< 1 Kings 20 >

1 Beni-Hadadi ọba Aramu sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dó ti Samaria, ó sì kọlù ú.
Siria siangpahrang Benhadad ni, a ransanaw pueng a pâkhueng teh, siangpahrang 32 touh ahni koe ao. Marang hoi leng hoi a takhang awh teh, Samaria kho hah a kalup awh teh a tuk awh.
2 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí ìlú sí Ahabu ọba Israẹli wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi wí,
Isarel siangpahrang koe khopui thung patounenaw a patoun teh ahni koe Benhadad ni hettelah ati.
3 ‘Fàdákà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.’”
Na tangka hoi sui hateh kaie doeh. Na yuca hoi hnokahawi pueng kaie doeh telah ati.
4 Ọba Israẹli sì dá a lóhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìwọ ṣe wí olúwa mi ọba, èmi àti ohun gbogbo tí mo ní tìrẹ ni.”
Isarel siangpahrang ni, oe siangpahrang ka bawipa na dei e patetlah doeh. Kai hoi ka tawn e pueng teh nange doeh telah ati.
5 Àwọn oníṣẹ́ náà sì tún padà wá, wọ́n sì wí pé, “Báyìí ni Beni-Hadadi sọ wí pé, ‘Mo ránṣẹ́ láti béèrè fún fàdákà rẹ àti wúrà rẹ, àwọn aya rẹ àti àwọn ọmọ rẹ.
A patounenaw ni bout a cei awh teh, Benhadad ni hettelah ati, na tangka hoi sui hoi na yu hoi na canaw hah na poe han telah taminaw bout a patoun.
6 Ṣùgbọ́n ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò rán àwọn ìránṣẹ́ mi sí ọ láti wá ilé rẹ wò àti ilé àwọn ìránṣẹ́ rẹ. Wọn yóò gba gbogbo ohun tí ó bá dára lójú rẹ, wọn yóò sì kó o lọ.’”
Hatei, tangtho tuektue nah ka taminaw nang koe ka patoun han, na im hoi na tami hoi, nim hah a tawng awh han. Na mit ni a noe e pueng hah a la awh vaiteh, koung a thokhai awh han telah ati.
7 Nígbà náà ni ọba Israẹli pe gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ wo bí ọkùnrin yìí ti ń fẹ́ ìyọnu! Nígbà tí ó ránṣẹ́ fún àwọn aya mi, àti fún àwọn ọmọ mi, àti fún fàdákà mi, àti fún wúrà mi, èmi kò sì fi dù ú.”
Isarel siangpahrang ni a ram dawk e kacuenaw pueng koung a kaw teh, pahren lahoi pâkuem awh. Bangkongtetpawiteh, hete tami ni runae tâcosak hanlah a kâcai. Bangkongtetpawiteh, kai koe tami a patoun teh, ka yu hoi ka ca hoi, ka tangka hoi ka suinaw hah a hei, kangek e hai nahoeh telah ati.
8 Àwọn àgbàgbà àti gbogbo ènìyàn dá a lóhùn pé, “Má ṣe fi etí sí tirẹ̀ tàbí kí ó gbà fún un.”
Kacuenaw hoi tamimaya ni ahni koe ahnimae lawk hai banglahai noutna hanh, na lung hai kuepkhai hanh telah atipouh awh.
9 Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn oníṣẹ́ Beni-Hadadi pé, “Sọ fún olúwa mi ọba pé, ‘Ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe ohun gbogbo tí ó ránṣẹ́ fún látètèkọ́ṣe, ṣùgbọ́n nǹkan yìí ni èmi kò le ṣe.’” Wọ́n padà lọ, wọ́n sì mú èsì padà wá fún Beni-Hadadi.
Hottelah Benhadad ni patounenaw koe siangpahrang ka bawipa koevah, na san koe patounenaw na patoun teh, ahmaloe na hei e pueng heh ka tarawi yawkaw han, hatei hete teh ka tarawi thai mahoeh ati, telah na dei pouh awh han telah ati. Patoun e naw teh a cei awh teh hote lawk hah a dei pouh awh.
10 Beni-Hadadi sì tún rán oníṣẹ́ mìíràn sí Ahabu wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú bí eruku Samaria yóò tó fún ìkúnwọ́ fún gbogbo ènìyàn tí ń tẹ̀lé mi.”
