< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
Kwasekusithi emva kwensuku ezinengi ilizwi leNkosi lafika kuElija ngomnyaka wesithathu lisithi: Hamba, uziveze kuAhabi, sengizanisa izulu ebusweni bomhlaba.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
UElija wasesiya ukuziveza kuAhabi. Njalo indlala yayilamandla eSamariya.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
UAhabi wasebiza uObhadiya owayephezu kwendlu yakhe. UObhadiya wayeyesaba-ke kakhulu iNkosi.
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
Ngoba kwathi lapho uJezebeli ebhubhisa abaprofethi beNkosi, uObhadiya wathatha abaprofethi abalikhulu, wabafihla ngamadoda angamatshumi amahlanu ebhalwini, wabondla ngesinkwa langamanzi.
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
UAhabi wasesithi kuObhadiya: Hamba elizweni uye emithonjeni yonke yamanzi lezifuleni zonke; mhlawumbe singathola utshani, silondoloze amabhiza lezimbongolo kuphila, ukuze singabhubhisi okwezifuyo.
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
Basebesehlukaniselana ilizwe ukuthi badabule phakathi kwalo; uAhabi wahamba ngenye indlela yedwa, uObhadiya laye wahamba ngenye indlela yedwa.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
Kwasekusithi uObhadiya esendleleni, khangela-ke, uElija wamhlangabeza; wamnanzelela, wawa ngobuso bakhe wathi: Nguwe yini, nkosi yami, Elija?
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
Wasesithi kuye: Yimi. Hamba uyetshela inkosi yakho ukuthi: Khangela, uElija ulapha.
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
Wasesithi: Ngoneni ukuthi unikele inceku yakho esandleni sikaAhabi ukuthi angibulale?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
Kuphila kukaJehova uNkulunkulu wakho, kakulasizwe lombuso inkosi yami engathumelanga kukho ukukudinga. Lapho besithi: Kakho; yafungisa lowombuso lalesosizwe ukuthi kabakutholanga.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
Khathesi-ke uthi: Hamba utshele inkosi yakho ukuthi: Khangela, uElija ulapha.
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
Kuzakuthi-ke sengisukile kuwe, uMoya weNkosi akuthwale akuse lapho engingazi khona; lapho sengifike ngatshela uAhabi, angakutholi, uzangibulala; kodwa mina inceku yakho ngiyayesaba iNkosi kusukela ebutsheni bami.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
Kakutshelwanga inkosi yami yini engakwenzayo lapho uJezebeli ebulala abaprofethi beNkosi, ukuthi ngafihla amadoda alikhulu kubaprofethi beNkosi, ngamadoda angamatshumi amahlanu ebhalwini, ngabondla ngesinkwa langamanzi?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
Khathesi-ke uthi: Hamba uyetshela inkosi yakho ukuthi: Khangela uElija ulapha. Abesengibulala.
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
UElija wasesithi: Kuphila kukaJehova wamabandla engimi phambi kwakhe, oqotho lamuhla ngizaziveza kuye.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
Ngakho uObhadiya wahamba ukuhlangabeza uAhabi, wamtshela; loAhabi wayahlangabeza uElija.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
Kwasekusithi uAhabi ebona uElija, uAhabi wathi kuye: Nguwe yini ongumhluphi kaIsrayeli?
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
Wasesithi: Kangimhluphanga uIsrayeli, kodwa nguwe lendlu kayihlo, ngokuyitshiya kwenu imilayo yeNkosi, lalandela oBhali.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
Ngakho-ke thuma, ubuthanisele kimi uIsrayeli wonke entabeni iKharmeli, labaprofethi bakaBhali abangamakhulu amane lamatshumi amahlanu labaprofethi bezixuku abangamakhulu amane abadla etafuleni likaJezebeli.
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
Ngakho uAhabi wathuma phakathi kwabo bonke abantwana bakoIsrayeli, wabuthanisa abaprofethi entabeni iKharmeli.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
UElija wasesondela ebantwini bonke wathi: Koze kube nini liqhula emicabangweni emibili? Uba iNkosi inguNkulunkulu, landelani yona; kodwa uba kunguBhali, mlandeleni. Kodwa abantu kabamphendulanga ngalizwi.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
UElija wasesithi ebantwini: Mina ngedwa ngingumprofethi weNkosi oseleyo; kodwa abaprofethi bakaBhali ngamadoda angamakhulu amane lamatshumi amahlanu.
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
Ngakho kabasinike amajongosi amabili, bazikhethele ijongosi elilodwa, baliqume iziqa, bazibeke phezu kwenkuni, bangafaki mlilo; lami ngizalungisa elinye ijongosi, ngilibeke phezu kwenkuni, ngingafaki mlilo.
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
Njalo bizani ibizo likankulunkulu wenu, lami ngizabiza ibizo leNkosi; uNkulunkulu ozaphendula ngomlilo nguye uNkulunkulu. Bonke abantu basebephendula bathi: Lelilizwi lilungile.
