< 1 Kings 2 >
1 Nígbà tí ọjọ́ ikú Dafidi súnmọ́ etílé, ó pàṣẹ fún Solomoni ọmọ rẹ̀.
Da: ibidi da bogomu galu, e da ea mano Soloumane ema misa: ne sia: i. E da ema dagomusa: fada: i sia: su amane sia: i,
2 Ó sì wí pé, “Èmi ti fẹ́ lọ sí ọ̀nà gbogbo ayé, nítorí náà jẹ́ alágbára kí o sì fi ara rẹ hàn bí ọkùnrin,
“Na bogomu eso da doaga: i. Di mae beda: ne, gasa fili aligima.
3 kí o sì wòye ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ béèrè, rìn ní ọ̀nà rẹ̀, kí o sì pa àṣẹ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti ìdájọ́ rẹ, àti ẹ̀rí rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé òfin Mose, nítorí kí ìwọ kí ó le è máa ṣe rere ní ohun gbogbo tí ìwọ ṣe, àti ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ,
Amola dia Hina Gode Ea hamoma: ne sia: be amo defele hamoma. Ea sema amola hamoma: ne sia: i Mousese ea Sema Buga ganodini dedei, amo defele hamoma. Di da amane hamosea, di da habodili ahoasea amola di adi hamosea, hahawane ba: mu.
4 kí Olúwa kí ó lè pa ìlérí rẹ̀ tí ó sọ nípa tèmi mọ́ pé, ‘Bí àwọn ọmọ rẹ bá kíyèsi ọ̀nà wọn, tí wọ́n bá sì fi gbogbo àyà wọn àti ọkàn wọn rìn níwájú mi ní òtítọ́, o kì yóò sì kùnà láti ní ọkùnrin kan lórí ìtẹ́ Israẹli.’
Hina Gode da nama amane ilegele sia: i, ‘Digaga fi da Na sia: amo mae fisili dafawane noga: le nabawane hamosea, ilia da Isala: ili fi ouligilalumu. Di da Ea sia: nabawane hamosea, Hina Gode da amo ilegele sia: i dafawane dima hamomu.
5 “Ìwọ pẹ̀lú sì mọ ohun tí Joabu ọmọ Seruiah ṣe sí mi àti ohun tí ó ṣe sí balógun méjì nínú àwọn ológun Israẹli, sí Abneri ọmọ Neri àti sí Amasa ọmọ Jeteri. Ó sì pa wọ́n, ó sì ta ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ ní ìgbà àlàáfíà bí í ti ojú ogun ó sì fi ẹ̀jẹ̀ náà sí ara àmùrè rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, àti sí ara sálúbàtà rẹ̀ tí ń bẹ ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Eno adomu gala. Dia dawa: amo Youa: be da Isala: ili dadi gagui wa: i ouligisu dunu aduna, (Ne ea mano A: bena amola Yidie ea mano Ama: isa) medole legeiba: le, na hou wadela: lesi. Ela da gegesu esoga dunu eno ha lai dunu medole legei. Be Youa: be da olofosu esoga amo dunu elama dabe i. E da wadela: i hame hamosu dunu medole legei. Be waha da amo se nabasu na fawane da naba.
6 Ṣe sí í gẹ́gẹ́ bí ọgbọ́n rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú ní àlàáfíà. (Sheol )
Dia hamomu amo di dawa: Amo dunu medole legema: ma. (Sheol )
7 “Ṣùgbọ́n fi inú rere hàn sí àwọn ọmọ Barsillai, ti Gileadi, jẹ́ kí wọn wà lára àwọn tí ó ń jẹun lórí tábìlì rẹ̀. Wọ́n dúró tì mí nígbà tí mo sá kúrò níwájú Absalomu arákùnrin rẹ.
Be Gilia: de dunu Basila: iai egefelali ilima asigima, amola ili ouligima. Bai na da diaola A: basalomema hobeabeba: le, ilia da nama asigi galu.
