< 1 Kings 20 >

1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
Forsothe Benadab, kyng of Sirye, gaderide al his oost, and two and thritti kyngis with hym, and horsis, and charis; and he stiede ayens Samarie, and fauyt, and bisegide it.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
And he sente messangeris to Achab, kyng of Israel, in to the citee,
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
and seide, Benadab seith these thingis, Thi siluer and thi gold is myn, and thi wyues, and thi beste sones ben myn.
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
And the kyng of Israel answeride, Bi thi word, my lord the kyng, Y am thin, and alle my thingis `ben thine.
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
And the messangeris turneden ayen, and seiden, Benadab, that sente vs to thee, seith these thingis, Thou schalt yyue to me thi siluer, and thi gold, and thi wyues, and thi sones.
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
Therfor to morewe, in this same our, Y schal sende my seruauntis to thee, and thei schulen seke thin hows, and the hows of thi seruauntis; and thei schulen putte in her hondis, and take awey al thing that schal plese hem.
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
Forsothe the kyng of Israel clepide alle the eldere men of the lond, and seide, Perseyue ye, and se, that he settith tresoun to vs; for he sente to me for my wyues, and sones, and for siluer, and gold, and Y forsook not.
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
And alle the gretter men in birthe, and al the puple seiden to hym, Here thou not, nether assente thou to hym.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
And he answeride to the messangeris of Benadab, Seie ye to my lord the kyng, Y schal do alle thingis, for whiche thou sentist in the bigynnyng to me, thi seruaunt; forsothe Y may not do this thing.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
And the messangeris turneden ayen, and telden alle thingis to hym. Which sente ayen, and seide, Goddis do these thingis to me, and adde these thingis, if the dust of Samarie schal suffice to the fistis of al the puple that sueth me.
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
And the kyng of Israel answeride, and seide, Seie ye to hym, A gird man, `that is, he that goith to batel, haue not glorie euenli as a man vngird.
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
Forsothe it was doon, whanne Benadab hadde herd this word, he drank, and the kyngis, in schadewyng places; and he seide to hise seruauntis, Cumpasse ye the citee.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
And thei cumpassiden it. And lo! o prophete neiyede to Acab, kyng of Israel, and seide to hym, The Lord God seith these thingis, Certis thou hast seyn al this multitude ful greet; lo! Y schal bitake it in to thin hond to dai, that thou wite that Y am the Lord.
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
And Achab seide, Bi whom? And he seide to Achab, The Lord seith these thingis, Bi the squyeris of the princes of prouynces. And Achab seide, Who schal bigynne to fiyte? And the prophete seide, Thou.
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Therfor he noumbryde the children of the princes of prouynces, and he foond the noumbre of twei hundrid and two and thretti; and aftir hem he noumbride the puple, alle the sones of Israel, seuene thousynde.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
And thei yeden out in myddai. Forsothe Benadab drank, and was drunkun in his schadewyng place, and two and thretti kyngis with hym, that camen to the help of hym.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
Sotheli the children of princes of prouynces yeden out in the firste frount. Therfor Benadab sente men, whiche telden to hym, and seide, Men yeden out of Samarie.
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
And he seide, Whether thei comen for pees, take ye hem quyke; whether to fiyte, take ye hem quyke.
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
Therfor the children of prynces of prouynces yeden out,
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
and the residue oost suede; and ech smoot the man that cam ayens hym. And men of Sirie fledden, and Israel pursuede hem; also Benadab, kyng of Sirie, fledde on an hors with his kniytis.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Also the king of Israel yede out, and smoot horsis and charis, and he smoot Sirie with a ful greet veniaunce.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Forsothe a prophete neiyede to the kyng of Israel, and seide, Go thou, and be coumfortid, and wyte, and se, what thou schalt do; for the kyng of Sirie schal stie ayens thee in the yeer suynge.
