< 1 Kings 18 >

1 Ó sì ṣe, lẹ́yìn ọjọ́ púpọ̀, ní ọdún kẹta, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Elijah wá pé, “Lọ, kí o sì fi ara rẹ̀ hàn fún Ahabu, èmi yóò sì rọ òjò sórí ilẹ̀.”
Aftir many daies the word of the Lord was maad to Elie, in the thridde yeer, and seide, Go, and schewe thee to Achab, that Y yyue reyn on the face of erthe.
2 Bẹ́ẹ̀ ni Elijah lọ fi ara rẹ̀ han Ahabu. Ìyàn ńlá sì mú ní Samaria,
Therfor Elie yede to schewe hym silf to Achab; forsothe greet hungur was in Samarie.
3 Ahabu sì ti pe Obadiah, ẹni tí ń ṣe olórí ilé rẹ̀. Obadiah sì bẹ̀rù Olúwa gidigidi.
And Achab clepide Abdie, dispendere, ether stiward, of his hows; forsothe Abdie dredde greetli the Lord God of Israel.
4 Nígbà tí Jesebeli sì ń pa àwọn wòlíì Olúwa kúrò, Obadiah sì mú ọgọ́rùn-ún wòlíì, ó sì fi wọ́n pamọ́ sínú ihò òkúta, àádọ́ta ní ihò kọ̀ọ̀kan, ó sì fi àkàrà pẹ̀lú omi bọ́ wọn.
For whanne Jezabel killide the prophetis of the Lord, he took an hundrid prophetis, and hidde hem, bi fifties and fifties, in dennes, and fedde hem with breed and watir.
5 Ahabu sì ti wí fún Obadiah pé, “Lọ sí gbogbo ilẹ̀ sí orísun omi gbogbo àti sí ilẹ̀ gbogbo. Bóyá àwa lè rí koríko láti gba àwọn ẹṣin àti àwọn ìbáaka là, kí a má bá à ṣòfò àwọn ẹranko pátápátá.”
Therfor Achab seide to Abdie, Go thou in to the lond, to alle wellis of watris, and in to alle valeis, if in hap we moun fynde gras, and saue horsis and mulis; and werk beestis perische not outirli.
6 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì pín ilẹ̀ tí wọ́n fẹ́ dé láàrín ara wọn, Ahabu gba ọ̀nà kan lọ, Obadiah sì gba ọ̀nà mìíràn lọ.
Therfor thei departiden the cuntreis to hem silf, that thei schulden cumpasse tho; Achab yede bi o weye, and Abdie yede bi another weie, `bi hym silf.
7 Bí Obadiah sì ti ń rìn lọ, Elijah sì pàdé rẹ̀. Obadiah sì mọ̀ ọ́n, ó dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni nítòótọ́, Elijah, olúwa mi?”
And whanne Abdie was in the weie, Elie mette hym; and whanne he hadde knowe Elie, he felde on his face, and seide, Whethir thou art my lord Elie?
8 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, lọ kí o sọ fún olúwa rẹ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’”
To whom he answeride, Y am. And Elie seide, Go thou, and seie to thi lord, Elie is present.
9 Obadiah sì béèrè pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ kí ni mo ha dá tí ìwọ fi ń fi ìránṣẹ́ rẹ lé Ahabu lọ́wọ́ láti pa?
And Abdie seide, What `synnede Y, for thou bitakist me in the hond of Achab, that he sle me?
10 Mo mọ̀ dájú pé bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti ń bẹ, kò sí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan tí olúwa mi kò ti rán ènìyàn lọ láti wò ọ́. Àti nígbà tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan bá wí pé o kò sí, òun a sì mú kí wọ́n búra wí pé wọn kò rí ọ.
Thi Lord God lyueth, for no folk ethir rewme is, whidur my lord, sekynge thee, sente not; and whanne alle men answeriden, He is not here, he chargide greetli alle rewmes and folkis, for thou were not foundun; and now thou seist to me,
11 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ wí fún mi pé kí n lọ sọ́dọ̀ olúwa mi, kí n sì wí pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’
Go, and seie to thi lord, Elie is present.
