< 1 Kings 19 >

1 Ahabu sì sọ gbogbo ohun tí Elijah ti ṣe fún Jesebeli àti bí ó ti fi idà pa gbogbo àwọn wòlíì.
HAI aku la no hoi o Ahaba ia Iezebela i ka mea a pau a Elia i hana'i, a me kona pepehi ana i ka poe kaula me ka pahikaua.
2 Nítorí náà Jesebeli rán oníṣẹ́ kan sí Elijah wí pé, “Kí àwọn òrìṣà kí ó ṣe sí mi àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí èmi kò bá ṣe ẹ̀mí rẹ bí ọ̀kan nínú wọn ní ìwòyí ọ̀la.”
Alaila hoouna ae la o Iezebela i ka elele io Elia la, i ae la, Pela hoi e hana mai ai na akua ia'u, a hui hou no, ke hoohalike ole aku au i kou ola apopo me neia ka hora, me ke ola o kekahi o lakou.
3 Elijah sì bẹ̀rù, ó sá fún ẹ̀mí rẹ̀. Nígbà tí ó sì dé Beerṣeba ti Juda, ó sì fi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sílẹ̀ níbẹ̀,
A ike oia, ku ae la ia iluna, a holo no kona ola, a hiki i Beereseba no Iuda, a haalele i kana kauwa malaila.
4 nígbà tí òun tìkára rẹ̀ sì lọ ní ìrìn ọjọ́ kan sí aginjù, ó sì wá sí ibi igi ọwọ̀ kan, ó sì jókòó lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbàdúrà kí òun bá le kú, wí pé, “Mo ti ní tó, Olúwa, gba ẹ̀mí mi kúrò; nítorí èmi kò sàn ju àwọn baba mi lọ.”
A hele ae la hoi oia, i ka hele ana o kekahi la, iloko ae o ka waonahele, hele hoi a noho iho malalo iho o ka laau iunipera; a nonoi aku la hoi nona iho e make ia; i aku la hoi, Ua nui; ano hoi, e Iehova, e lawe aku i kuu ola nei; no ka mea, aole oi aku ko'u maikai mamua o ko'u mau makua.
5 Nígbà náà ni ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi, ó sì sùn lọ. Sì wò ó, angẹli fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí o jẹun.”
Moe iho la oia a hiamoe ilalo o ka laau iunipera, aia hoi, ilaila, hoopa mai la kahi anela ia ia, i mai la, E ala, e ai.
6 Ó sì wò ó yíká, àkàrà tí a dín lórí ẹ̀yín iná, àti orù-omi wà lẹ́bàá orí rẹ̀. Ó sì jẹ, ó sì mu, ó sì tún dùbúlẹ̀.
Nana ae la hoi ia, aia hoi, kokoke i kona poo, he popopalaoa i hoomoaia maluna o ka lanahu, a he omole wai. Ai iho la ia a inu hoi, a moe hou iho la ilalo.
7 Angẹli Olúwa sì tún padà wá lẹ́ẹ̀kejì, ó sì tún fi ọwọ́ tọ́ ọ, ó sì wí pé, “Dìde, kí ó jẹun, nítorí ìrìnàjò náà jì fún ọ.”
Hele hou mai la ka anela o Iehova, o ka lua ia, a hoopa mai ia ia, i mai la hoi, E ala, e ai, no ka mea, he loihi ka hele ana nou.
8 Ó si dìde, ó sì jẹ, ó mu, o sì fi agbára oúnjẹ yìí lọ ní ogójì ọ̀sán àti ogójì òru sí Horebu, òkè Ọlọ́run.
Ala ae la ia, a ai iho la, a inu no hoi, a ma ka ikaika no ua ai la, i hele ai oia i na la he kanaha, a i na po he kanaha, i Horeba, ka mauna o ke Akua.
9 Níbẹ̀, ó lọ sí ibi ihò òkúta, ó sì wọ̀ níbẹ̀. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín yìí, Elijah?”
Hiki aku la ia ilaila i ke ana, noho ae la hoi ilaila; aia hoi ka olelo a Iehova ia ia, i mai la hoi oia ia ia, He aha la kau e hana nei maanei, e Elia?
10 Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi láti gbà á kúrò báyìí.”
I aku la hoi ia, Ua ikaika loa ae nei au mamuli o Iehova ke Akua o ko ka lani; no ka mea, ua haalele no na mamo a Iseraela i kau berita, ua hoohiolo hoi i kou mau kuahu, a ua pepehi no hoi i kou poe kaula me ka pahikaua: a owau wale no ka i koe mai, a ua imi mai lakou i ko'u ola e lawe aku.
11 Olúwa sì wí pé, “Jáde lọ, kí o sì dúró lórí òkè níwájú Olúwa, nítorí Olúwa fẹ́ rékọjá.” Nígbà náà ni ìjì ńlá àti líle sì fa àwọn òkè ńlá ya, ó sì fọ́ àwọn àpáta túútúú níwájú Olúwa; ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìjì náà. Lẹ́yìn ìjì náà ni ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà.
I mai la hoi oia, E puka'e, a e ku maluna o ka mauna imua o Iehova. Aia hoi, maalo ae la o Iehova, a haehae ae la ka makani nui ikaika i na mauna, a wawahi ae la i na pohaku imua o Iehova; aole nae o Iehova iloko o ka makani: a mahope iho o ka makani, he olai; aole nae o Iehova iloko o ke olai.
12 Lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀-ìrilẹ̀ náà ni iná wá, ṣùgbọ́n Olúwa kò sí nínú iná náà. Àti lẹ́yìn iná náà ni ohùn kẹ́lẹ́ kékeré wá.
