< 1 Kings 17 >

1 Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
Kinuna ni Elias a taga-Tisbe a masakupan ti Galaad, kenni Ahab, “Iti nagan ni Yahweh nga adda iti agnanayon a Dios ti Israel, a pagserserbiak, awanto ti linnaaw wenno tudo kadagitoy a tawtawen malaksid no ibagak nga umadda.”
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
Immay ti sao ni Yahweh kenni Elias a kunana,
3 “Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
“Pumanawka ditoy ket mapanka iti daya; aglemmengka iti waig ti Kerit nga adda iti daya ti Jordan.
4 Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
Uminomkanto iti danum iti waig ket binilinkon dagiti uwak a pakanendakanto sadiay.
5 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
Napan ngarud ni Elias ket inaramidna ti kas iti sao nga imbilin ni Yahweh. Napan nagnaed isuna idiay igid ti waig ti Kerit, nga adda iti daya ti Jordan.
6 Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
Nangyeg dagiti uwak kenkuana iti tinapay ken karne iti agsapa ken iti rabii, ket imminum isuna iti waig.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
Ngem saan a nagbayag, natianan ti waig gapu ta saan a nagtudtudo iti daga.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
Immay ti sao ni Yahweh kenkuana a kinunana,
9 “Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
“Agrubwatka, mapanka idiay Sarefat a masakupan ti Sidon, ket agnaedka sadiay. Dumngegka, binilinko ti maysa a balo a babai sadiay a mangisabetto iti kasapulam.”
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
Nagrubuat ngarud isuna ket napan idiay Sarefat ket idi makadanon iti pagserkan ti siudad, adda maysa a balo a babai sadiay a mangaykayo. Isu nga immawag isuna kenkuana ket kinunana, “Pangngaasim ta iyegannak iti bassit a danum tapno uminomak.”
11 Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
Bayat a mapmapan ti balo tapno mangala iti danum, immawag ni Elias kenkuana ket kinunana, “Pangngaasim ta iyegannak iti maysa a tinapay.”
12 Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
Simmungbat ti balo, “Iti nagan ni Yahweh a Diosmo nga adda iti agnanayon, awan ti tinapayko, ngem adda sangarakem laeng nga arina iti burnay ken sangkabassit a lana iti garapon. Kitaem, mangal-alaak iti dua a kayo a pagsungrod tapno panglutok iti daytoy nga agpaay kaniak ken iti anakko a lalaki, tapno makapangankami ket kalpasanna, mataykami.”
13 Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
Kinuna ni Elias kenkuana, “Saanka nga agdanag. Mapanka ket aramidem ti imbagam, ngem iyaramidannak nga umuna iti sangkabassit a tinapay ket iyegmo kaniak. Ket kalpasanna, agaramidka iti para kenka ken iti anakmo.
14 Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
Ta kuna ni Yahweh a Dios ti Israel, 'Saanto a maibusan ti burnay ti arina, ket saan pay nga agsardeng ti panagayus ti garapon ti lana, agingga iti aldaw a mangipatulod ni Yahweh iti tudo iti daga.”
15 Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
Isu nga inaramidna ti imbaga ni Elias kenkuana, ket isuna ken ti anakna agraman ni Elias, adda umanay a taraonda iti adu nga aldaw.
16 Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
Saan a naibusan ti burnay ti arina, ken saan a naibusan ti garapon iti lana, kas iti imbaga ti sao ni Yahweh, nga imbagana babaen kenni Elias.
17 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
Kalpasan dagidiay a banbanag, nagsakit ti anak ti balo nga akin-kukua iti balay. Nakaro unay ti sakitna nga uray la awanen ti anges a nabati kenkuana.
18 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
Isu a kinuna ti balo kenni Elias, “Ania ti basolko kenka, tao ti Dios? Immayka kadi kaniak tapno ipalagipmo dagiti basolko ken patayem ti anakko?”
19 Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
Ket simmungbat ni Elias iti balo, “Itedmo kaniak ti anakmo.” Innala ni Elias ti ubing kadagiti takiag ti balo ket binagkatna nga impan iti akin-ngato a siled a pagturturoganna, ket impaidanna ti ubing iti pagiddaanna.
20 Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
Immasug isuna kenni Yahweh ket kinunana, “O Yahweh a Diosko, nangyegka met kadi iti didigra iti balo a pakipagnanaedak, babaen iti panangpataymo iti anakna?”
21 Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
Ket namitlo a nagpakleb ni Elias iti bagi ti ubing; immasug isuna kenni Yahweh ket kinunana, “O Yahweh a Diosko, agpakaasiak kenka, pangngaasim ta isublim koma ti biag daytoy nga ubing.”
22 Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
Impangag ni Yahweh ti timek ni Elias; naisubli ti biag ti ubing ket nagbiag ti ubing.
23 Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
Inruar ni Elias ti ubing iti kuartona sana inyulog ket intedna iti inana, ket kinunana, “Adtoy, sibibiag ti anakmo.”
24 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”
Kinuna ti babai kenni Elias, “Ita, ammokon a taonaka ti Dios, ken ti sao ni Yahweh iti ngiwatmo ket pudno.”

< 1 Kings 17 >