< 1 Kings 2 >
1 Nígbà tí ọjọ́ ikú Dafidi súnmọ́ etílé, ó pàṣẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀.
І набли́зилися Давидові дні до смерти, і він наказав своєму синові Соломонові, говорячи:
2 Ó sì wí pé, “Èmi ti fẹ́ lọ sí ọ̀nà gbogbo ayé, nítorí náà jẹ́ alágbára kí o sì fi ara rẹ hàn bí ọkùnrin,
„ Ось я йду дорогою всієї землі, а ти будеш міцни́й та станеш мужем.
3 kí o sì wòye ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè, rìn ní ọ̀nà rẹ̀, kí o sì pa àṣẹ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti ìdájọ́ rẹ, àti ẹ̀rí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin Mose, nítorí kí ìwọ kí ó le è máa ṣe rere ní ohun gbogbo tí ìwọ ṣe, àti ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ,
І будеш ти стерегти́ нака́зи Господа, Бога свого, щоб ходити Його дорогами, щоб стерегти́ постанови Його, заповіді Його, та устави Його й сві́дчення Його, як писано в Мойсеєвім Зако́ні, щоб тобі щастило в усьому, що будеш робити, і скрізь, куди зве́рнешся,
4 kí Olúwa kí ó lè pa ìlérí rẹ̀ tí ó sọ nípa tèmi mọ́ pé, ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá kíyèsi ọ̀nà wọn, tí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà wọn àti ọkàn wọn rìn níwájú mi ní òtítọ́, o kì yóò sì kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
щоб ви́повнив Господь слово Своє, яке говорив мені, кажучи: Якщо сини твої будуть стерегти дороги свої, щоб ходити перед лицем Моїм у правді всім своїм серцем та всією душею своєю, то, сказав: Не буде переводу ніко́му від тебе на троні Ізраїлевім!
5 “Ìwọ pẹ̀lú sì mọ ohun tí Joabu ọmọ Seruiah ṣe sí mi àti ohun tí ó ṣe sí balógun méjì nínú àwọn ológun Israẹli, sí Abneri ọmọ Neri àti sí Amasa ọmọ Jeteri. Ó sì pa wọ́n, ó sì ta ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ ní ìgbà àlàáfíà bí í ti ojú ogun ó sì fi ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àmùrè rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àti sí ara sálúbàtà rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
А також ти знаєш, що́ зробив мені Йоа́в, син Церуїн, що́ зробив він двом провідника́м Ізраїлевих військ, — Авнерові, Неровому синові, та Амасі, синові Єтеровому. Він повбивав їх, і пролив воєнну кров у час миру, і попля́мив воєнною кров'ю свого пояса, що на сте́гнах його, та санда́лі свої, що на нога́х його.
6 Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú ní àlàáfíà. (Sheol )
І ти зро́биш за своєю мудрістю, і не даси зни́зитися сивині́ його мирно до шео́лу. (Sheol )
7 “Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Barsillai, ti Gileadi, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Absalomu arákùnrin rẹ.
А синам ґілеадянина Барзіллая зробиш ласку, і нехай вони будуть серед тих, що їдять за твоїм столом, бо вони отак прийшли до ме́не, коли я втікав перед Авесаломом, твоїм братом.
8 “Àti kí o rántí, Ṣimei ọmọ Gera ẹ̀yà Benjamini tí Bahurimu wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Mahanaimu. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jordani, mo fi Olúwa búra fún un pé, ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’
А ось з тобою Шім'ї, Ґерин син, веніяминівець із Бахуріму. А він прокля́в був мене гострим прокля́ттям того дня, коли я йшов до Маханаїму. Та він прийшов до Йорда́ну стрі́нути мене, і я присягнув йому Господом, говорячи: Не заб'ю тебе мечем!
