< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
Efter en lång tid kom Herrans ord till Elia, i tredje årena, och sade: Gack bort, och te dig för Achab, att jag må låta regna på jordena.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
Och Elia gick åstad, och tedde sig för Achab; men en ganska hård tid var i Samarien.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
Och Achab kallade Obadja sin hofmästare. Och Obadja fruktade Herran storliga;
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
Förty då Isebel utrotade Herrans Propheter, tog Obadja hundrade Propheter, och gömde dem i kulor, femtio här, och femtio der; och försörjde dem med bröd och vatten.
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
Så sade nu Achab till Obadja: Drag igenom landet till alla vattubrunnar och bäcker, att vi måtte finna gräs, och behålla hästar och mular, så att boskapen icke all förgås.
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
Och de delade sig i landet, så att de drogo det igenom. Achab drog allena på en väg, och Obadja desslikes allena på den andra vägen.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
Då nu Obadja var på vägenom, si, då mötte honom Elia. Och som han kände honom, föll han uppå sitt anlete, och sade: Äst du icke min herre Elia?
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
Han sade: Ja; gack och säg dinom herra: Si, Elia är här.
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
Han sade: Hvad hafver jag syndat, att du vill gifva din tjenare i Achabs händer, att han skall dräpa mig?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
Så sant som Herren din Gud lefver, det är intet folk eller Konungarike, dit min herre icke sändt hafver till att söka dig, och när de hafva sagt: Han är icke här, hafver han tagit en ed af det riket och folket, att man icke hade funnit dig.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
Och du säger nu: Gack och säg dinom herra: Si, Elia är här.
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
När jag nu ginge ifrå dig, så toge Herrans Ande dig bort, jag vet icke hvart; och jag komme då och underviste det Achab, och funne dig icke, så sloge han mig ihjäl; men jag din tjenare fruktar Herran af minom ungdom.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
Är minom herra icke undervist, hvad jag gjort hafver, då Isebel drap Herrans Propheter? att jag gömde hundrade Herrans Propheter, femtio här, och femtio der, uti kulor; och försörjde dem med bröd och vatten?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
Och nu säger du: Gack bort, och säg dinom herra: Elia är här; att han må dräpa mig.
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
Elia sade: Så sant som Herren Zebaoth lefver, för hvilkom jag står, i dag skall jag te mig för honom.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
Då gick Obadja emot Achab, och sade honom detta. Och Achab gick emot Elia.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
Och då Achab såg Elia, sade Achab till honom: Äst du den som förvillar Israel?
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
Han sade: Jag förvillar icke Israel, utan du och dins faders hus, dermed att I Herrans bud öfvergifvit hafven, och vandren efter Baalim.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
Nu väl, så sänd nu bort, och församla mig hela Israel på Carmels berg; och fyrahundrad och femtio Baals Propheter, och de fyrahundrad lundarnas Propheter, som äta vid Isebels bord.
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
Alltså sände Achab bort ibland all Israels barn, och församlade Propheterna på Carmels berg.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
Då gick Elia fram för allt folket, och sade: Huru länge halten I på båda sidor? Är Herren Gud, så vandrer efter honom; men är Baal det, så vandrer efter honom. Och folket svarade honom intet.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
Då sade Elia till folket: Jag allena är qvar blifven, en Herrans Prophet; men Baals Propheter äro fyrahundrade och femtio män,
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
Så får oss nu två stutar, och låter dem utvälja en stuten och stycka honom, och lägga honom på ved; men låte ingen eld komma dertill; så vill jag taga den andra stuten, och lägga honom på ved, och ej heller låta der någon eld till.
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
Så åkaller I edars guds namn, och jag vill åkalla Herrans Namn; hvilken Gud, som nu svarar med elden, han vare Gud. Och hela folket svarade och sade: Det är rätt.
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
Och Elia sade till Baals Propheter: Utväljer eder en stuten, och görer I först; förty I ären månge; och åkaller edars guds namn, och låter ingen eld dertill.
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
Och de togo stuten, som han fick dem, och redde till, och åkallade Baals namn, ifrå morgonen allt intill middag, och sade: Baal, hör oss. Men der var ingen röst eller svar. Och de sprungo om altaret, såsom deras seder var.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
Då nu middag var, bespottade dem Elia, och sade: Roper högt; ty han är en gud; han begrundar, eller hafver något beställa, eller är ute på markene, eller sofver tilläfventyrs, att han måtte vaka upp.
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
Och de ropade högt, och riste sig med knifvar, och med prener, efter deras sed, så att blodet gick der ut efter.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
Då nu middagen förgången var, propheterade de, intilldess man skulle göra spisoffer; och der var dock ingen röst, eller svar, eller tillhörare.
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
Då sade Elia till allt folket: Kommer hit till mig. Och då allt folket gick fram till honom, botade han Herrans altare, som nederslaget var;
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
Och tog tolf stenar, efter talet på Jacobs barnas slägter, till hvilken Herrans ord talade, och sade: Du skall heta Israel;
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
Och byggde af de stenar ett altare i Herrans Namn, och gjorde ena graf kringom altaret, tu kornmått vid;
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
Och redde till veden, och styckade stuten, och lade honom på veden;
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
Och sade: Hemter fyra sår fulla med vatten, och gjuter det på bränneoffret och uppå veden; och sade: Görer det än en tid. Och de gjorde det än en tid. Och han sade: Görer det än tredje reson. Och de gjorde det i tredje reson.
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
Och vattnet lopp om altaret, och grafven vardt också full med vatten.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
Och som tid var till att offra spisoffer, gick Propheten Elia fram, och sade: Herre, Abrahams Gud, Isaacs, och Israels, låt i denna dag kunnigt varda, att du äst Gud i Israel, och jag din tjenare, och att jag allt detta efter ditt ord gjort hafver.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Hör mig, Herre, hör mig, att detta folket må veta att du, Herre, äst Gud; att du sedan må omvända deras hjerta.
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
Då föll Herrans eld neder, och uppbrände bränneoffret, veden, stenar och jord, och uppslekte vattnet i grafvene.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
Då allt folket såg det; föll det på sitt ansigte, och sade: Herren är Gud, Herren är Gud.
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
Men Elia sade till dem: Tager fatt på Baals Propheter, att icke en af dem undslipper. Och de togo fatt på dem; och Elia förde dem neder till den bäcken Kison, och drap dem der.
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
Och Elia sade till Achab: Drag upp, ät och drick; förty det dånar, såsom det ville komma ett stort regn.
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
Och då Achab drog upp till att äta och dricka, gick Elia upp på kullen af Carmel, och böjde sig neder till jordena, och satte sitt hufvud emellan sin knä;
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
Och talade till sin dräng: Gack ditupp, och se ut till hafvet. Han gick upp, och såg ut, och sade: Der är intet. Han sade: Gack åter ditupp sju resor.
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
Och i sjunde resone sade han: Si, der går ett litet moln upp utu hafvet såsom en mans hand. Han sade: Gack upp, och säg Achab: Spänn före din vagn, och far ned, att regnet icke hinner dig.
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
Och förr än man såg till, vardt himmelen svart af moln och väder; och ett stort regn kom. Men Achab for, och kom till Jisreel.
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
Och Herrans hand kom öfver Elia, och han gjordade sina länder, och lopp för Achab, tilldess han kom till Jisreel.

< 1 Kings 18 >