< 1 Kings 17 >
1 Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
Emdi Giléadta turuwatqanlardin bolghan Tishbiliq Iliyas Ahabqa: — Men xizmitide turuwatqan Israilning Xudasi Perwerdigarning hayati bilen qesem qilimenki, méning sözümsiz bu yillarda ne shebnem ne yamghur chüshmeydu, dédi.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
Andin Perwerdigarning sözi uninggha kélip: —
3 “Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
Bu yerdin kétip, meshriq terepke bérip, Iordan deryasining u teripidiki qérit éqinining boyida özüngni yoshurghin;
4 Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
we shundaq boliduki, sen éqinning süyidin ichisen; mana, sanga u yerde ozuq yetküzüp bérishke qagha-quzghunlarni buyrudum, déyildi.
5 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
Shuning bilen u Perwerdigar buyrughandek qilip, Iordan deryasining u teripidiki qérit éqinigha bérip, u yerde turdi.
6 Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
Qagha-quzghunlar etigende nan bilen gösh, her kechte yene nan bilen gösh yetküzüp béretti. U özi éqinning süyidin ichetti.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
Lékin zéminda yamghur yaghmighini üchün birmezgildin kéyin éqin su qurup ketti.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
U waqitta Perwerdigarning sözi uninggha kélip: —
9 “Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
Ornungdin turup Zidondiki Zarefatqa bérip, u yerde turghin; mana, Men u yerdiki bir tul xotunni séni béqishqa buyrudum, déyildi.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
U ornidin turup Zarefatqa bérip, sheherning derwazisigha kelgende, mana u yerde bir tul xotun otun térip turatti. U tul xotunni chaqirip: — Ötünimen, qachida manga ichkili azraq su élip kelgeysen, dédi.
11 Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
U su alghili mangghanda, u yene: — Ötünimen, manga qolungda bir chishlem nanmu alghach kelgeysen, dédi.
12 Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
Emma u: — Perwerdigar Xudayingning hayati bilen, sanga qesem qilimenki, mende héch nan yoq, peqet idishta bir changgal un, kozida azghine may bar, mana ikki tal otun tériwatimen; andin bérip özüm bilen oghlumgha nan étip, uni yep ölimiz, dédi.
13 Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
Iliyas uninggha: — Qorqmighin; bérip éytqiningdek qilghin; lékin awwal bir kichik toqach étip, manga élip kelgin; andin özüng bilen oghlunggha nan etkin.
14 Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
Chünki Israilning Xudasi Perwerdigar mundaq deydu: — «Perwerdigar yer yüzige yamghur yaghduridighan kün’gichilik idishtiki un tügimeydu we kozidiki may kémeymeydu», dédi.
15 Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
Shuning bilen u bérip, Iliyasning éytqinidek qildi we u, Iliyas we ayalning öyidikiler xéli künlergiche yédi.
16 Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
Perwerdigarning Iliyas arqiliq éytqan sözi boyiche, idishtiki un tügimidi we kozidiki maymu kémeymidi.
17 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
Shu ishlardin kéyin shundaq boldiki, öyning igisi bolghan bu ayalning oghli késel boldi. Uning késili shundaq éghirliship kettiki, uningda nepes qalmidi.
18 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
Ayal Iliyasqa: — I Xudaning adimi, méning sen bilen néme alaqem bar idi? Sen gunahimni yadqa keltürüp, oghlumning jénigha zamin bolushqa keldingmu? — dédi.
19 Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
U uninggha: — Oghlungni qolumgha bergin, dep uni uning quchiqidin élip özi olturghan balixanigha élip chiqip öz ornigha qoyup,
20 Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
Perwerdigargha peryad qilip: — I Xudayim Perwerdigar, men méhman bolghan bu tul xotunning oghlini öltürüsh bilen uning béshighimu bala chüshürdungmu? — dep nida qildi.
21 Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
U balining üstige üch qétim özini chaplap, Perwerdigargha peryad qilip: — I Perwerdigar Xudayim, bu balining jéni özige yene yénip kirsun! — dep nida qildi.
22 Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
Perwerdigar Iliyasning peryadini anglidi; balining jéni uninggha yénip kirishi bilen u tirildi.
23 Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
Iliyas balini balixanidin élip chüshüp, öyge kirip, anisigha tapshurup berdi. Iliyas: — Mana oghlung tiriktur, dédi.
24 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”
Ayal Iliyasqa: — Men shu ish arqiliq emdi séning Xudaning adimi ikenlikingni, aghzingdin chiqqan Perwerdigarning sözi heqiqet ikenlikini bildim, dédi.