< 1 Kings 17 >
1 Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
És szóla Thesbites Illés, a Gileád lakói közül, Akhábnak: Él az Úr, az Izráel Istene, a ki előtt állok, hogy ez esztendőkben sem harmat, sem eső nem lészen; hanem csak az én beszédem szerint.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
És lőn az Úrnak beszéde ő hozzá, mondván:
3 “Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
Menj el innét, és menj napkelet felé, és rejtezzél el a Kérith patakja mellett, mely a Jordán felé folyik.
4 Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
És a patakból lesz néked italod; a hollóknak pedig megparancsoltam, hogy tápláljanak téged ott.
5 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
Elméne azért, és az Úrnak beszéde szerint cselekedék; és elméne és leüle a Kérith patakja mellett, a mely a Jordán felé folyik.
6 Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
És a hollók hoztak néki kenyeret és húst reggel és este, és a patakból ivott.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
És lőn néhány nap múlva, hogy kiszáradt a patak; mert nem volt eső a földre.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
És lőn az Úrnak beszéde ő hozzá, mondván:
9 “Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
Kelj fel, és menj el Sareptába, a mely Sídonhoz tartozik, és légy ott; ímé megparancsoltam ott egy özvegyasszonynak, hogy gondoskodjék rólad.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
És felkelvén, elméne Sareptába, és mikor a város kapujához érkezett, ímé egy özvegyasszony volt ott, a ki fát szedegetett, és megszólítván azt, monda néki: Hozz, kérlek, egy kevés vizet nékem valami edényben, hogy igyam.
11 Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
De mikor az elment, hogy vizet hozzon, utána kiáltott, és monda néki: Hozz, kérlek, egy falat kenyeret is kezedben.
12 Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
Az pedig monda: Él az Úr, a te Istened, hogy nincs semmi sült kenyerem, csak egy marok lisztecském van a vékában, és egy kevés olajom a korsóban, és most egy kis fát szedegetek, és haza megyek, és megkészítem azt magamnak és az én fiamnak, hogy megegyük és azután meghaljunk.
13 Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
Monda pedig néki Illés: Ne félj, menj el, cselekedjél a te beszéded szerint; de mindazáltal nékem süss abból először egy kis pogácsát, és hozd ide; magadnak és a te fiadnak pedig azután süss;
14 Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
Mert azt mondja az Úr, Izráel Istene, hogy sem a vékabeli liszt el nem fogy, sem a korsóbeli olaj meg nem kevesül addig, míg az Úr esőt ád a földnek színére.
15 Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
És ő elméne, és az Illés beszéde szerint cselekedék, és evék mind ő, mind amaz, mind annak háznépe, naponként.
16 Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
A vékabeli liszt nem fogyott el, sem pedig a korsóbeli olaj nem kevesült meg, az Úrnak beszéde szerint, a melyet szólott Illés által.
17 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
És lőn ezek után, hogy megbetegedék a ház gazdasszonyának fia, és az ő betegsége felette nagy vala, annyira, hogy már a lélekzete is elállott.
18 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
Monda azért Illésnek: Mit vétettem ellened, Istennek embere? Azért jöttél hozzám, hogy eszembe juttassad álnokságomat, és megöljed az én fiamat?
19 Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
És monda néki: Add ide a te fiadat. És ő elvevé azt az ő kebeléről, és felvivé a felházba, a melyben ő lakik vala, és az ő ágyára fekteté.
20 Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
Akkor kiálta az Úrhoz, és monda: Én Uram, Istenem, nyomorúságot hozol erre az özvegyre is, a kinél én lakom, hogy az ő fiát megölöd?
21 Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
És ráborult háromszor a gyermekre, és felkiáltott az Úrhoz, mondván: Én Uram, Istenem, térítsd vissza e gyermek lelkét ő belé!
22 Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
És meghallgatta az Úr Illés szavát, és megtért a gyermekbe a lélek, és megélede.
23 Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
És felvévén Illés a gyermeket, alávivé őt a felházból a házba, és adá őt az ő anyjának, és monda Illés: Lássad, él a te fiad!
24 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”
És monda az asszony Illésnek: Most tudtam meg, hogy te Isten embere vagy, és hogy az Úrnak beszéde a te ajkadon: igazság.