< 1 Kings 13 >

1 Sì kíyèsi i, ènìyàn Ọlọ́run kan wá láti Juda sí Beteli nípa ọ̀rọ̀ Olúwa, bì Jeroboamu sì ti dúró lẹ́bàá a pẹpẹ láti fi tùràrí jóná.
A IA hoi, hele ae la ke kanaka o ke Akua mailoko ae o Iuda ma ka olelo a Iehova, i Betela, e ku ana o Ieroboama ma ke kuahu e kuni i ka mea ala.
2 Ó sì kígbe sí pẹpẹ náà nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, “Pẹpẹ! Pẹpẹ! Báyìí ni Olúwa wí: ‘A ó bí ọmọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Josiah ní ilé Dafidi. Lórí rẹ ni yóò sì fi àwọn àlùfáà ibi gíga wọ̀n-ọn-nì tí ń fi tùràrí lórí rẹ̀ rú ẹbọ, a ó sì sun egungun ènìyàn lórí rẹ.’”
Kahea aku la oia i ke kuahu ma ka olelo a Iehova, i aku la, E ke kuahu, ke kuahu, ke i mai nei Iehova penei, Aia hoi, e hanau ana ke keiki na ka ohana a Davida, o Iosia kona inoa; a maluna iho ou e kaumaha ai oia i na kahuna pule o na wahi kiekie i kukuni i ka mea ala maluna ou, a e puhiia na iwi kanaka maluna iho ou.
3 Ní ọjọ́ kan náà ènìyàn Ọlọ́run sì fún wọn ní àmì kan wí pé, “Èyí ni àmì tí Olúwa ti kéde: kíyèsi i, pẹpẹ náà yóò ya, eérú tí ń bẹ lórí rẹ̀ yóò sì dànù.”
A haawi ae la i ka hoailona ia la, i ae la, Eia ka hoailona a Iehova i olelo mai ai; Aia hoi, e naha ana ke kuahu, e helelei iho ka lehu, ka mea maluna ona.
4 Nígbà tí Jeroboamu ọba sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ènìyàn Ọlọ́run, tí ó kígbe sí pẹpẹ náà ní Beteli, ó sì na ọwọ́ rẹ̀ jáde nínú pẹpẹ, ó sì wí pé, “Ẹ mú un!” ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ tí ó nà sí i sì kákò, bẹ́ẹ̀ ni kò sì le fà á padà mọ́.
Eia kekahi, i ka lohe ana o ke alii i ka olelo a ke kanaka o ke Akua, ka mea i kahea i ke kuahu, ma Betela, kikoo aku la o Ieroboama i kona lima mai ke kuahu aku, e i ana, E lalau ia ia. A maloo ae la kona lima ana i kikoo ai ia ia, aole hiki ia ia ke hoihoi ia ia iho.
5 Lẹ́sẹ̀kan náà, pẹpẹ ya, eérú náà sì dànù kúrò lórí pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bí àmì tí ènìyàn Ọlọ́run ti fi fún un nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
A ua naha ae la ke kuahu, a ua helelei iho ka lehu mai ke kuahu iho, e like me ka hoailona a ke kanaka o ke Akua i haawi ai, ma ka olelo a Iehova.
6 Nígbà náà ní ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Bẹ̀bẹ̀ pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì gbàdúrà fún mi kí ọwọ́ mi lè padà bọ̀ sípò.” Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Olúwa, ọwọ́ ọba sì padà bọ̀ sípò, ó sì padà sí bí ó ti wà tẹ́lẹ̀.
Olelo mai la hoi ke alii, i mai la i ke kanaka o ke Akua, E nonoi aku oe i ka maka o Iehova kou Akua, a e pule aku no'u, i hoola hou ia mai ko'u lima no'u. A nonoi aku la ke kanaka o ke Akua ia Iehova, a ua hoola hou ia ko ke alii lima nona, a lilo hoi ia e like me mamua.
7 Ọba sì wí fún ènìyàn Ọlọ́run náà pé, “Wá bá mi lọ ilé, kí o sì wá nǹkan jẹ, èmi yóò sì fi ẹ̀bùn fún ọ.”
Olelo mai la hoi ke alii i ke kanaka o ke Akua, E hele mai oe me au i ka hale, a e hooluolu ia oe iho, a e haawi aku au i ka makana nou.
