< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
Men när Ahab berättade för Isebel allt vad Elia hade gjort, och huru han hade dräpt alla profeterna med svärd,
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Sände Isebel en budbärare till Elia och lät säga: "Gudarna straffe mig nu och framgent om jag icke i morgon vid denna tid låter det gå med ditt liv såsom det gick med alla dessas liv."
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
När han förnam detta, stod han upp och begav sig i väg för att rädda sitt liv, och han kom så till Beer-Seba, som hör till Juda; där lämnade han kvar sin tjänare.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
Men själv gick han ut i öknen en dagsresa. Där satte han sig under en ginstbuske; och han önskade sig döden och sade: "Det är nog; tag nu mitt liv, HERRE, ty jag är icke förmer än mina fäder."
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
Därefter lade han sig att sova under en ginstbuske. Men se, då rörde en ängel vid honom och sade till honom: "Stå upp och ät."
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
När han då såg upp, fick han vid sin huvudgärd se ett bröd, sådant som bakas på glödande stenar, och ett krus med vatten. Och han åt och drack och lade sig åter ned.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Men HERRENS ängel rörde åter vid honom, för andra gången, och sade: "Stå upp och ät, ty eljest bliver vägen dig för lång."
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
Då stod han upp och åt och drack, och gick så, styrkt av den maten, i fyrtio dagar och fyrtio nätter, ända till Guds berg Horeb.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
Där gick han in i en grotta, och i den stannade han över natten. Då kom HERRENS ord till honom; han sade till honom: "Vad vill du här, Elia?"
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
Han svarade: "Jag har nitälskat för HERREN, härskarornas Gud. Ty Israels barn hava övergivit ditt förbund, rivit ned dina altaren och dräpt dina profeter med svärd; jag allena är kvar, och de stå efter att taga mitt liv."
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
Han sade: "Gå ut och ställ dig på berget inför HERREN." Då gick HERREN fram där, och en stor och stark storm, som ryckte loss berg och bröt sönder klippor, gick före HERREN; men icke var HERREN i stormen. Efter stormen kom en jordbävning; men icke var HERREN i jordbävningen.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
Efter jordbävningen kom en eld; men icke var HERREN i elden. Efter elden kom ljudet av en sakta susning.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
Så snart Elia hörde detta, skylde han sitt ansikte med manteln och gick ut och ställde sig vid ingången till grottan. Då kom en röst till honom och sade: "Vad vill du här, Elia?"
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
Han svarade: "Jag har nitälskat för HERREN, härskarornas Gud. Ty Israels barn hava övergivit ditt förbund, rivit ned dina altaren och dräpt dina profeter med svärd; jag allena är kvar, och de stå efter att taga mitt liv."
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
HERREN sade till honom: "Gå nu tillbaka igen, och tag vägen till Damaskus' öken, och gå in och smörj Hasael till konung över Aram.
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
Och Jehu, Nimsis son, skall du smörja till konung över Israel. Och till profet i ditt ställe skall du smörja Elisa, Safats son, från Abel-Mehola.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
Och så skall ske: den som kommer undan Hasaels svärd, honom skall Jehu döda, och den som kommer undan Jehus svärd, honom skall Elisa döda.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Men jag skall låta sju tusen män bliva kvar i Israel, alla de knän som icke hava böjt sig för Baal, och var mun som icke har givit honom hyllningskyss."
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
När han sedan gick därifrån, träffade han på Elisa, Safats son, som höll på att plöja; tolv par oxar gingo framför honom, och själv körde han det tolfte paret. Och Elia gick fram till honom och kastade sin mantel över honom.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Då släppte han oxarna och skyndade efter Elia och sade: "Låt mig först få kyssa min fader och min moder, så vill jag sedan följa dig." Han sade till honom: "Välan, du må gå tillbaka igen; du vet ju vad jag har gjort med dig."
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Då lämnade han honom och gick tillbaka och tog sina båda oxar och slaktade dem, och med oxarnas ok kokade han deras kött; detta gav han åt folket, och de åto. Därefter stod han upp och följde Elia och blev hans tjänare.

< 1 Kings 19 >