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, má ṣe kíyèsi í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.” (Sheol )
А тепер не прощай йому́, бо ти муж мудрий, і знатимеш, що́ зробити йому, — і ти сивину́ його зведе́ш у крові до шео́лу“. (Sheol )
10 Nígbà náà ni Dafidi sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi.
І спочив Давид з батьками своїми, і був похо́ваний у Давидовім Місті.
11 Dafidi ti jẹ ọba lórí Israẹli ní ogójì ọdún, ọdún méje ni Hebroni àti ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
А дні, що Давид царював над Ізраїлем, сорок літ: у Хевроні царював він сім літ, а в Єрусалимі царював тридцять і три роки.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
І сів Соломон на троні Давида, батька свого, і його царюва́ння було дуже міцне́.
13 Wàyí, Adonijah ọmọ Haggiti tọ Batṣeba, ìyá Solomoni wá. Batṣeba sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
І прийшов Адо́нія, син Гаґґітин, до Вірсавії, Соломонової матері, а вона сказала: „Чи при́хід твій — з миром?“І він відказав: „З миром“.
14 Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.” Batṣeba sì wí pé, “Máa wí.”
І сказав: „Справа в мене до те́бе“. А вона відказала: „Говори!“
15 Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Israẹli ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.
І він сказав: „Ти знаєш, що моє було це царство, і на мене звернув увесь Ізраїль своє обличчя, щоб мені царювати. Та відійшло царство, і доста́лось моєму братові, бо від Господа це сталось йому.
16 Nísinsin yìí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ó wí pé, “O lè wí.”
А тепер одне бажа́ння жадаю я від тебе: Не відмовляй мені!“А вона сказала йому: „Говори!“
17 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀síwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Solomoni ọba (òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Abiṣagi ará Ṣunemu ní aya.”
І він сказав: „Скажи цареві Соломонові, — бо він не відмовить тобі, — щоб він дав мені шунаммітку Авішаґ за жінку“.
18 Batṣeba sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”
І сказала Вірсавія: „Добре, — я скажу́ про тебе царе́ві“.
19 Nígbà tí Batṣeba sì tọ Solomoni ọba lọ láti bá a sọ̀rọ̀ nítorí Adonijah, ọba sì dìde láti pàdé rẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. Ó sì tẹ́ ìtẹ́ kan fún ìyá ọba, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀.
І прийшла Вірсавія до царя Соломона, щоб сказати йому про Адонія. А цар устав назустріч їй, і вклонився їй, та й сів на своєму троні. І поставив він трона й для царевої матері, і вона сіла по прави́ці його.
20 Ó sì wí pé, “Mo ní ìbéèrè kékeré kan láti béèrè lọ́wọ́ rẹ, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ọba sì dáhùn wí pé, “Béèrè, ìyá mi; èmi kì yóò kọ̀ ọ́.”
І сказала вона: „Одне мале жада́ння бажаю я від тебе, — не відмов мені“. І сказав їй цар: „Жадай, мати моя, бо я не відмо́влю тобі“.
21 Nígbà náà ni ó wí pé, “Jẹ́ kí a fi Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah arákùnrin rẹ ní aya.”
І сказала вона: „Нехай шунаммітка Авішаґ буде да́на братові твоєму Адонії за жінку“.
22 Solomoni ọba sì dá ìyá rẹ̀ lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi béèrè Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah! Ìwọ ìbá sì béèrè ìjọba fún un pẹ̀lú nítorí ẹ̀gbọ́n mi ní í ṣe, fún òun pàápàá àti fún Abiatari àlùfáà àti fun Joabu ọmọ Seruiah!”
І відповів цар Соломон та й сказав своїй матері: „І на́що ти про́сиш шунаммітку Авішаґ для Адонії? Та попроси для нього й царства, бо він брат мій, ста́рший від мене, і для нього, і для священика Евіятара, і для Йоава, Церуїного сина“!
