< 1 Kings 14 >
1 Ní àkókò náà Abijah ọmọ Jeroboamu sì ṣàìsàn,
En ce temps-là, Abija, fils de Jéroboam, tomba malade.
2 Jeroboamu sì wí fún aya rẹ̀ pé, “Lọ, sì pa ara rẹ dà, kí wọn kí ó má ba à mọ̀ ọ́n ní aya Jeroboamu. Nígbà náà ni kí o lọ sí Ṣilo. Ahijah wòlíì wà níbẹ̀; ẹni tí ó sọ fún mi pé, èmi yóò jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn yìí.
Jéroboam dit à sa femme: « Lève-toi, je t'en prie, et déguise-toi, afin qu'on ne te reconnaisse pas comme la femme de Jéroboam. Va à Silo. Voici, le prophète Achija y est, qui a dit que je serais roi de ce peuple.
3 Mú ìṣù àkàrà mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, àti àkàrà wẹ́wẹ́ àti ìgò oyin, kí o sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀. Òun yóò sì sọ fún ọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọkùnrin náà.”
Prends avec toi dix pains, des gâteaux et un pot de miel, et va le voir. Il te dira ce qu'il adviendra de l'enfant. »
4 Bẹ́ẹ̀ ni aya Jeroboamu sì ṣe bí ó ti wí, ó sì lọ sí ilé Ahijah ní Ṣilo. Ahijah kò sì ríran; ojú rẹ̀ ti fọ́ nítorí ogbó rẹ̀.
La femme de Jéroboam fit ainsi; elle se leva, alla à Silo, et arriva à la maison d'Achija. Or Achija ne pouvait pas voir, car ses yeux étaient fixes à cause de son âge.
5 Ṣùgbọ́n Olúwa ti sọ fún Ahijah pé, “Kíyèsi i, aya Jeroboamu ń bọ̀ wá béèrè nípa ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, nítorí tí ó ṣàìsàn, báyìí báyìí ni kí ìwọ kí ó wí fún un. Nígbà tí ó bá dé, yóò ṣe ara rẹ̀ bí ẹlòmíràn.”
Yahvé dit à Achija: « Voici que la femme de Jéroboam vient te demander des nouvelles de son fils, car il est malade. Dis-lui telle et telle chose, car il se peut que, lorsqu'elle entrera, elle se fasse passer pour une autre femme. »
6 Bẹ́ẹ̀ ni ó sì rí, nígbà tí Ahijah sì gbọ́ ìró ẹsẹ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Wọlé wá, aya Jeroboamu. Kí ló dé tí ìwọ fi ṣe ara rẹ bí ẹlòmíràn? A ti fi iṣẹ́ búburú rán mi sí ọ.
Et lorsque Achija entendit le bruit de ses pieds lorsqu'elle franchit la porte, il dit: « Entre, femme de Jéroboam! Pourquoi te fais-tu passer pour une autre? Car je suis envoyé vers toi avec une lourde nouvelle.
7 Lọ, sọ fún Jeroboamu pé báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Èmi sì gbé ọ ga láti inú àwọn ènìyàn, mo sì fi ọ́ jẹ olórí lórí Israẹli ènìyàn mi.
Va dire à Jéroboam: « Yahvé, le Dieu d'Israël, dit: « Parce que je t'ai élevé du milieu du peuple, que je t'ai établi prince de mon peuple d'Israël,
8 Mo fa ìjọba náà ya kúrò ní ilé Dafidi, mo sì fi fún ọ ṣùgbọ́n, ìwọ kò dàbí Dafidi ìránṣẹ́ mi, tí ó pa àṣẹ mi mọ́, tí ó sì tọ̀ mí lẹ́yìn tọkàntọkàn rẹ̀, láti ṣe kìkì èyí tí ó tọ́ ní ojú mi.
que j'ai arraché le royaume à la maison de David et que je te l'ai donné; et pourtant tu n'as pas été comme mon serviteur David, qui a gardé mes commandements et qui m'a suivi de tout son cœur, pour ne faire que ce qui était juste à mes yeux,
9 Ìwọ sì ti ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú rẹ lọ. Ìwọ sì ti ṣe àwọn ọlọ́run mìíràn fún ara rẹ, àwọn òrìṣà tí a gbẹ́; o sì ti mú mi bínú, o sì ti gbé mi sọ sí ẹ̀yìn rẹ.
