< 1 Kings 20 >

1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
Na rĩrĩ, Beni-Hadadi mũthamaki wa Suriata agĩcookanĩrĩria mbũtũ ciake ciothe cia ita, agĩtwarana hamwe na athamaki mĩrongo ĩtatũ na eerĩ, marĩ na mbarathi na ngaari cia ita, akĩambata akĩrigiicĩria itũũra rĩa Samaria na akĩrĩtharĩkĩra.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
Agĩtũma andũ mathiĩ itũũra rĩu inene kũrĩ Ahabu mũthamaki wa Isiraeli, makamwĩre atĩrĩ, “Beni-Hadadi ekuuga ũũ:
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
‘Betha na thahabu ciaku nĩ ciakwa, nao atumia aku na ciana ciaku, arĩa ega mũno, nĩ akwa.’”
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
Nake mũthamaki wa Isiraeli akĩmũcookeria atĩrĩ, “O ũguo uugĩte, wee mũthamaki mwathi wakwa-rĩ, niĩ mwene ndĩ waku, na kĩrĩa gĩothe ndĩ nakĩo nĩ gĩaku.”
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
Nao andũ acio maatũmĩtwo magĩcooka rĩngĩ makiuga atĩrĩ, “Beni-Hadadi ekuuga ũũ: ‘Ndaatũmanire ngĩenda betha ciaku, na thahabu, na atumia aku, o na ciana ciaku.
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
No ihinda ta rĩĩrĩ rũciũ nĩngatũma anene akwa moke moiruurie nyũmba ya ũthamaki na nyũmba cia anene aku. Nĩmagataha indo ciothe iria cia bata, macikuue.’”
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
Mũthamaki wa Isiraeli agĩĩta athuuri othe a bũrũri ũcio, akĩmeera atĩrĩ, “Githĩ mũtirona atĩ mũndũ ũyũ nĩ haaro aracaria! Rĩrĩa aatũmanire agĩĩtia atumia akwa na ciana ciakwa, na betha na thahabu ciakwa-rĩ, niĩ ndiamũgiririe.”
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
Athuuri na andũ othe makĩmũcookeria atĩrĩ, “Tiga kũmũthikĩrĩria, na ndũgetĩkĩre maũndũ macio mothe arenda.”
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
Nake agĩcookeria andũ acio maatũmĩtwo nĩ Beni-Hadadi, akĩmeera atĩrĩ, “Ĩrai mũthamaki, mwathi wakwa atĩrĩ, ndungata yaku nĩĩgwĩka maũndũ marĩa woririe rĩa mbere, no ũndũ ũyũ ũrenda rĩu ndingĩwĩĩtĩkĩra.” Magĩthiĩ magĩcookeria Beni-Hadadi ũhoro ũcio.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
Ningĩ Beni-Hadadi agĩtũma ũhoro rĩngĩ kũrĩ Ahabu, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ngai iroothũũra na ikĩrĩrĩrie gũthũũra, kũngĩtigara rũkũngũ Samaria rũiganu rwa kũhe andũ akwa o mũndũ ngundi ĩmwe.”
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
Mũthamaki wa Isiraeli agĩcookia atĩrĩ, “Mwĩrei ũũ: ‘Mũndũ ũrĩa ũreyooha indo cia mbaara ndaagĩrĩirwo nĩ gwĩtĩĩa ta mũndũ ũrĩa ũraciruta.’”
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
Hĩndĩ ĩrĩa Beni-Hadadi aiguire ũhoro ũcio rĩrĩa we na athamaki acio manyuuaga me hema-inĩ ciao, agĩatha andũ ake akĩmeera atĩrĩ, “Mwĩhaarĩriei gũtharĩkĩra Samaria.” Nĩ ũndũ ũcio makĩĩhaarĩria gũtharĩkĩra itũũra rĩu inene.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
Ihinda rĩu mũnabii agĩũka kũrĩ Ahabu mũthamaki wa Isiraeli, akĩmwĩra atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: ‘Nĩũrona ita rĩĩrĩ inene ũũ? Nĩngũrĩneana moko-inĩ maku ũmũthĩ, nĩgeetha ũmenye atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
Nake Ahabu akĩũria atĩrĩ, “No nũũ ũgwĩka ũguo?” Nake mũnabii ũcio akĩmũcookeria atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: Anene ethĩ arĩa matongoragia mbũtũ cia bũrũri nĩo megwĩka ũguo.” Ningĩ akĩũria atĩrĩ, “Na nũũ ũkaambĩrĩria mbaara?” Nake mũnabii akĩmũcookeria atĩrĩ, “Nĩwe ũkaamĩambĩrĩria.”
