< 1 Kings 16 >

1 Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
Forsothe the word of the Lord was maad to Hieu, sone of Anany, ayens Baasa, and seide,
2 “Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
For that that Y reiside thee fro dust, and settide thee duyk on Israel, my puple; sotheli thou yedist in the weie of Jeroboam, and madist my puple Israel to do synne, that thou schuldist terre me to ire, in the synnes of hem; lo!
3 Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
Y schal kitte awey the hyndrere thingis of Baasa, and the hyndrere thingis of `his hows, and Y schal make thin hows as the hows of Jeroboam, sone of Nabath.
4 Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
Doggis schulen ete that man of Baasa, that schal be deed in citee, and briddis of the eyr schulen ete that man of Baasa, that schal die in the feeld.
5 Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Sotheli the residue of wordis of Baasa, and what euer thingis he dide, and hise batels, whether these ben not writun in the book of wordis of daies of the kynges of Israel?
6 Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Therfor Baasa slepte with hise fadris, and he was biried in Thersa; and Hela, his sone, regnede for hym.
7 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
Forsothe whanne the word of the Lord was maad in the hond of Hieu, sone of Anany, ayens Baasa, and ayens his hows, and ayens al yuel which he dide bifor the Lord, to terre hym to ire in the werkis of hise hondis, that he schulde be as the hows of Jeroboam, for this cause he killide hym, that is, Hieu, the prophete, the sone of Anany.
8 Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
In the sixe and twentithe yeer of Aza, kyng of Juda, Hela, the sone of Baasa, regnyde on Israel, in Thersa, twei yeer.
9 Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
And Zamry, `his seruaunt, duyk of the half part of knyytis, rebellide ayens hym; sotheli Hela was in Thersa, and drank, and was drunkun in the hows of Arsa, prefect of Thersa.
10 Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Therfor Zamri felde in, and smoot, and killide hym, in the seuene and twentithe yeer of Asa, kyng of Juda; and regnede for hym.
11 Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
And whanne he hadde regned, and hadde setun on his trone, he smoot al the hows of Baasa, and he lefte not therof a pissere to the wal, and hise kynnesmen, and frendis.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
And Zamri dide awey al the hows of Baasa, bi the word of the Lord, which he spak to Baasa, in the hond of Hieu, the prophete, for alle the synnes of Baasa,
13 nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
and for the synnes of Hela, his sone, whiche synneden, and maden Israel to do synne, and wraththiden the Lord God of Israel in her vanytees.
14 Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Sotheli the residue of the wordis of Hela, and alle thingis whiche he dide, whether these ben not writun in the book of wordis of daies of the kyngis of Israel?
15 Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
In the seuene and twentithe yeer of Aza, kyng of Juda, Zamri regnede seuene daies in Tharsa; forsothe the oost bisegide Gebethon, the citee of Philisteis.
16 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
And whanne it hadde herd, that Zamri hadde rebellid, and hadde slayn the kyng, al Israel made Amry kyng to hem, that was prince of the chyualrye, on Israel, in that dai, in `the castels.
17 Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
Therfor Amry stiede, and al Israel with hym, fro Gebethon, and bisegide Thersa.
18 Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
Sothely Zamri siy, that the citee schulde be ouercomun, and he entride in to the palis, and brente hym silf with the kyngis hows;
19 nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
and he was deed in hise synnes whiche he synnede, doynge yuel bifor the Lord, and goynge in the weie of Jeroboam, and in hise synnes, bi whiche he made Israel to do synne.
20 Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Sotheli the residue of wordis of Zamri, and of his tresouns, and tyrauntrie, whether these ben not writun in the book of wordis of daies of the kyngis of Israel?
21 Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
Thanne the puple of Israel was departid in to twei partis; the half part of the puple suede Thebny, sone of Geneth, to make hym kyng, and the half part suede Amry.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
Sotheli the puple that was with Amry, hadde maystry ouer the puple that suede Thebny, the sone of Geneth; and Thebny was deed, and Amri regnede.
23 Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
In the oon and thrittithe yeer of Aza, kyng of Juda, Amri regnede on Israel, twelue yeer; in Thersa he regnede sixe yeer.
24 Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
And he bouyte of Soomeer, for twei talentis of siluer, the hil of Samarie, and `bildide that hil; and he clepide the name of the citee, which he hadde bildid, bi the name of Soomer, lord of the hil of Samarie.
25 Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Forsothe Amry dide yuel in the siyt of the Lord, and wrouyte weiwardli, ouer alle men that weren bifor hym.
26 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
And he yede in al the weie of Jeroboam, sone of Nabath, and in hise synnes, bi whiche he made Israel to do synne, that he schulde terre to ire, in his vanytees, the Lord God of Israel.
27 Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Forsothe the residue of wordis of Amry, and hise batels, which he dide, whether these ben not writun in the book of wordis of daies of the kyngis of Israel?
28 Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
And Amry slepte with hise fadris, and was biried in Samarie; and Achab, his sone, regnede for hym.
29 Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
Forsothe Achab, the sone of Amry, regnede on Israel, in the `eiyte and thrittithe yeer of Asa, kyng of Juda; and Achab, sone of Amry, regnede on Israel, in Samarie, two and twenti yeer.
30 Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
And Achab, sone of Amry, dide yuel in the siyte of the Lord, ouer alle men that weren bifor hym;
31 Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
and it suffiside not to hym that he yede in the synnes of Jeroboam, sone of Nabath, ferthermore and he weddide a wijf, Jezabel, the douyter of Methaal, kyng of Sydoneis; and he yede, and seruyde Baal, and worschipide hym.
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
And he settide an auter to Baal in the temple of Baal, which he hadde bildid in Samarie, and he plauntide a wode;
33 Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
and Achab addide in his werk, and terride to ire the Lord God of Israel, more thanne alle kyngis of Israel that weren bifor hym.
34 Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.
Forsothe in hise daies Ahiel of Bethel bildide Jerico; in Abiram, his firste sone, he foundide it, in Segub, his laste sone, he settide yatis therof, bi the word of the Lord, which he hadde spoke in the hond of Josue, sone of Nun.

< 1 Kings 16 >