< 1 Kings 15 >

1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
And in the eighteenth year of King Jeroboam son of Nebat, Abijam has reigned over Judah;
2 ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
he has reigned three years in Jerusalem, and the name of his mother [is] Maachah daughter of Abishalom;
3 Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
and he walks in all the sins of his father that he did before him, and his heart has not been perfect with his God YHWH, as the heart of his father David;
4 Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
but for David’s sake his God YHWH has given to him a lamp in Jerusalem, to raise up his son after him, and to establish Jerusalem,
5 Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
in that David did that which [is] right in the eyes of YHWH, and did not turn aside from all that He commanded him all [the] days of his life—except in the matter of Uriah the Hittite;
6 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
and there has been war between Rehoboam and Jeroboam all the days of his life.
7 Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
And the rest of the matters of Abijam and all that he did, are they not written on the scroll of the Chronicles of the Kings of Judah? And there has been war between Abijam and Jeroboam;
8 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Abijam lies with his fathers, and they bury him in the City of David, and his son Asa reigns in his stead.
9 Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
And in the twentieth year of Jeroboam king of Israel, Asa has reigned over Judah,
10 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
and he has reigned forty-one years in Jerusalem, and the name of his mother [is] Maachah daughter of Abishalom.
11 Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
And Asa does that which [is] right in the eyes of YHWH, like his father David,
12 Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
and removes the whoremongers out of the land, and turns aside all the idols that his fathers made;
13 Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
and also his mother Maachah—he turns her aside from being mistress, in that she made a horrible thing for an Asherah, and Asa cuts down her horrible thing, and burns [it] by the Brook of Kidron;
14 Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
but the high places have not been removed; only, the heart of Asa has been perfect with YHWH [for] all his days,
15 Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
and he brings in the sanctified things of his father, and his own sanctified things, to the house of YHWH: silver, and gold, and vessels.
16 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
And there has been war between Asa and Baasha king of Israel [for] all their days,
17 Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
and Baasha king of Israel goes up against Judah, and builds Ramah, not to permit anyone going out and coming in to Asa king of Judah.
18 Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
And Asa takes all the silver and the gold that are left in the treasures of the house of YHWH, and the treasures of the house of the king, and gives them into the hand of his servants, and King Asa sends them to Ben-Hadad, son of Tabrimmon, son of Hezion king of Aram, who is dwelling in Damascus, saying,
19 Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
“A covenant [is] between me and you, between my father and your father; behold, I have sent a reward of silver and gold to you; go, break your covenant with Baasha king of Israel, and he goes up from off me.”
20 Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
And Ben-Hadad listens to King Asa, and sends the heads of the forces that he has against cities of Israel, and strikes Ijon, and Dan, and Abel-Beth-Maachah, and all Chinneroth, besides all the land of Naphtali;
21 Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
and it comes to pass at Baasha’s hearing, that he ceases from building Ramah, and dwells in Tirzah.
22 Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
And King Asa has summoned all Judah—there is none exempt—and they lift up the stones of Ramah, and its wood, that Baasha has built, and King Asa builds with them Geba of Benjamin, and Mizpah.
23 Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
And the rest of all the matters of Asa, and all his might, and all that he did, and the cities that he built, are they not written on the scroll of the Chronicles of the Kings of Judah? Only, at the time of his old age he was diseased in his feet;
24 Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
and Asa lies with his fathers, and is buried with his fathers in the city of his father David, and his son Jehoshaphat reigns in his stead.
25 Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
And Nadab son of Jeroboam has reigned over Israel, in the second year of Asa king of Judah, and he reigns over Israel two years,
26 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
and does evil in the eyes of YHWH, and goes in the way of his father, and in his sin that he made Israel to sin.
27 Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
And Baasha son of Ahijah, of the house of Issachar, conspires against him, and Baasha strikes him in Gibbethon, which [belonged] to the Philistines—and Nadab and all Israel are laying siege against Gibbethon—
28 Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
indeed, Baasha puts him to death in the third year of Asa king of Judah, and reigns in his stead.
29 Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
And it comes to pass, at his reigning, he has struck the whole house of Jeroboam, he has not left any breathing to Jeroboam until his destroying him, according to the word of YHWH, that He spoke by the hand of His servant Ahijah the Shilonite,
30 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
because of the sins of Jeroboam that he sinned, and that he caused Israel to sin, by his provocation with which he provoked YHWH, God of Israel, to anger.
31 Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
And the rest of the matters of Nadab and all that he did, are they not written on the scroll of the Chronicles of the Kings of Israel?
32 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
And there has been war between Asa and Baasha king of Israel [for] all their days.
33 Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
In the third year of Asa king of Judah, Baasha son of Ahijah has reigned over all Israel in Tirzah, twenty-four years,
34 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
and he does evil in the eyes of YHWH, and walks in the way of Jeroboam, and in his sin that he caused Israel to sin.

< 1 Kings 15 >