12 Èmi kò sì mọ ibi tí ẹ̀mí Olúwa yóò gbé ọ lọ nígbà tí mo bá fi ọ́ sílẹ̀. Bí mo bá lọ, tí mo sì sọ fún Ahabu, tí kò sì rí ọ, òun a sì pa mí. Síbẹ̀ èmi ìránṣẹ́ rẹ bẹ̀rù Olúwa láti ìgbà èwe mi wá.
And whanne Y schal departe fro thee, the Spirit of the Lord schal bere thee awey in to a place which Y knowe not; and Y schal entre, and `Y schal telle to Achab, and he schal not fynde thee, and he schal sle me; forsothe thi seruaunt dredith the Lord fro his yong childhod.
13 Ṣé Olúwa mi kò ha ti gbọ́ ohun tí mo ṣe nígbà tí Jesebeli ń pa àwọn wòlíì Olúwa? Mo fi ọgọ́rùn-ún wòlíì Olúwa pamọ́ sínú ihò òkúta méjì, àràádọ́ta ní ọ̀kọ̀ọ̀kan, mo sì fi omi àti oúnjẹ bọ́ wọn.
Whether it is not schewid to thee, my lord, what Y dide, whanne Jesabel killide the prophetis of the Lord, that Y hidde of the prophetis of the Lord an hundrid men, bi fifty and bi fifti, in dennes, and Y fedde hem with breed and watir?
14 Ìwọ sì sọ fún mi nísinsin yìí pé, kí n tọ olúwa mi lọ pé, ‘Elijah ń bẹ níhìn-ín.’ Òun a sì pa mí!”
And now thou seist, Go, and seie to thi lord, Elie is present, that he sle me.
15 Elijah sì wí pé, “Bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, nítòótọ́ èmi yóò fi ara mi hàn fún Ahabu lónìí.”
And Elie seide, The Lord of oostis lyueth, bifor whos siyt Y stonde, for to dai Y schal appere to hym.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Obadiah sì lọ láti pàdé Ahabu, ó sì sọ fún un, Ahabu sì lọ láti pàdé Elijah.
Therfor Abdie yede in to the metyng of Achab, and schewide to hym; and Achab cam in to the meetyng of Elie.
17 Nígbà tí Ahabu sì rí Elijah, ó sì wí fún un pé, “Ṣé ìwọ nìyìí, ìwọ tí ń yọ Israẹli lẹ́nu?”
And whanne he hadde seyn Elie, he seide, Whether thou art he, that disturblist Israel?
18 Elijah sì dá a lóhùn pé, “Èmi kò yọ Israẹli lẹ́nu, bí kò ṣe ìwọ àti ilé baba rẹ. Ẹ ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, ẹ sì ń tọ Baali lẹ́yìn.
And he seide, Not Y disturble Israel, but thou, and the hows of thi fadir, whiche han forsake the comaundementis of the Lord, and sueden Baalym, `disturbliden Israel.
19 Nísinsin yìí kó gbogbo Israẹli jọ láti pàdé mi lórí òkè Karmeli. Àti kí o sì mú àádọ́ta lé ní irinwó àwọn wòlíì Baali àti irinwó àwọn wòlíì òrìṣà Aṣerah tí wọ́n ń jẹun ní tábìlì Jesebeli.”
Netheles now sende thou, and gadere to me al Israel, in the hil of Carmele, and foure hundrid and fifti prophetis of Baal, and foure hundrid prophetis of woodis, that eten of the table of Jezabel.
20 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, ó sì kó àwọn wòlíì jọ sí orí òkè Karmeli.
Achab sente to alle the sones of Israel, and gaderide prophetis in the hil of Carmele.
21 Elijah sì lọ síwájú gbogbo àwọn ènìyàn, ó sì wí pé, “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin yóò máa ṣiyèméjì? Bí Olúwa bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ṣùgbọ́n bí Baali bá ni Ọlọ́run, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò sì wí ohun kan.
