< 1 Kings 15 >

1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
La dix-huitième année du Roi Jéroboam fils de Nébat, Abijam commença à régner sur Juda.
2 ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
Et il régna trois ans à Jérusalem; sa mère avait nom Mahaca, et était fille d'Abisalom.
3 Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
Il marcha dans tous les péchés que son père avait commis avant lui, et son cœur ne fut point pur envers l'Eternel son Dieu, comme [l'avait été] le cœur de David son père.
4 Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
Mais pour l'amour de David l'Eternel son Dieu lui donna une Lampe dans Jérusalem, lui suscitant son fils après lui, et protégeant Jérusalem;
5 Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
Parce que David avait fait ce qui est droit devant l'Eternel, et tout le temps de sa vie il ne s'était point détourné de rien qu'il lui eût commandé, hormis dans l'affaire d'Urie l'Héthien.
6 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
Or il y eut toujours guerre entre Roboam et Jéroboam tout le temps que [Roboam] vécut.
7 Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
Et le reste des actions d'Abijam, et même tout ce qu'il a fait, n'est-il pas écrit au Livre des Chroniques des Rois de Juda? Il y eut aussi guerre entre Abijam et Jéroboam.
8 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Ainsi Abijam s'endormit avec ses pères, et on l'ensevelit en la Cité de David; et Asa son fils régna en sa place.
9 Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
La vingtième année de Jéroboam Roi d'Israël, Asa commença à régner sur Juda.
10 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
Et il régna quarante et un ans à Jérusalem; sa mère avait nom Mahaca, [et] elle était fille d'Abisalom.
11 Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
Et Asa fit ce qui est droit devant l'Eternel, comme David son père.
12 Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
Car il abolit du pays les prostitués à la paillardise, et ôta tous les dieux de fiente que ses pères avaient faits.
13 Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
Et même il déposa sa mère Mahaca, afin qu'elle ne fût plus régente, parce qu'elle avait fait un simulacre pour un bocage, et Asa mit en pièces le simulacre qu'elle avait fait, et le brûla près du torrent de Cédron.
14 Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
Mais les hauts lieux ne furent point ôtés; néanmoins le cœur d'Asa fut droit envers l'Eternel tout le temps de sa vie.
15 Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
Et il remit dans la maison de l'Eternel les choses qui avaient été consacrées par son père, avec ce qu'il avait aussi lui-même consacré, d'argent, d'or, et de vaisseaux.
16 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
r il y eut guerre entre Asa et Bahasa Roi d'Israël tout le temps de leur vie.
17 Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
Car Bahasa Roi d'Israël monta contre Juda, et bâtit Rama, afin de ne laisser sortir ni entrer personne vers Asa Roi de Juda.
18 Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
Et Asa prit tout l'argent et l'or qui était demeuré dans les trésors de l'Eternel, et dans les trésors de la maison Royale, et les donna à ses serviteurs, et le Roi Asa les envoya vers Ben-hadad fils de Tabrimon, fils de Hezjon Roi de Syrie, qui demeurait à Damas, pour lui dire:
19 Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
[Il y a] alliance entre moi et toi, et entre mon père et le tien; voici, je t'envoie un présent en argent et en or; Va, romps l'alliance que tu as avec Bahasa Roi d'Israël, et qu'il se retire de moi.
20 Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
Et Ben-hadad accorda cela au Roi Asa, et envoya les capitaines de son armée, contre les villes d'Israël, et frappa Hijon, Dan, Abel-beth-mahaca, et tout Kinneroth, qui était joignant tout le pays de Nephthali.
21 Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
Et il arriva qu'aussitôt que Bahasa l'eut appris, il cessa de bâtir Rama, et demeura à Tirtsa.
22 Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
Alors le Roi Asa fit publier par tout Juda que tous, sans en excepter aucun, eussent à emporter les pierres et le bois de Rama, que Bahasa faisait bâtir, et le Roi Asa en bâtit Guébah de Benjamin, et Mitspa.
23 Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Le reste de tous les faits d'Asa, et toute sa valeur, et tout ce qu'il a fait, et les villes qu'il a bâties, n'est-il pas écrit au Livre des Chroniques des Rois de Juda? Au reste, il fut malade de ses pieds au temps de sa vieillesse.
24 Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Et Asa s'endormit avec ses pères, avec lesquels il fut enseveli en la Cité de David son père, et Josaphat son fils régna en sa place.
25 Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
Or Nadab fils de Jéroboam commença à régner sur Israël la seconde année d'Asa Roi de Juda, et il régna deux ans sur Israël.
26 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
Et il fit ce qui déplaît à l'Eternel, et suivit le train de son père, et le péché par lequel il avait fait pécher Israël.
27 Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
Et Bahasa fils d'Ahija de la maison d'Issacar, fit une conspiration contre lui, et le frappa devant Guibbethon qui était aux Philistins, lorsque Nadab et tout Israël assiégeaient Guibbethon.
28 Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Bahasa donc le fit mourir la troisième année d'Asa Roi de Juda, et il régna en sa place;
29 Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
Et aussitôt qu'il vint à régner il frappa toute la maison de Jéroboam, et il ne laissa aucune âme vivante [de la race] de Jéroboam qu'il n'exterminât, selon la parole de l'Eternel qu'il avait proférée par son serviteur Ahija Silonite;
30 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
A cause des péchés de Jéroboam qu'il avait faits, et par lesquels il avait fait pécher Israël; [et] à cause du péché par lequel il avait irrité l'Eternel le Dieu d'Israël.
31 Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Le reste des faits de Nadab, et même tout ce qu'il a fait, n'est-il pas écrit au Livre des Chroniques des Rois d'Israël?
32 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
Or il y eut guerre entre Asa et Bahasa Roi d'Israël, tout le temps de leur vie.
33 Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
La troisième année d'Asa Roi de Juda, Bahasa fils d'Ahija commença à régner sur tout Israël à Tirtsa, [et régna] vingt et quatre ans.
34 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
Et il fit ce qui déplaît à l'Eternel, et suivit le train de Jéroboam, et son péché, par lequel il avait fait pécher Israël.

< 1 Kings 15 >