8 “Àti kí o rántí, Ṣimei ọmọ Gera ẹ̀yà Benjamini tí Bahurimu wà pẹ̀lú rẹ̀, tí ó bú mi ní èébú tí ó korò ní ọjọ́ tí mo lọ sí Mahanaimu. Nígbà tí ó sọ̀kalẹ̀ wá pàdé mi ní Jordani, mo fi Olúwa búra fún un pé, ‘Èmi kì yóò fi idà pa ọ́.’
Dunu eno dawa: ma-amo Simiai (Gila ea mano, e da Bahiulimi moilai Bediamini soge ganodini esalu). Na da Ma: ihana: ime sogega ahoanoba, e da nama gasa bagadewane gagabui aligima: ne ilegei. Be na da buhagilaloba, e da Yodane Hano amogai na gousa: i. Amola na da Hina Gode Ea Dioba: le, e hame medole legemu, amane dafawane ilegele sia: i.
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, má ṣe kíyèsi í gẹ́gẹ́ bí aláìlẹ́ṣẹ̀, ọkùnrin ọlọ́gbọ́n ni ìwọ ṣe; ìwọ yóò mọ ohun tí ìwọ yóò ṣe sí i. Mú ewú orí rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sínú isà òkú pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀.” (Sheol )
Be di da ema dawama: ne se dabe ima. Dia hamomu amo di dawa: Amo dunu medole legema: ne sia: ma.” (Sheol )
10 Nígbà náà ni Dafidi sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi.
Da: ibidi da bogole, ilia da ea da: i hodo Da: ibidi Moilai Bai Bagade ganodini uli dogonesi.
11 Dafidi ti jẹ ọba lórí Israẹli ní ogójì ọdún, ọdún méje ni Hebroni àti ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n ní Jerusalẹmu.
E da Isala: ili soge ode 40 agoane ouligisu hamoi. Amo ouligisu ganodini, e da ode fesuale agoane Hibalone moilai bai bagadega esala ouligilalu, amola ode 33 agoane Yelusaleme moilai bai bagadega esala ouligisu hamoi.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
Soloumane da eda Da: ibidi ea bagia hina bagade hou lai. Ea ouligilalusu da gasa bagade ba: i.
13 Wàyí, Adonijah ọmọ Haggiti tọ Batṣeba, ìyá Solomoni wá. Batṣeba sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
Amalalu, A:dounaidia (ea ame da Ha: gide) da Ba: desiba (Soloumane eme) ema asi. Ba: desiba da ema amane sia: i, “Di da olofolewane nama misibala: ?” E bu adole i, “Ma! Na da olofoiwane misi.”
14 Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.” Batṣeba sì wí pé, “Máa wí.”
Amalalu, e da amane sisa: asi, “Na da dima adole ba: mu gala.” Ba: desiba da amane adole ba: i, “Di da adi sia: ma: bela: ?”
15 Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Israẹli ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.
E bu adole i, “Di dawa: Na da hina bagade hou lamu da defea galu. Amola Isala: ili dunu huluane da na Isala: ili fi ouligima: ne dawa: i galu. Be hou eno da doaga: i. Amola Hina Gode Ea hanaiba: le, naeya da hina bagade hou lai dagoi.
16 Nísinsin yìí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ó wí pé, “O lè wí.”
Amola wali na da adole ba: su afae fawane gala. Na hanai logo mae hedofama.” Ba: desiba da bu adole ba: i, “Dia hanai da adila: ?”
17 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀síwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Solomoni ọba (òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Abiṣagi ará Ṣunemu ní aya.”
E bu adole i, “Hina bagade Soloumanema amane adole ba: ma (e da dia adole ba: mu hame hedofamu) ‘Siuneme a: fini A: bisia: ge amo A: dounaidia lama: ne ima.’”
