< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
Şi s-a întâmplat, că după multe zile, cuvântul DOMNULUI a venit la Ilie în anul al treilea, spunând: Du-te, arată-te lui Ahab; şi voi trimite ploaie pe pământ.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
Şi Ilie a mers să se arate lui Ahab. Şi era o foamete aspră în Samaria.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
Şi Ahab l-a chemat pe Obadia, care era guvernatorul casei sale. (Şi Obadia se temea mult de DOMNUL;
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
Fiindcă s-a întâmplat, când Izabela a stârpit pe profeţii DOMNULUI, că Obadia a luat o sută de profeţi şi i-a ascuns câte cincizeci într-o peşteră şi i-a hrănit cu pâine şi apă.)
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
Şi Ahab i-a spus lui Obadia: Du-te în ţară, la toate fântânile de apă şi la toate pâraiele; poate găsim iarbă pentru a salva caii şi catârii, ca să nu pierdem toate animalele.
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
Astfel, şi-au împărţit ţara între ei pentru a trece prin ea; Ahab a mers pe o cale, singur, şi Obadia a mers pe altă cale, singur.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
Şi pe când Obadia era pe cale, iată, Ilie l-a întâlnit; şi el l-a recunoscut şi a căzut cu faţa la pământ şi a spus: Tu eşti, domnul meu Ilie?
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
Şi el i-a răspuns: Eu sunt; du-te, spune domnului tău: Iată, Ilie este aici.
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
Şi el a spus: Cu ce am păcătuit eu, ca să dai pe servitorul tău în mâna lui Ahab, ca să mă ucidă?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
Precum DOMNUL Dumnezeul tău trăieşte, nu este naţiune sau împărăţie, la care domnul meu nu a trimis să te caute; şi când ei spuneau: Nu este acolo; el lua un jurământ de la împărăţie sau naţiune, că nu te-au găsit.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
Şi acum tu spui: Du-te, spune domnului tău: Iată, Ilie este aici.
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
Şi se va întâmpla, imediat ce eu voi pleca de la tine, că Duhul DOMNULUI te va duce nu ştiu unde; şi astfel, când vin şi îi spun lui Ahab şi el nu te va găsi, că mă va ucide; dar eu, servitorul tău, mă tem de DOMNUL din tinereţea mea.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
Nu i s-a spus domnului meu ce am făcut când Izabela a ucis pe profeţii DOMNULUI, cum am ascuns o sută de bărbaţi dintre profeţii DOMNULUI, câte cincizeci într-o peşteră şi i-am hrănit cu pâine şi apă?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
Şi acum tu spui: Du-te, spune domnului tău: Iată, Ilie este aici; şi el mă va ucide.
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
Şi Ilie a spus: Precum DOMNUL oştirilor trăieşte, înaintea căruia stau în picioare, în această zi mă voi arăta negreşit lui.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
Astfel Obadia a mers să îl întâlnească pe Ahab şi i-a spus; şi Ahab a mers să îl întâlnească pe Ilie.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
Şi s-a întâmplat, când Ahab l-a văzut pe Ilie, că Ahab i-a spus: Eşti tu cel care tulbură pe Israel?
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
Iar el a răspuns: Nu eu am tulburat pe Israel, ci tu şi casa tatălui tău, în aceea că aţi părăsit poruncile DOMNULUI şi tu ai urmat Baalilor.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
De aceea acum, trimite şi adună la mine tot Israelul pe muntele Carmel şi pe cei patru sute cincizeci de profeţi ai lui Baal şi pe cei patru sute de profeţi ai dumbrăvilor, care mănâncă la masa Izabelei.
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
Astfel, Ahab a trimis la toţi copiii lui Israel şi a adunat profeţii la muntele Carmel.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
Şi Ilie a venit la tot poporul şi a spus: Până când veţi şchiopăta voi între două opinii? Dacă DOMNUL este Dumnezeu, urmaţi-l pe el; dar dacă este Baal, atunci urmaţi-l pe el. Şi poporul nu i-a răspuns un cuvânt.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
Atunci a spus Ilie poporului: Eu, numai eu, am rămas profet al DOMNULUI; dar profeţii lui Baal sunt patru sute cincizeci de bărbaţi.
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
Să ni se dea de aceea doi tauri; şi ei să îşi aleagă un taur pentru ei şi să îl taie bucăţi şi să îl pună pe lemne şi să nu pună foc dedesubt; şi eu voi pregăti celălalt taur şi îl voi pune pe lemne şi nu voi pune foc dedesubt;
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
Şi să chemaţi numele dumnezeilor voştri, iar eu voi chema numele DOMNULUI; şi Dumnezeul care răspunde prin foc, acela să fie Dumnezeu. Şi tot poporul a răspuns şi a zis: Bine spus.
