< 1 Kings 2 >

1 Nígbà tí ọjọ́ ikú Dafidi súnmọ́ etílé, ó pàṣẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀.
David kah khohnin loh a duek ham a paan coeng dogah a capa Solomon te a uen tih,
2 Ó sì wí pé, “Èmi ti fẹ́ lọ sí ọ̀nà gbogbo ayé, nítorí náà jẹ́ alágbára kí o sì fi ara rẹ hàn bí ọkùnrin,
“Kai tah diklai boeih kah longpuei ah ka caeh dongah huel uh lamtah hlang la om laeh.
3 kí o sì wòye ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè, rìn ní ọ̀nà rẹ̀, kí o sì pa àṣẹ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti ìdájọ́ rẹ, àti ẹ̀rí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin Mose, nítorí kí ìwọ kí ó le è máa ṣe rere ní ohun gbogbo tí ìwọ ṣe, àti ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ,
Moses kah olkhueng dongah a daek bangla na Pathen BOEIPA kah a kuek te tah, a longpuei ah pongpa ham khaw, a khosing, a olpaek neh a laitloeknah khaw, a olphong khaw ngaithuen ham tuem. Te daengah ni na saii boeih neh na hoihaeng boeih te na cangbam thai eh.”
4 kí Olúwa kí ó lè pa ìlérí rẹ̀ tí ó sọ nípa tèmi mọ́ pé, ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá kíyèsi ọ̀nà wọn, tí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà wọn àti ọkàn wọn rìn níwájú mi ní òtítọ́, o kì yóò sì kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
Te daengah ni BOEIPA loh a ol te a thoh eh. Te te kai taengah a thui coeng tih, “Kamah mikhmuh kah a longpuei ah, oltak la a thinko boeih neh, a hinglu boeih neh pongpa ham khaw na ca rhoek loh a ngaithuen mak atah, na hlang he Israel ngolkhoel dong lamloh khoe boeh,” ti saeh.
5 “Ìwọ pẹ̀lú sì mọ ohun tí Joabu ọmọ Seruiah ṣe sí mi àti ohun tí ó ṣe sí balógun méjì nínú àwọn ológun Israẹli, sí Abneri ọmọ Neri àti sí Amasa ọmọ Jeteri. Ó sì pa wọ́n, ó sì ta ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ ní ìgbà àlàáfíà bí í ti ojú ogun ó sì fi ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àmùrè rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àti sí ara sálúbàtà rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
“Te phoeiah Zeruiah capa Joab loh kai soah a saii te khaw, Israel caempuei kah mangpa rhoi, Ner capa Abner taeng neh Jether capa Amasa taengah a saii te khaw na ming bal coeng. Amih rhoi te a ngawn tih rhoepnah khuiah caemtloek thii a cawk pah. Caemtloek thii te a cinghen kah a cihin neh a kho kah a khokhom dongah a hluk.
6 Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú ní àlàáfíà. (Sheol h7585)
Te dongah na cueihnah bangla saii lamtah a sampok te Saelkhui ah ngaimong la suntlak sak boeh. (Sheol h7585)
7 “Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Barsillai, ti Gileadi, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Absalomu arákùnrin rẹ.
Giladi kah Barzillai koca rhoek taengah tah sitlohnah tueng sak lamtah na maya Absalom mikhmuh lamkah ka yong vaengah kai taengah a tawn uh van dongah na caboei dongkah aka ca taengah om uh saeh.
8 “Àti kí o rántí, Ṣimei ọmọ Gera ẹ̀yà Benjamini tí Bahurimu wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Mahanaimu. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jordani, mo fi Olúwa búra fún un pé, ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’
Na taengkah Bahurim Benjamin koca Gera capa Shimei te ne. Anih loh kai thae m'phoei thil he rhunkhuennah neh n'daeh. Mahanaim la ka caeh nah hnin vaengah kai doe ham amah te Jordan la ha suntla. Tedae anih taengah BOEIPA rhangneh ka toemngam tih, “Nang te cunghang neh kan duek sak mahpawh,” ka ti nah.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, má ṣe kíyèsi í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.” (Sheol h7585)
Tedae, “Nang hlang cueih loh anih taengah hmil boeh. Anih taengah metla saii ham khaw na ming bitni. A sampok te saelkhui ah a thii neh suntlak sak,” a ti nah. (Sheol h7585)
10 Nígbà náà ni Dafidi sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi.
Te phoeiah David te a napa taengah khoem uh tih David khopuei ah a up.