23 Nígbà náà ni Solomoni ọba fi Olúwa búra pé, “Kí Ọlọ́run ki ó jẹ mí ní yà, àti jù bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, bí Adonijah kò bá ní fi ẹ̀mí rẹ̀ san ìbéèrè yìí!
І присягнув цар Соломон Господом, говорячи: „Так нехай зробить мені Бог, і так нехай додасть, коли не на душу свою говорив Адонія це слово...
24 Àti nísinsin yìí, bí ó ti dájú pé Olúwa wà láààyè, ẹni tí ó ti mú mi jókòó lórí ìtẹ́ baba mi Dafidi, àti tí ó sì ti kọ́ ilé fún mi bí ó ti ṣèlérí, lónìí ni a ó pa Adonijah!”
А тепер, — як живий Господь, що міцно поставив мене й посадовив мене на троні мого батька Давида, і що зробив мені дім, як говорив був, — сьогодні буде вбитий Адо́нія!“
25 Solomoni ọba sì pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì kọlu Adonijah, ó sì kú.
І послав цар Соломон через Бенаю, Єгоядиного сина, — і він ура́зив його, і той помер...
26 Ọba sì wí fún Abiatari àlùfáà pé, “Padà lọ sí pápá rẹ ni Anatoti, ó yẹ fún ọ láti kú, ṣùgbọ́n èmi kì yóò pa ọ́ nísinsin yìí, nítorí o ti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa Olódùmarè níwájú Dafidi baba mi, o sì ti ní ìpín nínú gbogbo ìyà tí baba mi jẹ.”
А священикові Евіятарові цар сказав: „Іди до Анатоту на поля́ свої, бо ти чоловік смерти, а цього дня не вб'ю тебе, бо носив ти ковчега Владики Господа перед обличчям батька мого Давида, і що терпів ти в усьому, в чому терпів мій батько“.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni yọ Abiatari kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà Olúwa, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípa ilé Eli ní Ṣilo ṣẹ.
І вигнав Соломон Евіятара, щоб не був священиком для Господа, щоб ви́повнилося слово Господнє, яке говорив у Шіло́ на дім Іліїв.
28 Nígbà tí ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Joabu, ẹni tí ó ti dìtẹ̀ pẹ̀lú Adonijah bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò wà pẹ̀lú Absalomu, ó sì sálọ sínú àgọ́ Olúwa, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
А звістка про це прийшла аж до Йоава, бо Йоав схилявся до Адонії, а до Авесалома не схилявся. І втік Йоав до Господньої скинії, і схопи́вся за роги же́ртівника...
29 A sì sọ fún Solomoni ọba pé Joabu ti sálọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Solomoni pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”
І доне́сено цареві Соломонові, що Йоав утік до скинії Господньої, і ось він при жертівнику. І послав Соломон Бенаю, Єгоядиного сина, говорячи: „Іди, — урази́ його!“
30 Benaiah sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Joabu pé, “Ọba sọ wí pé, ‘Jáde wá.’” Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò kú níhìn-ín.” Benaiah sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Joabu ṣe dá mi lóhùn.”
І ввійшов Беная до Господньої скинії, та й сказав до нього: „Так сказав цар: Вийди!“А той відказав: „Ні, я тут помру!“І передав Беная цареві це слово, говорячи: „Так сказав Йоав, і так відповів мені“.
31 Ọba sì pàṣẹ fún Benaiah pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọlù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé baba mi, tí Joabu ti ta sílẹ̀.
І сказав йому цар: „Зроби, як я говорив, і врази́ його. І поховаєш його, і зді́ймеш невинну кров, що Йоав пролив був, з мене та з дому мого батька.
32 Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dafidi baba mi kò sì mọ̀. Àwọn méjèèjì ni Abneri ọmọ Neri olórí ogun Israẹli, àti Amasa ọmọ Jeteri olórí ogun Juda, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnra rẹ̀ lọ.