18 Batṣeba sì dáhùn pé, “Ó dára èmi yóò bá ọba sọ̀rọ̀ nítorí rẹ̀.”
Ba: desiba da amane sia: i, “Defeawane! Na da hina bagadema dia hanai amo adosimu.”
19 Nígbà tí Batṣeba sì tọ Solomoni ọba lọ láti bá a sọ̀rọ̀ nítorí Adonijah, ọba sì dìde láti pàdé rẹ̀, ó sì tẹríba fún un, ó sì jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. Ó sì tẹ́ ìtẹ́ kan fún ìyá ọba, ó sì jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Amaiba: le, Ba: desiba da A: dounaidia ea adole ba: su adosimusa: , hina bagadema asi. Hina bagade da ea ame yosia: musa: , wa: legadole begudui. Amalalu, e da ea fisuga fili, amola e da fisu eno gaguli misa: ne sia: i. Amoga Ba: desiba da ea lobodafa la: ididili fi.
20 Ó sì wí pé, “Mo ní ìbéèrè kékeré kan láti béèrè lọ́wọ́ rẹ, má ṣe kọ̀ fún mi.” Ọba sì dáhùn wí pé, “Béèrè, ìyá mi; èmi kì yóò kọ̀ ọ́.”
E amane sia: i, “Na da dima adole ba: su fonobahadi gala. Na hanai logo mae hedofama.” Soloumane da amane adole ba: i, “Defea, ame! Dia hanai da adila: ? Na da dia hanai hame hihimu.”
21 Nígbà náà ni ó wí pé, “Jẹ́ kí a fi Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah arákùnrin rẹ ní aya.”
E bu adole i, “A: fini A: bisia: ge amo dia ola A: dounaidia lama: ne ema ima.”
22 Solomoni ọba sì dá ìyá rẹ̀ lóhùn pé, “Èéṣe tí ìwọ fi béèrè Abiṣagi ará Ṣunemu fún Adonijah! Ìwọ ìbá sì béèrè ìjọba fún un pẹ̀lú nítorí ẹ̀gbọ́n mi ní í ṣe, fún òun pàápàá àti fún Abiatari àlùfáà àti fun Joabu ọmọ Seruiah!”
Hina bagade da amane sia: i, “Dia abuliba: le A: bisia: ge amo ema ima: ne sia: sala: ? Di da agoane sia: beba: le, di da defele na hina bagade hou ema ima: ne sia: sa. Bai e da naola. Amola gobele salasu dunu A: baia: da amola Youa: be da e fuligala: sa.”
23 Nígbà náà ni Solomoni ọba fi Olúwa búra pé, “Kí Ọlọ́run ki ó jẹ mí ní yà, àti jù bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, bí Adonijah kò bá ní fi ẹ̀mí rẹ̀ san ìbéèrè yìí!
Amalalu, Soloumane da Hina Gode Ea Dioba: le dafawane ilegele sia: i, “A: dounaidia da amo adole ba: beba: le, na da e dabema: ne medole legema: ne sia: sa. Na da amo hame hamosea, Gode da na medole legemu da defea.
24 Àti nísinsin yìí, bí ó ti dájú pé Olúwa wà láààyè, ẹni tí ó ti mú mi jókòó lórí ìtẹ́ baba mi Dafidi, àti tí ó sì ti kọ́ ilé fún mi bí ó ti ṣèlérí, lónìí ni a ó pa Adonijah!”
Hina Gode da hamobeba: le, na da gasa fili, na ada Da: ibidi ea hina bagade fisu amoga hahawane ouligilala. Gode da Ea ilegele sia: i hame gogolei. E da Isala: ili ouligisu hou, na amola nagaga fi ninima i dagoi. Na da Hina Gode Esala amo Ea Dioba: le dafawane ilegele sia: sa. Wali esodafa, A:dounaidia da medole legei dagoi ba: mu.”
25 Solomoni ọba sì pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì kọlu Adonijah, ó sì kú.
Amaiba: le, hina bagade Soloumane da sia: beba: le, Bina: ia da gadili asili, A:dounaidia medole legei.
