< 1 Kings 14 >

1 Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
در آن روزها اَبیّام پسر یربعام پادشاه بیمار شد.
2 Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
یربعام به همسرش گفت: «قیافه‌ات را تغییر بده تا کسی تو را نشناسد و پیش اخیای نبی که در شیلوه است برو. او همان کسی است که به من گفت که بر این قوم پادشاه می‌شوم.
3 Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
ده نان، یک کوزه عسل و مقداری هم کلوچه برایش ببر و از او بپرس که آیا فرزند ما خوب می‌شود یا نه؟»
4 Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
پس همسر یربعام به راه افتاد و به خانهٔ اخیای نبی که در شیلوه بود رسید. اخیای نبی پیر شده بود و چشمانش نمی‌دید.
5 Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
اما خداوند به او گفته بود که به‌زودی ملکه در قیافهٔ مبدل به دیدار او می‌آید تا دربارهٔ وضع پسر بیمارش از وی سؤال کند، خداوند همچنین به اخیای نبی گفته بود که به ملکه چه بگوید.
6 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
پس وقتی اخیا صدای پای او را دم در شنید گفت: «ای همسر یربعام داخل شو! چرا قیافه‌ات را تغییر داده‌ای؟ من خبر ناخوشایندی برایت دارم!»
7 Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
سپس اخیا این پیغام را از جانب خداوند، خدای قوم اسرائیل به او داد تا به شوهرش یربعام برساند: «من تو را از میان مردم انتخاب کردم تا به پادشاهی برسی.
8 Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
سلطنت را از خاندان داوود گرفتم و به تو دادم؛ اما تو مثل بندهٔ من داوود از دستورهایم اطاعت نکردی. او از صمیم قلب مرا پیروی می‌کرد و آنچه را که من می‌پسندیدم انجام می‌داد.
9 Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
تو از تمام پادشاهانِ پیش از خودت بیشتر بدی کردی؛ بتها ساختی و بت‌پرست شدی و با ساختن این گوساله‌ها از من رو گردانیدی و مرا خشمگین نمودی.
10 “‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
پس من هم بر خاندان تو بلا می‌فرستم و تمام پسران و مردان خاندانت را، چه اسیر و چه آزاد، نابود می‌کنم. همان‌طور که کثافت حیوانات را می‌سوزانند، من هم خاندان تو را خواهم سوزاند تا اثری از آن بر جا نماند.
11 Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
به طوری که از خاندان تو هر که در شهر بمیرد، سگها او را می‌خورند و هر که در صحرا بمیرد، لاشخورها جسدش را می‌خورند. من که خداوند هستم این را می‌گویم.»
12 “Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
سپس اخیا به همسر یربعام گفت: «اکنون برخیز و به خانه‌ات برو. وقتی پایت به شهر برسد پسرت خواهد مرد.
13 Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
تمام اسرائیل برای او عزاداری کرده، او را دفن خواهند کرد. ولی از تمام اعضای خانوادهٔ یربعام این تنها کسی است که در قبر دفن می‌شود؛ زیرا تنها فرد خوبی که خداوند، خدای اسرائیل در تمام خانوادهٔ یربعام می‌بیند همین بچه است.
14 “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
خداوند پادشاه دیگری برای اسرائیل انتخاب می‌کند که خاندان یربعام را به کلی از بین می‌برد. این از همین امروز شروع می‌شود!
15 Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
خداوند اسرائیل را چنان تکان خواهد داد که مثل علفی که در مسیر آب رودخانه است بلرزد. خداوند اسرائیل را از این سرزمین خوب که به اجدادشان بخشیده، ریشه‌کن می‌کند و آنها را در آن طرف رود فرات آواره می‌سازد، زیرا آنها با بت‌پرستی‌شان خداوند را به خشم آوردند.
16 Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
خداوند همچنین به سبب گناه یربعام که اسرائیل را به گناه کشاند ایشان را ترک خواهد گفت.»
17 Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
پس زن یربعام به ترصه بازگشت. به محض اینکه پای او به آستانهٔ کاخ سلطنتی رسید، پسرش مرد.
18 Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
همان‌طور که خداوند به‌وسیلۀ اخیای نبی فرموده بود، پسر را دفن کردند و در سراسر اسرائیل برایش ماتم گرفتند.
19 Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
شرح وقایع جنگها و سایر رویدادهای دوران فرمانروایی یربعام در کتاب «تاریخ پادشاهان اسرائیل» نوشته شده است.
20 Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
یربعام بیست و دو سال سلطنت کرد و بعد از مرگ او، پسرش ناداب زمام امور را در دست گرفت.
21 Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
رحبعام، پسر سلیمان، چهل و یک ساله بود که پادشاه یهودا شد. مادرش اهل عمون و نامش نعمه بود. او در اورشلیم، شهری که خداوند از میان سایر شهرهای اسرائیل برگزیده بود تا اسمش را بر آن بگذارد به مدت هفده سال سلطنت کرد.
22 Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
در دورهٔ سلطنت او، مردم یهودا نسبت به خداوند گناه ورزیدند و با گناهان خود حتی بیش از اجدادشان خداوند را خشمگین کردند.
23 Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
زیرا آنها نیز روی هر تپه و زیر هر درخت سبز، بتخانه‌ها و ستونها و اشیره‌ها بر پا کردند.
24 Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
در این سرزمین حتی فاحشه‌های مرد و زن بودند که در بتکده‌ها به فاحشگی می‌پرداختند. مردم یهودا درست مثل همان قومهای خدانشناس که خداوند آنها را از سرزمین کنعان بیرون رانده بود، اعمال کراهت‌آور انجام می‌دادند.
25 Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
در سال پنجم سلطنت رحبعام، شیشق (پادشاه مصر) به اورشلیم حمله برد و آن را تصرف نمود.
26 Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
او خزانه‌های خانهٔ خداوند و کاخ سلطنتی را غارت کرد و تمام سپرهای طلا را که سلیمان ساخته بود، با خود به یغما برد.
27 Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
پس از آن رحُبعام پادشاه به جای سپرهای طلا، سپرهای مفرغین ساخت و آنها را به دست نگهبانانی که جلوی مدخل کاخ شاهی کشیک می‌دادند، سپرد.
28 Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
هر وقت پادشاه به خانهٔ خداوند می‌رفت، نگهبانان او سپرها را به دست می‌گرفتند و پس از پایان مراسم، آنها را دوباره به اتاق نگهبانی برمی‌گرداندند.
29 Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
رویدادهای دیگر دوران سلطنت رحبعام در کتاب تاریخ پادشاهان یهودا نوشته شده است.
30 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
در تمام دوران سلطنت رحبعام بین او و یربعام جنگ بود.
31 Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
وقتی رحبعام مرد، او را در آرامگاه سلطنتی، در شهر داوود دفن کردند. (مادر رحبعام نعمهٔ عمونی بود.) پس از رحبعام پسرش اَبیّام به جای او بر تخت پادشاهی نشست.

< 1 Kings 14 >