mais tu as fait le mal par-dessus tous ceux qui étaient avant toi, et tu es allé te faire d'autres dieux, des images en fonte, pour m'irriter,
10 “‘Nítorí èyí, Èmi yóò mú ibi wá sí ilé Jeroboamu. Èmi yóò ké gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò lọ́dọ̀ Jeroboamu, àti ọmọ ọ̀dọ̀ àti òmìnira ní Israẹli. Èmi yóò mú ilé Jeroboamu kúrò bí ènìyàn ti ń kó ìgbẹ́ kúrò, títí gbogbo rẹ̀ yóò fi tán.
C'est pourquoi voici, je vais faire venir le malheur sur la maison de Jéroboam, j'exterminerai de Jéroboam tous ceux qui urinent sur un mur, ceux qui sont enfermés et ceux qui sont en liberté en Israël, et je balaierai la maison de Jéroboam, comme on balaie du fumier jusqu'à ce qu'il ait disparu.
11 Ajá yóò jẹ ẹni Jeroboamu tí ó bá kú ní ìlú, àti ẹni tí ó bá kú ní igbó ni àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ. Olúwa ti sọ ọ́!’
Les chiens mangeront celui qui appartient à Jéroboam et qui meurt dans la ville, et les oiseaux du ciel mangeront celui qui meurt dans les champs, car Yahvé a parlé ».
12 “Ní ti ìwọ, padà lọ ilé, nígbà tí o bá sì fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ ìlú, ọmọ náà yóò kú.
Lève-toi donc, et va dans ta maison. Quand tes pieds entreront dans la ville, l'enfant mourra.
13 Gbogbo Israẹli yóò sì ṣọ̀fọ̀ fún un, wọn yóò sì sin ín. Òun nìkan ni a ó sì sin nínú ẹni tí ń ṣe ti Jeroboamu, nítorí lọ́dọ̀ rẹ̀ nìkan ni a ti rí ohun rere díẹ̀ sípa Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ní ilé Jeroboamu.
Tout Israël le pleurera et l'enterrera; car c'est le seul de Jéroboam qui sera mis au tombeau, parce qu'on a trouvé en lui quelque chose de bon pour l'Éternel, le Dieu d'Israël, dans la maison de Jéroboam.
14 “Olúwa yóò gbé ọba kan dìde fúnra rẹ̀ lórí Israẹli tí yóò ké ilé Jeroboamu kúrò. Ọjọ́ náà nìyìí! Kí ni? Àní nísinsin yìí.
Et Yahvé se suscitera sur Israël un roi qui exterminera la maison de Jéroboam. C'est le jour! Quoi? Dès maintenant.
15 Olúwa yóò kọlu Israẹli, yóò sì dàbí koríko ti ń mì nínú omi. Yóò sì fa Israẹli tu kúrò ní ilẹ̀ rere yìí, tí ó ti fi fún àwọn baba wọn, yóò sì fọ́n wọn ká kọjá odò Eufurate, nítorí wọ́n ti rú ìbínú Olúwa nípa ṣíṣe ère Aṣerah.
Car l'Éternel frappera Israël, comme un roseau qu'on secoue dans l'eau; il déracinera Israël de ce bon pays qu'il a donné à ses pères, et il le dispersera au delà du fleuve, parce qu'il a fait ses mâts d'Ashéra, en irritant l'Éternel.
16 Yóò sì kọ Israẹli sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀.”
Il livrera Israël à cause des péchés de Jéroboam, qu'il a commis et par lesquels il a fait pécher Israël. »
17 Nígbà náà ni aya Jeroboamu sì dìde, ó sì lọ, ó sì lọ sí Tirsa. Bí ó sì ti fi ẹsẹ̀ tẹ ìloro ilé, ọmọdé náà sì kú.
La femme de Jéroboam se leva et partit, et elle vint à Thirtsa. Comme elle arrivait sur le seuil de la maison, l'enfant mourut.
18 Wọ́n sì sin ín, gbogbo Israẹli sì ṣọ̀fọ̀ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí láti ẹnu ìránṣẹ́ rẹ̀, Ahijah wòlíì.