26 Ọba sì wí fún Abiatari àlùfáà pé, “Padà lọ sí pápá rẹ ni Anatoti, ó yẹ fún ọ láti kú, ṣùgbọ́n èmi kì yóò pa ọ́ nísinsin yìí, nítorí o ti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa Olódùmarè níwájú Dafidi baba mi, o sì ti ní ìpín nínú gbogbo ìyà tí baba mi jẹ.”
Amalalu, hina bagade Soloumane da gobele salasu dunu A: baia: dama amane sia: i, “Dia soge gabolo lai A: nadode amoga masa. Na da di medole legemu da defea gala, be na wahadafa di hame medole legemu. Bai di da na ada Da: ibidi musa: se nabaloba, di da e fidilalu amola Hina Gode Ea Gousa: su Sema Gagili amo ouligilalu.”
27 Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni yọ Abiatari kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà Olúwa, kí ó lè mú ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ nípa ilé Eli ní Ṣilo ṣẹ.
Amalalu, Soloumane da A: baia: da ea Hina Godema gobele salasu hawa: hamonanu amo fadegai. Amola Hina Gode da musa: Siailou moilaiga sia: i, (1 Sa: miuele 2:27-36 amo gobele salasu dunu Ilai amola ea fi da wadela: lesi dagoi ba: mu), amo sia: da didili hamoi dagoi ba: i.
28 Nígbà tí ìròyìn sì dé ọ̀dọ̀ Joabu, ẹni tí ó ti dìtẹ̀ pẹ̀lú Adonijah bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò wà pẹ̀lú Absalomu, ó sì sálọ sínú àgọ́ Olúwa, ó sì di ìwo pẹpẹ mú.
Youa: be da amo hou nabi dagoi. (E da A: dounaidia fuligala: lalu be A: basalome hame fuligala: i.) Amaiba: le, e da Hina Gode Abula Diasuga hobeale, oloda hegomai da: iya ‘hono’ amo gagui.
29 A sì sọ fún Solomoni ọba pé Joabu ti sálọ sínú àgọ́ Olúwa àti pé ó wà ní ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ. Nígbà náà ni Solomoni pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada pé, “Lọ, kí o sì kọlù ú.”
Soloumane da Youa: be da Hina Gode Abula Diasuga hobeale, oloda ‘hono’ gagulalebe, amo sia: nababeba: le, e da sia: adole iasu dunu ema asunasi. E da Youa: bema ea hobea: i bai amo adole ba: i. Youa: be da bu adole i, “Na da Hina Gode na gaga: ma: ne hobea: i. Bai na Soloumaneba: le beda: i.” Amaiba: le, Soloumane da Youa: be medole legemusa: , Bina: ia asunasi.
30 Benaiah sì wọ inú àgọ́ Olúwa, ó sì wí fún Joabu pé, “Ọba sọ wí pé, ‘Jáde wá.’” Ṣùgbọ́n ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, èmi yóò kú níhìn-ín.” Benaiah sì mú èsì fún ọba, “Báyìí ni Joabu ṣe dá mi lóhùn.”
E da Hina Gode Ea Abula Diasuga asili, Youa: bema amane sia: i, “Hina bagade da dima gadili misa amane sia: sa.” Youa: be da bu adole i, “Hame mabu! Na da guiguda: bogomu.” Bina: ia da hina bagadema buhagili, Youa: be ea sia: i ema olelei.
31 Ọba sì pàṣẹ fún Benaiah pé, “Ṣe bí ó ti wí. Kọlù ú, kí o sì sin ín, kí o sì mú ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi àti kúrò lọ́dọ̀ ilé baba mi, tí Joabu ti ta sílẹ̀.