11 Dafidi ti jẹ ọba lórí Israẹli ní ogójì ọdún, ọdún méje ni Hebroni àti ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
Israel sokah David a manghai tue he kum sawmli lo. Hebron ah kum rhih manghai tih Jerusalem ah kum sawmthum kum thum manghai.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
Solomon he a napa David kah ngolkhoel dongah a ngol tangloeng daengah a ram khaw rhap cikngae.
13 Wàyí, Adonijah ọmọ Haggiti tọ Batṣeba, ìyá Solomoni wá. Batṣeba sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
Te vaengah Haggith capa Adonijah te Solomon manu Bathsheba taengah ha pawk tih, “Sading la na pawk ngawn nama?” a ti nah hatah, “Sading la ue,” a ti nah.
14 Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.” Batṣeba sì wí pé, “Máa wí.”
Te phoeiah, “Nang ham ol pakhat ka khueh,” a ti nah hatah, “Thui saw,” a ti nah.
15 Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Israẹli ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.
Te dongah, “Kai hamla ram he om coeng tih ka manghai ham khaw Israel pum loh kai taengla a maelhmai a hooi te na ming. Tedae BOEIPA lamloh anih taengla a pha sak dongah ram he hoilae uh tih ka mana taengla pawk.
16 Nísinsin yìí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ó wí pé, “O lè wí.”
Tedae nang taeng lamkah te huithuinah pakhat ni kam bih coeng. Ka maelhmai he mangthung tak boeh,” a ti nah vaengah amah te, “Thui lah, thui lah,” a ti nah.
17 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀síwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Solomoni ọba (òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Abiṣagi ará Ṣunemu ní aya.”
Te dongah, “Manghai Solomon te thui pah mai, nang maelhmai te mangthung tak aih mahpawh. Shunam nu Abishag te kai taengah yuu la m'pae mai saeh,” a ti nah.
18 Batṣeba sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”
Bathsheba loh, “Then coeng, nang ham te manghai taengah ka thui bitni,” a ti nah.
19 Nígbà tí Batṣeba sì tọ Solomoni ọba lọ láti bá a sọ̀rọ̀ nítorí Adonijah, ọba sì dìde láti pàdé rẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. Ó sì tẹ́ ìtẹ́ kan fún ìyá ọba, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Te dongah Adonijah yueng te a taengah thui pah ham Bathsheba te manghai Solomon taengla kun. Manghai khaw anih doe ham thoo tih a taengah a bakop pah. A ngolkhoel dongah a ngol neh manghai manu ham ngolkhoel a phaih pah tih a bantang ah a ngol pah.
20 Ó sì wí pé, “Mo ní ìbéèrè kékeré kan láti béèrè lọ́wọ́ rẹ, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ọba sì dáhùn wí pé, “Béèrè, ìyá mi; èmi kì yóò kọ̀ ọ́.”
Te phoeiah, “Nang taeng lamkah huithuinah te pakhat ca he kam bih ka maelhmai he mangthung tak boeh,” a ti nah. Manghai loh anih te, “A nu bih saw, na maelhmai te ka mangthung tak mahpawh,” a ti nah.
21 Nígbà náà ni ó wí pé, “Jẹ́ kí a fi Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah arákùnrin rẹ ní aya.”
Te dongah, “Shunam nu Abishag te na maya Adonijah kah yuu la pae mai,” a ti nah.
22 Solomoni ọba sì dá ìyá rẹ̀ lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi béèrè Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah! Ìwọ ìbá sì béèrè ìjọba fún un pẹ̀lú nítorí ẹ̀gbọ́n mi ní í ṣe, fún òun pàápàá àti fún Abiatari àlùfáà àti fun Joabu ọmọ Seruiah!”
Te dongah manghai Solomon loh a manu te a doo tih, “Balae tih Adonijah ham Shunam nu Abishag te na bih. Ka manuca te kai lakah a ham dongah ram he khaw anih ham bih bal saw. Anih ham phoeiah khosoih Abiathar ham neh Zeruiah capa Joab ham khawm ta,” a ti nah.
23 Nígbà náà ni Solomoni ọba fi Olúwa búra pé, “Kí Ọlọ́run ki ó jẹ mí ní yà, àti jù bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, bí Adonijah kò bá ní fi ẹ̀mí rẹ̀ san ìbéèrè yìí!
