< 1 Kings 15 >

1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
Járobeám királynak, Nebát fiának tizennyolcadik évében király lett Abíjám Jehúda fölött.
2 ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
Három évig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve Máakha, Abísálóm leánya.
3 Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
És járt atyjának mindazon vétkeiben, melyeket őelőtte elkövetett, és szíve nem volt tökéletes az Örökkévaló, az ő Istene iránt, mint ősének, Dávidnak szíve.
4 Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
Mert Dávid kedvéért adott neki az Örökkévaló; az ő Istene, mécsest Jeruzsálemben, támasztván ő utána fiát és fönntartván Jeruzsálemet;
5 Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
mivel Dávid tette azt, ami helyes az Örökkévaló szemeiben és nem tért el mindattól, amit neki parancsolt, élete minden napjaiban, kivéve a chittita Úrija dolgában.
6 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
És háború volt Rechabeám és Járobeám között élete minden napjaiban:
7 Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
Abíjámnak egyéb dolgai pedig és mindaz, mit cselekedett, hiszen meg vannak írva Jehúda királyai történetének könyvében. És háború volt Abíjám és Járobeám között.
8 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
És feküdt Abíjám ősei mellé éa eltemették őt Dávid városában. Király lett helyette fia, Ásza.
9 Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
Járobeámnak, Izraél királyának húszadik évében király lett Ásza Jehúda fölött;
10 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
negyvenegy évig uralkodott Jeruzsálemben; anyjának neve pedig Máakha, Abísálóm leánya.
11 Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
És tette Ásza azt, ami helyes az Örökkévaló szemeiben, úgy mint őse, Dávid.
12 Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
Elmozdította a szentelt férfiakat az országból és eltávolította mind a bálványokat, melyeket készítettek ősei.
13 Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
Anyját, Máakhát is eltávolította, hogy ne legyen uralkodónő, mivel förtelmes képet készített az aséra számára; kivágta Ásza a förtelmes képet és elégette a Kidrón völgyében.
14 Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
De a magaslatok nem szűntek meg; csakhogy tökéletes volt Ászának szíve az Örökkévalóhoz minden napjaiban.
15 Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
És bevitte atyjának szentségeit és a maga szentségeit az Örökkévaló házába: ezüstöt, aranyat és edényeket.
16 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
És háború volt Ásza éa Báesa, Izraél királya között minden napjaikban.
17 Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
Fölvonult Báesa, Izraél királya Jehúda ellen és építette Rámát, hogy ne engedjen senkit ki- és bemenni Ásza, Jehúda királyának részéről.
18 Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
Akkor vette Ásza mind az ezüstöt és aranyat, ami megmaradt az Örökkévaló házának kincseiből és a király házának kincseit, szolgáinak kezébe adta, és elküldte őket Ásza király Ben-Hadádhoz, Tabrimmón fiához, Chezjón fiához, Arám királyához, aki Damaszkuszban székelt, mondván:
19 Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
Szövetség van köztem és közted, atyám és atyád között; íme küldtem neked ajándékot, ezüstöt és aranyat; menj, bontsd föl szövetségedet Báesával, Izraél királyával, hogy elvonuljon tőlem.
20 Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
Hallgatott Ben-Hadad Ásza királyra, elküldte az ő hadvezéreit Izraél városai ellen és megverte Ijjónt, Dánt, Abél-Bét-Máakhát, meg az egész Kinnerótot Naftáli egész földjével együtt.
21 Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
És volt, midőn meghallotta Báesa, fölhagyott Ráma építésével és maradt Tircában.
22 Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
Ásza király pedig összehívta egész Jehúdát, senki sem volt fölmentve, és elhordták Ráma köveit és fáit, melyekkel épített volt Báesa; és építette azokból Ásza király a Benjáminbeli Gébát és Micpát.
23 Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ászának mind az egyéb dolgai pedig, minden hőstette és mindaz, amit cselekedett, meg a városok, melyeket épített, hiszen meg vannak írva Jehúda királyai történetének könyvében. Csak vénsége idejében megbetegedett a lábaira.
24 Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
És feküdt Ásza ősei mellé és eltemették ősei mellé, ősének, Dávidnak városában. És király lett helyette fia, Jehósáfát.
25 Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
Nádáb, Járobeám fia pedig király lett Izraél fölött Ászának, Jehúda királyának második évében és uralkodott Izraél fölött két évig.
26 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
És tette azt, ami rossz az Örökkévaló szemeiben és járt atyának útja szerint és vétke szerint, mellyel vétkezésre indította Izraélt.
27 Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
De összeesküdött ellene Báesa, Achíja fia, Jisszákhár házából, éa megverte őt Báesa Gibbetónban, mely a filiszteusoké volt; Nádáb és egész Izraél éppen ostromolták Gibbetónt.
28 Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Megölte őt Báesa Ászának, Jehúda királyának harmadik évében és király lett helyette.
29 Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
És volt, mikor király lett, megölte Járobeám egész házát, nem hagyott meg egy lelket sem Járobeámtól, míg meg nem semmisítette; az Örökkévaló szava szerint, melyet szólt az ő szolgája, a Sílóbeli Achíja által:
30 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
Járobeám vétkei miatt, melyekkel vétkezett és melyekkel vétkezésre indította Izraélt, bosszantásáért, mellyel bosszantotta az Örökkévaló, Izraél Istenét.
31 Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Nádáb egyéb dolgai pedig és mindaz, amit cselekedett, hiszen meg vannak írva Izraél királyai történetének könyvében.
32 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
És háború volt Ásza és Báesa Izraél királya között minden napjaikban.
33 Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
Ászának, Jehúda királyának harmadik évében király lett Báesa, Achíja fia egész Izraél fölött, Tircában, huszonnégy évig.
34 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
És tette azt, ami rossz az Örökkévaló szemeiben és járt Járobeám útja szerint és vétke szerint, mellyel vétkezésre indította Izraélt.

< 1 Kings 15 >