< 1 Kings 17 >
1 Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
Tišbéjec Elija, ki je bil izmed prebivalcev Gileáda, je rekel Ahábu: » Kakor živi Gospod, Izraelov Bog, pred katerim stojim, tukaj ta leta ne bo niti rose niti dežja, razen glede na mojo besedo.«
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
Gospodova beseda je prišla k njemu, rekoč:
3 “Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
»Pojdi od tod in se obrni proti vzhodu in se skrij pri potoku Kerítu, ki je pred Jordanom.
4 Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
Zgodilo se bo, da boš pil iz potoka, krokarjem pa sem zapovedal, da te tam hranijo.«
5 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
Tako je odšel in storil glede na Gospodovo besedo, kajti odšel je in prebival pri potoku Kerítu, ki je pred Jordanom.
6 Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
Krokarji so mu prinašali kruh in meso zjutraj ter kruh in meso zvečer, pil pa je iz potoka.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
Čez nekaj časa se je pripetilo, da je potok usahnil, ker v deželi ni bilo dežja.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
K njemu je prišla beseda od Gospoda, rekoč:
9 “Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
»Vstani, pojdi v Zarepto, ki pripada Sidónu in prebivaj tam. Glej, tamkajšnji vdovi sem zapovedal, da te podpira.«
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
Tako je vstal in odšel v Zarepto. Ko je prišel k velikim vratom mesta, glej, je bila tam ženska vdova, ki je nabirala veje. Zaklical je k njej ter ji rekel: »Prinesi mi, prosim te, malo vode v posodi, da lahko pijem.«
11 Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
Ko je šla, da bi to prinesla, je zaklical k njej in rekel: »Prinesi mi, prosim te, grižljaj kruha v svoji roki.«
12 Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
Rekla je: » Kakor Gospod, tvoj Bog, živi, nimam kolača, temveč prgišče moke v sodčku in malo olja v vrču in glej, nabiram dve palici, da lahko grem in to pripravim zase in za svojega sina, da bova to lahko pojedla in umrla.«
13 Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
Elija ji je rekel: »Ne boj se. Pojdi in stôri, kakor si rekla. Toda od tega najprej meni naredi majhen kolač in mi ga prinesi, potem pa naredi zase in za svojega sina.
14 Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
Kajti tako govori Gospod, Izraelov Bog: ›Sodček z moko ne bo pošel niti v vrču ne bo zmanjkalo olja do dneva, ko Gospod pošlje dež na zemljo.‹«
15 Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
Odšla je in storila glede na Elijevo izjavo. Ona, on in njena hiša so jedli mnogo dni.
16 Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
In sodček z moko ni pošel niti olja v vrču ni zmanjkalo, glede na Gospodovo besedo, ki jo je govoril po Eliju.
17 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
Po teh stvareh se je pripetilo, da se je sin ženske, gospodarice hiše, počutil bolnega, in njegova slabost je bila tako huda, da v njem ni ostalo nobenega diha.
18 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
Eliju je rekla: »Kaj imam s teboj, oh ti Božji mož? Ali si prišel k meni, da mi prikličeš moj greh v spomin in da ubiješ mojega sina?«
19 Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
Rekel ji je: »Daj mi svojega sina.« Vzel ga je iz njenega naročja in ga odnesel gor na podstrešje, kjer je prebival in ga položil na svojo lastno posteljo.
20 Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
Klical je h Gospodu in rekel: »Oh Gospod, moj Bog, mar si zlo privedel tudi nad to vdovo, pri kateri se mudim, s pokončanjem njenega sina?«
21 Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
Trikrat se je raztegnil nad otrokom, klical h Gospodu in rekel: »Oh Gospod, moj Bog, prosim te, naj se duša tega otroka ponovno vrne vanj.«
22 Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
Gospod je uslišal Elijev glas in otrokova duša se je ponovno vrnila vanj in je oživel.
23 Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
Elija je vzel otroka, ga privedel dol iz sobe v hišo in ga izročil njegovi materi. Elija je rekel: »Poglej, tvoj sin živi.«
24 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”
Ženska je rekla Eliju: »Po tem sedaj vem, da si Božji mož in da je Gospodova beseda v tvojih ustih resnična.«