< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
Elmondta Acháb Ízébelnek mindazt, amit Élijáhú cselekedett, meg mindazt, ahogyan megölte mind a prófétákat karddal.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Ekkor követet küldött Ízébel Élijáhúhoz, mondván: Úgy tegyenek velem az istenek és úgy folytassák, bizony holnap ilyenkor olyanná teszem életedet, mint amazok bármelyikének életét.
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
Midőn ezt látta, fölkelt, elment élete kedvéért éa eljutott a Jehúdabeli Beér-Sébába és ott hagyta legényét.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
Ő pedig ment a pusztában egy napnyi úton, odaért és leült egy rekettyebokor alá; halált kívánt a lelkének éa mondta: Elég, most, oh Örökkévaló, vedd el lelkemet, mert nem vagyok én jobb az őseimnél.
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
Ekkor lefeküdt és elaludt egy rekettyebokor alatt; s íme megérintette egy angyal és mondta neki: Kelj föl, egyél!
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
Föltekintett és íme, feje mellett egy parázson sült lepény és egy korsó víz. Evett tehát és ivott és újra lefeküdt.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Másodszor is visszajött az Örökkévaló angyala, megérintette és mondta: Kelj föl, egyél, mert túlságos nagy utad lesz.
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
Fölkelt tehát, evett és ivott, és ment amaz evés erejével negyven nap és negyven éjjel, az Isten hegyéig, a Chórébig.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
Ott bement a barlangba és meghált ott; és íme, az Örökkévaló igéje lett hozzá és mondta neki: Mi dolgod itt, Élijáhú?
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
Mondta: Buzgólkodva buzgólkodtam az Örökkévalóért, a seregek Istenéért, mert elhagyták szövetségedet Izraél fiai, oltáraidat lerombolták és prófétáidat megölték a karddal; én egyedül maradtam meg, de életemre törtek, hogy elvegyék.
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
És mondta: Menj ki, állj a hegyen az Örökkévaló előtt! És íme az Örökkévaló arra vonul: nagy és erős szél, hegyeket bontó és sziklákat tördelő, az Örökkévaló előtt – nem a szélben az Örökkévaló. És a szél után földrengés – nem a földrengésben az Örökkévaló.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
És a földrengés után tűz – nem a tűzben az Örökkévaló. És a tűz után halk suttogás hangja.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
És volt, amint ezt hallotta Élijáhú, eltakarta arcát köpenyével, kiment és odaállt a barlang bejáratára; és íme, hang szólt hozzá és mondta: Mi dolgod itt, Élijáhú?
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
Mondta: Buzgólkodva buzgólkodtam az Örökkévalóért, a seregek Istenéért, mert elhagyták szövetségedet Izraél fiai, oltáraidat lerombolták és prófétáidat megölték a karddal; én egyedül maradtam meg, de életemre törtek, hogy elvegyék.
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
És szólt hozzá az Örökkévaló: Menj, térj vissza utadra, Damaszkusz pusztájába; és oda érvén, kend föl Chazáélt királynak Arám fölé.
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
Jéhút pedig, Nimaí fiát, kend föl királynak Izraél fölé; és Elísát, Sáfát fiát, Ábel-Mechólából, kend föl prófétának a magad helyébe.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
És lészen, aki megmenekül Chazáél kardjától, azt megöli Jéhú és aki megmenekül Jéhú kardjától, azt megöli Elísá.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
És meghagyok Izraélben hétezret: mindazon térdeket, melyek nem hajoltak meg a Báal előtt és mindazon szájat, mely nem csókolta meg.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
Elment onnan és találta Elísát, Sáfát fiát; az éppen szántott, tizenkét pár ökör volt előtte és ő maga a tizenkettedikkel. Átment hozzá Élijáhú és rája vetette a köpenyét.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Erre elhagyta az ökröket, Élijáhu után futott és mondta: hadd csókolom meg, kérlek, atyámat és anyámat, és majd megyek utánad! Mondta neki: Menj, térj vissza, mert mit tettem neked?
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Elment tőle, vette az egy pár ökröt, levágta azt és az ökrök szerszámain megfőzte húsukat, adott a népnek és ettek. Erre fölkelt, ment Élijáhú után és szolgája lett.

< 1 Kings 19 >