< 1 Kings 19 >
1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
UAhabi wasetshela uJezebeli konke uElija ayekwenzile, labo bonke ababulalayo, bonke abaprofethi, ngenkemba.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Khona uJezebeli wathuma isithunywa kuElija esithi: Kabenze njalo onkulunkulu, bengezelele njalo, uba ngalesisikhathi kusasa ngingenzi impilo yakho ibe njengempilo yomunye wabo.
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
Esekubonile, wasukuma, wahamba ngenxa yempilo yakhe, wafika eBherishebha engeyakoJuda, watshiya khona inceku yakhe.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
Kodwa yena wahamba uhambo losuku enkangala, wafika wahlala ngaphansi kwesihlahla serotemu, wacela ukuthi umphefumulo wakhe ufe, wathi: Kwanele, khathesi, Nkosi, thatha impilo yami, ngoba kangingcono kulabobaba.
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
Esecambalele elele ngaphansi kwesihlahla esithile serotemu, khangela-ke, khonokho ingilosi yamthinta, yathi kuye: Vuka udle.
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
Wasethalaza, khangela-ke, ekhanda lakhe iqebelengwana losiwe emalahleni, lesigxingi samanzi; wasesidla wanatha, waphinda walala.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Ingilosi yeNkosi yasifika ngokwesibili, yamthinta yathi: Vuka udle; ngoba uhambo lwakho lukhulu kakhulu kuwe.
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
Wasevuka wadla wanatha, wahamba ngamandla alokhokudla insuku ezingamatshumi amane lobusuku obungamatshumi amane, waze wafika eHorebe intaba kaNkulunkulu.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
Wasengena lapho ebhalwini, walala khona ubusuku. Khangela-ke, ilizwi leNkosi lafika kuye lathi kuye: Wenzani lapha, Elija?
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
Wathi: Bengitshiseka lokutshisekela iNkosi, uNkulunkulu wamabandla, ngoba abantwana bakoIsrayeli basitshiyile isivumelwano sakho, badiliza amalathi akho, babulala abaprofethi bakho ngenkemba; yimi ngedwa engiseleyo, njalo badinga impilo yami ukuyisusa.
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
Wasesithi: Phuma ume entabeni phambi kweNkosi. Khangela-ke, iNkosi yadlula. Umoya omkhulu olamandla wasudabula izintaba, waqhekeza amadwala phambi kweNkosi; kodwa iNkosi yayingekho emoyeni. Lemva komoya ukunyikinyeka komhlaba; kodwa iNkosi yayingekho ekunyikinyekeni komhlaba.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
Lemva kokunyikinyeka komhlaba umlilo; kodwa iNkosi yayingekho emlilweni. Njalo emva komlilo ilizwi elincinyane elinyenyezayo.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
Kwasekuthi uElija elizwa, wathandela ubuso bakhe ngesembatho sakhe, waphuma wema emlonyeni wobhalu. Khangela-ke, leza kuye ilizwi lathi: Wenzani lapha, Elija?
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
Wathi: Bengitshisekela lokutshisekela iNkosi, uNkulunkulu wamabandla, ngoba abantwana bakoIsrayeli basitshiyile isivumelwano sakho, badiliza amalathi akho, babulala abaprofethi bakho ngenkemba; yimi ngedwa engiseleyo, njalo badinga impilo yami ukuyisusa.
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
INkosi yasisithi kuye: Hamba, ubuyele ngendlela yakho uye enkangala yeDamaseko; lapho usufikile ugcobe uHazayeli abe yinkosi phezu kweSiriya,
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
loJehu indodana kaNimshi umgcobe abe yinkosi phezu kukaIsrayeli, loElisha indodana kaShafati weAbeli-Mehola umgcobe abe ngumprofethi esikhundleni sakho.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
Kuzakuthi-ke ozaphepha enkembeni kaHazayeli uJehu uzambulala, lozaphepha enkembeni kaJehu uElisha uzambulala.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Kodwa ngitshiyile koIsrayeli abazinkulungwane eziyisikhombisa, wonke amadolo angazanga aguqe kuBhali, lawo wonke umlomo ongazanga umange.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
Wasesuka lapho, wafica uElisha indodana kaShafati; wayelima ngezipani zenkabi zamajogwe alitshumi lambili phambi kwakhe, yena wayelesetshumi lambili. UElija wesesedlula eceleni kwakhe, waphosela isembatho sakhe phezu kwakhe.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Wasetshiya izinkabi, wagijima elandela uElija, wathi: Ake ngange ubaba lomama, besengikulandela. Wasesithi kuye: Hamba ubuyele, ngoba ngenzeni kuwe?
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Wasebuyela ekumlandeleni, wathatha isipani senkabi, wasihlaba, langezikhali zenkabi wapheka inyama yazo, wayinika abantu, bayidla. Wasesuka elandela uElija, wamsebenzela.