< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
Uzun waⱪit ɵtüp, Pǝrwǝrdigarning sɵzi [ⱪurƣaⱪqiliⱪning] üqinqi yilida Iliyasⱪa kelip: — Sǝn berip ɵzüngni Aⱨabning aldida ayan ⱪilƣin, wǝ Mǝn yǝr yüzigǝ yamƣur yaƣdurimǝn, deyildi.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
Xuning bilǝn Iliyas ɵzini Aⱨabning aldida ayan ⱪilƣili qiⱪip kǝtti. Aqarqiliⱪ bolsa Samariyǝdǝ ⱪattiⱪ idi.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
Aⱨab ordisidiki ƣojidar Obadiyani qaⱪirdi (Obadiya tolimu tǝⱪwadar kixi bolup Pǝrwǝrdigardin intayin ⱪorⱪatti.
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
Yizǝbǝl Pǝrwǝrdigarning pǝyƣǝmbǝrlirini ɵltürüp yoⱪitiwatⱪanda Obadiya yüz pǝyƣǝmbǝrni elip ǝlliktin-ǝlliktin ayrim-ayrim ikki ƣarƣa yoxurup, ularni nan wǝ su bilǝn baⱪⱪanidi).
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
Aⱨab Obadiyaƣa: — Zeminni kezip ⱨǝmmǝ bulaⱪ wǝ ⱨǝmmǝ jilƣilarƣa berip baⱪⱪin; u yǝrlǝrdǝ at-ⱪeqirlarni tirik saⱪliƣudǝk ot-qɵp tepilarmikin? Xundaⱪ bolsa bizning ulaƣlirimizning bir ⱪismini soymay turalarmiz, dedi.
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
Ular ⱨǝrbiri jaylarƣa bɵlünüp mangdi; Aⱨab ɵz aldiƣa mangdi, Obadiyamu ɵz aldiƣa mangdi.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
Obadiya ɵz yolida ketip barƣanda, mana, uningƣa Iliyas uqridi. U uni tonup yǝrgǝ yiⱪilip düm yetip: Bu rast sǝn, ƣojam Iliyasmu? — dǝp soridi.
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
U uningƣa: — Bu mǝn. Berip ɵz ƣojangƣa: — Iliyas ⱪaytip kǝldi! dǝp eytⱪin, dedi.
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
U Iliyasⱪa mundaⱪ dedi: — «Sǝn ⱪandaⱪsigǝ kǝminǝngni ɵltürgili Aⱨabning ⱪoliƣa tapxurmaⱪqi bolisǝn, mǝn zadi nemǝ gunaⱨ ⱪildim?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
Ɵz Hudaying Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, ƣojam adǝm ǝwǝtip seni izdimigǝn ⱨeq ǝl wǝ mǝmlikǝt ⱪalmidi. Xu ǝl, mǝmlikǝtlǝr: «U bu yǝrdǝ yoⱪ» desǝ, padixaⱨ ularƣa seni tapalmiƣanƣa ⱪǝsǝm iqküzdi.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
Lekin sǝn manga ⱨazir: — «Berip ƣojangƣa: — Iliyas ⱪaytip kǝldi! degin» — dǝysǝn!
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
Mǝn ⱪexingdin kǝtkǝndin keyin, Pǝrwǝrdigarning Roⱨi seni mǝn bilmigǝn yǝrgǝ elip baridu; xundaⱪta mǝn Aⱨabⱪa hǝwǝr yǝtküzüp, lekin u seni tapalmisa, meni ɵltüridu. Əmǝliyǝttǝ, kǝminǝng yaxliⱪimdin tartip Pǝrwǝrdigardin ⱪorⱪup kǝlgǝnmǝn.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
Yizǝbǝl Pǝrwǝrdigarning pǝyƣǝmbǝrlirini ɵltürgǝndǝ mening ⱪandaⱪ ⱪilƣinim, yǝni mǝn Pǝrwǝrdigarning pǝyƣǝmbǝrliridin yüzni ǝlliktin-ǝlliktin ayrim-ayrim ikki ƣarƣa yoxurup, ularni nan wǝ su bilǝn tǝminlǝp baⱪⱪanliⱪim sǝn ƣojamƣa mǝlum ⱪilinƣan ǝmǝsmu?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
Əmdi sǝn ⱨazir manga: — «Berip ƣojangƣa: — Mana Iliyas kǝldi degin», — deding. Xundaⱪ ⱪilsam u meni ɵltüridu!».
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
Lekin Iliyas: — Mǝn hizmitidǝ turuwatⱪan samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigarning ⱨayati bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, mǝn jǝzmǝn bügün uning aldida ayan bolimǝn, dedi.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
Xuning bilǝn Obadiya Aⱨabning ⱪexiƣa berip uningƣa hǝwǝr bǝrdi. Aⱨab Iliyas bilǝn kɵrüxkili bardi.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
Aⱨab Iliyasni kɵrgǝndǝ uningƣa: — Bu sǝnmu, i Israilƣa bala kǝltürgüqi?! — dedi.
