< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
Imbaga ni Ahab kenni Jezebel dagiti amin nga inaramid ni Elias, ken no kasano a pinapatayna dagiti amin a profeta ni Baal babaen iti kampilan.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Ket nangibaon ni Jezebel iti mensahero kenni Elias, a kunana, “Patayendak koma dagiti dios ken ad-adda pay iti dakes nga aramidenda kaniak, no saanko nga aramiden ti biagmo a kas iti biag ti maysa kadagidiay a natay a profeta, inton bigat iti kastoy met laeng nga oras.”
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
Idi nangngeg ni Elias dayta, nagrubwat isuna ken naglibas tapno maisalbar ti biagna ket napan idiay Beerseba, a masakupan ti Juda, ket imbatina sadiay ti adipenna.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
Ngem nagmalmalem a nagdaliasat isuna a nagturong idiay let-ang, ket nakadanon ken nagtugaw iti sirok ti kayo nga enebro. Kiniddawna a matay koman isuna, a kunana, “Saanakon a makaibtur, Yahweh, alaemon ti biagko, ta saanak a nasaysayaat ngem kadagiti natayen a kapuonak.”
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
Nagidda ngarud ken naturog isuna iti sirok ti kayo nga enebro; iti saan a ninamnama, maysa nga anghel iti nangsagid kenkuana ket kinunana, “Bumangonka ket manganka.”
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
Kimmita ni Elias, ket iti uloananna adda tinapay a nailuto kadagiti beggang ken sanga-karamba a danum. Isu a nangan ken imminon isuna ket nagidda manen.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Immay manen ti anghel ni Yahweh iti maikadua a gundaway ket sinagidna isuna ket kinunana, “Bumangonka ket manganka, gapu ta narigatto unay ti panagdaliasatmo.”
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
Isu a bimmangon isuna, nangan ken imminom, ket nagdaliasat isuna a nagturong idiay Horeb a bantay ti Dios, iti uppat a pulo nga aldaw ken uppat a pulo a rabii babaen iti pigsa nga impaay dayta a taraon.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
Napan isuna iti maysa a rukib sadiay ken nagtalinaed iti daytoy. Ket immay ti sao ni Yahweh kenkuana ket kinunana, “Ania ti ar-aramidem ditoy, Elias?”
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
Insungbat ni Elias, “Impasnekko ti nagserbi kenni Yahweh a Dios a mannakabalin amin, ta tinallikudan dagiti tattao ti Israel ti tulagmo, dinadaelda dagiti altarmo, ket pinatayda dagiti profetam babaen iti kampilan. Ita, siak laengen ti nabati ket kayatda pay a pukawen ti biagko.”
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
Insungbat ni Yahweh, “Rummuarka ket agtakderka iti bantay iti sangoanak.” Ket limmabas ni Yahweh, ket adda napigsa unay nga angin a nangdungpar kadagiti bantay ken nangburak kadagiti batbato iti sangoanan ni Yahweh, ngem awan ni Yahweh iti angin. Kalpasan ti angin, naggin-gined, ngem awan ni Yahweh iti ginggined.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
Kalpasan ti gingined immay ti apuy, ngem awan ni Yahweh iti apuy. Kalpasan ti apuy, adda immay a naalumamay a timek.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
Idi nangngeg ni Elias ti timek, imbalkotna iti rupana ti kagayna, rimmuar, ken nagtakder iti pagserkan ti rukib. Ket immay ti timek kenkuana a nagkuna, “Ania ti ar-aramidem ditoy, Elias?
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
Insungbat ni Elias, “Impasnekko ti nagserbi kenni Yahweh a Dios a mannakabalin amin, gapu ta tinallikudan dagiti tattao ti Israel ti tulagmo, dinadaelda dagiti altarmo, ket pinapatayda dagiti profetam babaen iti kampilan. Ita, siak laengen ti nabati ket kayatda met a pukawen ti biagko.”
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
Ket kinuna ni Yahweh kenkuana, “Agsublika ket mapanka iti let-ang ti Damasco, ket inton makasangpetka pulotamto ni Hazael nga agbalin nga ari ti Aram,
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
ket pulotamto ni Jehu nga anak ni Nimshi nga agbalin nga ari ti Israel, ket pulotamto ni Eliseo nga anak ni Safat a taga-Abel Mehola nga agbalin a profeta a sumukat kenka.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
Ket mapasamak a papatayento ni Jehu ti siasinoman a makalasat iti kampilan ni Hazael, ken papatayento met ni Eliseo ti siasinoman a makalasat iti kampilan ni Jehu.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Ngem mangibatiak para kaniak iti pito ribu a tattao ti Israel a saan pay a nagparintumeng kenni Baal, ken saan pay a nangagek kenkuana.”
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
Pimmanaw ngarud ni Elias sadiay ket nasarakanna ni Eliseo nga anak ni Safat nga agar-arado, nga addaan kadagiti sangapulo ket dua a paris a naisangol a baka iti sangoananna. Pagar-aradona ti maika sangapulo ket dua. Immasideg ni Elias kenni Eliseo ket inkabilna ti kagayna kenkuana.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Kalpasanna, pinanawan ni Eliseo dagiti baka ket kinamakamna ni Elias; kinunana, “Pangngaasim ta palubosannak a mangagek iti amak ken inak, kalpasanna sumurotak kenka.” Ket kinuna ni Elias kenkuana, “Agsublika, ngem panunotem ti inaramidko kenka.”
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Pimmanaw ngarud ni Eliseo iti ayan ni Elias ket innalana dagiti naisangol a baka, pinartina dagiti ayup, ket inlutona ti karne babaen iti kayo a sangol ti baka; ket intedna daytoy kadagiti tattao, ket nanganda. Ket nagrubuat isuna a simmurot kenni Elias, ket nagserbi kenkuana.

< 1 Kings 19 >