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
Şi Ilie a spus profeţilor lui Baal: Alegeţi-vă un taur şi pregătiţi-l întâi, pentru că voi sunteţi mulţi; şi chemaţi numele dumnezeilor voştri, dar să nu puneţi foc dedesubt.
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
Şi ei au luat taurul care le-a fost dat şi l-au pregătit; şi au chemat numele lui Baal de dimineaţă până la amiază, spunând: Baale, ascultă-ne. Dar nu a fost nicio voce, nici nu a răspuns nimeni. Şi săreau pe altarul care fusese făcut.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
Şi s-a întâmplat la amiază, că Ilie i-a batjocorit şi a spus: Strigaţi cu voce tare, pentru că el este dumnezeu; fie vorbeşte, sau urmăreşte ceva, sau este într-o călătorie, sau poate doarme şi trebuie trezit.
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
Şi au strigat cu voce tare şi s-au tăiat după obiceiul lor cu săbii şi suliţe, până când sângele a ţâşnit pe ei.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
Şi s-a întâmplat, când miezul zilei a trecut şi ei au profeţit până la timpul oferirii sacrificiului de seară, că nu a fost nici voce, nici cineva care să răspundă, nici cineva care să dea ascultare.
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
Şi Ilie a spus către tot poporul: Apropiaţi-vă de mine. Şi tot poporul s-a apropiat de el. Şi el a reparat altarul DOMNULUI care era dărâmat.
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
Şi Ilie a luat douăsprezece pietre, conform numărului triburilor fiilor lui Iacob, către care cuvântul DOMNULUI a venit, spunând: Israel va fi numele tău;
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
Şi cu pietrele a zidit un altar în numele DOMNULUI; şi a făcut un şanţ în jurul altarului, atât de mare încât să conţină două măsuri de sămânţă.
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
Şi a pus lemnele în ordine şi a tăiat taurul în bucăţi şi l-a pus pe lemne şi a spus: Umpleţi patru vedre cu apă şi turnaţi-o pe ofranda arsă şi pe lemne.
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
Şi a spus: Faceţi aceasta a doua oară. Şi au făcut aceasta a doua oară. Şi el a spus: Faceţi aceasta a treia oară. Şi au făcut aceasta a treia oară.
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
Şi apa curgea împrejurul altarului şi el a umplut de asemenea şanţul cu apă.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
Şi s-a întâmplat, pe timpul ofrandei sacrificiului de seară, că profetul Ilie s-a apropiat şi a spus: DOAMNE Dumnezeul lui Avraam, Isaac şi al lui Israel, să se cunoască în această zi că tu eşti Dumnezeu în Israel şi că eu sunt servitorul tău şi că am făcut toate aceste lucruri la cuvântul tău.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Ascultă-mă, DOAMNE, ascultă-mă, ca acest popor să ştie că tu eşti DOMNUL Dumnezeu şi că tu le-ai întors inima înapoi.
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
Atunci focul DOMNULUI a căzut şi a mistuit ofranda arsă şi lemnele şi pietrele şi ţărâna şi a supt apa care era în şanţ.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
Şi când tot poporul a văzut aceasta, au căzut cu feţele la pământ; şi au spus: DOMNUL, el este singurul Dumnezeu; DOMNUL, el este singurul Dumnezeu.
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
Şi Ilie le-a spus: Luaţi pe profeţii lui Baal; să nu scape niciunul dintre ei. Şi i-au luat; şi Ilie i-a coborât la pârâul Chişon şi i-a ucis acolo.
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
Şi Ilie i-a spus lui Ahab: Urcă-te, mănâncă şi bea, pentru că este zgomot de ploaie mare.
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
Astfel Ahab s-a urcat să mănânce şi să bea. Şi Ilie s-a urcat pe vârful Carmelului; şi s-a plecat la pământ şi şi-a pus faţa între genunchi,
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
Şi a spus servitorului său: Urcă acum, priveşte spre mare. Şi el s-a urcat şi a privit şi a spus: Nu este nimic. Iar el a spus: Du-te din nou de şapte ori.
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
Şi s-a întâmplat a şaptea oară, că el a spus: Iată, se ridică un nor mic din mare, ca o mână de om. Iar el a spus: Urcă-te şi spune lui Ahab: Pregăteşte-ţi carul şi coboară, ca să nu te oprească ploaia.
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
Şi s-a întâmplat între timp, că cerul s-a înnegrit cu nori şi vânt şi a fost o ploaie mare. Şi Ahab s-a urcat în carul său şi a mers la Izreel.
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
Şi mâna DOMNULUI a fost peste Ilie; şi el şi-a încins coapsele şi a alergat înaintea lui Ahab la intrarea în Izreel.

< 1 Kings 18 >