< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
Lekin Aⱨab Iliyasning ⱨǝmmǝ ⱪilƣinini, jümlidin ⱨǝmmǝ pǝyƣǝmbǝrlǝrni ⱪiliqlap ɵltürginini Yizǝbǝlgǝ eytip bǝrdi.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Yizǝbǝl bolsa Iliyasⱪa bir hǝwǝrqi ǝwǝtip: — Əgǝr ǝtǝ muxu waⱪitⱪiqǝ sǝn xularning janliriƣa ⱪilƣiningdǝk mǝn sening jeningni ohxax ⱪilmisam, ilaⱨlar mangimu xundaⱪ ⱪilsun ⱨǝmdǝ uningdinmu ziyadǝ ⱪilsun! — dǝp eytⱪuzdi.
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
U buni bilgǝndǝ, ɵz jenini ⱪutⱪuzmaⱪ üqün ⱪeqip Yǝⱨuda tǝwǝsidiki Bǝǝr-Xebaƣa bardi. U u yǝrdǝ ɵz hizmǝtkarini ⱪaldurup ⱪoyup,
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
Ɵzi qɵlning iqigǝ ⱪarap bir kün yol mangdi. U u yǝrdiki bir xiwaⱪning ⱪexiƣa kelip uning astida olturup, ɵzining ɵlümigǝ tilǝk tilǝp: — I Pǝrwǝrdigar ǝmdi boldi, jenimni alƣin; nemila degǝnbilǝn mǝn ata-bowilirimdin artuⱪ ǝmǝsmǝn, — dedi.
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
U xu xiwaⱪ astida yetip uhlap ⱪaldi. Mana bir pǝrixtǝ uni noⱪup uningƣa: — Ⱪopup, nan yegin, dedi.
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
U ⱪarisa bexida ⱪiziⱪ qoƣlarda pixiwatⱪan bir poxkal wǝ bir koza su turatti. U yǝp-iqip yǝnǝ uhliƣili yatti.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Andin Pǝrwǝrdigarning pǝrixtisi yǝnǝ kelip ikkinqi ⱪetim uni noⱪup uningƣa: — Ⱪopup nan yegin. Bolmisa yolungning eƣirini kɵtürǝlmǝysǝn, dedi.
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
U ⱪopup yǝp-iqti. Xu taamdin alƣan ⱪuwwǝt bilǝn u ⱪiriⱪ keqǝ-kündüz mengip Hudaning teƣi Ⱨorǝbgǝ yetip bardi.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
U u yǝrdiki ƣarƣa kirip ⱪondi. Wǝ mana, Pǝrwǝrdigarning sɵzi uningƣa kelip mundaⱪ deyildi: — I Iliyas, bu yǝrdǝ nemǝ ⱪiliwatisǝn?
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
U jawab berip: — Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Huda Pǝrwǝrdigar üqün zor otluⱪ muⱨǝbbǝt bilǝn ⱨǝsǝt ⱪildim. Qünki Israillar Sening ǝⱨdǝngni taxlap ⱪurbangaⱨliringni yiⱪitip, Sening pǝyƣǝmbǝrliringni ⱪiliq bilǝn ɵltürdi. Mǝn, yalƣuz mǝnla ⱪaldim wǝ ular mening jenimni alƣili ⱪǝstlǝwatidu, dedi.
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
U uningƣa: — Qiⱪip, Pǝrwǝrdigarning aldida taƣda turƣin, dedi. Mana, Pǝrwǝrdigar ɵtüp ketiwatatti; [uning aldida] zor küqlük bir xamal qiⱪip, taƣlarni sundurup, ⱪoram taxlarni parqilap qeⱪiwǝtti. Lekin Pǝrwǝrdigar xamalda ǝmǝs idi. Xamaldin keyin bir yǝr tǝwrǝx boldi. Lekin Pǝrwǝrdigar yǝr tǝwrǝxtǝ ǝmǝs idi.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
Yǝr tǝwrǝxtin keyin bir lawuldiƣan ot kɵtürüldi. Lekin Pǝrwǝrdigar otta ǝmǝs idi. Ottin keyin boxⱪina, mulayim bir awaz anglandi.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
Wǝ xundaⱪ boldiki, Iliyas xuni anglap, yüzini yepinqisi bilǝn orap ƣarning aƣziƣa berip turdi. Mana, bir awaz qiⱪip uningƣa: — I Iliyas, sǝn bu yǝrdǝ nemǝ ⱪiliwatisǝn? — dedi.
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
U jawab berip: — Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Huda Pǝrwǝrdigar üqün zor otluⱪ muⱨǝbbǝt bilǝn ⱨǝsǝt ⱪildim. Qünki Israillar Sening ǝⱨdǝngni taxlap ⱪurbangaⱨliringni yiⱪitip, Sening pǝyƣǝmbǝrliringni ⱪiliq bilǝn ɵltürdi. Mǝn yalƣuz mǝnla ⱪaldim wǝ ular mening jenimni alƣili ⱪǝstlǝwatidu, dedi.
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
Pǝrwǝrdigar uningƣa mundaⱪ dedi: — Barƣin, kǝlgǝn yolung bilǝn ⱪaytip, andin Dǝmǝxⱪning qɵligǝ barƣin. U yǝrgǝ barƣanda Ⱨazaǝlni Suriyǝ üstigǝ padixaⱨ boluxⱪa mǝsiⱨ ⱪilƣin.
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
Andin Nimxining oƣli Yǝⱨuni Israilning üstigǝ padixaⱨ boluxⱪa mǝsiⱨ ⱪilƣin; ɵz ornungƣa pǝyƣǝmbǝr boluxⱪa Abǝl-Mǝⱨolaⱨliⱪ Xafatning oƣli Elixanimu mǝsiⱨ ⱪilƣin.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
Wǝ xundaⱪ boliduki, Ⱨazaǝlning ⱪiliqidin ⱪeqip ⱪutulƣan ⱨǝrbirini Yǝⱨu ɵltüridu; Yǝⱨuning ⱪiliqidin ⱪeqip ⱪutulƣan ⱨǝrbirini Elixa ɵltüridu.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Lekin Israilda yǝttǝ ming kixini, yǝni Baalning aldida tizlirini pükmigǝn wǝ uningƣa aƣzini sɵygüzmigǝn ⱨǝrbirini ɵzümgǝ saⱪlap ⱪaldurdum, — dedi.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
U u yǝrdin qiⱪip, Xafatning oƣli Elixani tapti. U qaƣda u yǝr ⱨǝydǝwatatti; uning aldida on ikki jüp uy bar idi, u on ikkinqisi bilǝn ⱪox ⱨǝydǝwatatti. Iliyas kelip uning üstigǝ ɵz yepinqisini taxlap artip ⱪoydi.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
U uylarni taxlap Iliyasning kǝynidin yügürüp kelip: — Meni berip atam bilǝn anamni sɵygili ⱪoyƣin, andin mǝn kelip sanga ǝgixǝy, — dedi. U uningƣa: — Ⱪaytⱪin; mǝn sanga nemǝ ⱪildim? — dedi.
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
U uningdin ayrilip, ɵzi ixlǝtkǝn bir jüp uyni soyup, ularning jabduⱪini otun ⱪilip, gɵxini pixurup hǝlⱪⱪǝ beriwidi, ular yedi. Andin u ornidin ⱪopup Iliyasning kǝynidin ǝgixip, uning hizmitidǝ boldi.

< 1 Kings 19 >