Tout Israël l'enterra et prit le deuil, selon la parole de l'Éternel, qu'il avait prononcée par son serviteur Achija, le prophète.
19 Ìyókù ìṣe Jeroboamu, bí ó ti jagun, àti bí ó ti jẹ ọba, ni a kọ sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli.
Le reste des actions de Jéroboam, comment il a combattu et comment il a régné, cela est écrit dans le livre des Chroniques des rois d'Israël.
20 Jeroboamu sì jẹ ọba fún ọdún méjìlélógún, ó sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. Nadabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Le temps que Jéroboam régna fut de vingt-deux ans; puis il se coucha avec ses pères, et Nadab, son fils, régna à sa place.
21 Rehoboamu ọmọ Solomoni sì jẹ ọba ní Juda. Ó jẹ́ ẹni ọdún mọ́kànlélógún nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ní ọdún mọ́kànlélógún ní Jerusalẹmu, ìlú tí Olúwa ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama, ará Ammoni.
Roboam, fils de Salomon, régna en Juda. Roboam avait quarante et un ans lorsqu'il devint roi, et il régna dix-sept ans à Jérusalem, la ville que Yahvé avait choisie parmi toutes les tribus d'Israël, pour y mettre son nom. Le nom de sa mère était Naama, l'Ammonite.
22 Juda sì ṣe búburú níwájú Olúwa nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí wọ́n ti dá, wọ́n sì mú u jowú ju gbogbo èyí tí baba wọn ti ṣe lọ.
Juda fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, et ils excitèrent sa jalousie par les péchés qu'ils commirent, par-dessus tout ce qu'avaient fait leurs pères.
23 Wọ́n sì tún kọ́ ibi gíga fún ara wọn, àti ère òkúta àti òpó Aṣerah lórí gbogbo òkè gíga, àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
Ils se construisirent des hauts lieux, des colonnes sacrées et des mâts d'Ashéra, sur toute colline élevée et sous tout arbre vert.
24 Àwọn tí wọn jẹ́ ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà wà ní ilẹ̀ náà, àwọn ènìyàn náà sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde kúrò níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
Il y avait aussi des sodomites dans le pays. Ils faisaient toutes les abominations des nations que Yahvé avait chassées devant les enfants d'Israël.
25 Ó sì ṣe ní ọdún karùn-ún Rehoboamu, Ṣiṣaki ọba Ejibiti kọlu Jerusalẹmu.
La cinquième année du roi Roboam, Shishak, roi d'Égypte, monta contre Jérusalem.
26 Ó sì kó ìṣúra ilé Olúwa lọ àti ìṣúra ilé ọba. Gbogbo rẹ̀ ni ó kó lọ, pẹ̀lú asà wúrà tí Solomoni ti ṣe.
Il emporta les trésors de la maison de l'Éternel et les trésors de la maison du roi. Il emporta même tout, y compris tous les boucliers d'or que Salomon avait faits.
27 Rehoboamu ọba sì ṣe asà idẹ ní ipò wọn, ó sì fi wọ́n sí ọwọ́ olórí àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlẹ̀kùn ilé ọba.
Le roi Roboam fit à leur place des boucliers d'airain et les confia aux mains des chefs de garde qui gardaient la porte de la maison du roi.
28 Nígbàkígbà tí ọba bá sì lọ sí ilé Olúwa, wọ́n á rù wọ́n, wọ́n á sì mú wọn padà sínú yàrá olùṣọ́.
Chaque fois que le roi entrait dans la maison de Yahvé, les gardes les portaient et les ramenaient dans la salle des gardes.
29 Ní ti ìyókù ìṣe Rehoboamu, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ǹjẹ́ a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda bí?
Le reste des actes de Roboam, et tout ce qu'il a fait, n'est-il pas écrit dans le livre des Chroniques des rois de Juda?
30 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní ọjọ́ wọn gbogbo.
Il y eut une guerre continuelle entre Roboam et Jéroboam.
31 Rehoboamu sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú Dafidi. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Naama; ará Ammoni. Abijah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Roboam se coucha avec ses pères, et il fut enterré avec ses pères dans la ville de David. Le nom de sa mère était Naama, l'Ammonite. Son fils Abijam régna à sa place.