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Nĩ ũndũ ũcio Ahabu agĩĩta anene arĩa ethĩ 232 arĩa maatongoragia mbũtũ cia bũrũri. Ningĩ agĩcookanĩrĩria andũ acio angĩ a andũ a Isiraeli othe maarĩ 7,000.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
Nao makiumagara mĩaraho hĩndĩ ĩrĩa Beni-Hadadi na athamaki acio mĩrongo ĩtatũ na eerĩ arĩa maarĩ rũmwe nake, maanyuuaga njoohi marĩ hema-inĩ ciao.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
Anene acio ethĩ maatongoragia mbũtũ cia bũrũri nĩo maathiire mbere. Hĩndĩ ĩyo Beni-Hadadi nĩatũmĩte andũ a gũthigaana, nao makĩmũrehere ũhoro atĩrĩ, “Nĩ kũrĩ na andũ marooka moimĩte Samaria.”
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
Nake akiuga atĩrĩ, “Angĩkorwo mokĩte na thayũ-rĩ, manyiitei marĩ muoyo; angĩkorwo nĩ mbaara ya marehe-rĩ, manyiitei marĩ muoyo.”
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
Anene acio ethĩ atongoria a mbũtũ cia bũrũri makiumagara kuuma itũũra-inĩ marũmĩrĩirwo nĩ mbũtũ ya ita,
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
na o mũndũ akĩũraga thũ yake. Nĩ ũndũ ũcio Asuriata makĩũra maingatithĩtio nĩ andũ a Isiraeli. No Beni-Hadadi mũthamaki wa Suriata akĩũra ahaicĩte mbarathi me na andũ amwe ake arĩa ahaici a mbarathi.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Mũthamaki wa Isiraeli akĩmatindĩka na agĩtooria mbarathi na ngaari cia ita, akĩũraga Asuriata aingĩ mũno.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Thuutha ũcio mũnabii agĩkora mũthamaki wa Isiraeli, akĩmwĩra atĩrĩ, “Wĩhaarĩrie wega, na wone ũrĩa kwagĩrĩire nĩ gwĩkwo, tondũ kĩmera kĩrĩa gĩgũũka mũthamaki wa Suriata nĩagagũtharĩkĩra rĩngĩ.”
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Ihinda-inĩ rĩu anene a mũthamaki wa Suriata makĩmũtaara atĩrĩ, “Ngai cia andũ a Isiraeli nĩ ngai cia irĩma-inĩ. Kĩu nĩkĩo gĩatũmire matũkĩrie hinya. No tũngĩhũũrana nao werũ-inĩ, ti-itherũ nĩtũkamakĩria hinya.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
Ĩka atĩrĩ: Eheria athamaki othe kuuma mbũtũ-inĩ ciao, na ũmakũũranie na anene angĩ.
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
No nginya warahũre ita ta rĩrĩa wateire, mbarathi o harĩ mbarathi, na ngaari ya ita harĩ o ngaari ya ita, nĩgeetha tũhote kũrũa na Isiraeli werũ-inĩ. Ti-itherũ hĩndĩ ĩyo nĩ tũgaakorwo tũrĩ na hinya kũmakĩra.” Mũthamaki agĩĩtĩkania nao na agĩĩka o ũguo.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
Kĩmera kĩrĩa kĩarũmĩrĩire gĩakinya-rĩ, Beni-Hadadi agĩcookanĩrĩria Asuriata, magĩthiĩ Afeki makarũe na andũ a Isiraeli.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
Rĩrĩa andũ a Isiraeli o nao maacookanĩrĩirio na makĩneo indo ciothe, makiumagara magatũngane nao. Andũ a Isiraeli makĩamba hema ciao ingʼethanĩire nao matariĩ ta tũrũũru twĩrĩ twa mbũri. Hĩndĩ ĩyo Asuriata maiyũrĩte bũrũri ũcio wothe.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Mũndũ wa Ngai agĩũka, akĩĩra mũthamaki wa Isiraeli atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: ‘Tondũ Asuriata mareciiria Jehova nĩ ngai wa irĩma-inĩ na ti ngai wa ituamba-inĩ-rĩ, nĩngũneana mbũtũ ĩno nene ũũ moko-inĩ maku, nawe ũmenye atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
Ihinda rĩa mĩthenya mũgwanja maikarire mambĩte hema ciao mangʼethanĩire, na mũthenya wa mũgwanja makĩambĩrĩria mbaara. Andũ a Isiraeli makĩũraga thigari 100,000 cia magũrũ cia Asuriata, mũthenya ũmwe.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
Acio angĩ makĩũrĩra itũũra inene rĩa Afeki, kũrĩa rũthingo rwagwĩrĩire andũ ao 27,000. Nake Beni-Hadadi akĩũrĩra itũũra inene akĩĩhitha kanyũmba ga thĩinĩ.
