< 1 Kings 20 >
1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
HOULUULU ae la o Benehadada ke alii o Suria i kona poe kaua a pau: kanakolu kumamalua mau alii me ia, a me na lio a me na kaa: Pii mai la ia a hoopuni ia Samaria, a kaua ae la ia ia.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
Hoouna ae la oia i na elele io Ahaba la ke alii o ka Iseraela, iloko o ke kulanakauhale;
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
I ae la, Ke olelo nei o Benehadada, O kau kala, a me kau gula, o ka'u ia, a me kau mau wahine, a me kau mau keiki, o na mea maikai, o ka'u ia.
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
I aku la o ke alii o ka Iseraela, e like me kau olelo, e ke alii ko'u haku, ia oe no wau a me ka'u mau mea a pau.
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
Hoi hou mai na elele, a i mai la, Penei ka olelo ana a Benehadada, i ka i ana, Ua hoouna aku au iou la, i ka i ana aku, E haawi mai oe i kau kala, a me kau gula, a me kau mau wahine, a me kau mau keiki;
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
Aka, e hoouna hou aku au i ka'u mau kauwa iou la i ka la apopo me neia ka hora, a e huli lakou i kou hale, a me na hale o kau mau kauwa; a eia hoi, o ka mea makemakeia imua o kou mau maka, e lalau ko lakou lima, a e lawe mai.
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
Alaila hea ae la ke alii o ka Iseraela i na lunakahiko a pau o ka aina, i ae la, Ke noi aku nei au ia oukou, e nana i ko keia kanaka imi ana e kolohe wale mai; no ka mea, ua kii e mai nei oia i ka'u mau wahine, a me ka'u mau keiki, a me ka'u kala, a me ka'u gula, aole hoi au i hoole aku ia ia.
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
I aku la na lunakahiko a pau a me na kanaka a pau ia ia, Mai hoolohe aku, aole hoi e ae aku.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
Nolaila i olelo aku ai oia i na elele o Benehadada, E hai aku i kuu haku ke alii, O ka mea a pau au i kii mai ai i kau kauwa nei, i kinohou, oia ka'u e hana'i: aka, o keia mea, aole e hiki ia'u ke hana. A hoi na elele, a lawe hou ae la i ka olelo ia ia.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
Hoouna hou mai la o Benehadada io na la, i mai la, Pela e hana mai ai na akua ia'u, a e hui hou, ke lawa ka lepo o Samaria e piha ai na lima o ka poe kanaka a pau e hahai ana mamuli o'u.
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
Olelo aku la ke alii o ka Iseraela, i aku la, E olelo aku, Mai hookiekie ka mea e hookomo ana i ka mea kaua e like me ka mea e kala ana ia.
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
Eia kekahi, i kona lohe ana i keia olelo i kona wa e inu ana oia me na alii iloko o na halelewa, i ae la oia i kana poe kauwa, E hoonohonoho. Hoonohonoho ae la lakou e ku e i ke kulanakauhale.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
Hiki mai la kekahi kaula ia Ahaba ke alii o ka Iseraela, i ae la oia ia ia, Ke i mai nei o Iehova penei, Ua ike anei oe i keia lehulehu loa? Eia hoi, e haawi aku no au ia lakou iloko o kou lima; a e ike no oe owau no Iehova.
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
Ninau aku la o Ahaba, Ma owai la? Hai mai la oia, Ke i mai nei o Iehova, penei, Ma na kanaka ui o na lii o na panalaau. Alaila ninau hou aku la oia, Owai ka mea e hooinakaukau? Hai mai la oia, O oe.
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Helu ae la oia i na kanaka ui o na lii o na panalaau, elua haneri me kanakolu kumamalua; a mahope o lakou, helu ae la oia i na kanaka a pau, i na mamo a pau a Iseraela, ehiku tausani.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
Puka aku la lakou i ke awakea. Aka, e inu ana o Benehadada a ona iloko o na halelewa, oia pu me na lii, he kanakolu kumamalua alii e kokua ana ia ia.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
Puka mua aku la o na kanaka ui o na lii o na panalaau; hoouna ae la o Benehadada, a hoike aku la lakou ia ia, i aku la, Ke puka mai nei na kanaka mai loko mai o Samaria.
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
Olelo mai la oia, Ina i puka mai lakou no ka malu, e hopu ia lakou e ola ana; a ina i puka mai lakou no ke kaua, e hopu ia lakou e ola ana.
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
Pela i puka ai mai loko ae o ke kulanakauhale ua poe kanaka ui la o na lii o na panalaau, a me ka poe kana i hahai mamuli o lakou.
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
Pepehi ae la lakou pakahi i kona kanaka; a auhee ae la ko Suria, a hahai aku la ka Iseraela ia lakou; pakele aku la o Benehadada, ke alii o Suria maluna o ka lio, a me na hololio.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Puka aku la ke alii o ka Iseraela, a pepehi ae la i na lio a me na kaa, a laku hoi i ko Suria me ka luku nui loa.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Hele ae la ke kaula i ke alii o ka Iseraela, i ae la ia ia, E hele, e hookupaa ia oe iho, a e noonoo, a e ike i kau mea e hana aku ai; no ka mea, aia puni ka makahiki, e pii ku e hou mai ke alii o Suria ia oe.
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Olelo aku la na kauwa a ke alii o Suria ia ia, He mau akua o na puu ko lakou mau akua; nolaila i oi ai ko lakou ikaika mamua o ko kakou. E kaua aku kakou ia lakou ma ka papu, a e oi io aku ko kakou ikaika mamua o ko lakou.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
E hana hoi oe i keia mea, e hookaawale ae i na lii, kela kanaka keia kanaka mai kona wahi ae, a e pani i ko lakou hakahaka me na luna koa.
