< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
І минуло багато днів, і було Господнє слово до Іллі третього року, говорячи: „Іди, покажися до Аха́ва, а Я дам дощ на поверхню землі“.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
І пішов Ілля показатися до Ахава. А в Асирії був сильний голод.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
І покликав Ахав Овді́я, що був над домом, а Овді́й був дуже богобі́йний.
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
І сталося, коли Єзаве́ль вигу́блювала Господніх пророків, то Овді́й узяв сотню пророків, та й сховав їх по п'ятидесяти чоловіка в пече́рі, і годува́в їх хлібом та водою.
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
І сказав Ахав до Овдія: „Іди по кра́ю до всіх во́дних джере́л та до всіх потоків, — може зна́йдемо трави, і позоста́вимо при житті коня та мула, і не ви́губимо худоби“...
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
І поділили вони собі Край, щоб перейти по ньому, — Ахав пішов однією дорогою сам, Овді́й пішов сам другою дорогою.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
І був Овдій у дорозі, аж ось Ілля назу́стріч йому́. І пізнав він його, і впав на обличчя своє та й сказав: „Чи то ти, пане мій Іллє́?“
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
А той відказав йому: „Я. Іди, скажи панові своєму: Ось тут Ілля!“
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
А він сказав: „Чим я прогрішив, що ти віддаєш свого раба в Ахавову руку, щоб він убив мене?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
Як живий Господь, Бог твій, — немає наро́ду та царства, що туди не посилав би пан мій шукати тебе. А коли говорили: Нема його, то він заприсяга́в те царство та той народ, що зна́йдуть тебе.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
А тепер ти говориш: Іди, скажи своє́му панові: Ось тут Ілля!
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
І станеться, я піду́ від тебе, а Дух Господній понесе тебе на те місце, якого не знаю. І прийду́ я, щоб доне́сти Ахаву, а коли він не зна́йде тебе, то вб'є мене. А раб твій боїться Господа від своєї мо́лодости.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
Чи ж не було сказано панові моєму те, що́ зробив я, коли Єзаве́ль побивала Господніх пророків, а я сховав був із Господніх пророків сотню чоловіка, по п'ятидесяти чоловіка в печері, і годував їх хлібом та водою?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
А тепер ти кажеш: Іди, скажи своєму панові: Ось тут Ілля, — і він мене вб'є!“
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
Та Ілля відказав: „ Як живий Господь Савао́т, що я стою́ перед Його лицем, — сьогодні я покажу́ся йому!“
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
I пішов Овді́й назу́стріч Аха́ву, та й доніс йому те. І пішов Ахав навпро́ти Іллі.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
І сталося, коли Ахав побачив Іллю, то Ахав сказав до нього: „Чи це ти, що непоко́їш Ізраїля?“
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
А той відказав: „Не я внещасли́вив Ізраїля, а тільки ти та дім твого батька через ваше недотри́мання Господніх за́повідей, та й ти пішов за Ваалами.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
А тепер пошли, збери до мене на го́ру Карме́л усього Ізраїля та чотири сотні й п'ятдесят Ваалових пророків, та чотири сотні пророків Астарти, що їдять зо сто́лу Єзаве́лі“.
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
І послав Ахав по всіх Ізраїлевих синах, і зібрав пророків на го́ру Карме́л.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
І підійшов Ілля до всьо́го наро́ду й сказав: „Чи довго ви бу́дете скака́ти на двох галу́зках? Якщо Господь — Бог, ідіть за Ним, а якщо Ваал — ідіть за ним!“Та не відповів йому народ ані слова.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
І сказав Ілля до наро́ду: „Я сам позоста́вся Господній пророк, а пророків Ваалових — чотири сотні й п'ятдесят чоловіка.
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
І нехай дадуть нам двох бичкі́в, і нехай вони ви́беруть собі одно́го бичка́, і нехай заріжуть його, і нехай покладуть на дро́ва, а огню́ не покладу́ть. І я приготу́ю одного бичка́, і дам на дро́ва, а огню не покладу́.