Forsothe Elie neiyede to al the puple of Israel, and seide, Hou long halten ye in to twey partis? If the Lord is God, sue ye hym; forsothe if Baal is God, sue ye hym. And the puple answeride not o word to hym.
22 Nígbà náà ni Elijah wí fún wọn pé, “Èmi nìkan ṣoṣo ni ó kù ní wòlíì Olúwa, ṣùgbọ́n, àádọ́ta lé ní irinwó ni wòlíì Baali.
And Elie seide eft to the puple, Y dwellide aloone a prophete of the Lord; sotheli the prophetis of Baal ben foure hundrid and fifti, and the prophetis of woodis ben foure hundrid men.
23 Ẹ fún wa ní ẹgbọrọ akọ màlúù méjì. Jẹ́ kí wọn kí ó sì yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara wọn, kí wọn kí ó sì gé e sí wẹ́wẹ́, kí wọn kí ó sì tò ó sí orí igi, kí wọn kí ó má ṣe fi iná sí i. Èmi yóò sì tún ẹgbọrọ akọ màlúù kejì ṣe, èmi yóò sì tò ó sórí igi, èmi kì yóò sì fi iná sí i.
Tweyne oxis be youun to us; and chese thei oon oxe, and thei schulen kitte in to gobetis, and schulen putte on trees, but putte thei not fier vndur; and Y schal make the tother oxe in to sacrifice, and Y schal putte on the trees, and Y schal not putte fier vnder.
24 Nígbà náà ẹ ó sì ké pe orúkọ àwọn Ọlọ́run yín, èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa. Ọlọ́run náà tí ó fi iná dáhùn, òun ni Ọlọ́run.” Nígbà náà ni gbogbo àwọn ènìyàn náà sì wí pé, “Ohun tí ìwọ sọ dára.”
Clepe ye the name of youre goddis, and Y schal clepe the name of my God; and the God that herith bi fier, be he God. And al the puple answeride, and seide, The resoun is best, `which resoun Elie spak.
25 Elijah sì wí fún àwọn wòlíì Baali wí pé, “Ẹ yan ẹgbọrọ akọ màlúù kan fún ara yín, kí ẹ sì tètè kọ́ ṣe é, nítorí ẹ̀yin pọ̀. Ẹ ké pe orúkọ àwọn ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe fi iná sí i.”
Therfor Elie seide to the prophetis of Baal, Chese ye oon oxe to you, and make ye first, for ye ben the mo; and clepe ye the names of youre goddis, and putte ye not fier vnder.
26 Nígbà náà ni wọ́n sì mú ẹgbọrọ akọ màlúù náà, tí a ti fi fún wọn, wọ́n sì ṣe é. Nígbà náà ni wọ́n sì ké pe orúkọ Baali láti òwúrọ̀ títí di ọ̀sán gangan wí pé, “Baali! Dá wa lóhùn!” Wọ́n sì ń kégbe. Ṣùgbọ́n kò sí ìdáhùn; kò sí ẹnìkan tí ó sì dáhùn. Wọ́n sì jó yí pẹpẹ náà ká, èyí tí wọ́n tẹ́.
And whanne thei hadden take the oxe, whom Elie yaf to hem, thei maden sacrifice, and clepiden the name of Baal, fro the morewtid `til to myddai, and seiden, Baal, here vs! And no vois was, nether ony that answerd; and thei skippiden ouer the auter, which thei hadden maad.
27 Ní ọ̀sán gangan, Elijah bẹ̀rẹ̀ sí ń fi wọ́n ṣe ẹlẹ́yà ó sì wí pé, “Ẹ kígbe lóhùn rara Ọlọ́run sá à ni òun! Bóyá ó ń ṣe àṣàrò, tàbí kò ráyè, tàbí ó re àjò. Bóyá ó sùn, ó yẹ kí a jí i.”
And whanne it was thanne myddai, Elie scornede hem, and seide, Crie ye with gretter vois, for Baal is youre god, and in hap he spekith with an other, ethir he is in a herborgerie, ether in weie, ether certis he slepith, that he be reisid.