Benhadad ni ahni koe tami bout a patoun teh, ka hnukkâbangnaw pueng ni, Samaria khovah, vaiphu kutvang touh rip hmawt thai awh pawiteh, cathutnaw ni a ngai e patetlah na sak na lawiseh, hothlak ka pataw lahoi na sak naseh telah ati.
11 Ọba Israẹli sì dáhùn wí pé, “Sọ fún un pé, ‘Má jẹ́ kí ẹni tí ń hámọ́ra halẹ̀ bí ẹni tí ń bọ́ ọ sílẹ̀.’”
Isarel siangpahrang ni, ayâ ni ransa puengcang a kâmahrawk navah, a ransa puengcang ka rading e patetlah kâoup boihoeh telah dei pouh awh telah ati.
12 Beni-Hadadi sì gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí òun àti àwọn ọba ń mu ọtí nínú àgọ́ wọn, ó sì pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Ẹ ṣígun sí ìlú náà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ṣe tan láti kọlu ìlú náà.
Hahoi, ama hoi siangpahrangnaw ni, kâhatnae rim dawk yamu a nei awh lahunnah, hote lawk hah Benhadad ni a thai teh, a taminaw koe kârakueng awh haw, atipouh. Hottelahoi, kho tuk hanelah a kâcai awh.
13 Sì kíyèsi i, wòlíì kan tọ Ahabu ọba Israẹli wá, ó sì wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ rí gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun yìí? Èmi yóò fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ lónìí, nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.’”
Hahoi khenhaw! profet buet touh ni Isarel siangpahrang Ahab koe a cei sin teh, BAWIPA ni hettelah a dei. Hete kapap poung e tamihu hah na hmu maw. Khenhaw! sahnin na kut dawk na poe han, hahoi kai teh BAWIPA doeh tie na panue han telah ati.
14 Ahabu sì béèrè pé, “Ṣùgbọ́n ta ni yóò ṣe èyí?” Wòlíì náà sì dáhùn wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Nípa ìpẹ́ẹ̀rẹ̀ àwọn ìjòyè ìgbèríko.’” Nígbà náà ni ó wí pé. “Ta ni yóò bẹ̀rẹ̀ ogun náà?” Wòlíì sì dalóhùn pé, “Ìwọ ni yóò ṣe é.”
Ahab ni api hno lahoi maw telah ati, ahni ni BAWIPA ni telah a dei, khobawi a sannaw hah ka hno han telah ati. Ahni ni apinimaw tarantuknae kho a khang han telah ati. Ahni ni nang ni atipouh.
15 Nígbà náà ni Ahabu ka àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko, wọ́n sì jẹ́ igba ó lé méjìlélọ́gbọ̀n. Nígbà náà ni ó sì kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tókù jọ, gbogbo wọn sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin.
Hottelah ahni ni ram ukkungnaw hoi a sannaw a pâkhueng teh 232 touh a pha.
16 Wọ́n sì jáde lọ ní ọ̀sán gangan, nígbà tí Beni-Hadadi àti àwọn ọba méjìlélọ́gbọ̀n tí ń ràn án lọ́wọ́ ń mu àmupara nínú àgọ́.
Kanî tuengtalueng a thun nah a tâco awh teh, hatnavah, Benhadad hoi siangpahrang a ma kabawm hane siangpahrang 32 touh teh, kâhatnae rim dawk yamu a la parui awh.
17 Àwọn ìjòyè kéékèèké ìgbèríko tètè kọ́ jáde lọ. Beni-Hadadi sì ránṣẹ́ jáde, wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Àwọn ọkùnrin ń ti Samaria jáde wá.”
Hateh, ram ukkung bawi thoundoun hmaloe a tâco. Benhadad ni kâhmo hane a patoun teh, ahni koe Samaria kho hoi tami ka tâcawt e ao telah a dei pouh.
18 Ó sì wí pé, “Bí wọ́n bá bá ti àlàáfíà jáde wá, ẹ mú wọn láààyè; bí ti ogun ni wọ́n bá bá jáde, ẹ mú wọn láààyè.”
Ahni ni roum nahanelah ka tâco e lah awm pawiteh, a hring lahoi man awh. Tarantuk hanelah hoi ka tâcawt hanelah ao haiyah a hring lahoi man awh, telah ati.
19 Àwọn ìjòyè kéékèèké wọ̀nyí ti àwọn ìjòyè ìgbèríko jáde ti ìlú wá, àti ogun tí ó tẹ̀lé wọn.
Hottelah ram ukkung thoundoun hah a hnukkâbang e ransa hoi khopui thung hoi a tâco awh.
