< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
Tedy oznajmił Achab Jezabeli wszystko, co uczynił Elijasz, a iż prawie wszystkie proroki pomordował mieczem.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Przetoż posłała Jezabela posła do Elijasza, mówiąc: To mi niech uczynią bogowie, i to mi niech przyczynią, jeźli o tym czasie jutro nie położę duszy twojej, jako duszy którego z onych.
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
Co gdy wyrozumiał Elijasz, wstał i odszedł, aby duszę swą zachował, a przyszedł do Beerseby, która była w Judztwie, i zostawił tam sługę swego.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
A sam poszedł w puszczę na jeden dzień drogi: a gdy przyszedł, i usiadł pod jednym jałowcem, życzył sobie umrzeć, i rzekł: Dosyć już, o Panie; weźmijże duszę moję, bom nie jest lepszym nad ojców moich.
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
I położył się, a zasnął pod onym jałowcem, a oto w tenże czas tknął go Anioł i rzekł mu: Wstań, a jedz.
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
A gdy się obejrzał, oto w głowach jego był chleb na węglu upieczony i czasza wody. A tak jadł i pił, i położył się znowu.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Potem wrócił się Anioł Pański powtóre, i tknął go, a rzekł: Wstań, jedz, albowiem daleką masz drogę przed sobą.
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
A tak wstawszy jadł i pił, a szedł w mocy pokarmu onego czterdzieści dni i czterdzieści nocy, aż do góry Bożej Horeb.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
I wszedł tam do jaskini, a przenocował tam. A oto słowo Pańskie do niego, mówiąc: Cóż tu czynisz Elijaszu?
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
Który odpowiedział; Gorliwiem się zastawiał o Pana, Boga zastępów; albowiem synowie Izraelscy opuścili przymierze twoje, ołtarze twoje zburzyli, i proroki twoje mieczem pomordowali, a zostałem ja sam, i szukają duszy mojej, aby mi ją odjęli.
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
Tedy onże głos rzekł: Wynijdź, a stań na górze przed Panem. A oto Pan przechodził, i wiatr gwałtowny i mocny podwracający góry, i łamiący skały przed Panem; ale Pan nie był w onym wietrze. Za wiatrem było trzęsiemie ziemi; ale nie był Pan i w onem trzęsieniu.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
Za trzęsieniem był ogień; ale Pan nie był w ogniu; za ogniem był głos cichy i wolny.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
To gdy usłyszał Elijasz, zakrył oblicze swoje płaszczem swoim, a wyszedłszy stanął we drzwiach jaskini. A oto do niego głos mówiący: Co tu czynisz Elijaszu?
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
A on odpowiedział: Gorliwiem się zastawiał o Pana, Boga zastępów: albowiem opuścili przymierze twoje synowie Izraelscy, ołtarze twoje poburzyli, a proroki twoje mieczem pomordowali, i zostałem ja sam, a szukają duszy mojej, aby mi ją odjęli.
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
Ale Pan rzekł do niego: idź, wróć się drogą twą na puszczę Damaską, a gdy tam przyjdziesz, pomażesz Hazaela za króla nad Syryją;
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
A Jehu, syna Namsy, pomażesz za króla nad Izraelem, a Elizeusza, syna Safatowego, z Abelmechola, pomażesz za proroka miasto siebie.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
I stanie się, że ktokolwiek ujdzie miecza Hazaelowego, zabije go Jehu, a ktokolwiek ujdzie miecza Jehu, zabije go Elizeusz.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Jednakiem sobie zachował w Izraelu siedm tysięcy, których wszystkich kolana nie kłaniały się Baalowi, i których wszystkich usta nie całowały go.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
A tak on odszedłszy stamtąd, znalazł Elizeusza, syna Safatowego, a on orze, a dwanaście jarzm wołów przed nim, a sam był przy dwunastem jarzmie, a idąc mimo niego Elijasz, wrzucił nań płaszcz swój.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Który opuściwszy woły bierzał za Elijaszem, i rzekł: Niech pocałuję proszę ojca mego, i matkę moję, a pójdę za tobą; któremu rzekł: Idź, a wróć się zasię, ponieważ widzisz, com ci uczynił.
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
A tak wróciwszy się do niego wziął parę wołów, i zabił je, a przy drwach z pługa nawarzył mięsa z nich, i dał ludowi, i jedli. A wstawszy szedł za Elijaszem, i służył mu.

< 1 Kings 19 >