< 1 Kings 13 >

1 Sì kíyèsi i, ènìyàn Ọlọ́run kan wá láti Juda sí Beteli nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, bì Jeroboamu sì ti dúró lẹ́bàá a pẹpẹ láti fi tùràrí jóná.
Men då kom på HERRENS befallning en gudsman från Juda till Betel, just när Jerobeam stod vid altaret för att där tända offereld.
2 Ó sì kígbe sí pẹpẹ náà nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, “Pẹpẹ! Pẹpẹ! Báyìí ni Olúwa wí: ‘A ó bí ọmọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Josiah ní ilé Dafidi. Lórí rẹ ni yóò sì fi àwọn àlùfáà ibi gíga wọ̀n-ọn-nì tí ń fi tùràrí lórí rẹ̀ rú ẹbọ, a ó sì sun egungun ènìyàn lórí rẹ.’”
Och mannen ropade mot altaret på HERRENS befallning och sade: "Altare! Altare! Så säger HERREN: Se, åt Davids hus skall födas en son vid namn Josia, han skall på dig slakta offerhöjdsprästerna som antända offereld på dig, och människoben skall man då bränna upp på dig."
3 Ní ọjọ́ kan náà ènìyàn Ọlọ́run sì fún wọn ní àmì kan wí pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa ti kéde: kíyèsi i, pẹpẹ náà yóò ya, eérú tí ń bẹ lórí rẹ̀ yóò sì dànù.”
På samma gång angav han ett tecken, i det han sade: "Detta är tecknet på att det är HERREN som har talat: se, altaret skall rämna, och askan därpå skall spillas ut."
4 Nígbà tí Jeroboamu ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run, tí ó kígbe sí pẹpẹ náà ní Beteli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde nínú pẹpẹ, ó sì wí pé, “Ẹ mú un!” ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ tí ó nà sí i sì kákò, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le fà á padà mọ́.
När konung Jerobeam hörde dessa ord, som gudsmannen ropade mot altaret i Betel, räckte han ut sin hand från altaret och sade: "Gripen honom." Men handen som han hade räckt ut mot honom förvissnade, och han kunde icke draga den tillbaka till sig igen.
5 Lẹ́sẹ̀kan náà, pẹpẹ ya, eérú náà sì dànù kúrò lórí pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bí àmì tí ènìyàn Ọlọ́run ti fi fún un nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
Och altaret rämnade, och askan på altaret spilldes ut; det var det tecken som gudsmannen på HERRENS befallning hade angivit.
6 Nígbà náà ní ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì gbàdúrà fún mi kí ọwọ́ mi lè padà bọ̀ sípò.” Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Olúwa, ọwọ́ ọba sì padà bọ̀ sípò, ó sì padà sí bí ó ti wà tẹ́lẹ̀.
Då tog konungen till orda och sade till gudsmannen: "Bönfall inför HERREN, din Gud, och bed för mig att jag må kunna draga min hand tillbaka till mig igen." Och gudsmannen bönföll inför HERREN; och konungen kunde då draga sin hand tillbaka till sig igen, och den var likadan som förut.
7 Ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Wá bá mi lọ ilé, kí o sì wá nǹkan jẹ, èmi yóò sì fi ẹ̀bùn fún ọ.”
Då talade konungen till gudsmannen: "Kom hem med mig och vederkvick dig; sedan vill jag giva dig en gåva."
8 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run náà dá ọba lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá tilẹ̀ fún mi ní ìdajì ìní rẹ, èmi kì yóò lọ pẹ̀lú rẹ tàbí kí èmi jẹ oúnjẹ tàbí mu omi ní ibí yìí.
Men gudsmannen svarade konungen: "Om du än vill giva mig hälften av vad som finnes i ditt hus, så kommer jag dock icke med dig; här på orten vill jag varken äta eller dricka.
9 Nítorí a ti pa á láṣẹ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi tàbí padà ní ọ̀nà náà tí o gbà wá.’”
Ty så har HERREN genom sitt ord bjudit mig och sagt: Du skall varken äta eller dricka, och ej heller vända tillbaka samma väg du har gått hit."
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó gba ọ̀nà mìíràn, kò sì padà gba ọ̀nà tí ó gbà wá sí Beteli.
Därefter gick han sina färde en annan väg och vände icke tillbaka samma väg han hade kommit till Betel.
11 Wòlíì àgbà kan wà tí ń gbé Beteli, ẹni tí àwọn ọmọ rẹ̀ dé, tí ó sì ròyìn gbogbo ohun tí ènìyàn Ọlọ́run náà ti ṣe ní Beteli ní ọjọ́ náà fún un. Wọ́n sì tún sọ fún baba wọn ohun tí ó sọ fún ọba.