20 Olúkúlùkù sì pa ọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Àwọn ará Aramu sì sá, Israẹli sì lépa wọn. Ṣùgbọ́n Beni-Hadadi ọba Aramu sì sálà lórí ẹṣin pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́ṣin.
Hahoi tami pueng ni amae tami lengkaleng a thei awh. Hottelah Sirianaw a yawng awh teh, Isarelnaw ni a pâlei awh. Siria siangpahrang Benhadad teh, marang a kâcui teh marang kâcuinaw hoi a hlout awh.
21 Ọba Israẹli sì jáde lọ, ó sì kọlu àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́, ó pa àwọn ará Aramu ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Isarel siangpahrang a tâco teh, marang hoi leng hoi a tuk awh teh, Sirianaw moi a thei awh.
22 Lẹ́yìn náà, wòlíì náà sì wá sọ́dọ̀ ọba Israẹli, ó sì wí pé, “Lọ, mú ara rẹ gírí, kí o sì mọ̀, kí o sì wo ohun tí ìwọ yóò ṣe, nítorí ní àmọ́dún ọba Aramu yóò tún gòkè tọ̀ ọ́ wá.”
Hahoi, profet ni Isarel siangpahrang koe a hrawi teh, ahni koe tha kâlat nateh, na sak hane kahawicalah pouk. Bangkongtetpawiteh, kompawi toteh Siria siangpahrang ni bout na tuk awh han, telah atipouh.
23 Àwọn ìránṣẹ́ ọba Aramu sì wí fún un pé, “Ọlọ́run wọn, ọlọ́run òkè ni. Ìdí nìyìí tí wọ́n ṣe ní agbára jù wá lọ. Ṣùgbọ́n bí a bá bá wọn jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ dájúdájú.
Siria siangpahrang e sannaw ni ahni koe, ahnimae cathutnaw teh mon cathutnaw lah ao. Hatdawkvah maimouh hlak a tha ao hnawn awh telah ati awh.
24 Nǹkan yìí ni kí o sì ṣe, mú àwọn ọba kúrò, olúkúlùkù kúrò ní ipò rẹ̀, kí o sì fi baálẹ̀ sí ipò wọn.
Hahoi, hettelah na ti han, siangpahrangnaw hah koung tha nateh, amamae hmuen koe ram ukkung lah hrueng.
25 Kí o sì tún kó ogun jọ fún ara rẹ bí èyí tí ó ti sọnù; ẹṣin fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ fún kẹ̀kẹ́; kí a bá lè bá Israẹli jà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀. Nítòótọ́ àwa yóò ní agbára jù wọ́n lọ.” Ó sì gba tiwọn, ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Hahoi ransa hoi leng na raphoe e yit touh ransa bout sak. Hottelah tanghling dawk na tuk awh vaiteh, ahnimouh hlak thao awh mingming han doeh telah ati awh. A lawk hah a caksak awh teh, hottelah a sak awh.
26 Ó sì ṣe ní àmọ́dún, Beni-Hadadi ka iye àwọn ará Aramu, ó sì gòkè lọ sí Afeki, láti bá Israẹli jagun.
Hahoi, kompawi toteh, hettelah ao. Benhadad ni Sirianaw hah a pâkhueng teh. Isarel tuk hanelah Aphek vah a takhang awh.
27 Nígbà tí a sì ka àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì pèsè oúnjẹ, wọ́n sì lọ pàdé wọn. Àwọn ọmọ Israẹli sì dó ní òdìkejì wọn gẹ́gẹ́ bí agbo ọmọ ewúrẹ́ kékeré méjì, nígbà tí àwọn ará Aramu kún ilẹ̀ náà.
Isarel catounnaw teh a kamkhueng awh teh, rawca a rakueng pouh awh teh, tarantuk hanelah a tâco awh. Isarelnaw hmaehu yitca e hu hni touh e patetlah a kangdue sin awh. Sirianaw teh a ram dawk king a kawi awh.
28 Ènìyàn Ọlọ́run kan sì gòkè wá, ó sì sọ fún ọba Israẹli pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Nítorí tí àwọn ará Aramu rò pé Olúwa, Ọlọ́run òkè ni, ṣùgbọ́n òun kì í ṣe Ọlọ́run àfonífojì, nítorí náà èmi ó fi gbogbo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn yìí lé ọ lọ́wọ́, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Hahoi Cathut e tami ni Isarel siangpahrang koe a hnai teh, ahni koe, BAWIPA ni hettelah a dei, Sirianaw ni Jehovah teh mon cathut lah ao teh, tanghling cathut lah awm hoeh ati awh. Hatdawkvah, hete tami moikapap e naw heh na kut dawk na poe han, hottelah hoi kai heh BAWIPA lah ka o tie hah na panue awh han telah ati.
