāca atkal atpakaļ un sacīja: tā runā BenHadads un saka: es gan pie tevis esmu sūtījis un licis sacīt: tavu sudrabu un tavu zeltu un tavas sievas un tavus bērnus tev man būs dot,
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
Bet rītu ap šo laiku es savus kalpus pie tevis sūtīšu, izmeklēt tavu namu un tavu kalpu namu, un viss, kas tur skaists priekš tavām acīm, to tiem būs ņemt un aiznest.
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
Tad Israēla ķēniņš saaicināja visas zemes vecajus un sacīja: ņemiet jel vērā un redziet, kā šis ļaunu meklē. Jo tas pie manis ir sūtījis pēc manām sievām un pēc maniem bērniem un pēc mana sudraba un zelta, un es tam to neesmu liedzis.
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
Bet visi vecaji un visi ļaudis uz viņu sacīja: nepaklausi un neļauj to.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
Tad viņš sacīja uz BenHadada vēstnešiem: sakāt ķēniņam, manam kungam: visu, par ko tu pirmo reizi pie sava kalpa sūtījis, to es darīšu, bet šo lietu es nevaru darīt. Tad tie vēstneši nogāja un viņam atsacīja to vārdu.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
Un BenHadads sūtīja pie viņa un lika sacīt: lai man dievi šā vai tā dara, ja Samarijas pīšļi pietiks visu ļaužu saujām, kas man ir līdz.
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
Bet Israēla ķēniņš atbildēja un sacīja: atsakiet tā: kas apjozies, tas lai nelielās kā tas, kas atjozies.
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
Kad nu tas šo vārdu dzirdēja, ar tiem ķēniņiem teltīs dzerot, tad viņš sacīja uz saviem kalpiem taisāties. Un tie taisījās pret to pilsētu.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
Un redzi, viens pravietis nāca pie Ahaba, Israēla ķēniņa, un sacīja: “Tā saka Tas Kungs: vai tu esi redzējis visu šo lielo pulku? Redzi, Es to šodien došu tavā rokā, lai tu atzīsti, ka Es esmu Tas Kungs.”
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
Un Ahabs sacīja: “Caur ko?” Tad viņš sacīja: “Tā saka Tas Kungs: caur zemes valdnieku puišiem.” Un viņš sacīja: “Kas lai uzsāk kauju?” Tad viņš sacīja: “Tu pats.”
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Tad viņš skaitīja tos zemes valdnieku puišus, to bija divsimt trīsdesmit un divi. Un pēc tiem viņš skaitīja visus ļaudis, visus Israēla bērnus, to bija septiņi tūkstoši.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
Un tie izgāja dienasvidū. Bet BenHadads dzēra un piedzērās teltīs ar tiem trīsdesmit un diviem ķēniņiem, kas tam bija palīgā.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
Un tie zemes valdnieku puiši izgāja papriekš. Tad BenHadads izsūtīja, un tie tam teica un sacīja: vīri nāk no Samarijas.
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
Tad viņš sacīja: vai tie nākuši uz mieru, sagrābiet tos dzīvus, vai tie nākuši uz kauju, dzīvus tos sagrābiet!
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
Kad nu šie zemes valdnieku puiši no pilsētas bija izgājuši un arī tas karaspēks, kas tiem gāja pakaļ,
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
Tad tie kāva vīrs vīru. Un Sīrieši bēga un Israēls tiem dzinās pakaļ. Bet BenHadads, Sīrijas ķēniņš, izglābās uz zirga un ar jātniekiem.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Un Israēla ķēniņš izgāja un kāva zirgus un ratus un kāva Sīriešus lielā kaušanā.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Tad tas pravietis nāca pie Israēla ķēniņa un uz to sacīja; ej, stiprinājies: ņem vērā un lūko, ko tu dari, jo nākošā gadā Sīrijas ķēniņš atkal nāks pret tevi.
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Jo Sīrijas ķēniņa kalpi uz to sacīja: viņu dievi ir kalna dievi, tāpēc tie bijuši stiprāki nekā mēs. Kaut mums ar tiem būtu jākaro klajumā! Varbūt ka mēs būtu stiprāki nekā tie.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
Tāpēc dari tā: atcel tos ķēniņus, ikvienu no viņa vietas, un iecel viņu vietā virsniekus.
