< 1 Kings 14 >

1 Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
Tegoż czasu rozniemógł się Abijas, syn Jeroboama.
2 Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
I rzekł Jeroboam do żony swej: Wstań teraz, a odmień się, aby nie poznano, żeś ty żoną Jeroboamową, a idź do Sylo; oto tam jest Achyjasz prorok, który mi powiedział, żem miał zostać królem nad tym ludem.
3 Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
A wziąwszy z sobą dziesięcioro chleba, i placków, i faskę miodu, idź do niego; on ci oznajmi, co się stanie dziecięciu.
4 Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
I uczyniła tak żona Jeroboamowa, a wstawszy poszła do Sylo, i weszła do domu Achyjaszowego; ale Achyjasz nie mógł już widzieć, bo mu były zaszły oczy dla starości jego.
5 Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
A Pan rzekł do Achyjasza: Oto żona Jeroboamowa wchodzi, aby się od ciebie czego wywiedziała o synu swym, przeto że choruje; ale tak a tak rzeczesz jej, a stanie się, gdy będzie wchodziła, zmyśli się być inszą.
6 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
Przetoż gdy usłyszał Achyjasz tupanie nóg jej, wchodzącej we drzwi, rzekł: Wnijdź żono Jeroboamowa; przecz się zmyślasz być inszą? Jam bowiem srogim posłem do ciebie.
7 Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
Idź, powiedz Jeroboamowi: Tak mówi Pan, Bóg Izraelski: Ponieważem cię wywyższył z pośrodku ludu, a postanowiłem cię książęciem nad ludem moim Izraelskim;
8 Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
I oderwałem królestwo od domu Dawidowego, a dałem je tobie, tyś jednak nie był jako sługa mój Dawid, który strzegł rozkazania mego, i który chodził za mną całem sercem swojem, to tylko czyniąc, co jest dobrego w oczach moich;
9 Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
Aleś czynił złe nad wszystkie, którzy byli przed tobą; albowiem odszedłszy, poczyniłeś sobie bogi cudze, i lane, abyś mię pobudził do gniewu, a mnieś zarzucił w tył sobie:
10 “‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
Przetoż oto Ja przywiodę złe na dom Jeroboamowy, i wytracę z Jeroboama aż do najmniejszego szczenięcia, więźnia, i opuszczonego w Izraelu, i wymiotę ostatki domu Jeroboamowego, jako wymiatają gnój, aż do czysta.
11 Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
Tego, który z domu Jeroboamowego umrze w mieście, zjedzą psy, a który umrze na polu, zjedzą ptaki powietrzne, ponieważ Pan wyrzekł.
12 “Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
A ty wstawszy idź do domu twego a gdy wchodzić będziesz do miasta, tedy umrze dziecię.
13 Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
I będzie go płakał wszystek Izrael, i pochowają go; bo ten sam z domu Jeroboamowego wnijdzie do grobu, przeto iż się znalazło o nim samym słowo dobre od Pana, Boga Izraelskiego w domu Jeroboamowym.
14 “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
Wszakże postanowi sobie Pan króla nad Izraelem, który wykorzeni dom Jeroboamowy dnia tego; a co mówię, wzbudzi? I owszem już wzbudził.
15 Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
I uderzy Pan Izraela, i zachwieje nim, jako się chwieje trzcina na wodach, a wykorzeni Izraela z ziemi tej dobrej, którą dał ojcom ich, i rozproszy je za rzekę, przeto iż sobie poczynili gaje, wzruszając Pana ku gniewu.
16 Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
A tak wyda Izraela dla grzechu Jeroboamowego, który grzeszył, i który do grzechu przywiódł Izraela.
17 Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
Tedy wstała żona Jeroboamowa, i poszła, a przyszła do Tersa; a gdy wstępowała na próg domu, umarło dziecię.
18 Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
I pochowali je, a płakał go wszystek Izrael według słowa Pańskiego, które opowiedział przez sługę swego Achyjasza proroka.
19 Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
A inne sprawy Jeroboamowe, jako walczył, i jako królował, oto spisane są w kronikach o królach Izraelskich.
20 Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
A dni, których królował Jeroboam, było dwadzieścia i dwa lat, i zasnął z ojcy swymi, a Nadab, syn jego, królował miasto niego.
21 Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
Roboam też, syn Salomona, królował w Judzie. A było Roboamowi czterdzieści lat i jeden, gdy począł królować, a siedmnaście lat królował w mieście Jeruzalemie, które Pan obrał ze wszystkich pokoleń Izraelskich, aby tam przebywało imię jego. A imię matki jego było Naama, Ammonitka.
22 Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
I czynił Juda złe przed Panem, a wzruszyli go ku gniewu grzechami swemi, któremi grzeszyli nad wszystko, co czynili ojcowie ich.
23 Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Albowiem i oni pobudowali sobie wyżyny, i słupy, i gaje na każdym pagórku wysokim, i pod każdem drzewem zielonem.
24 Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Byli też i Sodomczycy w onej ziemi, sprawujący się według wszystkich obrzydliwości poganów, które wyrzucił Pan od obliczności synów Izraelskich.
25 Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
I stało się roku piątego królowania Roboama, że wyciągnął Sesak, król Egipski, przeciw Jeruzalemowi.
26 Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
I pobrał skarby domu Pańskiego, i skarby domu królewskiego, wszystko to pobrał; wziął też wszystkie tarcze złote, które był sprawił Salomon;
27 Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
Miasto których król Roboam sprawił tarcze miedziane, i poruczył je przełożonym nad piechotą, którzy strzegli drzwi domu królewskiego.
28 Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
A gdy wchodził król do domu Pańskiego, brała je piechota, i zasię odnosiła do komor swoich.
29 Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
A inne sprawy Roboamowe, i wszystko co czynił, azaż nie są napisane w kronikach o królach Judzkich?
30 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
I była wojna między Roboamem i między Jeroboamem po wszystkie dni.
31 Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
I zasnął Roboam z ojcy swymi, a pochowany jest z nimi w mieście Dawidowem; a imię matki jego było Naama, Ammonitka. I królował Abijam, syn jego, miasto niego.

< 1 Kings 14 >