< 1 Kings 16 >

1 Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
A LAILA hiki mai la ka olelo a Iehova ia Iehu ke keiki a Hanani, e ku e ana ia Baasa, i ka i ana mai,
2 “Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
No ka mea, ua hookiekie ae au ia oe mai ka lepo ae, a hoolilo au ia oe i alii maluna o ko'u poe kanaka Iseraela; a ua hele hoi oe ma ka aoao o Ieroboama, a ua hoolilo ae oe i ko'u poe kanaka Iseraela e lawehala, e hoonaukiuki mai lakou ia'u me ko lakou mau hewa;
3 Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
Eia hoi, e kaili ae auanei au i ka hope o Baasa a me ka hope o kana ohana, a e hoolilo ae au i kou ohana e like me ka ohana a Ieroboama ke keiki a Nebata.
4 Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
O ka Baasa mea e make maloko o ke kulanakauhale, oia ka na ilio e ai ai; a o kana mea e make ma kula, oia ka na manu o ka lewa e ai ai.
5 Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A o na oihana e ae a Baasa, a me kana mea i hana'i, a me kona ikaika, aole anei ia i kakauia ma ka buke 'a na lii o ka Iseraela?
6 Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A hiamoe iho la o Baasa me kona mau makua, a ua kanuia ma Tireza: a ua alii ae la o Ela kana keiki ma kona hakahaka.
7 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
Eia hoi, ma ka lima o Iehu ke kaula, ke keiki a Hanani i hiki mai ai ka Iehova olelo ku e ia Baasa, a i kana ohana hoi, no ka hewa a pau ana i hana'i imua o na maka o Iehova, e hoonaukiuki ia ia me ka hana a kona mau lima, i kona hoohalike ana me ka ohana a Ieroboama, a no kona pepehi ana ia ia.
8 Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
I ka iwakalua kumamaono o ka makahiki o Asa ke alii o Iuda, i hoomaka ai o Ela ke keiki a Baasa i kona alii ana maluna o ka Iseraela, ma Tireza i na makahiki elua.
9 Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
A kipi ae la ia ia kana kauwa o Zimeri ka luna o ka hapalua o kona mau kaa, ia ia ma Tireza, e inu ana a ona maloko o ka hale o Areza ka puuku o kona hale ma Tireza.
10 Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A komo ae la o Zimeri a pepehi ae la hoi ia ia, a hoomake loa ia ia, i ka iwakalua kumamahiku o ka makahiki o Asa ke alii o Iuda, a ua alii ae la oia ma kona hakahaka.
11 Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
Eia hoi kekahi, ia ia i hoomaka ai i kona alii ana, a noho ia ma ka nohoalii, pepehi koke ae la oia i ka ohana a pau a Baasa: aole oia i hokoe nona i kekahi kane, o kona io, a o kona mau hanauna.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
Pela i luku ai o Zimeri i ka ohana a pau a Baasa, e like me ka olelo a Iehova ana i olelo ku e ai ia Baasa ma ka lima o Iehu ke kaula;
13 nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
No na hewa a pau o Baasa, a no na hewa o Ela kana keiki, i lawehala ai laua, a i hoolilo ai hoi laua i ka Iseraela e lawehala, i ka hoonaukiuki ana ia Iehova ke Akua o ka Iseraela ma ko laua mau mea lapuwale.
14 Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A o na oihana e ae a Ela, a o ka mea a pau ana i hana'i, aole anei ia i kakauia ma ka buke oihana a na lii o ka Iseraela?
15 Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
I ka iwakalua kumamahiku o ka makahiki o Asa ke alii o Iuda, i alii ai o Zimeri i na la ehiku ma Tireza; a e hoomoana ku e ana na kanaka ia Gibetona o ko Pilisetia.
16 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
A lohe ae na kanaka hoomoana i ka olelo, ua kipi o Zimeri a ua pepehi hoi i ke alii: nolaila hooalii ae la ka Iseraela a pau ia Omeri ka alihikaua i alii maluna o ka Iseraela ia la i kahi hoomoana.
17 Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
Pii ae la o Omeri a me ka Iseraela pu a pau me ia, mai Gibetona ae, a hoopuni ae la ia Tireza.