І нехай оберне Господь його кров на його голову, що він ура́зив був двох мужів справедливих та ліпших від нього, і повбивав їх мече́м, а батько мій Давид того не знав: Авнера, Нериного сина, провідника́ Ізраїлевого війська, та Амасу, сина Єтеревого, провідника́ Юдиного війська.
33 Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Joabu àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dafidi àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”
І нехай зве́рнеться їхня кров на голову Йоава та на голову насіння його навіки. А Давидові й насінню його та дому його й трону його нехай буде мир від Господа аж навіки“.
34 Bẹ́ẹ̀ ni Benaiah ọmọ Jehoiada sì gòkè lọ, ó sì kọlu Joabu, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní aginjù.
І пішов Беная, Єгоядин син, і вра́зив його, та й убив його. І був він похо́ваний у своїм домі в пустині.
35 Ọba sì fi Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ olórí ogun ní ipò Joabu àti Sadoku àlùfáà ní ipò Abiatari.
А цар, замість нього, настанови́в над ві́йськом Бенаю, Єгоядиного сина, а священика Садока цар настановив замість Евіятара.
36 Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣimei, ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jerusalẹmu, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.
І послав цар, і покликав Шім'ї та й сказав йому: „Збудуй собі дім в Єрусалимі, й осядеш там, і не ви́йдеш звідти ані сюди, ані туди.
37 Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá àfonífojì Kidironi, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”
І буде того дня, як ти ви́йдеш і пере́йдеш поток Кедро́н, то щоб ти добре знав, що конче помреш. Кров твоя буде на голові твоїй!“
38 Ṣimei sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí olúwa mi ọba ti wí.” Ṣimei sì gbé ní Jerusalẹmu fún ìgbà pípẹ́.
І сказав Шім'ї до царя: „Добра це річ. Як наказав пан мій цар, так зробить раб твій'.“І сидів Шім'ї в Єрусалимі багато днів.
39 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Ṣimei méjì sì sálọ sọ́dọ̀ Akiṣi ọmọ Maaka, ọba Gati, a sì sọ fún Ṣimei pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gati.”
І сталося в кінці трьох років, і втекли́ двоє рабів Шім'ї до Ахіша, Маахіного сина, ґатського царя. І доне́сли Шім'ї, говорячи: „Ось раби́ твої в Ґаті!“
40 Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi ní Gati láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣimei sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gati.
І встав Шім'ї, й осідлав осла свого та й подався до Ахіша, щоб пошукати своїх рабів. І пішов Шім'ї, і привів своїх рабів з Ґату.
41 Nígbà tí a sì sọ fún Solomoni pé Ṣimei ti lọ láti Jerusalẹmu sí Gati, ó sì ti padà.
А Соломонові доне́сено, що Шім'ї пішов з Єрусалиму в Ґат і вернувся.
42 Ọba pe Ṣimei lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú.’ Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’
І послав цар, і покликав Шім'ї та й сказав до нього: „Чи ж я не заприсяг тебе Господом, і не взяв свідка проти тебе, говорячи: Того дня, коли ти ви́йдеш і пі́деш туди чи сюди, щоб ти добре знав, що конче помреш? І ти сказав мені: Добра це річ, що я чув.
43 Èéṣe, nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”
І чому́ ти не додержувався Господньої прися́ги та нака́за, що я наказав був тобі?“
44 Ọba sì tún wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dafidi baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.
І сказав цар до Шім'ї: „Ти знаєш усе те зло, і знало твоє серце, що зробив ти Давидові, батькові моєму. І поверне Господь твоє зло на твою голову.
45 Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Solomoni ọba, ìtẹ́ Dafidi yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”
А цар Соломон — благословенний, а Давидів трон буде стояти міцно перед Господнім лицем аж навіки“.
46 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣimei, ó sì pa á. Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Solomoni.
І цар наказав Бенаї, Єгоядиному синові, і той вийшов і вра́зив його, — і він номер. І царство зміцніло в Соломоновій руці.