29 Wọ́n sì dó sí òdìkejì ara wọn fún ọjọ́ méje, àti ní ọjọ́ keje, wọ́n pàdé ogun. Àwọn ọmọ Israẹli sì pa ọ̀kẹ́ márùn-ún ẹlẹ́ṣẹ̀ nínú àwọn ará Aramu ní ọjọ́ kan.
Hnin sari touh thung avoivang lah a tungpup awh. Ahni sari hnin vah a kâtuk awh. Isarelnaw ni Sirianaw hah hnin touh dawk ransa 100, 000 a thei awh.
30 Àwọn tókù sì sá àsálà lọ sí Afeki, sínú ìlú tí odi ti wó lù ẹgbàá mẹ́tàlá lé ẹgbẹ̀rún nínú wọn. Beni-Hadadi sì sálọ sínú ìlú, ó sì fi ara pamọ́ sínú ìyẹ̀wù.
Alouknaw teh Aphek kho thung vah a yawng awh. Kacawie tami 27, 000 touh teh rapan katim e ni koung a ten. Benhadad teh a yawng teh, khopui dawk imrakhan thung a kâen.
31 Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, a ti gbọ́ pé àwọn ọba ilẹ̀ Israẹli jẹ́ ọba aláàánú, mo bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí àwa kí ó tọ̀ ọ́ lọ pẹ̀lú aṣọ ọ̀fọ̀ ní ẹ̀gbẹ́ wa, àti okùn yí orí wa ká. Bóyá òun yóò gba ẹ̀mí rẹ là.”
A taminaw ni ahni koe khenhaw! Isarelnaw e imthungnaw thung dawk, Siangpahrang heh pahrennae ka tawn e siangpahrangnaw doeh telah ka panue awh. Burihni kâkhu hoi kaimae lû dawk rui hoi pâkhit nateh, Isarel siangpahrang koe na cetkhai yawkaw. Ama ni na pâhlung yawkaw han doeh telah ati awh.
32 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di aṣọ ọ̀fọ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ wọn, wọ́n sì fi okùn yí orí wọn ká, wọ́n sì tọ ọba Israẹli wá, wọ́n sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ Beni-Hadadi wí pé, ‘Èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí èmi kí ó yè.’” Ọba sì dáhùn wí pé, “Ó ń bẹ láààyè bí? Arákùnrin mi ni òun.”
Hottelah buri hni a kâkhu awh teh, a lû dawk rui hoi a pâkhi awh teh, Isarel siangpahrang koe a cei awh. Na san Benhadad ni pahren lahoi na pâhlung na seh ati telah ati awh. Ahni ni a hring rah maw, ahni teh ka hmaunawngha nahoehmaw, telah ati.
33 Àwọn ọkùnrin náà sì ṣe àkíyèsí gidigidi, wọ́n sì yára gbá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú, wọ́n sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, Beni-Hadadi arákùnrin rẹ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ lọ mú u wá.” Nígbà tí Beni-Hadadi jáde tọ̀ ọ́ wá, Ahabu sì mú u gòkè wá sínú kẹ̀kẹ́.
Hotnaw ni pouknae kahawi hoi a lungthung hoi a dei katang e han doeh ati awh teh, na hmaunawngha Benhadad doeh atipouh awh. Ahni ni cet awh nateh, ahni hah thokhai awh atipouh. Hottelah Benhadad teh a tâco teh, ahni koe a cei teh ahni ni leng dawk a kâcui sak.
34 Beni-Hadadi sì wí pé, “Èmi yóò dá àwọn ìlú tí baba mi ti gbà lọ́wọ́ baba rẹ padà, ìwọ sì le la ọ̀nà fún ara rẹ ní Damasku, bí baba mi ti ṣe ní Samaria.” Ahabu sì wí pé, “Èmi yóò rán ọ lọ pẹ̀lú májẹ̀mú yìí.” Bẹ́ẹ̀ ni ó ba dá májẹ̀mú, ó sì rán an lọ.
Benhadad ni ahni koe, apa ni na pa koe kho a la e hah bout na poe han. Hahoi, apa ni Samaria kho hno yonae hmuen a sak e patetlah Damaskas kho vah hno yonae hmuen na sak van han telah ati. Hottelah ahni koe lawkkamnae a sak sak teh a cei sak.