Men i Betel bodde en gammal profet. Dennes son kom och förtäljde för honom allt vad gudsmannen den dagen hade gjort i Betel, huru han hade talat till konungen. När de hade förtäljt detta för sin fader,
12 Baba wọn sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ọ̀nà wo ni ó gbà?” Àwọn ọmọ rẹ̀ sì fi ọ̀nà tí ènìyàn Ọlọ́run láti Juda gbà hàn án.
frågade deras fader dem vilken väg han hade gått. Och hans söner visste vilken väg gudsmannen som kom från Juda hade gått.
13 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un tán, ó sì gùn ún.
Då sade han till sina söner: "Sadlen åsnan åt mig." När de då hade sadlat åsnan åt honom, satte han sig på den
14 Ó sì tẹ̀lé ènìyàn Ọlọ́run náà lẹ́yìn. Ó sì rí i tí ó jókòó lábẹ́ igi óákù kan, ó sì wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá bí?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Èmi ni.”
och begav dig åstad efter gudsmannen och fann honom sittande under terebinten; och han frågade honom: "Är du den gudsman som har kommit från Juda?" Han svarade: "Ja."
15 Nígbà náà ni wòlíì náà sì wí fún un pé, “Bá mi lọ ilé, kí o sì jẹun.”
Då sade han till honom: "Kom med mig hem och ät med mig."
16 Ènìyàn Ọlọ́run náà sì wí pé, “Èmi kò le padà sẹ́yìn tàbí bá ọ lọ ilé, tàbí kí èmi kí ó jẹ oúnjẹ tàbí mu omi pẹ̀lú rẹ níhìn-ín.
Men han svarade: "Jag kan icke vända om med dig och följa dig, och jag vill icke äta eller dricka med dig här på orten;
17 A ti sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi níhìn-ín tàbí kí o padà lọ nípa ọ̀nà tí ìwọ bá wá.’”
ty så har blivit mig sagt genom HERRENS ord: Du skall varken äta eller dricka där; du skall icke heller gå tillbaka samma väg du har gått dit."
18 Wòlíì àgbà náà sì wí fún un pé, “Wòlíì ni èmi náà pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìwọ. Angẹli sì sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Mú un padà wá sí ilé rẹ, kí ó lè jẹ oúnjẹ àti kí ó lè mu omi.’” (Ṣùgbọ́n ó purọ́ fún un ni.)
Han sade till honom: "Jag är ock en profet såsom du, och en ängel har talat till mig på HERRENS befallning och sagt: 'För honom tillbaka med dig hem och giv honom att äta och dricka.'" Men häri ljög han för honom.
19 Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà sì padà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì jẹ oúnjẹ ó sì mu omi ní ilé rẹ̀.
Då vände han tillbaka med honom och åt i hans hus och drack.
20 Bí wọ́n sì ti jókòó ti tábìlì, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ wòlíì tí ó mú un padà wá pé;
Men under det att de sutto till bords, kom HERRENS ord till profeten som hade fört honom tillbaka.
21 Ó sì kígbe sí ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́, ìwọ kò sì pa àṣẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ mọ́.
Och han ropade till gudsmannen som hade kommit från Juda och sade: "Så säger HERREN: Därför att du har varit gensträvig mot HERRENS ord och icke hållit det bud som HERREN, din Gud, har givit dig,
22 Ìwọ padà, ìwọ sì ti jẹ oúnjẹ, ìwọ sì ti mu omi níbi tí ó ti sọ fún ọ pé kí ìwọ kí ó má ṣe jẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Nítorí náà, a kì yóò sin òkú rẹ sínú ibojì àwọn baba rẹ.’”
utan vänt tillbaka och ätit och druckit på den ort där han hade förbjudit, dig att äta och dricka, därför skall din döda kropp icke komma i dina fäders grav.
23 Nígbà tí ènìyàn Ọlọ́run sì ti jẹun tán àti mu omi tan, wòlíì tí ó ti mú u padà sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un.
Sedan han nu hade ätit och druckit, sadlade han åsnan åt honom, åt profeten som han hade fört tillbaka.
24 Bí ó sì ti ń lọ ní ọ̀nà rẹ̀, kìnnìún kan pàdé rẹ̀ ní ọ̀nà, ó sì pa á, a sì gbé òkú rẹ̀ sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró tì í lẹ́gbẹ̀ẹ́.