28 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì kígbe lóhùn rara, wọ́n sì fi ọ̀bẹ àti ọ̀kọ̀ ya ara wọn gẹ́gẹ́ bí ìṣe wọn, títí tí ẹ̀jẹ̀ fi tú jáde ní ara wọn.
Therfor thei crieden with greet vois, and thei kerueden hem silf with knyues and launcetis, bi her custom, til thei weren bisched with blood.
29 Nígbà tí ọjọ́ yẹ àtàrí, wọ́n sì ń fi òmùgọ̀ sọtẹ́lẹ̀ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, ṣùgbọ́n kò sí ohùn, kò sì ṣí ìdáhùn, kò sì ṣí ẹni tí ó kà á sí.
Sotheli after that mydday passide, and while thei prophesieden, the tyme cam, in which the sacrifice is wont to be offrid, nether vois was herd `of her goddis, nether ony answeride, nether perceyuede hem preiynge.
30 Nígbà náà ni Elijah wí fún gbogbo àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ súnmọ́ mi.” Wọ́n sì súnmọ́ ọn, ó sì tún pẹpẹ Olúwa tí ó ti wó lulẹ̀ ṣe.
Elie seide to al the puple, Come ye to me. And whanne the puple cam to him, he arrayede the auter of the Lord, that was distried.
31 Elijah sì mú òkúta méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún ẹ̀yà ọmọ Jakọbu kan, ẹni tí ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ wá wí pé, “Israẹli ni orúkọ rẹ̀ yóò máa jẹ́.”
And he took twelue stonys, bi the noumbre of lynagis of sones of Jacob, to which Jacob the word of the Lord was maad, and seide, Israel schal be thi name.
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ pẹ̀lú àwọn òkúta wọ̀nyí ní orúkọ Olúwa, ó sì wa yàrá yí pẹpẹ náà ká, tí ó lè gba ìwọ̀n òsùwọ̀n irúgbìn méjì.
And he bildide an auter of stonys, in the name of the Lord, and he made a ledyng to of watir, `ether a dich, as bi twei litle dichis in the cumpas of the auter.
33 Ó sì to igi náà dáradára, ó sì ké ẹgbọrọ akọ màlúù náà wẹ́wẹ́, ó sì tò ó sórí igi. Nígbà náà ni ó sì wí fún wọn wí pé, “Ẹ fi omi kún ìkòkò mẹ́rin, kí ẹ sì tu sórí ẹbọ sísun àti sórí igi náà.”
And he dresside trees, and he departide the oxe bi membris, and puttide on the trees,
34 Ó sì wí pe, “Ẹ ṣe é ní ìgbà kejì.” Wọ́n sì ṣe é ní ìgbà kejì. Ó sì tún wí pé, “Ṣe é ní ìgbà kẹta.”
and seide, Fille ye foure pottis with watir, and schede ye on the brent sacrifice, and on the trees. And eft he seide, Also the secounde tyme do ye this. `And thei diden the secounde tyme. And he seide, Do ye the same thing the thridde tyme; and thei diden the thridde tyme.
35 Omi náà sì sàn yí pẹpẹ náà ká, ó sì fi omi kún yàrá náà pẹ̀lú.
And the watris runnen aboute the auter, and the dich of ledyng to `of watir was fillid.
36 Ó sì ṣe, ní ìrúbọ àṣálẹ́, wòlíì Elijah sì súnmọ́ tòsí, ó sì gbàdúrà wí pé, “Olúwa, Ọlọ́run Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, jẹ́ kí ó di mí mọ̀ lónìí pé ìwọ ni Ọlọ́run ní Israẹli àti pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, àti pé mo ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí nípa àṣẹ rẹ.
And whanne the tyme was thanne, that the brent sacrifice schulde be offrid, Elye the prophete neiyede, and seide, Lord God of Abraham, of Isaac, and of Israel, schewe thou to dai that thou art God of Israel, and that Y am thi seruaunt, and haue do alle these wordis bi thi comaundement.
37 Gbọ́ ti èmi, Olúwa, gbọ́ ti èmi, kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí lè mọ̀ pé ìwọ Olúwa ni Ọlọ́run àti pé ìwọ tún yí ọkàn wọn padà.”