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
UElija wasesithi kubaprofethi bakaBhali: Zikhetheleni ijongosi elilodwa, lililungise kuqala, ngoba libanengi, libize ibizo likankulunkulu wenu, kodwa lingafaki mlilo.
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
Basebethatha ijongosi ababelinikiwe, balilungisa, babiza ibizo likaBhali kusukela ekuseni kwaze kwaba semini, besithi: Bhali, siphendule! Kodwa kakubanga lalizwi, kakubanga lophendulayo. Basebeseqa phezu kwelathi elalenziwe.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
Kwasekusithi emini uElija wadlala ngabo wathi: Memezani ngelizwi elikhulu, ngoba ungunkulunkulu; ngoba uyanakana, loba umonyukile, kumbe usekuhambeni, mhlawumbe ulele, njalo kudingeka ukuthi avuswe.
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
Basebememeza ngelizwi elikhulu, bazisika njengokomkhuba wabo ngezinkemba langemikhonto, kwaze kwantshaza igazi kubo.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
Kwasekusithi sekwedlulile imini, baprofetha kwaze kwaba sekunikelweni komnikelo, kakubanga lelizwi, njalo kakubanga lophendulayo, njalo kakubanga lonakekelayo.
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
UElija wasesithi ebantwini bonke: Sondelani kimi. Bonke abantu basebesondela kuye. Waselungisa ilathi leNkosi elaselidilikile.
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
UElija wasethatha amatshe alitshumi lambili, ngokwenani lezizwe zamadodana kaJakobe, okwafika kuye ilizwi leNkosi lisithi: Ibizo lakho lizakuba nguIsrayeli.
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
Ngalawomatshe wasesakha ilathi ebizweni leNkosi, wenza umgelo ozingelezela ilathi, ngokwesilinganiso samaseya amabili enhlanyelo.
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
Waselungisa inkuni, waliquma iziqa ijongosi, walibeka phezu kwenkuni, wasesithi: Gcwalisani izimbiza ezine ngamanzi, liwathele phezu komnikelo wokutshiswa laphezu kwenkuni.
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
Wasesithi: Kwenzeni okwesibili. Bakwenza okwesibili. Wathi: Kwenzeni okwesithathu. Basebekwenza okwesithathu.
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
Amanzi asehamba azingelezela ilathi, lomgelo lawo wawugcwalisa ngamanzi.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
Kwasekusithi ekunikelweni komnikelo uElija umprofethi wasondela wathi: Nkosi, Nkulunkulu kaAbrahama, uIsaka, loIsrayeli, kakwaziwe lamuhla ukuthi unguNkulunkulu koIsrayeli, lami ngiyinceku yakho, lokuthi ngizenzile zonke lezizinto njengokwelizwi lakho.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Ngiphendule, Nkosi, ungiphendule, ukuze lababantu bazi ukuthi wena uyiNkosi uNkulunkulu, lokuthi uyiphendulile futhi inhliziyo yabo.
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
Wasusehla umlilo weNkosi, waqothula umnikelo wokutshiswa lenkuni lamatshe lothuli, wakhotha lamanzi asemgelweni.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
Kwathi abantu bonke bekubona bathi mbo ngobuso babo, bathi: UJehova nguye onguNkulunkulu; uJehova nguye onguNkulunkulu.
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
UElija wasesithi kibo: Babambeni abaprofethi bakaBhali, kungaphunyuki lamunye wabo. Basebebabamba. UElija wasebehlisela esifuleni iKishoni, wababulalela khona.
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
UElija wasesithi kuAhabi: Yenyuka, udle unathe, ngoba kulomsindo wobunengi bezulu.
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
UAhabi wasesenyuka ukuyakudla lokunatha. UElija wasesenyukela engqongeni yeKharmeli; wakhothamela phansi emhlabathini, wafaka ubuso bakhe phakathi kwamadolo akhe.
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
Wasesithi encekwini yakhe: Yenyuka khathesi, ukhangele ngaselwandle. Yasisenyuka, yakhangela, yathi: Kakulalutho. Wasesithi: Buyela, kasikhombisa.
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
Kwasekusithi ngesikhathi sesikhombisa yathi: Khangela, iyezana elingangesandla somuntu lisenyuka olwandle. Wasesithi: Yenyuka uyetshela uAhabi: Bophela inqola, wehle, hlezi izulu likuvalele.
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
Kwasekusithi kungakafiki lesosikhathi isibhakabhaka sasesisiba mnyama ngamayezi langomoya, kwaba lezulu elikhulu. UAhabi wasegada, waya eJizereyeli.
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
Lesandla seNkosi sasiphezu kukaElija; wabopha ukhalo lwakhe, wagijima phambi kukaAhabi, uze ufike eJizereyeli.

< 1 Kings 18 >