< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
Après bien des jours, la parole de Yahvé fut adressée à Élie, la troisième année, en ces termes: « Va, montre-toi à Achab, et je ferai tomber la pluie sur la terre. »
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
Élie alla se montrer à Achab. La famine était grave à Samarie.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
Achab appela Abdias, qui avait la charge de la maison. (Or Abdias craignait beaucoup Yahvé;
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
car lorsque Jézabel avait exterminé les prophètes de Yahvé, Abdias avait pris cent prophètes, en avait caché cinquante dans une caverne, et les avait nourris de pain et d'eau).
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
Achab dit à Abdias: « Parcourez le pays, allez à toutes les sources d'eau et à tous les ruisseaux. Peut-être trouverons-nous de l'herbe et sauverons-nous les chevaux et les mules en vie, afin de ne pas perdre tous les animaux. »
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
Et ils se partagèrent le pays pour le parcourir. Achab prit un chemin à part, et Abdias prit un autre chemin à part.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
Comme Abdias était en chemin, voici qu'Élie le rencontra. Il le reconnut, tomba sur sa face et dit: « Est-ce toi, mon seigneur Élie? »
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
Il lui répondit: « C'est moi. Va dire à ton maître: « Voici Élie, il est là! ».
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
Il dit: « Comment ai-je péché, pour que tu livres ton serviteur entre les mains d'Achab, afin qu'il me tue?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
L'Éternel, ton Dieu, est vivant! Il n'y a ni nation ni royaume où mon seigneur n'ait envoyé pour te chercher. Quand on a dit: « Il n'est pas ici », il a juré par le royaume et la nation qu'on ne te trouverait pas.
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
Maintenant, vous dites: « Va dire à ton maître: « Voici Élie qui est ici ».
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
Il arrivera, dès que je te quitterai, que l'Esprit de Yahvé te portera je ne sais où; aussi, quand je viendrai prévenir Achab, et qu'il ne te trouvera pas, il me tuera. Mais moi, ton serviteur, j'ai craint Yahvé dès ma jeunesse.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
N'a-t-on pas raconté à mon seigneur ce que j'ai fait quand Jézabel a tué les prophètes de l'Éternel, comment j'ai caché cent hommes des prophètes de l'Éternel avec cinquante dans une caverne, et comment je les ai nourris de pain et d'eau?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
Et maintenant, tu dis: « Va dire à ton maître: « Voici Élie », et il me tuera. Il me tuera. »
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
Élie dit: « L'Éternel des armées est vivant, devant qui je me tiens, et je me montrerai à lui aujourd'hui. »
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
Abdias alla à la rencontre d'Achab et le lui dit, et Achab alla à la rencontre d'Élie.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
Lorsqu'Achab vit Élie, il lui dit: « Est-ce toi, le trouble-fête d'Israël? »
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
Il répondit: « Ce n'est pas Israël que j'ai troublé, mais toi et la maison de ton père, parce que vous avez abandonné les commandements de l'Éternel et que vous avez suivi les Baals.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
Maintenant, envoie et rassemble vers moi tout Israël sur la montagne du Carmel, ainsi que quatre cent cinquante des prophètes de Baal et quatre cents des prophètes d'Ashéra, qui mangent à la table de Jézabel. »
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
Achab envoya donc chercher tous les enfants d'Israël et rassembla les prophètes sur le mont Carmel.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
Élie s'approcha de tout le peuple et dit: « Jusques à quand hésiterez-vous entre les deux camps? Si Yahvé est Dieu, suivez-le; mais si c'est Baal, suivez-le. » Les gens n'ont pas dit un mot.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
Et Élie dit au peuple: « Moi, et moi seul, je suis resté comme prophète de l'Éternel; mais les prophètes de Baal sont quatre cent cinquante hommes.
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
Qu'ils nous donnent donc deux taureaux; qu'ils en choisissent un pour eux, qu'ils le coupent en morceaux, qu'ils le posent sur le bois et qu'ils n'y mettent pas le feu; et moi, je préparerai l'autre taureau, je le poserai sur le bois et je n'y mettrai pas le feu.