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
U jawab berip: — Israilƣa bala kǝltürgüqi mǝn ǝmǝs, bǝlki sǝn bilǝn atangning jǝmǝtidikilǝr! Qünki silǝr Pǝrwǝrdigarning ǝmrlirini taxlap Baal degǝn butlarƣa tayinip ǝgǝxkǝnsilǝr.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
Əmdi adǝm ǝwǝtip Karmǝl teƣida pütkül Israilni yenimƣa jǝm ⱪil, xundaⱪla Yizǝbǝlning dastihinidin ƣizalinidiƣan Baalning tɵt yüz ǝllik pǝyƣǝmbiri bilǝn Axǝraⱨning tɵt yüz pǝyƣǝmbirini yiƣdur, — dedi.
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
Xuning bilǝn Aⱨab Israillarning ⱨǝmmisigǝ adǝmlǝrni ǝwǝtip, pǝyƣǝmbǝrlǝrni Karmǝl teƣiƣa yiƣdurdi.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
Iliyas barliⱪ hǝlⱪⱪǝ yeⱪin kelip: — Ⱪaqanƣiqǝ ikki pikir arisida arisaldi turisilǝr? Əgǝr Pǝrwǝrdigar Huda bolsa, uningƣa ǝgixinglar; Baal Huda bolsa, uningƣa ǝgixinglar, dedi. Əmma hǝlⱪ uningƣa jawab bǝrmǝy, ün-tin qiⱪarmidi.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
Iliyas hǝlⱪⱪǝ: — Pǝrwǝrdigarning pǝyƣǝmbǝrliridin pǝⱪǝt mǝn yalƣuz ⱪaldim. Əmma Baalning pǝyƣǝmbǝrliri tɵt yüz ǝllik kixidur.
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
Əmdi bizgǝ ikki buⱪa berilsun. Ular ɵzlirigǝ bir buⱪini tallap, soyup parqilap otunning üstigǝ ⱪoysun, ǝmma ot yaⱪmisun. Mǝnmu baxⱪa bir buⱪini tǝyyar ⱪilip ot yaⱪmay otunning üstigǝ ⱪoyay.
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
Silǝr bolsanglar, ɵz ilaⱨliringlarning namini qaⱪirip nida ⱪilinglar. Mǝn bolsam, Pǝrwǝrdigarning namini qaⱪirip nida ⱪilimǝn. Ⱪaysi Huda ot bilǝn jawab bǝrsǝ, xu Huda bolsun, dedi. Ⱨǝmmǝ hǝlⱪ: — Bu obdan gǝp, dǝp jawab bǝrdi.
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
Iliyas Baalning pǝyƣǝmbǝrlirigǝ: Silǝr kɵp bolƣaq awwal ɵzünglar üqün bir buⱪini tallap tǝyyar ⱪilinglar; andin ⱨeq ot yaⱪmay ɵz ilaⱨinglarning namini ⱪiqⱪirip nida ⱪilinglar, dedi.
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
Ular uning degini boyiqǝ ɵzlirigǝ berilgǝn buⱪini elip uni tǝyyar ⱪildi. Ətigǝndin qüxkiqǝ ular Baalning namini ⱪiqⱪirip: — I Baal, bizgǝ jawab bǝrgin! dǝp nida ⱪildi. Lekin ⱨeq awaz yaki ⱨeq jawab bolmidi. Ular raslanƣan ⱪurbangaⱨ qɵrisidǝ tohtimay sǝkrǝytti.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
Qüx kirgǝndǝ Iliyas ularni zangliⱪ ⱪilip: — Ünlükrǝk ⱪiqⱪiringlar; qünki u bir ilaⱨ ǝmǝsmu? Bǝlkim u qongⱪur hiyalƣa qɵmüp kǝtkǝndu, yaki ix bilǝn qiⱪip kǝtkǝndu, yaki bir sǝpǝrgǝ qiⱪip kǝtkǝndu? Yaki bolmisa u uhlawatⱪan boluxi mumkin, uni oyƣitixinglar kerǝk?! — dedi.
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
Ular tehimu ünlük qaⱪirip ɵz ⱪaidisi boyiqǝ ⱪanƣa milinip kǝtküqǝ ɵzlirini ⱪiliq wǝ nǝyzǝ bilǝn tilatti.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
Qüxtin keyin ular «bexarǝt beriwatⱪan» ⱨalǝtkǝ qüxüp kǝqlik ⱪurbanliⱪ waⱪtiƣiqǝ xu ⱨalǝttǝ turdi. Lekin ⱨeq awaz anglanmidi, yaki jawab bǝrgüqi yaki ijabǝt ⱪilƣuqi mǝlum bolmidi.
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
Iliyas ⱨǝmmǝ hǝlⱪⱪǝ: — Yenimƣa yeⱪin kelinglar, dedi. Ⱨǝmmǝ hǝlⱪ uningƣa yeⱪin kǝlgǝndin keyin u Pǝrwǝrdigarning xu yǝrdiki yiⱪitilƣan ⱪurbangaⱨini ⱪaytidin ⱪurup qiⱪti.
