< 1 Kings 14 >
1 Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
På den tiden var Abia, Jerobeams son, krank.
2 Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
Och Jerobeam sade till sina hustru: Statt upp, och förkläd dig, så att ingen kan märka, att du äst Jerobeams hustru, och gack bort till Silo; si, der är den Propheten Ahia, den mig sade, att jag skulle varda Konung öfver detta folk.
3 Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
Och tag med dig tio bröd, och kakor, och ett käril med hannog, och gack till honom, att han må säga dig, huru med piltenom gå skall.
4 Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
Och Jerobeams hustru gjorde så, och stod upp, och gick bort till Silo, och kom i Ahia hus; men Ahia kunde intet se; ty hans ögon voro mörk vorden för ålders skull.
5 Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
Men Herren sade till Ahia: Si, Jerobeams hustru kommer, att hon skall fråga ett ärende af dig om sin son, ty han är krank: så tala nu du med henne så och så. Då hon nu inkom, höll hon sig främmande.
6 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
Som nu Ahia hörde dönen af hennes fötter, vid hon ingick, sade han: Kom hitin, du Jerobeams hustru; hvi håller du dig så främmande? Jag är sänder till dig ett hårdt bådskap.
7 Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
Gack bort, och säg Jerobeam: Så säger Herren Israels Gud: Jag hafver upphöjt dig utu folkena, och satt dig till en Första öfver mitt folk Israel;
8 Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
Och hafver rifvit riket ifrå Davids hus, och gifvit det dig; men du hafver intet varit såsom min tjenare David, den min bud höll, och vandrade efter mig med allo hjerta, så att han gjorde hvad mig ljuft var;
9 Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
Och du hafver illa gjort, öfver alla de som för dig varit hafva; du hafver gångit bort, och gjort dig andra gudar, och gjuten beläte, att du skulle reta mig till vrede; och hafver kastat mig bakom din rygg;
10 “‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
Och si, jag skall låta komma olycko öfver Jerobeams hus, och förgöra af Jerobeam ock den uppå väggena pissar; den innelyckta, och den igenlefda i Israel; och skall utsopa Jerobeams hus efterkomman de, såsom man träck utsopar, tilldess det blifver allt ute med honom.
11 Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
Den som af Jerobeam dör i stadenom, honom skola hundarna äta; men den som dör på markene, honom skola himmelens foglar äta; ty Herren hafver det sagt.
12 “Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
Så statt nu upp, och gack hem; och då din fot träder in i staden, skall pilten blifva död.
13 Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
Och hela Israel skall begråta honom, och skola begrafvan; ty denne allena af Jerobeam skall till grafva komma; förty något godt är funnet i honom för Herranom Israels Gud, i Jerobeams hus.
14 “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
Och Herren skall uppväcka en Konung öfver Israel, han skall utrota Jerobeams hus på den dagen; och hvad är det nu allaredo sker?
15 Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
Och Herren skall slå Israel, såsom rören böjas i vattnena; och skall utrycka Israel utu desso goda landena, som han deras fader gifvit hafver, och skall förströ dem bort öfver älfvena; derföre att de hafva gjort sig lundar till att förtörna Herran;
16 Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
Och skall öfvergifva Israel, för Jerobeams synds skull, hvilken syndat hafver och kommit Israel till att synda.
17 Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
Och Jerobeams hustru stod upp, gick, och kom till Thirza; och då hon kom till tröskelen åt huset, blef pilten död.
18 Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
Och de begrofvo honom, och hele Israel begreto honom, efter Herrans ord, som han genom sin tjenare Propheten Ahia talat hade.
19 Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
Hvad mer om Jerobeam sägandes är, huru han stridde och regerade, si, det är skrifvet i Israels Konungars Chrönico.
20 Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Tiden, som Jerobeam regerade, var tu och tjugu år; och han af somnade med sina fäder. Och hans son Nadab vardt Konung i hans stad.
21 Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
Så var nu Rehabeam, Salomos son, Konung i Juda; ett och fyratio år gammal var Rehabeam, då han vardt Konung; och regerade i sjutton år i Jerusalem, i dem stadenom, som Herren utvalt hade utur alla Israels slägter, att han skulle sätta der sitt Namn uti. Hans moder het Naama, en Ammonitiska.
22 Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
Och Juda gjorde det ondt var för Herranom, och rette honom mera, än allt det deras fäder gjort hade, med deras synder som de gjorde.
23 Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Ty de byggde sig också höjder, stodar och lundar, på alla höga backar, och under all grön trä.
24 Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Och voro desslikes roffare i landena; och de gjorde all Hedningarnas styggelse, som Herren för Israels barn fördrifvit hade.
25 Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
Men i femte Konung Rehabeams åre drog Sisak, Konungen i Egypten, uppemot Jerusalem;
26 Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
Och tog ut de håfvor utu Herrans hus, och utu Konungshuset, och allt det som der tagas kunde; och tog alla gyldene sköldar, som Salomo hade göra låtit;
27 Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
I hvilkas stad Konung Rehabeam lät göra kopparsköldar, och befallde dem under de öfversta drabanternas hand, som dörrena vaktade för Konungshuset.
28 Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
Och så ofta Konungen gick in uti Herrans hus, båro drabanterna dem; och hade dem åter uti drabantakammaren igen.
29 Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
Hvad nu mer af Rehabeam sägandes är, och allt det han gjort hafver, si, det är skrifvet i Juda Konungars Chrönico.
30 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
Men emellan Rehabeam och Jerobeam var örlig, så länge de lefde.
31 Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Och Rehabeam afsomnade med sina fäder, och vardt begrafven med sina fäder uti Davids stad; och hans moder het Naama, en Ammonitiska. Och hans son Abiam vardt Konung i hans stad.