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
Tu invoqueras le nom de ton dieu, et moi j'invoquerai le nom de Yahvé. Le Dieu qui répond par le feu, qu'il soit Dieu. » Tout le peuple répondit: « Ce que tu dis est bien. »
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
Élie dit aux prophètes de Baal: « Choisissez pour vous un taureau, et habillez-le le premier, car vous êtes nombreux; invoquez le nom de votre dieu, mais n'y mettez pas le feu. »
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
Ils prirent le taureau qu'on leur avait donné, l'habillèrent et invoquèrent le nom de Baal depuis le matin jusqu'à midi, en disant: « Baal, écoute-nous! ». Mais il n'y avait pas de voix, et personne ne répondait. Ils sautèrent autour de l'autel qui avait été construit.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
À midi, Élie se moqua d'eux et dit: « Criez à haute voix, car c'est un dieu. Ou bien il est plongé dans ses pensées, ou bien il est parti quelque part, ou bien il est en voyage, ou bien il dort et il faut le réveiller. »
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
Ils criaient à haute voix et se coupaient sur leur chemin avec des couteaux et des lances jusqu'à ce que le sang jaillisse sur eux.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
Quand midi fut passé, ils prophétisèrent jusqu'au moment de l'offrande du soir; mais il n'y eut ni voix, ni réponse, et personne ne fit attention.
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
Elie dit à tout le peuple: « Approchez-vous de moi! »; et tout le peuple s'approcha de lui. Il répara l'autel de Yahvé qui avait été renversé.
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
Elie prit douze pierres, selon le nombre des tribus des fils de Jacob, à qui la parole de Yahvé avait été adressée en disant: « Israël sera ton nom. »
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
Avec les pierres, il construisit un autel au nom de Yahvé. Il fit autour de l'autel une tranchée assez grande pour contenir deux seahs de semences.
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
Il rangea le bois, coupa le taureau en morceaux et le posa sur le bois. Il dit: « Remplissez d'eau quatre jarres, et versez-la sur l'holocauste et sur le bois. »
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
Il dit: « Faites-le une seconde fois. » Et ils le firent une seconde fois. Il dit: « Faites-le une troisième fois. » Et ils le firent une troisième fois.
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
L'eau coulait autour de l'autel; il remplit aussi d'eau la tranchée.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
Au moment de l'offrande du soir, le prophète Élie s'approcha et dit: « Yahvé, Dieu d'Abraham, d'Isaac et d'Israël, que l'on sache aujourd'hui que tu es Dieu en Israël et que je suis ton serviteur, et que j'ai fait toutes ces choses selon ta parole.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Écoute-moi, Yahvé, écoute-moi, afin que ce peuple sache que toi, Yahvé, tu es Dieu, et que tu as ramené son cœur à la raison. »
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
Le feu de l'Éternel tomba et consuma l'holocauste, le bois, les pierres et la poussière, et il lécha l'eau qui était dans le fossé.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
Quand tout le peuple vit cela, il tomba sur sa face. Ils disaient: « Yahvé, c'est Dieu! Yahvé, c'est Dieu! »
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
Élie leur dit: « Saisissez les prophètes de Baal! Ne laissez pas un seul d'entre eux s'échapper! » Ils s'en emparèrent, et Élie les fit descendre au torrent de Kishon, où il les tua.
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
Élie dit à Achab: « Lève-toi, mange et bois, car on entend le bruit d'une pluie abondante. »
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
Et Achab monta pour manger et pour boire. Élie monta au sommet du Carmel; il se prosterna par terre et mit son visage entre ses genoux.
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
Il dit à son serviteur: « Monte maintenant et regarde vers la mer. » Il est monté et a regardé, puis a dit: « Il n'y a rien. » Il a dit sept fois: « Vas-y encore ».
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
La septième fois, il dit: « Voici qu'un petit nuage, semblable à la main d'un homme, s'élève de la mer. » Il dit: « Monte, dis à Achab: « Prépare-toi et descends, pour que la pluie ne t'arrête pas. »"
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
En peu de temps, le ciel s'obscurcit de nuages et de vent, et il y eut une grande pluie. Achab monta à cheval et se rendit à Jizreel.
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
La main de Yahvé était sur Elie; il mit son manteau dans sa ceinture et courut devant Achab jusqu'à l'entrée de Jizreel.

< 1 Kings 18 >