Soloumane da amane sia: i, “Youa: be ea sia: i defele hamoma. Amogawi e medole legema amola ea da: i hodo uli dogoma. Youa: be da wadela: i hame hamosu dunu medole legebeba: le, dunu huluane da Da: ibidi amola ea fi ilima ougili fofogadigi. Be e bogosea, ninia da amo se bu hame nabimu.
32 Olúwa yóò sì san ẹ̀jẹ̀ tí ó ti ta sílẹ̀ padà fún un, nítorí tí ó kọlu ọkùnrin méjì, ó sì fi idà rẹ̀ pa wọ́n, Dafidi baba mi kò sì mọ̀. Àwọn méjèèjì ni Abneri ọmọ Neri olórí ogun Israẹli, àti Amasa ọmọ Jeteri olórí ogun Juda, wọ́n jẹ́ olódodo, wọ́n sì sàn ju òun fúnra rẹ̀ lọ.
Hina Gode da Youa: bema se iasu imunu. Bai e da na ada Da: ibidima mae adole, wadela: i hame hamosu dunu aduna (ela hou noga: i da Youa: be ea hou baligi) amo medole legei. Amo dunu da A: bena (Isala: ili dadi gagui wa: i ouligisudafa) amola Ama: isa (Yuda dadi gagui wa: i ouligisudafa).
33 Kí ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ wọn wá sórí Joabu àti sórí irú-ọmọ rẹ̀ títí láé. Ṣùgbọ́n sórí Dafidi àti irú-ọmọ rẹ̀, sí ilé rẹ̀ àti sí ìtẹ́ rẹ̀, ni kí àlàáfíà Olúwa wà títí láé.”
Amo medole legesu hou ea se dabe iasu da mae fisili, eso huluane, Youa: be amola ea fi ilima doaga: ga: la: lumu. Be Hina Gode da mae fisili, eso huluane Da: ibidi ea fi amo da ea fisuga fisia, ilima hahawane dogolegesu hou amola hasalasisu hou imunu.”
34 Bẹ́ẹ̀ ni Benaiah ọmọ Jehoiada sì gòkè lọ, ó sì kọlu Joabu, ó sì pa á, a sì sin ín ní ilẹ̀ ibojì ara rẹ̀ ní aginjù.
Amaiba: le, Bina: ia da Hina Gode Abula Diasuga asili, Youa: be medole legei. Ilia da ea da: i hodo ea moilai sogega uli dogone sali.
35 Ọba sì fi Benaiah ọmọ Jehoiada jẹ olórí ogun ní ipò Joabu àti Sadoku àlùfáà ní ipò Abiatari.
Soloumane da Bina: iama, Youa: be ea sogebi (dadi gagui wa: i ouligisu) i dagoi. Amola e da gobele salasu sogebi (A: baia: da musa: ouligisu) amo Sa: idogema i dagoi.
36 Nígbà náà ni ọba ránṣẹ́ sí Ṣimei, ó sì wí fún un pé, “Kọ́ ilé fún ara rẹ ní Jerusalẹmu, kí o sì máa gbé ibẹ̀, ṣùgbọ́n kí o má sì ṣe lọ sí ibòmíràn.
Amalalu, hina bagade da Simiai ema misa: ne sia: i. E da ema amane sia: i, “Dia diasu amo guiguda: Yelusaleme moilai bai bagade amo ganodini gaguma. Amogawi esaloma amola moilai mae yolesima.
37 Ọjọ́ tí ìwọ bá jáde, tí o sì kọjá àfonífojì Kidironi, kí ìwọ kí ó mọ̀ dájúdájú pé ìwọ yóò kú; ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wà lórí ara rẹ.”
Be di da moilaiga ga asili, Gidalone Hano amo baligisia, di da bogosu ba: mu. Amola di da dia hamobeba: le fawane amo se dabe iasu ba: mu.”
38 Ṣimei sì dá ọba lóhùn pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára. Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe bí olúwa mi ọba ti wí.” Ṣimei sì gbé ní Jerusalẹmu fún ìgbà pípẹ́.
