< 1 Kings 15 >

1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
Nibatning oƣli Yǝroboam padixaⱨning sǝltǝnitining on sǝkkizinqi yilida Abiyam Yǝⱨudaning üstigǝ padixaⱨ bolup
2 ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
Yerusalemda üq yil sǝltǝnǝt ⱪildi. Uning anisining ismi Maakaⱨ bolup, Abixalomning ⱪizi idi.
3 Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
Abiyamning ⱪǝlbi bowisi Dawutning kɵnglidǝk Hudasi Pǝrwǝrdigarƣa pütünlǝy beƣixlanƣan ǝmǝs idi, bǝlki atisi Rǝⱨoboamning uningdin ilgiri ⱪilƣan barliⱪ gunaⱨlirida mangatti.
4 Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
Xundaⱪtimu Dawutning sǝwǝbidin Hudasi Pǝrwǝrdigar Yerusalemda uningƣa [yoruⱪ] bir qiraƣni ⱪaldurux üqün, Dawutning ǝwladini uningdin keyinmu tiklǝp turƣuzdi wǝ Yerusalemni ⱪoƣdidi.
5 Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
Qünki Dawut Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ durus bolƣanni ⱪilip, Ⱨittiy Uriyaƣa ⱪilƣanliridin baxⱪa ɵmrining ⱨǝmmǝ künliridǝ Pǝrwǝrdigar uningƣa ǝmr ⱪilƣanliridin qiⱪmidi.
6 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
Əmdi [Abiyamning] pütün ɵmridǝ Rǝⱨoboam bilǝn Yǝroboam bir-biri bilǝn jǝng ⱪilixip turdi.
7 Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
Abiyamning baxⱪa ixliri wǝ ⱪilƣanlirining ⱨǝmmisi «Yǝⱨuda padixaⱨlirining tarih-tǝzkiriliri» degǝn kitabta pütülgǝn ǝmǝsmidi? Abiyam bilǝn Yǝroboam bir-biri bilǝn jǝng ⱪilixip turatti.
8 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Abiyam ɵz ata-bowilirining arisida uhlidi; ular uni «Dawutning xǝⱨiri»dǝ dǝpnǝ ⱪildi. Andin oƣli Asa ornida padixaⱨ boldi.
9 Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
Israilning padixaⱨi Yǝroboam sǝltǝnitining yigirminqi yilida Asa Yǝⱨudaning üstigǝ padixaⱨ bolup
10 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
Yerusalemda ⱪiriⱪ bir yil sǝltǝnǝt ⱪildi. Uning qong anisining ismi Maaⱪaⱨ bolup, Abixalomning ⱪizi idi.
11 Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
Asa atisi Dawut ⱪilƣandǝk Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ durus bolƣanni ⱪildi.
12 Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
U kǝspiy bǝqqiwazlarni zemindin ⱨǝydǝp, ata-bowiliri yasatⱪan ⱨǝmmǝ yirginqlik mǝbudlarni yoⱪitiwǝtti.
13 Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
U yǝnǝ qong anisi Maaⱪaⱨni yirginqlik bir «Axǝraⱨ» tüwrükni yasiƣini üqün hanixliⱪ mǝrtiwisidin qüxürüwǝtti. Asa bu yirginqlik butni kesip Kidron jilƣisida kɵydürüwǝtti.
14 Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
«Yuⱪiri jaylar» yoⱪitilmisimu, Asaning ⱪǝlbi ɵmrining barliⱪ künliridǝ Pǝrwǝrdigarƣa pütünlǝy beƣixlanƣanidi.
15 Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
Ⱨǝm atisi ⱨǝm u ɵzi [Pǝrwǝrdigarƣa] atap yasiƣan nǝrsilǝrni, jümlidin kümüx bilǝn altunni wǝ türlük ⱪaqa-ⱪuqilarni Pǝrwǝrdigarning ɵyigǝ kǝltürdi.
16 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
Əmdi Asa wǝ Israilning padixaⱨi Baaxa barliⱪ künliridǝ bir-biri bilǝn jǝng ⱪilixip turdi.
17 Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
Israilning padixaⱨi Baaxa Yǝⱨudaƣa ⱪarxi ⱨujum ⱪildi; ⱨeqkim Yǝⱨudaning padixaⱨi Asa bilǝn bardi-kǝldi ⱪilmisun dǝp, Ramaⱨ xǝⱨirini mǝⱨkǝm ⱪilip yasidi.
18 Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
U waⱪitta Asa Pǝrwǝrdigarning ɵyidiki hǝzinilǝrdǝ ⱪalƣan barliⱪ altun-kümüx wǝ padixaⱨning ordisidiki hǝzinilǝrdǝ ⱪalƣan altun-kümüxni elip hizmǝtkarlirining ⱪoliƣa tapxurdi; andin Asa padixaⱨ ularni Dǝmǝxⱪtǝ turuxluⱪ Suriyǝ padixaⱨi Ⱨezionning nǝwrisi, Tabrimmonning oƣli Bǝn-Ⱨadadⱪa ǝwǝtti wǝ xular bilǝn bu hǝwǝrni yǝtküzüp: —
19 Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
«Mening atam bilǝn silining atilirining arisida bolƣandǝk mǝn bilǝn silining arilirida bir ǝⱨdǝ bolsun. Mana, siligǝ kümüx bilǝn altundin ⱨǝdiyǝ ǝwǝttim; ǝmdi Israilning padixaⱨi Baaxa bilǝn bolƣan ǝⱨdiliridin ⱪollirini üzsilǝ; xuning bilǝn u meni ⱪamal ⱪilixtin ⱪol üzsun» — dedi.