18 Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
Eia hoi kekahi, i ka ike ana o Zimeri ua hoopioia ke kulanakauhale, komo ae la oia i ke keena alii o ko ke alii hale, a puhi iho la i ka hale o ke alii maluna o kona poo iho, a make iho la,
19 nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
No kona mau hewa ana i hana'i, i kana hana ino ana imua o na maka o Iehova, a i kona hele ana ma ka aoao o Ieroboama, a me kona hewa ana i hana'i, i lawehala ai ka Iseraela.
20 Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A o na oihana e ae a Zimeri, a me kona kipi ana, ana i hana'i, aole anei ia i kakauia ma ka buke oihana a na lii o ka Iseraela?
21 Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
Alaila maheleia'e la na kanaka o ka Iseraela i na apana elua: hahai kekahi hapalua mamuli o Tibeni ke keiki a Ginata, e hoalii ia ia; a hahai ae la kekahi hapalua mamuli o Omeri.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
Lanakila ae la ka poe kanaka i hahai mamuli o Omeri maluna o ka poe kanaka i hahai mamuli o Tibeni ke keiki a Ginata, a make o Tibeni, a alii ae la o Omeri.
23 Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
I ke kanakolu kumamakahi o ka makahiki o Asa ke alii o Iuda hoomaka ae la o Omeri i kona alii ana maluna o ka Iseraela, i na makahiki he umikumamalua: aono makahiki i alii ai oia ma Tireza.
24 Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
Kuai lilo mai la oia me Semera, i ka puu Samaria, i na talena kala elua, a kukulu ae la maluna o ka puu, a kapa ae i ka inoa o ke kulanakauhale ana i hana'i, o Samaria, mamuli o ka inoa o Semera ka haku aina o ka puu.
25 Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Aka, ua hana hewa ae la o Omeri imua o na maka o Iehova, a hoopakela aku i kona hewa mamua o ka poe a pau mamua ona.
26 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
No ka mea, na hele ae la oia ma na aoao a pau o Ieroboama ke keiki a Nebata, a me kona hewa i hoolilo ai oia i ka Iseraela e lawehala, e hoonaukiuki ia Iehova ke Akua o ka Iseraela ma ko lakou mau mea lapuwale.
27 Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
A o na oihana e ae a Omeri i hana'i a me ka ikaika ana i hoike ai, aole anei ia i kakauia ma ka buke oihana o na lii o ka Iseraela?
28 Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A hiamoe iho la o Omeri me kona mau makua ma Samaria, a ua alii ae la o Ahaba kana keiki ma kona hakahaka.
29 Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
Hoomaka ae la o Ahaba ke keiki a Omeri i kona alii ana maluna o ka Iseraela i ke kanakolu kumamawalu o ka makahiki o Asa ke alii o Iuda; a ua alii ae la o Ahaba ke keiki a Omeri maluna o ka Iseraela ma Samaria i na makahiki he iwakalua kumamalua.
30 Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Hoopakela ae la o Ahaba ke keiki a Omeri i ka hana hewa imua o na maka o Iehova mamua o ka poe a pau mamua ona.
31 Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
Eia hoi kekahi, me he mea la, he mea uuku nona ke hele ma na hewa o Ieroboama ke keiki a Nebata, lawe iho la oia ia Iesebela ke kaikamahine a Etebaala ke alii o ko Sidona, i wahine, a hele hoi ia e malama ia Baala, a hoomana ae la ia ia,
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
Kukulu ae la oia i kuahu no Baala maloko o ka hale o Baala, ana i hana'i ma Samaria.
33 Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
Hana iho la o Ahaba i wahi e hoomana'i, a ua oi aku ko Ahaba hoonaukiuki ana ia Iehova ke Akua o ka Iseraela mamua o na alii a pau o ka Iseraela mamua ona.
34 Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.
I kona mau la hoi, kukulu ae la o Hiela no Betela ia Ieriko; a ia Abirama i kana hiapo i hoonoho ai oia i ke kumu, a ia Seguba kana keiki hope loa i kukulu ai oia i na pani; e like me ka Iehova olelo ana i olelo mai ai ma ka lima o Iosua ke keiki a Nuna.

< 1 Kings 16 >