< 1 Kings 16 >
1 Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
Tada bi upućena riječ Jahvina Jehuu, sinu Hananijevu, protiv Baše:
2 “Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
“Iz praha sam te podigao i postavio knezom nad mojim narodom Izraelom, ali si ti krenuo Jeroboamovim putem i navodiš narod moj Izrael na grijehe te me razjaruješ njihovim grijesima;
3 Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
zato ću netragom pomesti Bašu i kuću njegovu: učinit ću s tvojom kućom kao i s kućom Jeroboama, sina Nebatova.
4 Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
Tko iz obitelji Bašine umre u gradu, pojest će ga psi, a tko im umre u polju, pojest će ga ptice nebeske.”
5 Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Ostala povijest Bašina, što je učinio, njegova djela, zar sve to nije zapisano u knjizi Ljetopisa kraljeva izraelskih?
6 Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Baša je počinuo sa svojim ocima i sahranjen je u Tirsi. Sin njegov Ela zakraljio se mjesto njega.
7 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
Ali riječ Jahvina po Jehuu proroku, sinu Hananijevu, nije bila upravljena protiv Baše i njegove kuće samo zbog toga što je činio zlo u očima Jahve i ljutio ga djelima svojih ruku te bio kao i kuća Jeroboamova nego i zbog toga što je i nju istrijebio.
8 Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
Dvadeset i šeste godine kraljevanja Ase u Judeji postade Ela, sin Bašin, kraljem Izraela u Tirsi; vladao je svega dvije godine.
9 Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
Njegov dvoranin Zimri, zapovjednik polovine bojnih kola, uroti se protiv njega. Kad je bio u Tirsi, opio se u kući Arse, upravitelja dvora u Tirsi.
10 Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Tada provali Zimri, udari na njega i ubi ga, dvadeset i sedme godine Asina kraljevanja Judejom, te zavlada mjesto njega.
11 Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
Čim je zavladao i sjeo na prijestolje, poubija svu obitelj Bašinu; nije mu poštedio ni što uza zid mokri, ni njegovih rođaka ni prijatelja.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
Tako Zimri iskorijeni svu kuću Bašinu po riječi koju je Jahve rekao protiv Baše preko sluge svoga proroka Jehua,
13 nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
zbog sviju grijeha što su ih činili Baša i sin mu Ela i tako zavodili Izraela, srdeći Jahvu, Boga Izraelova, svojim krivim bogovima.
14 Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Ostala povijest Elina, sve što je učinio, zar to nije zapisano u knjizi Ljetopisa kraljeva izraelskih?
15 Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
Dvadeset i sedme godine Asina kraljevanja Judejom postade Zimri kraljem u Tirsi i vladao je sedam dana. Narod je tada opsjedao Gibeton, koji je pripadao Filistejcima.
16 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
Kad je utaboreni narod čuo da se Zimri pobunio i ubio kralja, sav Izrael istoga dana u taboru proglasi kraljem nad Izraelom zapovjednika vojske Omrija.
17 Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
Zatim Omri i sav Izrael s njime odoše od Gibetona i opsjedoše Tirsu.
18 Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
Kad je Zimri vidio da će grad biti osvojen, uđe u utvrdu kraljevskoga dvora, zapali nad sobom kraljevski dvor i tako pogibe.
19 nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
To je bilo zbog grijeha koje je počinio radeći što je zlo u očima Jahvinim i hodeći putem Jeroboama i njegovih grijeha kojima je zavodio Izraela.
20 Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Ostala povijest Zimrijeva i njegova urota koju je skovao, zar sve to nije zapisano u knjizi Ljetopisa kraljeva izraelskih?
21 Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
Tada se Izraelov narod razdijelio: polovica se odlučila za Tibnija, sina Ginatova, da ga učini kraljem, a druga polovica za Omrija.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
Ali pristaše Omrijeve nadjačaše pristaše Tibnija, sina Ginatova, pa kad Tibni umrije, postade Omri kraljem.
23 Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
Trideset i prve godine Asina kraljevanja Judejom postade Omri kraljem Izraela za dvanaest godina. U Tirsi je kraljevao šest godina.
24 Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
Tada kupi od Šemera za dva talenta srebra brdo Samariju; sagradi grad koji po imenu Šemera, vlasnika brijega, nazva Samarija.
25 Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Ali je Omri činio zlo u očima Jahvinim i bio je gori od svojih prethodnika.
26 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
U svemu je slijedio Jeroboama, sina Nebatova, i njegove grijehe kojima je zavodio Izraela i srdio Jahvu, Boga Izraelova, svojim lažnim bogovima.
27 Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Ostala povijest Omrijeva, sve što je učinio, njegovi pothvati koje je izveo, zar to nije zapisano u knjizi Ljetopisa kraljeva izraelskih?
28 Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Omri počinu sa svojim ocima i sahranjen je u Samariji. Njegov sin Ahab postade kraljem mjesto njega.
29 Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
Ahab, sin Omrijev, postade izraelskim kraljem u trideset i osmoj godini Asina kraljevanja Judejom i vladao je dvadeset i dvije godine nad Izraelom u Samariji.
30 Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Ahab, sin Omrijev, činio je u očima Jahvinim više zla od svih svojih prethodnika.
31 Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
I malo mu bijaše što je hodio u grijesima Jeroboama, sina Nebatova, nego se još oženi Izebelom, kćerju Etbaala, kralja sidonskog, i poče služiti Baalu i klanjati mu se;
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
Baalu podiže žrtvenik u Baalovu hramu što ga bijaše sagradio u Samariji.
33 Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
Ahab je podigao i Ašeru i učinio druga zlodjela i razljutio Jahvu, Boga Izraelova, više od svih kraljeva izraelskih koji bijahu prije njega.
34 Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.
Za njegova je vremena Hiel iz Betela sagradio Jerihon; uz žrtvu svoga prvorođenca Abirama podigao je temelje, a uz žrtvu svoga mezimca Seguba postavio je gradska vrata, po riječi koju je Jahve rekao po svome sluzi Jošui, sinu Nunovu.