A mahope iho o ke olai, he ahi; aole nae o Iehova iloko o ke ahi; a mahope iho o ke ahi, he kamumu o ke aheahe malie.
13 Nígbà tí Elijah sì gbọ́ ọ, ó sì fi agbádá rẹ̀ bo ojú rẹ̀, ó sì jáde lọ, ó dúró ní ẹnu ihò òkúta náà. Nígbà náà ni ohùn kan tọ̀ ọ́ wá wí pé, “Kí ni ìwọ ń ṣe níhìn-ín, Elijah?”
Eia kekahi, a lohe o Elia, uhi ae la oia i kona maka i kona aahu, a puka ae la oia a ku ma ke komo ana o ke ana. Aia hoi, he leo ia ia, i mai la hoi ia, O ke aha la kau e hana nei maanei, e Elia?
14 Ó sì dáhùn pé, “Èmi ti ń jowú fún Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun. Àwọn ọmọ Israẹli ti kọ májẹ̀mú rẹ sílẹ̀, wọ́n sì ti wó pẹpẹ rẹ lulẹ̀, wọ́n sì ti fi idà pa àwọn wòlíì rẹ. Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù, wọ́n sì ń gbìyànjú láti pa èmi náà báyìí.”
I aku la hoi oia, Ua ikaika loa ae nei au mamuli o Iehova ke Akua o ko ka lani; no ka mea, ua haalele no na mamo a Iseraela i kau berita, ua hoohiolo hoi i kou mau kuahu, a ua pepehi no hoi i kou poe kaula me ka pahikaua; a owau wale no ka i koe mai, a ua imi mai lakou i ko'u ola e lawe aku.
15 Olúwa sì wí fún un pé, “Padà lọ sí ọ̀nà tí ìwọ ti wá, kí o sì lọ sí aginjù Damasku. Nígbà tí ìwọ bá dé ibẹ̀, fi òróró yan Hasaeli ní ọba lórí Aramu.
I mai la hoi o Iehova ia ia, E hele, e hoi ma kou aoao i ka waonahele o Damaseko; a hiki aku oe, e poni aku ia Hazaela i alii maluna o Suria;
16 Tún fi òróró yan Jehu ọmọ Nimṣi ní ọba lórí Israẹli, àti kí o fi òróró yan Eliṣa ọmọ Ṣafati, ará Abeli-Mehola ní wòlíì ní ipò rẹ.
A o Iehu ke keiki a Nimesi kau e poni ai i alii maluna o ka Iseraela; o Elisai ke keiki a Sapata no Abelamehola kau e poni ai i kaula ma kou hakahaka.
17 Jehu yóò pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Hasaeli, Eliṣa yóò sì pa ẹni tí ó bá sálà kúrò lọ́wọ́ idà Jehu.
Eia auanei keia, o ka mea pakele i ka pahikaua a Hazela, oia ka Iehu e pepehi ai; a o ka mea pakele i ka pahikaua a Iehu, oia ka Elisai e pepehi ai.
18 Síbẹ̀, èmi ti pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn mọ́ fún ara mi ní Israẹli, àní gbogbo eékún tí kò ì tí ì kúnlẹ̀ fún òrìṣà Baali, àti gbogbo ẹnu tí kò ì tí ì fi ẹnu kò ó ní ẹnu.”
Aka, Ke hookoe nei au i na tausani ehiku iloko o ka Iseraela, i na kuli a pau i kukuli ole ia Baala, a me na waha a pau i honi ole ia ia.
19 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ kúrò níbẹ̀, ó sì rí Eliṣa ọmọ Ṣafati. Ó ń fi àjàgà màlúù méjìlá tulẹ̀ níwájú rẹ̀, àti òun náà níwájú èkejìlá. Elijah sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì da agbádá rẹ̀ bò ó.
Hele aku la hoi oia mai laila aku, a loaa ia ia o Elisai ke keiki a Sapata, e oopalau ana ia, o na paa bipi kauo he umikumamalua mamua ona, a oia me ka umikumamalua; a maalo ae o Elia ia ia, a kau ae hoi i kona aahu maluna ona.
20 Nígbà náà ni Eliṣa sì fi àwọn màlúù sílẹ̀, ó sì sáré tọ Elijah lẹ́yìn. Ó wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, jẹ́ kí èmi lọ fi ẹnu ko baba àti ìyá mi ní ẹnu. Nígbà náà ni èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Elijah sì dáhùn wí pé, “Padà sẹ́yìn, kí ni mo fi ṣe ọ́?”
Haalele ae la hoi oia i na bipi kauo, a hahai aku la mamuli o Elia, i aku la, Ke noi aku nei au e honi au i ko'u makuakane, a me kuu makuwahine, alaila e hahai au mamuli ou. I mai la hoi oia ia ia, E hoi aku, no ka mea, o ke aha la ka'u i hana aku ai ia oe?
21 Eliṣa sì fi í sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn. Ó sì mú àjàgà màlúù rẹ, ó sì pa wọ́n. Ó sì fi ohun èlò àwọn màlúù náà bọ́ ẹran wọn, ó sì fi fún àwọn ènìyàn, wọ́n sì jẹ. Nígbà náà ni ó sì dìde láti tọ Elijah lẹ́yìn, ó sì ṣe ìránṣẹ́ fún un.
Hoi hou aku la oia mai ona aku la, a lalau iho la i kekahi paa bipi kauo, a pepehi loa ia, a baila ae la i ko laua io me na mea haua o ka bipi, a haawi ae na na kanaka, a ai iho la lakou. Alaila, ku ae la oia iluna, a hahai aku la mamuli o Elia, a lawelawe ae la nana.

< 1 Kings 19 >