Te phoeiah manghai Solomon loh BOEIPA dongah a toemngam tih, “Pathen loh kai taengah saii van saeh lamtah he ol he a hinglu neh a thui pawt atah Adonijah khaw koei van saeh.
24 Àti nísinsin yìí, bí ó ti dájú pé Olúwa wà láààyè, ẹni tí ó ti mú mi jókòó lórí ìtẹ́ baba mi Dafidi, àti tí ó sì ti kọ́ ilé fún mi bí ó ti ṣèlérí, lónìí ni a ó pa Adonijah!”
BOEIPA kah hingnah loh kai n'thoh tih kai he n'ngol sak coeng. A pa David kah ngolkhoel dongah kai n'ngol sak tih a thui bangla ka im a thoh coeng. Adonijah te tihnin ah duek kuekluek saeh,” a ti nah.
25 Solomoni ọba sì pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì kọlu Adonijah, ó sì kú.
Te phoeiah manghai Solomon loh Jehoiada capa Benaiah kut te a tueih tih anih sola a cuuk thil dongah Adonijah te duek.
26 Ọba sì wí fún Abiatari àlùfáà pé, “Padà lọ sí pápá rẹ ni Anatoti, ó yẹ fún ọ láti kú, ṣùgbọ́n èmi kì yóò pa ọ́ nísinsin yìí, nítorí o ti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa Olódùmarè níwájú Dafidi baba mi, o sì ti ní ìpín nínú gbogbo ìyà tí baba mi jẹ.”
Manghai loh khosoih Abiathar te khaw, “Nang bang hlang kah dueknah ngawn tah, Anathoth kah namah khohmuen la mael laeh. Tedae tihnin ah he nang kan duek sak mahpawh. A pa David mikhmuh ah ka Boeipa Yahovah kah thingkawng te na koh tih a cungkuem neh a pa a phaep uh vaengah na phaep puei dongah,” a ti nah.
27 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni yọ Abiatari kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà Olúwa, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípa ilé Eli ní Ṣilo ṣẹ.
Solomon loh Abiathar te BOEIPA kah khosoih la aka om lamloh a khoe vaengah tah Shiloh kah Eli imkhui ah a thui BOEIPA ol te soep.
28 Nígbà tí ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Joabu, ẹni tí ó ti dìtẹ̀ pẹ̀lú Adonijah bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò wà pẹ̀lú Absalomu, ó sì sálọ sínú àgọ́ Olúwa, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
Te vaengah olthang loh Joab te a paan. Joab he Adonijah taengla buung tih Absalom taengah buung pawh. Te dongah Joab te BOEIPA kah dap la rhaelrham tih hmueihtuk ki te a tuuk.
29 A sì sọ fún Solomoni ọba pé Joabu ti sálọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Solomoni pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”
Tedae manghai Solomon taengah, “BOEIPA kah dap khuila Joab rhaelrham tih hmueihtuk taengah om ke,” tila a puen pah. Te dongah Solomon loh Jehoiada capa Benaiah te a tueih tih, “Cet lamtah anih te cuuk thil,” a ti nah.
30 Benaiah sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Joabu pé, “Ọba sọ wí pé, ‘Jáde wá.’” Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò kú níhìn-ín.” Benaiah sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Joabu ṣe dá mi lóhùn.”
Benaiah khaw BOEIPA kah dap khuila kun tih a taengah, “Manghai loh he ni a thui, ha coe laeh,” a ti nah. Tedae, “Pawh heah ka duek eh,” a ti nah. Te vaengah Benaiah loh manghai te ol a mael tih, “He ni Joab loh a thui tih he tlam ni kai n'doo,” a ti nah.
31 Ọba sì pàṣẹ fún Benaiah pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọlù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé baba mi, tí Joabu ti ta sílẹ̀.
Manghai loh anih te, “A thui bangla saii laeh, Anih te cuuk thil lamtah up laeh. Joab loh lunglilungla la thii a long sak te kai taeng lamkah neh a pa imkhui lamloh hnut laeh.
32 Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dafidi baba mi kò sì mọ̀. Àwọn méjèèjì ni Abneri ọmọ Neri olórí ogun Israẹli, àti Amasa ọmọ Jeteri olórí ogun Juda, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnra rẹ̀ lọ.
Amah lakah ah aka dueng tih aka then hlang panit te a cuuk thil dongah amah thii te BOEIPA loh a lu dongah mael sak saeh. A pa David kah a ming pawt ah Israel kah caempuei mangpa Ner capa Abner khaw, Judah kah caempuei mangpa Jether capa Amasa te khaw cunghang neh a ngawn bal.