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Sotheli the seruauntis of the kyng of Sirie seiden to hym, The Goddis of hillis ben the Goddis of the sones of Israel, therfor thei ouercamen vs; but it is betere that we fiyte ayens hem in feeldi placis, and we schulen geet hem.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
Therfor do thou this word; remoue thou alle kyngis fro thin oost, and sette thou princis for hem;
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
and restore thou the noumbre of knyytis, that felden of thine, and horsis bi the formere horsis, and restore thou charis, bi the charis whiche thou haddist bifore; and we schulen fiyte ayens hem in feeldy places, and thou schalt se, that we schulen gete hem. He bileuyde to the counsel of hem, and dide so.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
Therfor after that the yeer hadde passid, Benadab noumbride men of Sirie, and he stiede in to Affech, to fiyte ayens Israel.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
Forsothe the sones of Israel weren noumbrid; and whanne meetis weren takun, thei yeden forth euene ayens, and thei, as twey litle flockis of geet, settiden tentis ayens men of Sirie. Forsothe men of Sirie filliden the erthe.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
And o prophete of God neiyede, and seide to the kyng of Israel, The Lord God seith these thingis, For men of Sirie seiden, God of hillis is the Lord of hem, and he is not God of valeis, Y schal yyue al this greet multitude in thin hond, and ye schulen wite that Y am the Lord.
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
In seuene daies these and thei dressiden scheltruns euene ayens; forsothe in the seuenthe dai the batel was joyned togidere, and the sones of Israel smytiden of men of Syrie an hundrid thousynde of foot men in o dai.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
Forsothe thei that leften fledden in to the citee of Affech, and the wal felde doun on seuene and twenti thousynde of men that leften. Forsothe Benadab fledde, and entride in to the citee, in to a closet that was with ynne a closet;
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
and hise seruauntis seiden to him, We herden that the kyngis of the hows of Israel ben merciful, therfor putte we sackis in oure leendis, and cordis in oure heedis, and go we out to the kyng of Israel; in hap he schal saue oure lyues.
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Thei girdiden her leendis with sackis, and puttiden coordis in her heedis, and thei camen to the kyng of Israel, and seiden to hym, Thi seruaunt Benadab seith, Y preye thee, lete `my soule lyue. And he seide, If Benadab lyueth yit, he is my brother.
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
Which thing the men of Sirie token for a graciouse word, and rauyschiden hastily the word of his mouth, and seiden, Thi brother Benadab lyueth. And Achab seide to hem, Go ye, and brynge ye hym to me. Therfor Benadab yede out to hym, and he reiside Benadab in to his chare.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
`Which Benadab seide to hym, Y schal yelde the citees whiche my fadir took fro thi fadir, and make thou stretis to thee in Damask, as my fadir made in Samarie; and Y schal be boundun to pees, and Y schal departe fro thee. Therfor he made boond of pees, and delyuerede hym.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
Thanne sum man of the sones of prophetis seide to his felowe, in the word of the Lord, Smyte thou me. And he nolde smyte.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
To `whiche felowe he seide, For thou noldist here the vois of the Lord, lo! thou schalt go fro me, and a lioun schal smyte thee. And whanne he hadde go a litil fro hym, a lioun foond hym, and slowy hym.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
But also the prophete foond another man, and he seide to that man, Smyte thou me. Which smoot him, and woundide him.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Therfor the prophete yede, and mette the kyng in the weie; and he chaungide his mouth and iyen, by sprynging of dust.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
And whanne the kyng hadde passid, he criede to the kyng, and seide, Thi seruaunt yede out to fiyte anoon, and whanne o man hadde fledde, sum man brouyte hym to me, and seide, Kepe thou this man; and if he aschapith, thi lijf schal be for his lijf, ether thou schalt paye a talent of siluere.
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
Sotheli while Y was troblid, and turnede me hidur and thidur, sodeynly he apperide not. And the kyng of Israel seide to hym, This is thi doom which thou hast demed.
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
And anoon he wipide awey the dust fro his face, and the kyng of Israel knew him, that he was of the prophetis.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
Which seide to the kyng, The Lord seith these thingis, For thou deliueridist fro thin hond a man worthi the deeth, thi lijf schal be for his lijf, and thi puple `schal be for his puple.
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Therfor the kyng of Israel turnede ayen in to his hows, and dispiside to here, and cam wod in to Samarie.

< 1 Kings 20 >