35 Nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, ọkùnrin kan nínú àwọn ọmọ àwọn wòlíì sì wí fún èkejì rẹ̀ pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí,” ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti lù ú.
Hahoi Profet capanaw thung hoi tami buet touh ni, BAWIPA e lawk patetlah a hui koe vah, kai na hem haw telah atipouh. Hote tami ni na hem ngai hoeh atipouh.
36 Nígbà náà ni ó wí pé, “Nítorí tí ìwọ kò gba ohùn Olúwa gbọ́, kíyèsi i, bí ìwọ bá kúrò ní ọ̀dọ̀ mi, kìnnìún yóò pa ọ́.” Bí ó ti jáde lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, kìnnìún kan rí i, ó sì pa á.
Hat toteh, ahni koevah, BAWIPA e lawk na tarawi ngaihoeh dawkvah, khenhaw! nang ni na ceitakhai tahma vah, Sendek ni na kei han atipouh e patetlah a cei teh Sendek ni a hmue teh a kei.
37 Wòlíì náà sì rí ọkùnrin mìíràn, ó sì wí fún un pé, “Jọ̀ ọ́, lù mí.” Bẹ́ẹ̀ ni ọkùnrin náà sì lù ú, ó sì pa á lára.
Hahoi alouke tami bout a hmu teh, kai na hem haw atipouh teh ahni ni a hem.
38 Wòlíì náà sì lọ, ó sì dúró de ọba ní ojú ọ̀nà. Ó pa ara rẹ̀ dà ní fífi eérú bo ojú.
Hahoi profet teh a cei teh, lam vah siangpahrang a pawp, a tampa dawk a yeng e hoi mit a huem teh, a phunloukcalah a kâsak.
39 Bí ọba sì ti ń rékọjá, wòlíì náà ké sí i, ó sì wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ jáde wọ àárín ogun lọ, ẹnìkan sì wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ìgbèkùn kan, ó sì wí pé, ‘Pa ọkùnrin yìí mọ́. Bí a bá fẹ́ ẹ kù, ẹ̀mí rẹ yóò lọ dípò ẹ̀mí rẹ̀, tàbí kí ìwọ san tálẹ́ǹtì fàdákà kan.’
Siangpahrang a tho toteh siangpahrang a kaw teh, na sanpa heh tarankâtuknae hmuen lungui vah ka cei teh, khenhaw! tami buet touh ni kai koe tami buet touh a thokhai. Hete tami heh kahawicalah ring, yawng payon pawiteh, a hringnae yueng lah na hringnae ka hma han, hoehpawiteh, tangka talen buet touh na poe han telah ati.
40 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ìṣe níhìn-ín àti lọ́hùn ún, a fẹ́ ẹ kù.” Ọba Israẹli sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ ni ìdájọ́ rẹ yóò rí, ìwọ fúnra rẹ̀ ti dá a.”
Na sanpa heh puenghoi ka rucat dawkvah, ka yawng takhai telah ati. Isarel siangpahrang ni nang nama ni lawk na tâtueng e patetlah na lathueng vah lawkcengnae ka phat e doeh telah atipouh.
41 Nígbà náà ni wòlíì náà yára, ó sì mú eérú kúrò ní ojú rẹ̀, ọba Israẹli sì mọ̀ ọ́n pé ọ̀kan nínú àwọn wòlíì ni ó ń ṣe.
Ahni ni minhmai huemnae hah a rading teh, Isarel siangpahrang ni profet buet touh doeh tie hah a panue.
42 Ó sì wí fún ọba pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti jọ̀wọ́ ọkùnrin tí èmi ti yàn sí ìparun pátápátá lọ́wọ́ lọ. Nítorí náà, ẹ̀mí rẹ yóò lọ fún ẹ̀mí rẹ, ènìyàn rẹ fún ènìyàn rẹ̀.’”
Profet ni ahni koevah, BAWIPA ni hettelah a dei, thoe ka bo e tami na hlout sak dawkvah, ahnie hringnae yueng lah nange hringnae, ahnie taminaw yueng lah nange taminaw na sung sak han telah ati.
43 Ọba Israẹli sì lọ sí ilé rẹ̀ ní wíwú gbọ́, inú rẹ sì bàjẹ́, ó sì wá sí Samaria.
Hahoi Isarel siangpahrang teh minhmai mathoe lungmathoe laihoi a ban teh Samaria kho a pha.

< 1 Kings 20 >