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Un taisi sev karaspēku, kāds tas bija, kas tev zudis, un zirgus, kā bija zirgi, un ratus, kā bija rati, un iesim ar tiem kauties klajumā; vai nebūsim stiprāki par tiem? Un tas klausīja viņu balsi un tā darīja.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
Un otrā gadā BenHadads skaitīja Sīriešus un cēlās uz Afeku, karot pret Israēli.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
Un Israēla bērni arī tapa skaitīti un izrīkoti, un gāja tiem pretī, un Israēla bērni apmetās tiem pretī, kā divi kazu pulciņi, bet zeme bija Sīriešu pilna.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Un tas Dieva vīrs nāca un runāja uz Israēla ķēniņu un sacīja: “Tā saka Tas Kungs: tāpēc ka Sīrieši sacījuši: Tas Kungs ir kalnu Dievs un ne arī ieleju Dievs, tad visu šo lielo pulku Es dodu tavā rokā, lai jūs atzīstat, ka Es esmu Tas Kungs.”
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
Un tie palika apmetušies viens otram pretim septiņas dienas. Un septītā dienā kaušanās sākās, un Israēla bērni nokāva no Sīriešiem simts tūkstoš kājniekus vienā dienā.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
Un tie atlikušie bēga uz Afekas pilsētu, un mūris sagruva pār divdesmit un septiņtūkstošiem no šiem atlikušiem. Un BenHadads bēga un nāca pilsētā no vienas istabas otrā.
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
Tad viņa kalpi uz to sacīja: redzi, mēs esam dzirdējuši, ka Israēla nama ķēniņi ir žēlīgi ķēniņi. Apvilksim maisus ap saviem gurniem un virves ap savām galvām, un iesim ārā pie Israēla ķēniņa; vai viņš tavai dvēselei neļaus dzīvot.
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Un tie apvilka maisus ap saviem gurniem un virves ap savām galvām, un nāca pie Israēla ķēniņa un sacīja: tavs kalps BenHadads saka: ļauj jel manai dvēselei dzīvot. Tad tas sacīja: vai viņš vēl dzīvs? Viņš ir mans brālis.
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
Un tie vīri saprata šo vārdu sev par labu un steigšus to lika sev apstiprināt no viņa un sacīja: tad BenHadads tavs brālis? Un viņš sacīja: ejat un atvediet to šurp. Tad BenHadads iznāca pie viņa, un viņš tam lika kāpt ratos.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
Un BenHadads uz to sacīja: tās pilsētas, ko mans tēvs tavam tēvam paņēmis, es gribu atdot, un dari sev ielas Damaskā, itin kā mans tēvs darījis Samarijā. (Un Ahabs sacīja: ) ar šo derību es tevi atlaidīšu. Tā viņš ar to derēja derību un to atlaida.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
Un viens vīrs no praviešu bērniem sacīja uz otru caur Tā Kunga vārdu: sit jel mani. Bet tas vīrs liedzās to sist.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
Un viņš uz šo sacīja: tāpēc ka tu Tā Kunga balsi neesi klausījis, redzi, tad tevi lauva sitīs, kad tu no manis aiziesi. Kad nu tas no viņa aizgāja, lauva to sastapa un saplēsa.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
Un viņš atrada citu vīru un sacīja: sit jel mani. Un tas vīrs to sita, un to sizdams ievainoja.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Tad tas pravietis gāja un nostājās ķēniņam ceļā un aptina savu vaigu ar drānu.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
Kad nu ķēniņš gāja garām, tad viņš sauca uz ķēniņu un sacīja: tavs kalps bija izgājis kaujā, un redzi, viens vīrs nāca malā un atveda pie manis vienu vīru un sacīja: apsargi šo vīru; ja tas kaut kā nozustu, tad tava dvēsele būs viņa dvēseles vietā, vai tev būs jāmaksā viens talents sudraba.
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
Kad nu tavam kalpam šur tur kas bija jādara, tad viņš nozuda. Un Israēla ķēniņš sacīja: tāds tavs spriedums, kā pats spriedis.
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
Tad viņš steigšus noņēma to drānu no sava vaiga, un Israēla ķēniņš to pazina, ka tas bija viens no tiem praviešiem.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
Un viņš uz to sacīja: “Tā saka Tas Kungs: “Tāpēc ka tu šo vīru, ko es liku izdeldēt, esi izlaidis no rokas, tad tava dvēsele būs viņa dvēseles vietā, un tavi ļaudis viņa ļaužu vietā.””
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Un Israēla ķēniņš nogāja saīdzis un dusmīgs savā namā un aizgāja uz Samariju.