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
І ви покличете ім'я́ бога вашого, а я покли́чу Ім'я́ Господа. І станеться, той Вог, що відповість огнем, — Він Бог!“І відповів той наро́д та й сказав: „Це добре слово!“
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
І сказав Ілля до Ваалових пророків: „Виберіть собі одно́го бичка́, і приготу́йте перші, бо ви численні́ші, і покличте ім'я́ свого́ бога, а огню́ не покладете“.
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
І взяли́ вони того бичка, що він дав їм, і вони приготува́ли й кли́кали Ваалове ім'я́ від ра́нку й аж до полу́дня, говорячи: „Ваа́ле, почу́й нас!“Та не було ані голосу, ані ві́дповіді. І скакали вони біля же́ртівника, що зроби́ли.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
І сталося опі́вдні, і сміявся з них Ілля й говорив: „Кличте голосом сильні́шим, бо він бог! Може він розду́мує, або відлучи́вся, або в дорозі! Може він спить, то проки́неться!“
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
І стали вони кликати голосом сильні́шим, і коло́лися, за своїм зви́чаєм, меча́ми та ра́тищами, аж лила́ся з них кров.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
І сталося, як минувся пі́вдень, то вони пророкували аж до часу прине́сення хлібної жертви, — та не було́ ані голосу, ані відповіді, ані слуху...
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
І сказав Ілля до всього наро́ду: „Підійдіть до ме́не!“І підійшов увесь наро́д до нього, а він поправив розбитого Господнього же́ртівника.
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
І взяв Ілля дванадцятеро каміння, за числом племе́н синів Якова, до якого було слово Господнє, говорячи: „Ізра́їль буде їм'я́ твоє!“
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
і збудува́в із того камі́ння же́ртівника в Ім'я́ Господнє, і зробив рова, площею на дві са́ті насіння, навколо же́ртівника.
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
І наклав дров, і зарізав бичка та й поклав на дро́вах.
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
І він сказав: „Напо́вніть чотири відрі́ води, і нехай виллють на цілопа́лення та на дро́ва“. І сказав: „Повторіть!“І повтори́ли. І сказав: „Зробіть утре́тє!“І зробили втре́тє.
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
І потекла вода навколо же́ртівника, а також рів напо́внився водою.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
І сталося в час прине́сення хлі́бної жертви, що підійшов пророк Ілля та й сказав: „Господи, Боже Авраамів, Ісаків та Ізраїлів! Сьогодні пізна́ють, що Ти Ізраїлів Бог, а я Твій раб, і що все оце я зробив Твоїм словом.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Вислухай мене, Господи, вислухай мене, і нехай пізна́є цей наро́д, що Ти — Господь, Бог, і Ти обе́рнеш їхнє серце наза́д!“
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
І спав Господній огонь, та й поже́р цілопа́лення, і дро́ва, і камі́ння, і по́рох, і ви́лизав воду, що в рові.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
І побачили це всі люди, та й попа́дали на обличчя свої й говорили: „Господь, — Він Бог, Господь, — Він Бог!“
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
І сказав до них Ілля: „Схопі́ть Ваалових пророків! Нехай ніхто не втече́ з них!“І похапа́ли їх, а Ілля звів їх до потоку Кішо́н, та й порізав їх...
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
І сказав Ілля до Ахава: „Увійди, їж і пий, бо ось чути шум дощу́“.
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
І пішов Ахав, щоб їсти та нити, а Ілля зійшов на верхі́в'я Карме́лу, і нахили́вся до землі, і поклав обличчя своє між свої колі́на.
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
І сказав він до свого хло́пця: „Вийди, подивися в на́прямі моря!“І той вийшов і подивився та й сказав: „Нема нічо́го“. Та він відказав: „Вернися сім раз!“
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
І сталося сьомого разу, і він сказав: „Ось мала хмара, немов долоня лю́дська, підійма́ється з моря“. А він сказав: „Піди, скажи Ахавові: Запрягай і зійди, і не затримає тебе дощ“.
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
І сталося по недовгому ча́сі, і поте́мніло небо від хмар, і зірвався вітер, — і пішов великий дощ. А Ахав сів на воза, та й відправився в Їзреел.
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
А Господня рука була́ на Іллі. І він опереза́в свої сте́гна, та й побіг перед Ахавом аж до самого Їзреелу.

< 1 Kings 18 >