Lord, here thou me; Lord, here thou me; that this puple lerne, that thou art the Lord God, and that thou hast conuertid eft the herte of hem.
38 Nígbà náà ni iná Olúwa bọ́ sílẹ̀, ó sì sun ẹbọ sísun náà àti igi, àti àwọn òkúta, àti erùpẹ̀, ó sì tún lá omi tí ń bẹ nínú yàrá náà.
Sotheli fier of the Lord felde doun, and deuouride brent sacrifice, and trees, and stonus, and lickide vp also the poudre, and the water that was in the `leding of water.
39 Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn sì rí èyí, wọ́n da ojú wọn bolẹ̀, wọ́n sì kígbe pé, “Olúwa, òun ni Ọlọ́run! Olúwa, òun ni Ọlọ́run!”
And whanne al the puple hadde seyn this, it felde in to his face, and seide, The Lord he is God; the Lord he is God.
40 Nígbà náà ni Elijah sì pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ mú àwọn wòlíì Baali. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọ̀kan nínú wọn kí ó sálọ!” Wọ́n sì mú wọn, Elijah sì mú wọn sọ̀kalẹ̀ sí àfonífojì Kiṣoni, ó sì pa wọ́n níbẹ̀.
And Elie seide to hem, Take ye the prophetis of Baal; not oon sotheli ascape of hem. And whanne thei hadden take hem, Elie ledde hem to the stronde of Cison, and killide hem there.
41 Elijah sì wí fún Ahabu pé, “Lọ, jẹ, kí o sì mu, nítorí ìró ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò ń bọ̀.”
And Elie seide to Achab, Stie thou, ete, and drynke, for the sown of myche reyn is.
42 Bẹ́ẹ̀ ni Ahabu gòkè lọ láti jẹ àti láti mu. Ṣùgbọ́n Elijah gun orí òkè Karmeli lọ ó sì tẹríba, ó sì fi ojú rẹ̀ sí agbede-méjì eékún rẹ̀.
Achab stiede to ete and drynke; forsothe Elie stiede in to the hil of Carmele, and he settide lowli his face to the erthe, bitwixe hise knees;
43 Ó sì wí fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ pé, “Lọ, kí o sì wo ìhà Òkun, òun sì gòkè lọ, ó sì wò.” Ó sì wí pé, “Kò sí nǹkan níbẹ̀.” Ó sì wí pé, “Tún lọ nígbà méje.”
and seide to his child, Stie thou, and biholde ayens the see. And whanne he hadde stied, and hadde biholde, he seide, No thing is. And eft Elie seide to hym, Turne thou ayen bi seuene tymes.
44 Nígbà keje, ìránṣẹ́ náà sì wí pé, “Àwọsánmọ̀ kékeré kan dìde láti inú Òkun, gẹ́gẹ́ bí ọwọ́ ènìyàn.” Elijah sì wí pé, “Lọ, kí o sọ fún Ahabu pé, ‘Di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ, kí òjò ó má ba à dá ọ dúró.’”
Sotheli in the seuenthe tyme, lo! a litil cloude as the step of a man stiede fro the see. And Elie seide, Stie thou, and seie to Achab, Ioyne thi chare, and go doun, lest the reyn byfor ocupie thee.
45 Ó sì ṣe, nígbà díẹ̀ sí i, ọ̀run sì ṣú fún àwọsánmọ̀, ìjì sì dìde, òjò púpọ̀ sì rọ̀, Ahabu sì gun kẹ̀kẹ́ lọ sí Jesreeli.
And whanne thei turneden hem hidur and thidur, lo! heuenes weren maad derk, and cloud, and wynd, and greet reyn was maad. Therfor Achab stiede, and yede in to Jezrael;
46 Agbára Olúwa sì ń bẹ lára Elijah; ó sì di àmùrè ẹ̀gbẹ́ rẹ, ó sì sáré níwájú Ahabu títí dé Jesreeli.
and the hond of the Lord was maad on Elie, and whanne the leendis weren gird, he ran bifor Achab, til he cam in to Jezrael.

< 1 Kings 18 >