Simiai da amane sia: i, “Defea hina bagade! Na da dia sia: i defele hamomu.” Amaiba: le, e da eso bagohame Yelusaleme amo ganodini esalu.
39 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún mẹ́ta, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ Ṣimei méjì sì sálọ sọ́dọ̀ Akiṣi ọmọ Maaka, ọba Gati, a sì sọ fún Ṣimei pé, “Àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ méjì wà ní Gati.”
Be ode udiana gidigili, ea udigili hawa: hamosu dunu aduna da hobeale, Ga: de soge hina bagade A: igisi (Ma: iaga ea mano) ema asi. Simiai da ela da Ga: de sogega doaga: i nababeba: le,
40 Fún ìdí èyí, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi ní Gati láti wá àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni Ṣimei sì lọ, ó sì mú àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ padà bọ̀ láti Gati.
e da ea dougi da: iya fisu ligisili, fila heda: le, ea udigili hawa: hamosu dunu hogomusa: , Ga: de soge hina bagade A: igisima asi. E da ea udigili hawa: hamosu dunu ba: beba: le, ela ea diasuga bu oule misi.
41 Nígbà tí a sì sọ fún Solomoni pé Ṣimei ti lọ láti Jerusalẹmu sí Gati, ó sì ti padà.
Soloumane da ea hamoi nababeba: le,
42 Ọba pe Ṣimei lẹ́jọ́, ó wí fún un pé, “Ǹjẹ́ èmi kò ti mú ọ búra ní ti Olúwa, èmi sì ti kìlọ̀ fún ọ pé, ‘Ní ọjọ́ tí ìwọ bá kúrò láti lọ sí ibikíbi, kí o mọ̀ dájú pé ìwọ yóò kú.’ Nígbà náà ni ìwọ sì sọ fún mi pé, ‘Ohun tí ìwọ sọ dára. Èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn.’
e da ema misa: ne sia: sili, ema amane sia: i, “Na sia: beba: le, di da Hina Gode Ea Dioba: le amo Yelusaleme hamedafa yolesima: ne ilegele sia: i. Amola na da dima sisane sia: i, di da Yelusaleme yolesea, dafawane bogomu. Di da amo sia: dafawaneyale ilegei amola na sia: nabawane hamoma: ne sia: i.
43 Èéṣe, nígbà náà tí ìwọ kò pa ìbúra Olúwa mọ́, àti kí o sì ṣe ìgbọ́ràn sí àṣẹ tí mo pa fún ọ?”
Amaiba: le, di da abuliba: le dia ilegele sia: i wadela: lesibala: ? Amola na hamoma: ne sia: i hame nabibala: ?
44 Ọba sì tún wí fún Ṣimei pé, “Ìwọ mọ̀ ní ọkàn rẹ gbogbo búburú tí ìwọ ti ṣe sí Dafidi baba mi. Báyìí, Olúwa yóò san gbogbo ìṣe búburú rẹ padà fún ọ.
Di da na ada Da: ibidima wadela: le bagade hamoi. Amo di dawa: Amaiba: le, Hina Gode da dima dawa: ma: ne se dabe imunu.
45 Ṣùgbọ́n a ó sì bùkún fún Solomoni ọba, ìtẹ́ Dafidi yóò sì wà láìfòyà níwájú Olúwa títí láéláé.”
Be E da nama hahawane dogolegele imunu amola Da: ibidi ea hina bagade ouligisu hou da gasa fili, eso huluane dialumu.”
46 Nígbà náà ni ọba pàṣẹ fún Benaiah ọmọ Jehoiada, ó sì jáde lọ, ó sì kọlu Ṣimei, ó sì pa á. Ìjọba náà sì wá fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ Solomoni.
Amalalu, hina bagade da Bina: iama hamoma: ne sia: beba: le, e da ga asili, Simiai medole legei. Amalalu, Soloumane da gasa fili, Isala: ili ouligisu hou gaguiwane ba: i.