20 Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
Bǝn-Ⱨadad Asa padixaⱨning sɵzigǝ kirip, ɵz ⱪoxunining sǝrdarlirini Israilning xǝⱨǝrlirigǝ ⱨujum ⱪilixⱪa ǝwǝtip, Ijon, Dan, Bǝyt-Maaⱪaⱨdiki Abǝl, pütkül Kinnǝrǝt yurti bilǝn Naftalining pütkül zeminini beⱪindurdi.
21 Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
Baaxa bu hǝwǝrni anglap, Ramaⱨ istiⱨkamini yasaxtin ⱪolini yiƣip, Tirzaⱨⱪa berip turdi.
22 Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
Asa padixaⱨ bolsa pütkül Yǝⱨudaning adǝmlirini ⱨeqbirini ⱪoymay qaⱪirip yiƣdi; ular Baaxa Ramaⱨ xǝⱨirini yasaxⱪa ixlǝtkǝn taxlar bilǝn yaƣaqlarni Ramaⱨtin toxup elip kǝtti. Asa padixaⱨ muxularni ixlitip Binyamin zeminidiki Gebani wǝ Mizpaⱨni mǝⱨkǝm ⱪilip yasidi.
23 Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Əmdi Asaning baxⱪa ixliri, uning zor ⱪudriti, uning ⱪilƣinining ⱨǝmmisi, xundaⱪla yasiƣan xǝⱨǝrlǝr toƣrisida «Yǝⱨuda padixaⱨlirining tarih-tǝzkiriliri» degǝn kitabta pütülgǝn ǝmǝsmidi? Lekin ⱪeriƣanda, uning putida bir kesǝl pǝyda boldi.
24 Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Asa ɵz ata-bowiliri arisida uhlidi wǝ Dawutning xǝⱨiridǝ dǝpnǝ ⱪilindi. Andin uning oƣli Yǝⱨoxafat ornida padixaⱨ boldi.
25 Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
Yǝⱨudaning padixaⱨi Asaning sǝltǝnitining ikkinqi yilida Yǝroboamning oƣli Nadab Israil üstigǝ ⱨɵküm sürüxkǝ baxlidi; u Israilƣa ikki yil padixaⱨ boldi.
26 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
U Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ rǝzil bolƣanni ⱪilip atisining yolida mengip, atisining Israilni gunaⱨⱪa putlaxturƣan gunaⱨlirida mangdi.
27 Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
Lekin Issakar jǝmǝtidin bolƣan Ahiyaⱨning oƣli Baaxa uningƣa ⱪǝst ⱪilip, uni Filistiylǝrning tǝwǝsidiki Gibbetonda ɵltürdi. Xu qaƣda Nadab pütün Israillar bilǝn birliktǝ Gibbetonƣa ⱪorxap ⱨujum ⱪiliwatatti.
28 Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Yǝⱨuda padixaⱨi Asaning sǝltǝnitining üqinqi yilida Baaxa Nadabni ɵltürüp, ɵzi uning ornida padixaⱨ boldi.
29 Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
Wǝ xundaⱪ boldiki, u padixaⱨ bolƣanda Yǝroboamning pütkül jǝmǝtini qepip ɵltürdi; Pǝrwǝrdigarning ⱪuli Xiloⱨluⱪ Ahiyaⱨning wasitisi bilǝn eytⱪan sɵzi ǝmǝlgǝ axurulup, u Yǝroboamning jǝmǝtidin nǝpisi barlarni birinimu ⱪoymay pütünlǝy yoⱪatti.
30 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
Bu ix Yǝroboamning sadir ⱪilƣan gunaⱨliri ⱨǝm uning Israilni gunaⱨⱪa putlaxturƣan gunaⱨliri tüpǝylidin boldi; u xular bilǝn Israilning Hudasi Pǝrwǝrdigarning ƣǝzipini ⱪattiⱪ ⱪozƣiƣanidi.
31 Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Nadabning baxⱪa ixliri bilǝn ⱪilƣanlirining ⱨǝmmisi «Israil padixaⱨlirining tarih-tǝzkiriliri» degǝn kitabta pütülgǝn ǝmǝsmidi?
32 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
Asa wǝ Israilning padixaⱨi Baaxa barliⱪ künliridǝ bir-biri bilǝn jǝng ⱪilixip turdi.
33 Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
Yǝⱨudaning padixaⱨi Asaning sǝltǝnitining üqinqi yilida Ahiyaⱨning oƣli Baaxa pütün Israil üstigǝ Tirzaⱨta ⱨɵküm sürüxkǝ baxlidi; u yigirmǝ tɵt yil sǝltǝnǝt ⱪildi.
34 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
U Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ rǝzil bolƣanni ⱪildi; u Yǝroboamning yolida yürüp, Israilni gunaⱨⱪa patⱪuzƣan gunaⱨida mangdi.

< 1 Kings 15 >