8 Ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run náà dá ọba lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá tilẹ̀ fún mi ní ìdajì ìní rẹ, èmi kì yóò lọ pẹ̀lú rẹ tàbí kí èmi jẹ oúnjẹ tàbí mu omi ní ibí yìí.
I aku la ua kanaka la o ke Akua i ke alii, Ina e haawi mai oe i ka hapalua o kou hale ia'u, aole au e komo me oe, aole hoi au e ai i ka berena, aole hoi au e inu i ka wai ma keia wahi.
9 Nítorí a ti pa á láṣẹ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa wí pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi tàbí padà ní ọ̀nà náà tí o gbà wá.’”
No ka mea, pela no i kauohaia mai ai au ma ka olelo a Iehova, i ka i ana mai, Mai ai i ka berena aole hoi e inu i ka wai, aole hoi e hoi mai ma ke ala ou i hele aku ai.
10 Bẹ́ẹ̀ ni ó gba ọ̀nà mìíràn, kò sì padà gba ọ̀nà tí ó gbà wá sí Beteli.
Pela hoi i hele ai oia ma ke ala e, aole i hoi mai ma ke ala i hele aku ai oia i Betela.
11 Wòlíì àgbà kan wà tí ń gbé Beteli, ẹni tí àwọn ọmọ rẹ̀ dé, tí ó sì ròyìn gbogbo ohun tí ènìyàn Ọlọ́run náà ti ṣe ní Beteli ní ọjọ́ náà fún un. Wọ́n sì tún sọ fún baba wọn ohun tí ó sọ fún ọba.
E noho ana kekahi kaula kahiko ma Betela, a hele mai la kana mau keiki, a hai mai la ia ia i na hana a pau a ke kanaka o ke Akua i hana'i ia la ma Betela; o na olelo ana i olelo ai i ke alii, oia ka lakou i hai ai i ko lakou makuakane.
12 Baba wọn sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ọ̀nà wo ni ó gbà?” Àwọn ọmọ rẹ̀ sì fi ọ̀nà tí ènìyàn Ọlọ́run láti Juda gbà hàn án.
A olelo aku la ko lakou makuakane ia lakou, Ma ke ala hea i hele ai ia? Ua ike hoi kana mau keiki i ke ala i hele ai ke kanaka o ke Akua, i ka mea i hele mai, mai Iuda mai.
13 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi.” Nígbà tí wọ́n sì ti di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un tán, ó sì gùn ún.
I aku la hoi oia i kana mau keiki, E kau aku i ka noholio maluna o ka hoki no'u. Kau aku la hoi lakou i ka noho maluna o ka hoki nona, a holo oia maluna iho.
14 Ó sì tẹ̀lé ènìyàn Ọlọ́run náà lẹ́yìn. Ó sì rí i tí ó jókòó lábẹ́ igi óákù kan, ó sì wí fún un pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá bí?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Èmi ni.”
Hahai aku la oia mamuli o ke kanaka o ke Akua, a loaa oia ia ia e noho ana malalo ae o ka laau oka; a i aku la oia ia ia, O oe anei ke kanaka o ke Akua i hele mai mai Iuda mai? I mai la oia, Owau no.
15 Nígbà náà ni wòlíì náà sì wí fún un pé, “Bá mi lọ ilé, kí o sì jẹun.”
I aku la oia ia ia, E hele mai me au i ka hale e ai i ka berena.
16 Ènìyàn Ọlọ́run náà sì wí pé, “Èmi kò le padà sẹ́yìn tàbí bá ọ lọ ilé, tàbí kí èmi kí ó jẹ oúnjẹ tàbí mu omi pẹ̀lú rẹ níhìn-ín.
I mai la hoi oia, Aole e hiki ia'u ke hoi aku me oe, aole hoi au e ai i ka berena, aole hoi e inu i ka wai i keia wahi.
17 A ti sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ jẹ oúnjẹ tàbí mu omi níhìn-ín tàbí kí o padà lọ nípa ọ̀nà tí ìwọ bá wá.’”
No ka mea, ua oleloia mai ia'u ma ka olelo a Iehova, Mai ai i ka berena, aole hoi e inu i ka wai malaila, aole hoi e hoi mai ma ke ala ou e hele aku ai.