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
A e helu ae i poe kaua nou, e like me kau poe kaua i haule, he lio no ka lio, he kaa no ke kaa; a e kaua aku kakou ia lakou ma ka papu, a e kela io aku ko kakou ikaika mamua o ko lakou. Hoolohe mai la oia i ko lakou leo, a hana iho la pela.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
Eia hoi keia, i ka puni ana o ka makahiki, helu aku la o Benehadada i ko Suria, a pii mai la i Apeka e kaua i ka Iseraela.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
A ua heluia'e la na mamo a Iseraela, e noho makaukau ana no hoi lakou a pau, a hele ku e aku la ia lakou; a hoomoana iho la o na mamo a Iseraela imua o lakou, e like me na ohana liilii elua o na keiki kao; aka, o ko Suria, ua paapu ka aina ia lakou.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Hele mai la ke kanaka o ke Akua, a olelo mai la i ke alii o ka Iseraela, i mai la, Ke i mai nei o Iehova penei, No ka mea, ke olelo nei lakou, He Akua no na puu o Iehova, aole he Akua ia no na awawa, nolaila e haawi aku ai au i keia poe lehulehu nui iloko o kou lima, a e ike oukou owau no Iehova.
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
Hoomoana ae la lakou kekahi i mua o kekahi i na la ehiku. Eia hoi i ka hiku o ka la kaua iho la lakou; pepehi iho la na mamo a Iseraela i ko Suria i hookahi haneri tausani kanaka hele wawae, i ka la hookahi.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
A holo aku la ke koena i Apeka iloko o ke kulanakauhale; a malaila i hiolo ai ka pa maluna o na tausani he iwakalua kumamahiku o na kanaka i koe. Holo aku la hoi o Benehadada, a komo iloko o ke kulanakauhale, iloko o ke keena maloko ae.
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
I aku la kana mau kauwa ia ia, Eia hoi, ua lohe kakou he poe alii lokomaikai na lii o ka ohana a Iseraela; nolaila, ea, e hookomo i ke kapa eleele, ma ko makou puhaka, a e kau na kaula ma ko makou mau poo, a e puka aku i ke alii o ka Iseraela; e hoola paha auanei oia ia oe.
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Kau iho la lakou i ke kapa eleele ma ko lakou mau puhaka, a kau i na kaula maluna o ko lakou mau poo, a hele i ke alii o ka Iseraela, i mai la hoi, Ke i mai nei kau kauwa Benehadada, Ke noi aku nei au ia oe e ola au. I aku la oia, E ola ana anei ia? O ko'u hoahanau no ia.
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
Haka pono mai la na kanaka i puka mai paha mai loko ona, a hopu koke ae, a olelo mai la lakou, O kou hoahanau Benehadada. Alaila olelo aku la ia, E kii aku oukou, a lawe mai ia ia. Alaila hele mai la o Benehadada io na la, a hooee ae la oia ia ia iloko o ke kaa.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
Olelo ae la o Benehadada ia ia, O na kulanakauhale a ko'u makuakane i kaili ae ai mai kou makuakane ae, oia ka'u e hoihoi aku ai; a e hana oe nou i na alanui ma Damaseko me ko'u makuakane i hana'i ma Samaria. I ae la o Ahaba, Me ia berita e hookuu aku ai au ia oe. Hana iho la oia i berita me ia, a hookuu aku la ia ia.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
A o kekahi kanaka no na keiki a na kaula i olelo ae la i kona hoalauna, ma ka olelo a Iehova, Ke noi aku nei au e pepehi mai oe ia'u. Aole hoi i pepehi na kanaka la ia ia.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
Alaila olelo ae la oia ia ia, No kou hoolohe ole ana i ka leo o Iehova, eia hoi, i kou hele ana mai o'u aku nei, e pepehi koke no ka liona ia oe. A hele ae la ia mai ona aku la, a loaa koke iho la i ka liona, a make ia ia i ka pepehiia.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
Alaila loaa ia ia kekahi kanaka, olelo aku la oia ia ia, Ke noi aku nei au e pepehi mai oe ia'u: pepehi aku la hoi oia ia ia, a eba ia ia i ka pepehiia.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Hele aku la hoi ke kaula, a kali i ke alii ma ke alanui, a hoonalonalo i kona ano me ka lehu maluna o kona wahi maka.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
A maalo ae la ke alii, kahea aku la oia i ke alii, i aku la hoi, Hele aku la kau kauwa iwaena konu o ke kaua; aia hoi, kapae ae la kekahi kanaka, a lawe mai i kekahi kanaka io'u nei, i mai la, E malama ia ia nei: ina paha i nalo, alaila e lilo kou ola no kona ola, a i ole ia, e uku oe i hookahi talena kala.
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
A i ko'u lawelawe ana io ia nei, nalo wale ae la ia. Olelo mai la ke alii o ka Iseraela ia ia, Pela ka hooponopono ana nou, nau no ia i hoakaka.
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
Lalelale ae la oia e hoohemo ae i ka lehu mai kona wahi maka ae; a ike mai ke alii o ka Iseraela ia ia o kekahi ia o na kaula.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
I aku la oia ia ia, Ke i mai nei o Iehova penei, No kou hookuu ana mai loko ae o kou lima i ke kanaka a'u i hoolilo ai i ka luku loa ia, nolaila e lilo kou ola no kona ola, a o kou poe kanaka no kona poe kanaka.
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Hoi aku la hoi ke alii o ka Iseraela i kona hale, me ke kaumaha, a me ka uluhua a hiki i Samaria.