< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
Şi Ahab i-a istorisit Izabelei tot ce făcuse Ilie şi cum ucisese cu sabia pe toţi profeţii.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Atunci Izabela a trimis un mesager la Ilie, spunând: Astfel să îmi facă dumnezeii şi încă mai mult, dacă nu îţi fac viaţa ta ca viaţa unuia dintre ei, mâine pe timpul acesta.
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
Şi când el a văzut aceasta, s-a ridicat şi a mers pentru a-şi salva viaţa şi a venit la Beer-Şeba, care aparţine de Iuda, şi a lăsat pe servitorul său acolo.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
Iar el a mers în pustiu cale de o zi şi a ajuns şi a şezut sub un ienupăr; şi a cerut ca sufletul lui să moară şi a spus: Este destul; acum, DOAMNE, ia-mi viaţa, pentru că nu sunt mai bun decât părinţii mei.
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
Şi s-a culcat şi pe când dormea sub un ienupăr, iată, un înger l-a atins şi i-a spus: Scoală-te şi mănâncă.
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
Şi s-a uitat şi, iată, era o turtă coaptă pe cărbuni şi un urcior cu apă la capul său. Şi a mâncat şi a băut şi s-a culcat din nou.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Şi îngerul DOMNULUI a venit din nou, a doua oară, şi l-a atins şi a spus: Scoală-te şi mănâncă; deoarece călătoria ta este prea mare pentru tine.
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
Şi s-a sculat şi a mâncat şi a băut şi a mers în puterea mâncării aceleia patruzeci de zile şi patruzeci de nopţi până la Horeb, muntele lui Dumnezeu.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
Şi a intrat acolo într-o peşteră şi a rămas toată noaptea acolo; şi, iată, cuvântul DOMNULUI a venit la el şi i-a spus: Ce faci tu aici, Ilie?
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
Şi el a spus: Am fost foarte gelos pentru DOMNUL Dumnezeul oştirilor; deoarece copiii lui Israel au părăsit legământul tău, au dărâmat altarele tale şi au ucis cu sabia pe profeţii tăi; şi eu, numai eu, am rămas; şi ei mă caută să îmi ia viaţa.
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
Iar el a spus: Ieşi şi stai în picioare pe munte înaintea DOMNULUI. Şi, iată, DOMNUL a trecut şi un vânt mare şi puternic a despicat munţii şi a sfărâmat în bucăţi stâncile înaintea DOMNULUI, dar DOMNUL nu era în vânt; şi după vânt, un cutremur, dar DOMNUL nu era în cutremur.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
Şi după cutremur, un foc, dar DOMNUL nu era în foc; şi după foc o voce blândă, şoptită.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
Şi s-a întâmplat când Ilie a auzit aceasta, că şi-a înfăşurat faţa în mantaua sa şi a ieşit şi a stat în picioare la intrarea peşterii. Şi, iată, a ajuns la el o voce care a spus: Ce faci tu aici, Ilie?
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
Iar el a spus: Am fost foarte gelos pentru DOMNUL Dumnezeul oştirilor, deoarece copiii lui Israel au părăsit legământul tău, au dărâmat altarele tale şi au ucis cu sabia pe profeţii tăi; şi eu, numai eu, am rămas; şi ei mă caută să îmi ia viaţa.
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
Iar DOMNUL i-a zis: Du-te, întoarce-te pe calea ta către pustiul Damascului; şi când ajungi, să ungi pe Hazael să fie împărat peste Siria;
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
Şi pe Iehu, fiul lui Nimşi, să îl ungi să fie împărat peste Israel; şi pe Elisei, fiul lui Şafat, din Abel-Mehola, să îl ungi să fie profet în locul tău.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
Şi se va întâmpla, că pe cel care scapă de sabia lui Hazael îl va ucide Iehu; şi pe cel care scapă de sabia lui Iehu îl va ucide Elisei.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Totuşi, mi-am lăsat şapte mii în Israel, toţi genunchii ce nu s-au plecat înaintea lui Baal şi fiecare gură care nu l-a sărutat.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
Astfel, el s-a depărtat de acolo şi l-a găsit pe Elisei, fiul lui Şafat, care ara cu douăsprezece juguri de boi înaintea lui şi el cu al doisprezecelea; şi Ilie a trecut pe lângă el şi şi-a aruncat mantaua peste el.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Şi el a lăsat boii şi a alergat după Ilie şi a spus: Lasă-mă, te rog, să sărut pe tatăl meu şi pe mama mea şi apoi te voi urma. Iar el i-a spus: Du-te, întoarce-te: fiindcă ce ţi-am făcut?
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Şi el s-a întors de la el şi a luat o pereche de boi şi i-a înjunghiat şi a fiert carnea lor cu uneltele boilor şi a dat poporului şi ei au mâncat. Apoi s-a ridicat şi a mers după Ilie şi i-a servit.

< 1 Kings 19 >