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
Iliyas on ikki taxni aldi. Bu taxlarning sani Pǝrwǝrdigarning «Naming Israil bolsun» degǝn sɵzini tapxuruwalƣan Yaⱪupning oƣulliridin qiⱪⱪan ⱪǝbililǝrning sani bilǝn ohxax idi.
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
Xu taxlardin u Pǝrwǝrdigarning nami bilǝn bir ⱪurbangaⱨni yasidi. U ⱪurbangaⱨning qɵrisidǝ ikki seaⱨ dan patⱪudǝk azgal kolidi.
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
Andin u otunni rastlap, buⱪini parqilap otunning tɵpisigǝ ⱪoydi.
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
U: — Tɵt idixni suƣa toxⱪuzup uni kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ wǝ otunning üstigǝ tɵkünglar, — dedi. Andin: Yǝnǝ bir ⱪetim ⱪilinglar» — dewidi, ular xundaⱪ ⱪildi. U yǝnǝ: — Üqinqi mǝrtiwǝ xundaⱪ ⱪilinglar, dedi. Ular üqinqi mǝrtiwǝ xundaⱪ ⱪilƣanda
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
su ⱪurbangaⱨning qɵrisidin eⱪip qüxüp, kolanƣan azgalnimu su bilǝn toldurdi.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
Kǝqlik ⱪurbanliⱪning waⱪti kǝlgǝndǝ Iliyas pǝyƣǝmbǝr ⱪurbanliⱪⱪa yeⱪin kelip mundaⱪ dua ⱪildi: — Əy Pǝrwǝrdigar, Ibraⱨim bilǝn Isⱨaⱪ wǝ Israilning Hudasi, Ɵzüngning Israilda Huda bolƣiningni axkara ⱪilƣaysǝn, xundaⱪla mening Sening ⱪulung bolup bularning ⱨǝmmisini buyruⱪung bilǝn ⱪilƣanliⱪimni bügün bildürgǝysǝn.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Manga ijabǝt ⱪilƣaysǝn, ǝy Pǝrwǝrdigar, ijabǝt ⱪilƣaysǝn; xuning bilǝn bu hǝlⱪⱪǝ sǝn Pǝrwǝrdigarning Huda ikǝnlikingni ⱨǝmdǝ ularning ⱪǝlblirini toƣra yolƣa yandurƣuqi ɵzüng ikǝnlikingni bildürgǝysǝn, dedi.
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigarning oti qüxüp kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪni, otunni, taxlarni wǝ topini kɵydürüp azgaldiki sunimu yoⱪitiwǝtti.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
Hǝlⱪlǝrning ⱨǝmmisi buni kɵrüpla, ular düm yiⱪilip: — Pǝrwǝrdigar, u Hudadur, Pǝrwǝrdigar, u Hudadur, deyixti.
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
Iliyas hǝlⱪⱪǝ buyrup: — Baalning pǝyƣǝmbǝrlirini tutunglar, ⱨeqⱪaysini ⱪoyup bǝrmǝnglar, — dedi. Ular ularni tutⱪanda Iliyas ularni kixun jilƣisiƣa elip berip, u yǝrdǝ ⱪǝtl ⱪildurdi.
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
Iliyas Aⱨabⱪa bolsa: — Qiⱪip yǝp-iqkin. Qünki ⱪattiⱪ yamƣurning xaldirliƣan awazi anglanmaⱪta, — dedi.
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
Aⱨab ⱪopup yǝp-iqix üqün qiⱪti. Əmma Iliyas Karmǝlning qoⱪⱪisiƣa qiⱪip yǝrgǝ engixip, bexini tizining otturisiƣa ⱪoyup tizlinip
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
hizmǝtkariƣa: — Qiⱪip dengiz tǝrǝpkǝ ⱪariƣin, dedi. U qiⱪip sǝpselip ⱪarap: — Ⱨeqnǝrsǝ kɵrünmǝydu, dedi. U jǝmiy yǝttǝ ⱪetim: — Berip ⱪarap baⱪⱪin, dǝp buyrudi.
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
Yǝttinqi ⱪetim kǝlgǝndǝ u: — Mana, dengizdin qiⱪiwatⱪan, adǝm aliⱪinidǝk kiqik bir bulutni kɵrdum — dedi. Iliyas uningƣa: — Qiⱪip Aⱨabⱪa: — «Ⱨarwini ⱪetip tɵwǝngǝ qüxkin, bolmisa yamƣur seni tosuwalidu», dǝp eytⱪin, — dedi.
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
Angƣuqǝ asman bulut bilǝn tutulup, boran qiⱪip ⱪattiⱪ bir yamƣur yaƣdi. Aⱨab ⱨarwiƣa qiⱪip Yizrǝǝlgǝ kǝtti.
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
Pǝrwǝrdigarning ⱪoli Iliyasning wujudida turƣaq, u belini baƣlap Aⱨabning aldida Yizrǝǝlning kirix eƣiziƣiqǝ yügürüp mangdi.

< 1 Kings 18 >