< 1 Kings 17 >

1 Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
Tedy Eliáš Tesbitský, obyvatel Galádský, mluvil k Achabovi: Živť jest Hospodin Bůh Izraelský, před jehož oblíčejem stojím, že nebude těchto let rosy ani deště, jediné vedlé řeči mé.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
I stalo se slovo Hospodinovo k němu, řkoucí:
3 “Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
Odejdi odsud a obrať se k východu, a skrej se u potoka Karit, kterýž jest naproti Jordánu.
4 Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
A budeš z toho potoka píti, krkavcům pak jsem přikázal, aby tě tam krmili.
5 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
Kterýž odšed, učinil, jakž mu přikázal Hospodin. Nebo odšed, usadil se při potoku Karit, kterýž byl proti Jordánu.
6 Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
A krkavci přinášeli jemu chléb a maso každého jitra, též chléb a maso každého večera, a z potoka pil.
7 Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
Tedy po přeběhnutí dnů některých vysechl ten potok, nebo nebylo žádného deště v té zemi.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
I stalo se slovo Hospodinovo k němu, řkoucí:
9 “Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
Vstaň a jdi do Sarepty Sidonské, a buď tam. Aj, přikázal jsem ženě vdově, aby tě živila.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
Kterýž vstav, šel do Sarepty, a přišel k bráně města, a aj, žena vdova sbírala tu dříví. A zavolav jí, řekl: Medle, přines mi trochu vody v nádobě, abych se napil.
11 Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
A když šla, aby přinesla, zavolal jí zase a řekl: Medle, přines mi také kousek chleba v ruce své.
12 Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
I odpověděla: Živť jest Hospodin Bůh tvůj, žeť nemám žádného chleba, ani podpopelného, kromě hrsti mouky v kbelíku a maličko oleje v nádobce, a aj, sbírám dvě dřevě, abych šla a připravila to sobě a synu svému, abychom snědouce to, za tím zemříti musili.
13 Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
I řekl jí Eliáš: Neboj se. Jdi a učiň, jakž jsi řekla, a však udělej mi prvé z toho malý chléb podpopelný a přines mi; potom sobě a synu svému uděláš.
14 Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
Neboť toto praví Hospodin Bůh Izraelský: Mouka z kbelíka toho nebude strávena, aniž oleje v nádobce té ubude až do toho dne, když dá Hospodin déšť na zemi.
15 Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
I šla a učinila vedlé řeči Eliášovy, a jedla ona i on i čeled její až do těch dní.
16 Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
Z kbelíka toho mouka nebyla strávena, aniž oleje v nádobce ubylo, vedlé řeči Hospodinovy, kterouž mluvil skrze Eliáše.
17 Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
A když to přeběhlo, stalo se, že se roznemohl syn ženy, paní toho domu, a byla nemoc jeho velmi těžká, tak že nezůstalo v něm dýchání.
18 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
Protož řekla Eliášovi: Co mně a tobě, muži Boží? Přišel jsi ke mně, abys mi připomenul nepravost mou, a umořil syna mého?
19 Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
Kterýž odpověděl jí: Dej sem syna svého. A vzav ho z lůna jejího, vnesl jej na síň, kdež sám přebýval, a položil ho na lůžko své.
20 Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
Tedy volal k Hospodinu a řekl: Hospodine Bože můj, také-liž s tou vdovou, u kteréž pohostinu jsem, tak zle nakládáš, že jsi umořil syna jejího?
21 Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
A roztáh se nad dítětem po třikrát, zvolal k Hospodinu a řekl: Hospodine Bože můj, prosím, nechť se navrátí duše dítěte tohoto do vnitřností jeho.
22 Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
I vyslyšel Hospodin hlas Eliášův, a navrátila se duše dítěte do vnitřností jeho, i ožilo.
23 Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
A vzav Eliáš dítě, snesl je z síně do domu, a dal je matce jeho. I řekl Eliáš: Pohleď, syn tvůj živ jest.
24 Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”
Tedy řekla žena Eliášovi: Jižť jsem nyní poznala, že jsi muž Boží, a že řeč Hospodinova v ústech tvých jest pravá.

< 1 Kings 17 >