18 Wòlíì àgbà náà sì wí fún un pé, “Wòlíì ni èmi náà pẹ̀lú, gẹ́gẹ́ bí ìwọ. Angẹli sì sọ fún mi nípa ọ̀rọ̀ Olúwa pé, ‘Mú un padà wá sí ilé rẹ, kí ó lè jẹ oúnjẹ àti kí ó lè mu omi.’” (Ṣùgbọ́n ó purọ́ fún un ni.)
Olelo aku la oia, He kaula no hoi au e like me oe, a ua olelo mai nei ka anela ia'u ma ka olelo a Iehova, i mai la, E hoihoi mai oe ia ia me oe iloko o kou hale e ai oia i ka berena, a inu hoi i ka wai. Hoopunipuni mai no ia ia ia.
19 Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn Ọlọ́run náà sì padà pẹ̀lú rẹ̀, ó sì jẹ oúnjẹ ó sì mu omi ní ilé rẹ̀.
Pela ia i hoi ai me ia, a ai iho la i ka berena maloko o kona hale, a ua inu hoi i ka wai.
20 Bí wọ́n sì ti jókòó ti tábìlì, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ wòlíì tí ó mú un padà wá pé;
Eia kekahi, i ko laua noho ana, i ka papaaina, hiki mai la ka olelo a Iehova i ke kaula nana ia i hoihoi mai.
21 Ó sì kígbe sí ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti Juda wá wí pé, “Báyìí ni Olúwa wí: ‘Ìwọ ti ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́, ìwọ kò sì pa àṣẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ mọ́.
A kahea aku la oia i ke kanaka o ke Akua i hele aku mai Iuda aku, i aku la, Ke i mai nei o Iehova penei, No ka mea, ua hookuli oe i ka waha o Iehova, aole oe i malama i ke kauoha a Iehova kou Akua i kauoha mai ai ia oe,
22 Ìwọ padà, ìwọ sì ti jẹ oúnjẹ, ìwọ sì ti mu omi níbi tí ó ti sọ fún ọ pé kí ìwọ kí ó má ṣe jẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Nítorí náà, a kì yóò sin òkú rẹ sínú ibojì àwọn baba rẹ.’”
Aka, ua hoi mai nei oe, a ua ai oe i ka berena, a ua inu hoi i ka wai ma keia wahi i olelo ai oia ia oe, Mai ai oe i ka berena, mai inu oe i ka wai; aole e hiki kou kupapau i ka halekupapau o kou mau makua.
23 Nígbà tí ènìyàn Ọlọ́run sì ti jẹun tán àti mu omi tan, wòlíì tí ó ti mú u padà sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún un.
Eia hoi kekahi, mahope iho o kana ai ana i ka berena, a mahope iho o kona inu ana, kau aku la oia i ka noholio maluna o ka hoki nona, no ke kaula ana i hoihoi mai ai.
24 Bí ó sì ti ń lọ ní ọ̀nà rẹ̀, kìnnìún kan pàdé rẹ̀ ní ọ̀nà, ó sì pa á, a sì gbé òkú rẹ̀ sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró tì í lẹ́gbẹ̀ẹ́.
A hele ae ia, halawai ka liona me ia, a pepehi mai la ia ia: a ua hooleiia kona kupapau ma ke alanui; a ku mai la ka hoki kokoke ia ia, a o ka liona kekahi i ku mai kokoke i ke kupapau.
25 Àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá sì rí pé ó gbé òkú náà sọ sí ojú ọ̀nà, kìnnìún náà sì dúró ti òkú náà; wọ́n sì wá, wọ́n sì sọ ọ́ ní ìlú tí wòlíì àgbà náà ń gbé.
Aia hoi, maalo ae la na kanaka a ike ae la hoi i ke kupapau, i hooleiia i ke alanui, a e ku ana hoi ka liona kokoke i ke kupapau; a hele lakou a hai ma ke kulanakauhale i noho ai ke kaula elemakule.
26 Nígbà tí wòlíì tí ó mú un padà wá láti ọ̀nà rẹ̀ sì gbọ́ èyí, ó sì wí pé, “Ènìyàn Ọlọ́run náà ni tí ó ba ọ̀rọ̀ Olúwa jẹ́. Olúwa sì ti fi lé kìnnìún lọ́wọ́, tí ó sì fà á ya, tí ó sì pa á, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti kìlọ̀ fún un.”