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
Anene ake makĩmwĩra atĩrĩ, “Ta rora, nĩtũiguĩte atĩ athamaki a nyũmba ya Isiraeli nĩ marĩ tha. Twĩtĩkĩrie tũthiĩ kũrĩ mũthamaki wa Isiraeli twĩhotorete nguo cia makũnia njohero na twĩrigiicĩirie mĩhĩndo mĩtwe iitũ. No gũkorwo nĩagetĩkĩra kũhonokia muoyo waku.”
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Makĩĩhotora nguo cia makũnia njohero, na makĩrigiicĩria mĩhĩndo mĩtwe yao, magĩthiĩ kũrĩ mũthamaki wa Isiraeli, makĩmwĩra atĩrĩ, “Ndungata yaku Beni-Hadadi egũkwĩra atĩrĩ, ‘Ndagũthaitha reke ndũũre muoyo.’” Nake mũthamaki akĩmooria atĩrĩ, “Arĩ o muoyo? Ũcio-rĩ, nĩ mũrũ wa baba.”
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
Andũ acio makĩigua ũguo meerwo taarĩ kĩmenyithia kĩega, makĩgwatĩria kiugo gĩake, makiuga atĩrĩ, “Ĩĩ nĩguo, Beni-Hadadi nĩ mũrũ wa thoguo.” Mũthamaki akiuga atĩrĩ, “Thiĩi mũmũrehe.” Rĩrĩa Beni-Hadadi oimĩrire, Ahabu akĩmũingĩria ngaari-inĩ yake ya ita.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
Beni-Hadadi akĩĩra Mũthamaki Ahabu atĩrĩ, “Nĩngũgũcookeria matũũra marĩa baba aatunyire thoguo, nawe ũthondeke kũndũ kwa wonjoria thĩinĩ wa Dameski, o ta ũrĩa baba eekĩte Samaria.” Nake Ahabu akiuga atĩrĩ, “Kũngĩgĩa na kĩrĩkanĩro kĩa ũiguano witũ nawe, nĩngũrekereria ũthiĩ.” Nĩ ũndũ ũcio magĩthondeka kĩrĩkanĩro kĩa ũiguano, akĩmwĩtĩkĩria athiĩ.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
Na ũndũ wa kiugo kĩa Jehova, mũndũ ũmwe wa ariũ a anabii nĩerire mũndũ wa thiritũ yake atĩrĩ, “Ngũtha na mũtĩ waku wa mbaara,” no mũndũ ũcio akĩrega.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
Nĩ ũndũ ũcio mũnabii akĩmwĩra atĩrĩ, “Tondũ ndũnathĩkĩra Jehova-rĩ, wathiĩ wandiga o ũguo nĩũkũũragwo nĩ mũrũũthi.” Na thuutha wa mũndũ ũcio gũthiĩ-rĩ, agĩkorwo nĩ mũrũũthi, ũkĩmũũraga.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
Ningĩ mũnabii akĩona mũndũ ũngĩ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ndagũthaitha ngũtha,” nake mũndũ ũcio akĩmũgũtha na akĩmũtiihia.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Mũnabii agĩthiĩ, akĩrũgama mũkĩra-inĩ wa njĩra etereire mũthamaki. Ehumbĩrĩte maitho na gĩtambaya kĩa mũtwe nĩguo ndakamenyeke.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
Na rĩrĩa mũthamaki aahĩtũkaga-rĩ, mũnabii ũcio akĩmwĩta, akĩmwĩra atĩrĩ, “Niĩ ndungata yaku ndĩrathiĩte harĩa mbaara ĩneneheire, nake mũndũ ũmwe arooka kũrĩ niĩ arĩ na mũndũ mũtahe, aranjĩĩra atĩrĩ, ‘Rangĩra mũndũ ũyũ, na angĩũra, wee nĩwe ũkooragwo handũ hake, kana ũrĩhe taranda ĩmwe ya betha.’
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
Hĩndĩ ĩrĩa ndungata yaku yagĩire na mĩhangʼo ya haha na harĩa mũndũ ũcio akĩũra.” Mũthamaki wa Isiraeli akiuga atĩrĩ, “Rĩu nĩrĩo ituĩro rĩaku, o ta ũguo wee mwene woiga.”
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
Hĩndĩ ĩyo mũnabii akĩeheria gĩtambaya maitho-inĩ na ihenya, nake mũthamaki wa Isiraeli akĩmũmenya atĩ nĩ ũmwe wa anabii.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
Akĩĩra mũthamaki atĩrĩ, “Jehova ekuuga ũũ: ‘Nĩũrekereirie mũndũ ũrĩa niĩ ndĩratuĩte atĩ no nginya akue. Nĩ ũndũ ũcio wee nĩwe ũgũkua handũ hake, nao andũ aku mooragwo handũ ha andũ ake.’”
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Mũthamaki wa Isiraeli agĩthiĩ Samaria nyũmba-inĩ yake ya ũthamaki athitĩtie gĩthiithi na arĩ mũrakaru.

< 1 Kings 20 >