33 Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Joabu àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dafidi àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”
Amih rhoi thii te Joab lu so neh a tiingan soah kumhal duela mael saeh. Tedae David so neh a tiingan soah khaw, a imkhui so neh a ngolkhoel soah khaw BOEIPA taeng lamkah ngaimongnah he kumhal duela om saeh,” a ti nah.
34 Bẹ́ẹ̀ ni Benaiah ọmọ Jehoiada sì gòkè lọ, ó sì kọlu Joabu, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní aginjù.
Te dongah Jehoiada capa Benaiah te cet tih anih te a cuuk thil. Anih te a duek sak phoeiah khosoek kah amah im ah a up.
35 Ọba sì fi Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ olórí ogun ní ipò Joabu àti Sadoku àlùfáà ní ipò Abiatari.
Manghai loh anih yueng la caempuei soah Jehoiada capa Benaiah te a khueh tih manghai loh Abiathar yueng la Zadok te khosoih a paek.
36 Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣimei, ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jerusalẹmu, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.
Manghai loh Shimei te a tah tih a khue. Te phoeiah anih te, “Jerusalem ah namah ham im sa lamtah khosa pahoi, tedae te lamloh melam, melam khaw mop boeh.
37 Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá àfonífojì Kidironi, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”
Tedae na mop hnin te om tih Kidron soklong te na kat vaengah na ming rhoe na ming bitni. Na duek rhoe na duek vetih na thii te namah lu ah ni a tlak eh,” a ti nah.
38 Ṣimei sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí olúwa mi ọba ti wí.” Ṣimei sì gbé ní Jerusalẹmu fún ìgbà pípẹ́.
Shimei loh manghai taengah, “Ka boei manghai kah a thui bangla ol then te na sal loh a ngai van bitni,” a ti nah. Te dongah Shimei khaw Jerusalem ah kum a yet kho a sak.
39 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Ṣimei méjì sì sálọ sọ́dọ̀ Akiṣi ọmọ Maaka, ọba Gati, a sì sọ fún Ṣimei pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gati.”
Tedae kum thum a bawtnah te a pha vaengah tah Shimei kah sal rhoi te Gath manghai Maakah capa Akhish taengla yong rhoi. Te dongah Shimei taengla puen tih, “Na sal rhoi te Gath ah om ke,” a ti nah.
40 Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi ní Gati láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣimei sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gati.
Te dongah Shimei te thoo tih a laak te a khih. Te phoeiah a sal rhoi toem ham Gath kah Akhish taengla cet. Shimei te cet tih a sal rhoi te Gath lamloh a khuen.
41 Nígbà tí a sì sọ fún Solomoni pé Ṣimei ti lọ láti Jerusalẹmu sí Gati, ó sì ti padà.
Tedae Shimei Jerusalem lamloh Gath la cet tih a mael te Solomon taengla a puen pah.
42 Ọba pe Ṣimei lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú.’ Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’
Te dongah manghai loh Shimei te a tah tih a khue. Te phoeiah anih te, “BOEIPA dongah nang kan toemngam moenih a? Nang te kan rhalrhing sak vaengah, ‘Na mop tih melam, melam khaw na caeh hnin ah na duek rhoe na duek ni tila ming rhoe ming laeh,’ ka ti te ta. Kamah taengah, ‘Ol then te ka hnatun bitni,’ na ti.
43 Èéṣe, nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”
Te lalah balae tih BOEIPA kah olhlo neh olpaek nang taengah kang uen te na ngaithuen pawh?” a ti nah.
44 Ọba sì tún wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dafidi baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.
Te phoeiah manghai loh Shimei te, “Namah loh boethae cungkuem te na ming, a pa David taengah na saii te na thinko loh a ming. Te dongah na boethae te BOEIPA loh namah lu ah tlak sak saeh.
45 Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Solomoni ọba, ìtẹ́ Dafidi yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”
Tedae manghai Solomon tah a yoethen tih David kah ngolkhoel khaw kumhal due BOEIPA mikhmuh ah cikngae la om ni,” a ti nah.
46 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣimei, ó sì pa á. Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Solomoni.
Manghai loh Jehoiada capa Benaiah te a uen coeng dongah cet tih Shimei te a cuuk thil tih a duek sak. Te phoeiah ram he Solomon kut ah cikngae coeng.

< 1 Kings 2 >