A i ka lohe ana o ke kaula nana ia i hoihoi ae mai ke ala ae, olelo ae la oia, O ke kanaka o ke Akua ia, ka mea i malama ole i ka olelo a Iehova; a ua haawi ae nei o Iehova ia ia i ka liona ka mea nana ia i uhae a i pepehi hoi, e like me ka olelo a Iehova ana i olelo mai ai ia ia.
27 Wòlíì náà sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì fún mi,” wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Kauoha ae la hoi oia i kana mau keiki, i ae la, E kau i ka noholio maluna o ka hoki no'u; kau aku la hoi lakou i ka noholio.
28 Nígbà náà ni ó sì jáde lọ, ó sì rí òkú náà tí a gbé sọ sí ojú ọ̀nà, pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti kìnnìún tí ó dúró lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀. Kìnnìún náà kò sì jẹ òkú náà, tàbí fa kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà ya.
Holo aku la ia a loaa ia ia kona kupapau i hooleiia ma ke alanui, e ku ana no ka hoki a me ka liona kokoke i ke kupapau: aole i ai ka liona i ke kupapau, aole hoi i uhae aku i ka hoki.
29 Nígbà náà ni wòlíì náà gbé òkú ènìyàn Ọlọ́run náà, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì gbé e padà wá sí ìlú ara rẹ̀ láti ṣọ̀fọ̀ fún un àti láti sin ín.
Hapai ae la ke kaula i ke kupapau o ke kanaka o ke Akua, a kau aku la ia ia maluna o ka hoki, a hoihoi mai ia ia: a hoi mai hoi ke kaula elemakule i ke kulanakauhale, e uwe ae, a e kanu hoi ia ia.
30 Nígbà náà ni ó gbé òkú náà sínú ibojì ara rẹ̀, wọ́n sì ṣọ̀fọ̀ lórí rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Ó ṣe, arákùnrin mi!”
Hoomoe iho la oia i kona kupapau iloko o kona luakupapau iho, a uwe ae lakou ia ia, e olelo ana, Auwe kuu hoahanau!
31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti sìnkú rẹ̀ tán, ó sì wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Nígbà tí mo bá kú, ẹ sin mí ní ibojì níbi tí a sin ènìyàn Ọlọ́run sí; ẹ tẹ́ egungun mi lẹ́bàá egungun rẹ̀.
Eia hoi kekahi, mahope iho o kona kanu ana ia ia, olelo ae la oia i kana mau keiki, i ae la, Aia make au, e kanu iho oukou ia'u maloko o ka halekupapau, kahi i kanuia'i ke kanaka o ke Akua, e waiho pu iho i ko'u mau iwi me kona mau iwi:
32 Nítorí iṣẹ́ tí ó jẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Olúwa sí pẹpẹ tí ó wà ní Beteli àti sí gbogbo ojúbọ lórí ibi gíga tí ń bẹ ní àwọn ìlú Samaria yóò wá sí ìmúṣẹ dájúdájú.”
No ka mea, o ka olelo ana i hea ku e aku ai i ke kuahu ma Betela ma ka olelo a Iehova, a i na hale a pau o na wahi kiekie maloko o na kulanakauhale o Samaria, e ko io auanei no ia.
33 Lẹ́yìn nǹkan yìí, Jeroboamu kò padà kúrò nínú ọ̀nà búburú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tún yan àwọn àlùfáà sí i fún àwọn ibi gíga nínú gbogbo àwọn ènìyàn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ di àlùfáà, a yà á sọ́tọ̀ fún ibi gíga wọ̀nyí.
Mahope ae o keia mea, aole i huli ae o Ieroboama mai kona aoao hewa ae, aka, hoolilo ae la oia i na makaainana, i mau kahuna pule no na wahi kiekie; o ka mea makemake, oia kana i hoolaa ai, a lilo ia i kahuna no na wahi kiekie.
34 Èyí sì ni ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jeroboamu, èyí tí ó yọrí sí ìṣubú rẹ̀, a sì pa á run kúrò lórí ilẹ̀.
A lilo keia mea i hewa no ka ohana a Ieroboama, e oki aku ai, a e luku aku ai hoi ia mai ka ili o ka honua aku.

< 1 Kings 13 >