Och denne begav sig åstad; men ett lejon kom emot honom på vägen och dödade honom. Sedan låg hans döda kropp utsträckt där på vägen, under det att åsnan stod bredvid den; och lejonet stod också bredvid den döda kroppen.
25 Àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá sì rí pé ó gbé òkú náà sọ sí ojú ọ̀nà, kìnnìún náà sì dúró ti òkú náà; wọ́n sì wá, wọ́n sì sọ ọ́ ní ìlú tí wòlíì àgbà náà ń gbé.
Då nu folk som gick därförbi fick se den döda kroppen ligga utsträckt på vägen och lejonet stå bredvid den döda kroppen, gingo de in i staden där den gamle profeten bodde och omtalade det där.
26 Nígbà tí wòlíì tí ó mú un padà wá láti ọ̀nà rẹ̀ sì gbọ́ èyí, ó sì wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run náà ni tí ó ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́. Olúwa sì ti fi lé kìnnìún lọ́wọ́, tí ó sì fà á ya, tí ó sì pa á, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti kìlọ̀ fún un.”
När profeten, som hade fört honom tillbaka från hans väg, hörde det, sade han: "Det är gudsmannen, han som var gensträvig mot HERRENS ord; därför har HERREN givit honom i lejonets våld, och det har krossat och dödat honom, i enlighet med det ord som HERREN hade talat till honom."
27 Wòlíì náà sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi,” wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Därefter tillsade han sina söner att de skulle sadla åsnan åt honom; och de sadlade den.
28 Nígbà náà ni ó sì jáde lọ, ó sì rí òkú náà tí a gbé sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Kìnnìún náà kò sì jẹ òkú náà, tàbí fa kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà ya.
Så begav han sig åstad och fann den döda kroppen liggande utsträckt på vägen och åsnan och lejonet stående bredvid den döda kroppen; lejonet hade icke ätit av den döda kroppen och ej heller krossat åsnan.
29 Nígbà náà ni wòlíì náà gbé òkú ènìyàn Ọlọ́run náà, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì gbé e padà wá sí ìlú ara rẹ̀ láti ṣọ̀fọ̀ fún un àti láti sin ín.
Då tog profeten upp gudsmannens döda kropp och lade den på åsnan och förde den tillbaka; och den gamle profeten begav sig in i sin stad för att hålla dödsklagan och begrava honom.
30 Nígbà náà ni ó gbé òkú náà sínú ibojì ara rẹ̀, wọ́n sì ṣọ̀fọ̀ lórí rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ó ṣe, arákùnrin mi!”
Och han lade hans döda kropp i sin egen grav; och de höllo dödsklagan efter honom och ropade: "Ack ve, min broder!"
31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú rẹ̀ tán, ó sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Nígbà tí mo bá kú, ẹ sin mí ní ibojì níbi tí a sin ènìyàn Ọlọ́run sí; ẹ tẹ́ egungun mi lẹ́bàá egungun rẹ̀.
Då han nu hade begravit honom, sade han till sina söner: "När jag dör, så begraven mig i den grav där gudsmannen ligger begraven; läggen mina ben vid sidan av hans ben.
32 Nítorí iṣẹ́ tí ó jẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Olúwa sí pẹpẹ tí ó wà ní Beteli àti sí gbogbo ojúbọ lórí ibi gíga tí ń bẹ ní àwọn ìlú Samaria yóò wá sí ìmúṣẹ dájúdájú.”
Ty förvisso skall det ord gå i fullbordan, som han på HERRENS befallning ropade mot altaret i Betel och mot alla offerhöjdshus i Samariens städer."
33 Lẹ́yìn nǹkan yìí, Jeroboamu kò padà kúrò nínú ọ̀nà búburú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tún yan àwọn àlùfáà sí i fún àwọn ibi gíga nínú gbogbo àwọn ènìyàn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ di àlùfáà, a yà á sọ́tọ̀ fún ibi gíga wọ̀nyí.
Dock vände Jerobeam efter detta icke om från sin onda väg, utan gjorde åter allahanda man ur folket till offerhöjdspräster; vem som hade lust därtill fick av honom mottaga handfyllning till att vara offerhöjdspräst.
34 Èyí sì ni ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jeroboamu, èyí tí ó yọrí sí ìṣubú rẹ̀, a sì pa á run kúrò lórí ilẹ̀.
På detta sätt blev han för Jerobeams hus en orsak till synd, och en orsak till att det blev utplånat och utrotat från jorden.

< 1 Kings 13 >